< Numbers 1 >

1 Olúwa bá Mose sọ̀rọ̀ ní aginjù Sinai nínú àgọ́ àjọ ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kejì ní ọdún kejì tí àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti, ó wí pé,
PAN przemówił do Mojżesza na pustyni Synaj, w Namiocie Zgromadzenia, pierwszego [dnia] drugiego miesiąca, w drugim roku po ich wyjściu z ziemi Egiptu, tymi słowy:
2 “Ka gbogbo àgbájọ ènìyàn Israẹli nípa ẹbí wọn, àti nípa ìdílé baba wọn, to orúkọ wọn olúkúlùkù ọkùnrin ní ọ̀kọ̀ọ̀kan.
Policzcie całe zgromadzenie synów Izraela według ich rodzin i według domów ich ojców, licząc imiona wszystkich mężczyzn, głowa po głowie;
3 Ìwọ àti Aaroni ni kí ẹ kà gbogbo ọmọkùnrin Israẹli gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn láti ọmọ ogún ọdún sókè, àwọn tí ó tó lọ sójú ogun.
Od dwudziestu lat wzwyż, wszystkich w Izraelu zdolnych do walki. Ty i Aaron policzycie ich według ich oddziałów.
4 Kí ẹ mú ọkùnrin kọ̀ọ̀kan láti inú olúkúlùkù ẹ̀yà kí ó sì wá pẹ̀lú yín, kí olúkúlùkù jẹ́ olórí ilé àwọn baba rẹ̀.
I będzie z wami jeden mężczyzna z każdego pokolenia, głowa domu swoich ojców.
5 “Orúkọ àwọn ọkùnrin tí yóò ràn ọ́ lọ́wọ́ nìyí: “Láti ọ̀dọ̀ Reubeni, Elisuri ọmọ Ṣedeuri.
A oto imiona mężczyzn, którzy będą z wami: z [pokolenia] Rubena – Elizur, syn Szedeura;
6 Láti ọ̀dọ̀ Simeoni, Ṣelumieli ọmọ Suriṣaddai.
Z Symeona – Szelumiel, syn Suriszaddaja;
7 Láti ọ̀dọ̀ Juda, Nahiṣoni ọmọ Amminadabu.
Z Judy – Nachszon, syn Amminadaba;
8 Láti ọ̀dọ̀ Isakari, Netaneli ọmọ Suari.
Z Issachara – Netaneel, syn Suara;
9 Láti ọ̀dọ̀ Sebuluni, Eliabu ọmọ Heloni.
Z Zebulona – Eliab, syn Chelona;
10 Láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ Josẹfu: láti ọ̀dọ̀ Efraimu, Eliṣama ọmọ Ammihudu. Láti ọ̀dọ̀ Manase, Gamalieli ọmọ Pedasuri.
Z synów Józefa: z Efraima – Eliszama, syn Ammihuda, z Manassesa – Gamliel, syn Pedahsura;
11 Láti ọ̀dọ̀ Benjamini, Abidani ọmọ Gideoni.
Z Beniamina – Abidan, syn Gideoniego;
12 Láti ọ̀dọ̀ Dani, Ahieseri ọmọ Ammiṣaddai.
Z Dana – Achiezer, syn Ammiszaddaja;
13 Láti ọ̀dọ̀ Aṣeri, Pagieli ọmọ Okanri.
Z Aszera – Pagiel, syn Okrana;
14 Láti ọ̀dọ̀ Gadi, Eliasafu ọmọ Deueli.
Z Gada – Eliasaf, syn Deuela;
15 Láti ọ̀dọ̀ Naftali, Ahira ọmọ Enani.”
Z Neftalego – Achira, syn Enana.
16 Àwọn wọ̀nyí ni wọ́n yàn nínú àwùjọ ènìyàn, olórí àwọn ẹ̀yà baba wọn. Àwọn ni olórí àwọn ẹbí Israẹli.
