< Numbers 32 >

1 Àwọn ọmọ Reubeni àti àwọn ọmọ Gadi, tí wọ́n ní ẹran ọ̀sìn àti ohun ọ̀sìn rí wí pé ilẹ̀ Jaseri àti Gileadi dára fún ohun ọ̀sìn.
Nowe the children of Reuben, and the children of Gad had an exceeding great multitude of cattell: and they sawe the lande of Iazer, and the lande of Gilead, that it was an apt place for cattel.
2 Àwọn ọmọ Gadi àti àwọn ọmọ Reubeni sì wá, wọ́n wá sí ọ̀dọ̀ Mose àti Eleasari àlùfáà àti sí olórí gbogbo ìlú, wọ́n sì wí pé,
Then the children of Gad, and the childre of Reuben came, and spake vnto Moses and to Eleazar the Priest, and vnto the princes of the Congregation, saying,
3 “Atarotu, Diboni, Jaseri, Nimra, Heṣboni, Eleale, Sebamu, Nebo, àti Beoni.
The land of Ataroth, and Dibon, and Iazer, and Nimrah, and Heshbon, and Elealeh, and Shebam, and Nebo, and Beon,
4 Ni ilẹ̀ tí Olúwa ti ṣẹ́gun níwájú ìjọ Israẹli tí ó sì dára fún ohun ọ̀sìn, ṣáwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ sì ní ohun ọ̀sìn.”
Which countrey the Lord smote before the Congregation of Israel, is a lande meete for cattell, and thy seruants haue cattell:
5 Wọ́n wí pé, “Tí a bá rí ojúrere rẹ, jẹ́ kí a fi ilẹ̀ yìí fún ìránṣẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí ìní. Má ṣe jẹ́ kí a rékọjá odò Jordani.”
Wherefore, said they, if we haue foud grace in thy sight, let this lande be giuen vnto thy seruants for a possession, and bring vs not ouer Iorde.
6 Mose sọ fún àwọn ọmọ Gadi àti fún ọmọ Reubeni pé, “Ṣé kí àwọn arákùnrin yín lọ sí ogun, kí ẹ̀yin kí ó sì jókòó sí bí?
And Moses said vnto the children of Gad, and to the children of Reuben, Shall your brethren goe to warre, and ye tary heere?
7 Kí ni ó dé tí o fi mú ìrẹ̀wẹ̀sì bá àwọn ọmọ Israẹli láti lọ sí ibi ilẹ̀ tí Olúwa ti fi fún wọn?
Wherefore now discourage ye the heart of the children of Israel, to goe ouer into the lande, which the Lord hath giuen them?
8 Èyí ni nǹkan tí baba yín ṣe nígbà tí mo rán wọn láti Kadeṣi-Barnea láti lọ wo ilẹ̀ náà.
Thus did your fathers when I sent them from Kadesh-barnea to see the lande.
9 Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n lọ sí àfonífojì Eṣkolu tí wọ́n rí ilẹ̀ náà, wọ́n mú ìrẹ̀wẹ̀sì bá àwọn ọmọ Israẹli láti wọ ilẹ̀ tí Olúwa ti fi fún wọn.
For when they went vp euen vnto the riuer of Eshcol, and sawe the land: they discouraged the heart of the childre of Israel, that they woulde not goe into the lande, which the Lord had giuen them.
10 Ìbínú Olúwa sì dìde sí wọn ní ọjọ́ náà, ó sì búra, wí pé,
And the Lordes wrath was kindled the same day, and he did sweare, saying,
11 ‘Nítorí wọn kò tẹ̀lé mi tọkàntọkàn, kì í ṣe ọ̀kan nínú àwọn ọkùnrin náà tí ó jẹ́ ogún ọdún tàbí jù bẹ́ẹ̀ lọ tí ó gòkè láti Ejibiti ni yóò rí ilẹ̀ tí mo pinnu gẹ́gẹ́ bí ìbúra fún Abrahamu, fún Isaaki àti fún Jakọbu:
None of the men that came out of Egypt from twentie yeere olde and aboue, shall see the land for the which I sware vnto Abraham, to Izhak, and to Iaakob, because they haue not wholly followed me:
12 kò sí ẹnìkankan àyàfi Kalebu ọmọ Jefunne ti Kenissiti àti Joṣua ọmọ Nuni, nítorí wọ́n tẹ̀lé Olúwa tọkàntọkàn.’
Except Caleb the sonne of Iephunneh the Kenesite, and Ioshua the sonne of Nun: for they haue constantly followed the Lord.
13 Ìbínú Olúwa ru sí àwọn ọmọ Israẹli ó sì mú wọn rìn ní aginjù fún ogójì ọdún, títí tí àwọn ìran tí wọ́n ṣe búburú ní ojú rẹ̀ fi lọ.
And the Lord was very angry with Israel, and made them wander in the wildernesse fourty yeeres, vntill all the generation that had done euill in the sight of the Lord were consumed.
14 “Níbí ni ẹ̀yin wà, ẹ̀yin ẹlẹ́ṣẹ̀, ẹ̀yin dìde ní ipò baba yín, ẹ sì jẹ́ kí ìbínú gbígbóná Olúwa ru sí Israẹli.
