< Philippians 4 >

1 Nítorí náà ẹ̀yin ará mi olùfẹ́, ti mo sì ń ṣàfẹ́rí gidigidi, ayọ̀ àti adé mi, ẹ dúró ṣinṣin bẹ́ẹ̀ nínú Olúwa, ẹ̀yin olùfẹ́ mi.
NOLAILA hoi, e na hoahanau o'u i alohaia, a i makemake nui ia, o kuu olioli a me kuu leialii; pela e kupaa ai oukou iloko o ka Haku, e na mea i alohaia.
2 Èmi ń bẹ̀ Euodia, mo sì ń bẹ Sintike, kí wọn ní inú kan náà nínú Olúwa.
Ke noi aku nei au ia Euodia, ke noi aku nei hoi au ia Sunetuke, i hookahi ko laua manao iloko o ka Haku.
3 Mo sì bẹ̀ yin pẹ̀lú bí alájọru àjàgà mi tòótọ́, ran àwọn obìnrin wọ̀nyí lọ́wọ́, nítorí wọn bá mi ṣiṣẹ́ pọ̀ ní ìfẹ̀gbẹ́-kẹ̀gbẹ́ nínú ìyìnrere, àti Klementi pẹ̀lú, àti àwọn olùbáṣiṣẹ́ mi yòókù pẹ̀lú, orúkọ àwọn tí ń bẹ nínú ìwé ìyè.
Ke noi aku nei hoi au ia oe kekahi, e ka hoalawehana io, e kokua aku oe ia mau wahine, i hooikaika pu me au ma ka euanelio, a me Kelemeneto hoi, a me o'u mau hoalawehana e ae, aia no maloko o ka buke ola ko lakou mau inoa.
4 Ẹ máa yọ̀ nínú Olúwa nígbà gbogbo: mo sì tún wí pé. Ẹ máa yọ̀.
E hauoli mau oukou i ka Haku; ke olelo hou aku nei hoi au, e hauoli oukou.
5 Ẹ jẹ́ ki ìpamọ́ra yín di mímọ́ fún gbogbo ènìyàn, Olúwa ń bẹ nítòsí.
I hoikeia hoi ko oukou akahai i na kanaka a pau. Ua kokoke mai ka Haku.
6 Ẹ má ṣe ṣe àníyàn ohunkóhun; ṣùgbọ́n nínú ohun gbogbo, nípa àdúrà àti ẹ̀bẹ̀ pẹ̀lú ìdúpẹ́, ẹ máa fi ìbéèrè yín hàn fún Ọlọ́run.
Mai manao nui oukou i kekahi mea; aka, i na mea a pau e hoike aku i ko oukou makemake i ke Akua ma ka pule, a me ka noi aku, a me ka hoomaikai aku.
7 Àti àlàáfíà Ọlọ́run, tí ó ju ìmòye gbogbo lọ, yóò pa ọkàn àti èrò yín mọ nínú Kristi Jesu.
A o ka maluhia o ke Akua, ka mea i oi aku i ko ke kanaka manao a pau, e hoomalu mai i ko oukou naau a me ko oukou manao ma o Kristo Iesu la.
8 Ní àkótán, ará, ohunkóhun tí í ṣe òtítọ́, ohunkóhun tí í ṣe ọ̀wọ̀, ohunkóhun tí í ṣe títọ́ ohunkóhun tí í ṣe mímọ́, ohunkóhun tí í ṣe fífẹ́, ohunkóhun tí ó ni ìròyìn rere, bí ìwà títọ́ kan bá wà, bí ìyìn kan bá sì wà, ẹ máa gba nǹkan wọ̀nyí rò.
Eia hoi e na hoahanau, o na mea oiaio, na mea maikai, na mea pono, na mea hala ole, na mea lokomaikai, na mea lono maikai ia; ina he mea kupono, ina hoi he mea e hoomaikaiia'i, e noonoo iho oukou ia mau mea.
9 Àwọn nǹkan tí ẹ̀yin ti kọ́, tí ẹ̀yin sì ti gbà, tí ẹ̀yin sì ti gbọ́, tí ẹ̀yin sì ti rí lọ́wọ́ mi, ẹ máa ṣe wọ́n: Ọlọ́run àlàáfíà yóò sì wà pẹ̀lú yín.
O na mea a oukou i aoia'i, i loaa hoi, i lohe a i ike hoi ia'u, o keia ka oukou e hana'i; a me oukou hoi ke Akua ka mea e malu ai.
10 Èmi yọ̀ gidigidi nínú Olúwa pé, nísinsin yìí, ẹ̀yin tún ti sọjí nínú àníyàn ọkàn yín sí mi, nítòótọ́ ọkàn yín ń fàmọ́ mi ṣùgbọ́n ẹ kò ní àǹfààní tó.
Ua olioli nui au i ka Haku, no ka mea, ua kupu hou mai ko oukou manao e kokua ia'u; malaila no oukou i manao ai, aka, aole a oukou mea e hiki ai.