Ci powołani, [sławni] spośród zgromadzenia, byli naczelnikami pokoleń swych ojców, wodzami tysięcy w Izraelu.
17 Mose àti Aaroni mú àwọn ènìyàn tí a dárúkọ wọ̀nyí
Mojżesz i Aaron przyjęli więc tych mężczyzn, którzy zostali imiennie wyznaczeni.
18 wọ́n sì pe gbogbo àwùjọ ènìyàn Israẹli jọ ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kejì. Àwọn ènìyàn sì dárúkọ baba ńlá wọn nípa ẹbí àti ìdílé wọn. Wọ́n sì ṣe àkọsílẹ̀ orúkọ àwọn ọmọkùnrin ní ọ̀kọ̀ọ̀kan láti ọmọ ogún ọdún sókè,
I zebrali całe zgromadzenie w pierwszym dniu drugiego miesiąca, a każdy podawał swoje pochodzenie według swych rodzin, według domów swych ojców i według liczby imion, od dwudziestu lat wzwyż, głowa po głowie.
19 gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose. Bẹ́ẹ̀ náà ló ṣe kà wọ́n nínú aginjù Sinai.
Jak PAN rozkazał Mojżeszowi, tak policzył ich na pustyni Synaj.
20 Láti ìran Reubeni tí í ṣe àkọ́bí Israẹli, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún sókè tí wọ́n lè lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn, lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
Synów Rubena, pierworodnego Izraela, ich potomków według ich rodzin, według domów ich ojców, według liczby imion, głowa po głowie, wszystkich mężczyzn od dwudziestu lat wzwyż, wszystkich zdolnych do walki;
21 Àwọn tí a kà ní ẹ̀yà Reubeni jẹ́ ẹgbàá mẹ́tàlélógún ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta.
Naliczono z pokolenia Rubena czterdzieści sześć tysięcy pięciuset.
22 Láti ìran Simeoni, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún sókè, tí wọ́n lè lọ sójú ogun ni wọ́n kà, wọ́n sì to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
Synów Symeona, ich potomków według ich rodzin, według domów ich ojców, naliczonych według liczby imion, głowa po głowie, wszystkich mężczyzn od dwudziestu lat wzwyż, wszystkich zdolnych do walki;
23 Iye àwọn tí á kà nínú ẹ̀yà Simeoni jẹ́ ẹgbàá mọ́kàndínlọ́gbọ̀n ó lé ọ̀ọ́dúnrún.
Naliczono z pokolenia Symeona pięćdziesiąt dziewięć tysięcy trzystu.
24 Láti ìran Gadi, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún sókè tí wọ́n lè lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan, gẹ́gẹ́ bí ẹbí àti ìdílé wọn.
Synów Gada, ich potomków według ich rodzin, według domów ich ojców, według liczby imion, od dwudziestu lat wzwyż, wszystkich zdolnych do walki;
25 Iye àwọn tí a kà nínú ẹ̀yà Gadi jẹ́ ẹgbàá méjìlélógún ó lé àádọ́talélẹ́gbẹ̀jọ.
Naliczono z pokolenia Gada czterdzieści pięć tysięcy sześciuset pięćdziesięciu.
26 Láti ìran Juda, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún sókè, tí wọ́n le lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
Synów Judy, ich potomków według ich rodzin, według domów ich ojców, według liczby imion, od dwudziestu lat wzwyż, wszystkich zdolnych do walki;
27 Iye tí a kà nínú ẹ̀yà Juda jẹ́ ẹgbàá mẹ́tàdínlógójì ó lé ẹgbẹ̀ta.
Naliczono z pokolenia Judy siedemdziesiąt cztery tysiące sześciuset.
28 Láti ìran Isakari, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún sókè tí wọ́n le lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
Synów Issachara, ich potomków według ich rodzin, według domów ich ojców, według liczby imion, od dwudziestu lat wzwyż, wszystkich zdolnych do walki;
29 Iye tí a kà nínú ẹ̀yà Isakari jẹ́ ẹgbàá mẹ́tàdínlọ́gbọ̀n ó lé irinwó.
Naliczono z pokolenia Issachara pięćdziesiąt cztery tysiące czterystu.