And behold, ye are risen vp in your fathers steade as an encrease of sinfull men, still to augment the fierce wrath of the Lord, toward Israel.
15 Tí ẹ̀yin bá yípadà ní ẹ̀yìn rẹ̀ yóò sì fi àwọn ènìyàn wọ̀nyí sílẹ̀ ní aginjù, ìwọ yóò sì mú un ṣe ìparun.”
For if ye turne away from following him, he will yet againe leaue the people in the wildernesse, and ye shall destroy all this folke.
16 Nígbà náà wọ́n wá sí òkè ní ọ̀dọ̀ rẹ̀, “Àwa yóò fẹ́ láti kọ́ ilé ẹran níhìn-ín yìí fún ohun ọ̀sìn wa, àti ìlú fún àwọn obìnrin àti ọmọ wẹ́wẹ́ wa.
And they went neere to him, and said, We will builde sheepe foldes here for our sheepe, and for our cattell, and cities for our children.
17 Ṣùgbọ́n àwa ṣetán láti dira ogun ṣáájú àwọn ọmọ Israẹli títí tí a yóò fi mú wọn dé ọ̀dọ̀ wọn lákokò yìí, àwọn obìnrin àti ọmọ wẹ́wẹ́ wa yóò gbé inú ìlú tí a mọ odi sí fún ìdáàbòbò wọn lọ́wọ́ olùgbé ilẹ̀ náà.
But we our selues will be readie armed to go before the children of Israel, vntill we haue brought them vnto their place: but our childre shall dwell in the defenced cities, because of the inhabitants of the lande.
18 A kì yóò padà sí ilẹ̀ wa láìṣe pé gbogbo àwọn ọmọ Israẹli ti gba ogún wọn.
We will not returne vnto our houses, vntil the children of Israel haue inherited, euery man his inheritance.
19 A kì yóò gba ogún kankan pẹ̀lú wọn ní òdìkejì Jordani, nítorí ogún ti wa, ti wá sí ọ̀dọ̀ wa ní ìhà ìlà-oòrùn Jordani.”
Neither wil we inherite with them beyond Iorden and on that side, because our inheritance is fallen to vs on this side Iorden Eastwarde.
20 Nígbà náà ni Mose sọ fún wọn pé, “Tí ẹ̀yin yóò bá pa ara yín lára, níwájú Olúwa fún ogún.
And Moses saide vnto them, If ye will doe this thing, and goe armed before the Lord to warre:
21 Bí gbogbo yín yóò bá lọ sí Jordani ní ìhámọ́ra níwájú Olúwa, títí yóò fi lé àwọn ọ̀tá rẹ̀ kúrò níwájú rẹ̀.
And will goe euery one of you in harnesse ouer Iorden before the Lord, vntill he hath cast out his enemies from his sight:
22 Tí a ó sì fi ṣe ilẹ̀ náà níwájú Olúwa; ẹ̀yin lè padà tí yóò sì di òmìnira lọ́wọ́ ìdè níwájú Olúwa àti Israẹli. Ilẹ̀ yìí yóò sì jẹ́ tiyín níwájú Olúwa.
And vntill the land be subdued before the Lord, then ye shall returne and be innocent toward the Lord, and toward Israel: and this land shalbe your possession before the Lord.
23 “Ṣùgbọ́n tí ẹ̀yin bá kọ̀ láti ṣe èyí, ẹ̀yin yóò máa dẹ́ṣẹ̀ sí Olúwa; kí ẹ̀yin kí ó sì mọ̀ dájú pé ẹ̀ṣẹ̀ yín yóò fi yín hàn.
But if ye will not doe so, beholde, ye haue sinned against the Lord, and be sure, that your sinne will finde you out.
24 Ẹ kọ́ ilé fún àwọn obìnrin yín àti ọmọ wẹ́wẹ́ yín, àti ilé fún agbo ẹran yín, ṣùgbọ́n kí ẹ̀yin kí ó ṣe ohun tí ẹ ti pinnu.”
Builde you then cities for your children and folds for your sheepe, and do that ye haue spoke.
25 Àwọn ọmọ Gadi àti ọmọ Reubeni sọ fún Mose pé, “Àwa ìránṣẹ́ rẹ yóò ṣe gẹ́gẹ́ bí olúwa wa ti pàṣẹ.
Then the children of Gad and the children of Reuben spake vnto Moses, saying, Thy seruats will doe as my lorde commandeth:
26 Àwọn ọmọ wa àti ìyàwó wa, àwọn agbo ẹran àti ohun ọ̀sìn wa yóò dúró ní ìlú Gileadi.
Our childre, our wiues, our sheepe, and al our cattell shall remaine there in the cities of Gilead,
27 Ṣùgbọ́n àwọn ìránṣẹ́ rẹ, gbogbo ọkùnrin tí ó wọ ìhámọ́ra ogun, yóò rékọjá lọ láti jà níwájú Olúwa; gẹ́gẹ́ bí olúwa wa ti sọ.”
