< Proverbs 18 >

1 Ènìyàn tí kò ba ni rẹ́ a máa lépa ìmọ̀ ara rẹ̀; ó kọjú ìjà sí gbogbo ìdájọ́ òdodo.
Samolub szuka tego, co mu się podoba, i wtrąca się w każdą sprawę.
2 Aláìgbọ́n kò rí inú dídùn sí òye ṣùgbọ́n ó ní inú dídùn sí sísọ èrò tirẹ̀.
Głupi nie ma upodobania w rozumie, lecz w tym, co serce mu objawia.
3 Nígbà ti ènìyàn búburú dé ni ẹ̀gàn dé, nígbà ti ẹ̀gàn dé ni ìtìjú dé.
Gdy przychodzi niegodziwy, przychodzi też pogarda, a z hańbą urąganie.
4 Ọ̀rọ̀ ẹnu ènìyàn jẹ́ omi jíjìn, ṣùgbọ́n orísun ọgbọ́n jẹ́ odò tí ń sàn.
Słowa ust człowieka są jak głębokie wody, a źródło mądrości jak płynący potok.
5 Kò dára kí ènìyàn ṣe ojúsàájú fún ènìyàn búburú tàbí kí a fi ìdájọ́ òdodo du aláìṣẹ̀.
Niedobrze przez wzgląd na osobę niegodziwą krzywdzić sprawiedliwego w sądzie.
6 Ètè aláìgbọ́n dá ìjà sílẹ̀ ẹnu rẹ̀ sì ń ṣokùnfà ẹgba.
Wargi głupiego wchodzą w spór, a jego usta wołają o razy.
7 Ẹnu aláìgbọ́n ni ó ba tirẹ̀ jẹ́, ètè rẹ̀ sì jẹ́ ìdẹ̀kùn fún ọkàn rẹ̀.
Usta głupiego [są] jego zgubą, a jego wargi sidłem jego duszy.
8 Ọ̀rọ̀ olófòófó dàbí oúnjẹ àdídùn; wọ́n a sì wọ ìsàlẹ̀ inú lọ.
Słowa plotkarza są jak rany i przenikają do głębi wnętrzności.
9 Ẹni tí kò ṣe déédé nínú iṣẹ́ rẹ̀ arákùnrin ló jẹ́ fún apanirun.
Kto jest niedbały w pracy, jest bratem marnotrawcy.
10 Orúkọ Olúwa, ilé ìṣọ́ agbára ni; olódodo sá wọ inú rẹ̀, ó sì rí ìgbàlà.
Imię PANA [jest] potężną wieżą, sprawiedliwy ucieka do niej i jest bezpieczny.
11 Ọ̀rọ̀ olówó ni ìlú olódi wọn; wọ́n rò ó bí i wí pé odi tí kò ṣe é gùn ni.
Zamożność bogacza [jest] jego warownym miastem i jak wysoki mur w jego wyobrażeniu.
12 Ṣáájú ìṣubú ọkàn ènìyàn a kọ́kọ́ máa gbéraga, ṣùgbọ́n ìrẹ̀lẹ̀ ni ó máa ń ṣáájú ọlá.
Przed upadkiem serce człowieka jest wyniosłe, a chwałę poprzedza pokora.
13 Ẹni tí ó ń fèsì kí ó tó gbọ́, èyí ni ìwà òmùgọ̀ àti ìtìjú rẹ̀.
Kto odpowiada, zanim wysłucha, [ujawnia] głupotę i [ściąga na] siebie hańbę.
14 Ọkàn ènìyàn a máa gbé e ró nígbà àìsàn, ṣùgbọ́n ta ni ó le forí ti ọkàn tí ó rẹ̀wẹ̀sì.
Duch człowieka zniesie jego chorobę, ale któż zniesie strapionego ducha?
15 Ọkàn olóye ní i gba ìmọ̀; etí ọlọ́gbọ́n ní í ṣe àwárí rẹ̀.
Serce rozumnego zdobywa wiedzę, a ucho mądrych szuka wiedzy.
16 Ẹ̀bùn máa ń ṣí ọ̀nà fún ẹni tí ń fún ni lẹ́bùn a sì mú un wọlé sí ọ̀dọ̀ àwọn olókìkí.
Dar człowieka toruje mu drogę i prowadzi go przed wielkich.
17 Ẹni tí ó kọ́kọ́ rọjọ́ máa ń dàbí i pé ó jàre, títí ẹlòmíràn yóò fi bọ́ síwájú kí ó sì tú àṣírí gbogbo.
Ten, który jest pierwszy w swojej sprawie, [zdaje się] sprawiedliwy, ale przychodzi jego bliźni i sprawdza go.
18 Ìbò dídì máa ń parí ìjà a sì mú kí àwọn alátakò méjì jìnnà sí ara wọn.
Los kładzie kres sporom i rozstrzyga między możnymi.
19 Arákùnrin tí a ṣẹ̀ sí ṣòro yípadà ju ìlú olódi lọ, ìjà wọ sì dàbí ọ̀pá ìdábùú ààfin.
Brat obrażony [trudniejszy do zdobycia] niż warowne miasto, a spory są jak rygle w zamku.
20 Láti inú èso ẹnu rẹ̀ ikùn ènìyàn a yó; láti inú ìkórè ẹnu rẹ̀ ni ó ti jẹ yó.
Owocem swoich ust nasyci człowiek swoje wnętrze, nasyci się plonem swych warg.
21 Ikú àti ìyè ń bẹ nípa ahọ́n wọn, àwọn tí ó sì fẹ́ràn rẹ̀ yóò jẹ ẹ́.
Śmierć i życie są w mocy języka, a kto go miłuje, spożyje jego owoc.
22 Ẹni tí ó rí aya fẹ́, rí ohun rere, o sì gba ojúrere lọ́dọ̀ Olúwa.
Kto znalazł żonę, znalazł coś dobrego i dostąpił łaski od PANA.
23 Tálákà ń bẹ̀bẹ̀ fún àánú, ṣùgbọ́n ọlọ́rọ̀ a dáhùn pẹ̀lú ìkanra.
Ubogi prosi pokornie, ale bogaty odpowiada surowo.
24 Ènìyàn tí ó ní ọ̀rẹ́ púpọ̀ le è parun, ṣùgbọ́n ọ̀rẹ́ kan wà tí ó súnmọ́ ni tímọ́tímọ́ ju arákùnrin.
Człowiek, który ma przyjaciół, musi obchodzić się z nimi po przyjacielsku, a jest przyjaciel, który przylgnie bardziej niż brat.

< Proverbs 18 >