30 Láti ìran Sebuluni, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún sókè tí wọ́n lè lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
Synów Zebulona, ich potomków według ich rodzin, według domów ich ojców, według liczby imion, od dwudziestu lat wzwyż, wszystkich zdolnych do walki;
31 Iye tí a kà nínú ẹ̀yà Sebuluni jẹ́ ẹgbàá méjìdínlọ́gbọ̀n ó lé egbèje.
Naliczono z pokolenia Zebulona pięćdziesiąt siedem tysięcy czterystu.
32 Láti inú àwọn ọmọ Josẹfu. Láti ìran Efraimu, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọ́n jẹ́ ogún ọdún sókè tí wọ́n lè lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
Synów Józefa, z synów Efraima, ich potomków według ich rodzin, według domów ich ojców, według liczby imion, od dwudziestu lat wzwyż, wszystkich zdolnych do walki;
33 Iye tí a kà nínú ẹ̀yà Efraimu jẹ́ ọ̀kẹ́ méjì ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta.
Naliczono z pokolenia Efraima czterdzieści tysięcy pięciuset.
34 Láti ìran Manase, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún sókè, tí wọ́n lè lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
Synów Manassesa, ich potomków według ich rodzin, według domów ich ojców, według liczby imion, od dwudziestu lat wzwyż, wszystkich zdolnych do walki;
35 Iye tí a kà nínú ẹ̀yà Manase jẹ́ ẹgbàá ẹẹ́rìndínlógún ó lé igba.
Naliczono z pokolenia Manassesa trzydzieści dwa tysiące dwustu.
36 Láti ìran Benjamini, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún sókè ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
Synów Beniamina, ich potomków według ich rodzin, według domów ich ojców, według liczby imion, od dwudziestu lat wzwyż, wszystkich zdolnych do walki;
37 Iye tí a kà nínú ẹ̀yà Benjamini jẹ́ ẹgbàá mẹ́tàdínlógún ó lé egbèje.
Naliczono z pokolenia Beniamina trzydzieści pięć tysięcy czterystu.
38 Láti ìran Dani, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ọmọ ogún ọdún sókè, tí wọ́n lè lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
Synów Dana, ich potomków według ich rodzin, według domów ich ojców, według liczby imion, od dwudziestu lat wzwyż, wszystkich zdolnych do walki;
39 Iye tí a kà nínú ẹ̀yà Dani jẹ́ ẹgbàá mọ́kànlélọ́gbọ̀n ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin.
Naliczono z pokolenia Dana sześćdziesiąt dwa tysiące siedmiuset.
40 Láti ìran Aṣeri, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún sókè, tí wọ́n le lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
Synów Aszera, ich potomków według ich rodzin, według domów ich ojców, według liczby imion, od dwudziestu lat wzwyż, wszystkich zdolnych do walki;
41 Iye tí a kà nínú ẹ̀yà Aṣeri jẹ́ ọ̀kẹ́ méjì ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀jọ.
Naliczono z pokolenia Aszera czterdzieści jeden tysięcy pięciuset.
42 Láti ìran Naftali, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún ó lé, tí wọ́n lè lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
Synów Neftalego, ich potomków według ich rodzin, według domów ich ojców, według liczby imion, od dwudziestu lat wzwyż, wszystkich zdolnych do walki;
43 Iye àwọn tí a kà nínú ẹ̀yà Naftali jẹ́ ẹgbàá mẹ́rìndínlọ́gbọ̀n ó lé egbèje.
Naliczono z pokolenia Neftalego pięćdziesiąt trzy tysiące czterystu.
44 Wọ̀nyí ni àwọn ènìyàn tí Mose àti Aaroni kà, pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́ àwọn olórí méjìlá fún Israẹli, tí ẹnìkọ̀ọ̀kan ṣojú fún ìdílé rẹ̀.