11 Kì í ṣe pé èmi ń sọ nítorí àìní: nítorí pé ni ipòkípò tí mo bá wà, mo tí kọ́ láti ní ìtẹ́lọ́rùn nínú rẹ̀.
Aole au i olelo pela no ka nele; no ka mea, ua aoia hoi au e oluolu iho i na mea a pau i loaa ia'u.
12 Mo mọ̀ ohun tí o jẹ láti wa nínú àìní, mo sì mọ ohun tí ó jẹ láti ni lọ́pọ̀lọ́pọ̀. Nínú ohunkóhun àti nínú ohun gbogbo mo ti kọ́ àṣírí láti máa jẹ́ àjẹyó tàbí láti wà ni àìjẹun, láti máa ni ànító àti láti ṣe aláìní.
Ua ike hoi au i ka noho ilihune, a me ka noho lako: i na wahi a pau, a i na mea a pau, ua aoia mai la au e noho maona a e noho pololi, e noho lako a e noho nele.
13 Èmi le ṣe ohun gbogbo nínú Kristi ẹni ti ń fi agbára fún mi.
E hiki no ia'u na mea a pau, ke kokua mai o Kristo ia'u.
14 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ṣeun gidigidi ní ti pé ẹ̀yin ṣe alábápín nínú ìpọ́njú mi.
Aka hoi, ua hana pono mai oukou, i ko oukou manawalea ana mai ia'u i ko'u popilikia.
15 Ẹ̀yin pàápàá sì mọ̀ pẹ̀lú, ẹ̀yin ará Filipi, pé ni ìbẹ̀rẹ̀ ìyìnrere, nígbà tí mo kúrò ni Makedonia, kò sí ìjọ kan ti ó bá mi ń ṣe alábápín ní ti gbígbà àti fífún ni, bí kò ṣe ẹ̀yin nìkan ṣoṣo.
E ko Pilipi, ua ike no oukou, i ka wa kinohou o ka euanelio, ia'u i haalele ai ia Makedonia, aole kekahi ekalesia e ae i launa mai ia'u i ka haawi ana a i ka lawe ana, o oukou wale no.
16 Nítorí ní Tẹsalonika ẹ̀yin fi nǹkan ránṣẹ́, lẹ́ẹ̀kan fún àìní mi.
No ka mea, a i Tesalouike hookahi a elua hoi o ko oukou hoouka ana mai i ka mea e pono ai kuu nele.
17 Kì í ṣe nítorí ti èmi ń fẹ́ ẹ̀bùn náà, ṣùgbọ́n èmi ń fẹ́ èso ti yóò máa di púpọ̀ nítorí yín.
Aole ka makana ka'u e imi nei; aka, ke imi nei au i ka hua e nui ai ko oukou pono.
18 Ṣùgbọ́n mo ní ohun gbogbo, mo sì ti di púpọ̀, mo sì tún ni lọ́pọ̀lọ́pọ̀ nígbà ti mo tí gba nǹkan wọ̀nyí lọ́wọ́ Epafiroditu tí a ti rán wá láti lọ́dọ̀ yín, ọrẹ olóòórùn dídùn, ẹbọ ìtẹ́wọ́gbà, tì í ṣe inú dídùn gidigidi sí Ọlọ́run.
A ia'u na mea he nui, a ua lako hoi: ua piha au i ka oukou mau mea i loaa mai ma o Epaperodito la, he mea ala oluolu, he mohai hooluolu, i maliuia mai hoi e ke Akua.
19 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run mi yóò pèsè ní kíkún fún gbogbo àìní yín, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ̀ nínú ògo nínú Kristi Jesu.
Aka, e haawi mai ana ko'u Akua i na mea a pau e pono ai oukou, no kona waiwai i kahi nani ma o Kristo Iesu la.
20 Ṣùgbọ́n ògo ni fún Ọlọ́run àti Baba wa láé àti láéláé. Àmín. (aiōn g165)
A i ke Akua ko kakou Makua ka hoonani mau loa ia i ke ao pau ole. Amene. (aiōn g165)
21 Ẹ kí olúkúlùkù ènìyàn mímọ́ nínú Kristi Jesu. Àwọn ará tí ó wà pẹ̀lú mi kí yín.
E uwe aku i na haipule a pau iloko o Kristo Iesu. Ke uwe aku nei na hoahanau me au ia oukou.
22 Gbogbo àwọn ènìyàn mímọ́ kí yín, pàápàá àwọn tí ń ṣe ti agbo ilé Kesari.
Ke uwe aku nei na haipule a pau ia oukou, o lakou hoi no na ohua o Kaisara.
23 Oore-ọ̀fẹ́ Jesu Kristi Olúwa wa, kí ó wà pẹ̀lú ẹ̀mí yín. Àmín.
O ke aloha o ko kakou Haku o Iesu Kristo me oukou a pau. Amene.

< Philippians 4 >