But thy seruants will goe euery one armed to warre before the Lord for to fight, as my lorde saith.
28 Nígbà náà ni Mose pàṣẹ nípa wọn fún Eleasari àlùfáà àti Joṣua ọmọ Nuni àti sí gbogbo olórí ìdílé ẹ̀yà Israẹli.
So concerning them, Moses commanded Eleazar the Priest, and Ioshua the sonne of Nun, and the chiefe fathers of the tribes of the children of Israel:
29 Mose sì wí fún wọn pé, “Tí àwọn ọmọ Gadi àti ọmọ Reubeni, gbogbo ọkùnrin tí ó wọ ìhámọ́ra fún ogun rékọjá odò Jordani pẹ̀lú níwájú Olúwa, nígbà tí ẹ ṣẹ́gun ilẹ̀ náà níwájú yín, fún wọn ní ilẹ̀ Gileadi gẹ́gẹ́ bí ìní wọn.
And Moses said vnto them, If the children of Gad, and the children of Reuben, will go with you ouer Iorden, all armed to fight before the Lord, then when the land is subdued before you, ye shall giue the the lad of Gilead for a possessio:
30 Ṣùgbọ́n tí wọn kò bá fẹ́ bá yín rékọjá pẹ̀lú ìhámọ́ra, wọn gbọdọ̀ gba ìní wọn pẹ̀lú yín ní Kenaani.”
But if they will not goe ouer with you armed, then they shall haue their possessions amog you in the land of Canaan.
31 Àwọn ọmọ Gadi àti ọmọ Reubeni dáhùn pé, “Ìránṣẹ́ rẹ yóò ṣe ohun tí Olúwa ti sọ.
And the children of Gad, and the children of Reuben answered, saying, As the Lord hath said vnto thy seruants, so will we doe.
32 A máa rékọjá níwájú Olúwa lọ sí Kenaani pẹ̀lú ìhámọ́ra, ṣùgbọ́n ẹrù tí a jogún yóò wà ní ẹ̀bá Jordani.”
We will goe armed before the Lord into the lande of Canaan: that the possession of our inheritance may be to vs on this side Iorden.
33 Nígbà náà Mose fún àwọn ọmọ Gadi àti àwọn ọmọ Reubeni àti ààbọ̀ ẹ̀yà Manase ọmọ Josẹfu ní ilẹ̀ ọba Sihoni ọba àwọn ọmọ Amori àti ilẹ̀ ọba Ogu ọba Baṣani ní gbogbo ilẹ̀ náà pẹ̀lú ìlú rẹ̀ àti agbègbè tí ó yí i ka.
So Moses gaue vnto them, euen to the children of Gad, and to the children of Reuben, and to halfe the tribe of Manasseh the sonne of Ioseph, the kingdome of Sihon King of the Amorites, and the kingdome of Og King of Bashan, the lande with the cities thereof and coastes, euen the cities of the countrey round about.
34 Àwọn ará Gadi wọ́n kọ́ Diboni, Atarotu, Aroeri;
Then the children of Gad built Dibon, and Ataroth, and Aroer,
35 pẹ̀lú Atrotu Ṣofani, Jaseri, àti Jogbeha,
And Atroth, Shophan, and Iazer, and Iogbehah,
36 pẹ̀lú Beti-Nimra, àti Beti-Harani ìlú olódi, àti agbo fún àgùntàn.
And Beth-nimrah, and Beth-haran, defenced cities: also sheepe foldes.
37 Àwọn ọmọ Reubeni sì kọ́ Heṣboni, Eleale, Kiriataimu,
And the children of Reuben built Heshbon, and Elealeh, and Kiriathaim,
38 pẹ̀lú Nebo pẹ̀lú Baali-Meoni (wọ́n pàrọ̀ orúkọ wọn) àti Sibma. Wọ́n sì sọ ìlú tí wọ́n tún kọ́ ní orúkọ mìíràn.
And Nebo, and Baal-meon, and turned their names, and Shibmah: and gaue other names vnto the cities which they built.
39 Àwọn ọmọ Makiri ọmọ Manase lọ sí Gileadi, wọ́n sì lé àwọn ọmọ Amori tí ó wà níbẹ̀.
And the children of Machir the sonne of Manasseh went to Gilead, and tooke it, and put out the Amorites that dwelt therein.
40 Mose sì fi àwọn ọmọ Gileadi fún àwọn ọmọ Makiri àwọn ìran Manase, wọ́n sì tẹ̀dó síbẹ̀.
Then Moses gaue Gilead vnto Machir the sonne of Manasseh, and he dwelt therein.
41 Jairi, ọmọ Manase gba ibùjókòó wọn, ó sì pè wọ́n ní Haffotu Jairi.
And Iair the sonne of Manasseh went and tooke the small townes thereof, and called them Hauoth Iair.
42 Noba gba Kenati àti àwọn ìtẹ̀dó rẹ̀, ó sì pè é ní Noba lẹ́yìn orúkọ ara rẹ̀.
Also Nobah went and tooke Kenath, with the villages thereof and called it Nobah, after his owne name.

< Numbers 32 >