To są ci, których policzyli Mojżesz, Aaron i książęta Izraela, dwunastu mężczyzn, po jednym z każdego domu swych ojców.
45 Gbogbo ọmọkùnrin Israẹli tó jẹ́ ọmọ ogún ọdún sókè, tó sì lè lọ sójú ogun ni wọ́n kà gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn.
I było wszystkich policzonych synów Izraela, według domów ich ojców, od dwudziestu lat wzwyż, wszystkich zdolnych do walki w Izraelu;
46 Àpapọ̀ iye wọn jẹ́ ọgbọ̀n ọ̀kẹ́ ó lé egbèjìdínlógún dín làádọ́ta.
Wszystkich policzonych było sześćset trzy tysiące pięciuset pięćdziesięciu.
47 A kò ka àwọn ìdílé ẹ̀yà Lefi mọ́ àwọn ìyókù.
Lecz Lewici nie zostali policzeni z nimi według pokolenia swych ojców.
48 Nítorí Olúwa ti sọ fún Mose pé,
PAN rozkazał bowiem Mojżeszowi:
49 “Ìwọ kò gbọdọ̀ ka ẹ̀yà Lefi, tàbí kí o kà wọ́n mọ́ àwọn ọmọ Israẹli.
Tylko pokolenia Lewiego nie spisuj i nie licz go razem z synami Izraela;
50 Dípò èyí yan àwọn ọmọ Lefi láti jẹ́ alábojútó àgọ́ ẹ̀rí, lórí gbogbo ohun èlò àti ohun gbogbo tó jẹ́ ti àgọ́ ẹ̀rí. Àwọn ni yóò máa gbé àgọ́ àti gbogbo ohun èlò rẹ̀, wọn ó máa mójútó o, kí wọn ó sì máa pàgọ́ yí i ká.
Lecz ustanowisz Lewitów nad Przybytkiem Świadectwa i nad wszystkimi jego naczyniami, i nad wszystkim, co do niego należy. Oni będą nosić przybytek i wszystkie jego sprzęty; oni też będą go obsługiwać i rozbijać obóz dokoła przybytku.
51 Ìgbàkígbà tí àgọ́ yóò bá tẹ̀síwájú, àwọn ọmọ Lefi ni yóò tú palẹ̀, nígbàkígbà tí a bá sì tún pa àgọ́, àwọn ọmọ Lefi náà ni yóò ṣe é. Àlejò tó bá súnmọ́ tòsí ibẹ̀, pípa ni kí ẹ pa á
A gdy przybytek będzie miał wyruszyć, Lewici go rozbiorą; także gdy przybytek ma być wznoszony, Lewici ustawią go; a obcy, który się do niego zbliży, poniesie śmierć.
52 kí àwọn ọmọ Israẹli pa àgọ́ wọn gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn olúkúlùkù ní ibùdó tirẹ̀ lábẹ́ ọ̀págun tirẹ̀.
I synowie Izraela będą rozbijać namioty, każdy w swoim obozie i każdy pod swoim sztandarem, według swych zastępów.
53 Àwọn ọmọ Lefi yóò jẹ́ alábojútó àti olùtọ́jú àgọ́ ẹ̀rí náà, kí ìbínú má ba à sí lára ìjọ àwọn ọmọ Israẹli; kí àwọn ọmọ Lefi sì máa ṣe ìtọ́jú àgọ́ ẹ̀rí náà.”
Lecz Lewici rozbiją obóz wokół Przybytku Świadectwa, aby gniew nie spadł na zgromadzenie synów Izraela. Lewici będą pełnić straż przy Przybytku Świadectwa.
54 Àwọn ọmọ Israẹli sì ṣe ohun gbogbo gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
I synowie Izraela uczynili zgodnie ze wszystkim, co PAN rozkazał Mojżeszowi, tak właśnie uczynili.

< Numbers 1 >