< Numbers 26 >

1 Lẹ́yìn àjàkálẹ̀-ààrùn Olúwa sọ fún Mose àti Eleasari ọmọ Aaroni, àlùfáà pé,
And it came to pass after the plague, that Jehovah spoke to Moses and to Eleazar the son of Aaron the priest, saying,
2 “Ka iye gbogbo àwọn ọmọ Israẹli gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọ́n; láti ẹni ogun ọdún àti jù bẹ́ẹ̀ lọ tí ó lè jà lójú ogun ní Israẹli.”
Take the sum of the whole assembly of the children of Israel, from twenty years old and upward, according to their fathers' houses, all that go forth to military service in Israel.
3 Lórí pẹ̀tẹ́lẹ̀ ti Moabu pẹ̀lú Jordani tí ó kọjá Jeriko, Mose àti Eleasari àlùfáà sọ̀rọ̀ pẹ̀lú wọn ó wí pé,
And Moses and Eleazar the priest spoke with them in the plains of Moab by the Jordan of Jericho, saying,
4 “Ka iye àwọn ọkùnrin tí ó jẹ́ ọmọ-ogun ọdún tàbí jù bẹ́ẹ̀ lọ, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.” Èyí ni àwọn ọmọ Israẹli tí ó jáde láti Ejibiti wá.
From twenty years old and upward...; as Jehovah had commanded Moses and the children of Israel, who went forth out of the land of Egypt.
5 Àwọn ọmọ Reubeni, àkọ́bí ọmọkùnrin Israẹli, láti ẹni ti ìdílé Hanoku, láti ọ̀dọ̀ ẹni tí ìdílé Hanoku ti jáde wá, láti ìdílé Pallu, láti ọ̀dọ̀ ẹni tí ìdílé àwọn ọmọ Pallu ti jáde wá;
Reuben, the firstborn of Israel: the children of Reuben: [of] Enoch, the family of the Enochites; of Pallu, the family of the Palluites;
6 ti Hesroni, ìdílé àwọn ọmọ Hesroni; ti Karmi, ìdílé àwọn ọmọ Karmi.
of Hezron, the family of the Hezronites; of Carmi, the family of the Carmites.
7 Wọ̀nyí ni ìdílé àwọn ọmọ Reubeni; àwọn tí a sì kà nínú wọn jẹ́ ẹgbàá mọ́kànlélógún ó lé lẹ́gbẹ̀sán ó dín àádọ́rin.
These are the families of the Reubenites; and they that were numbered of them were forty-three thousand seven hundred and thirty.
8 Àwọn ọmọkùnrin Pallu ni Eliabu,
And the sons of Pallu: Eliab;
9 àwọn ọmọkùnrin Elifelehu ni Nemueli àti Eliabu, Datani àti Abiramu. Èyí ni Datani àti Abiramu náà tí wọ́n ní òkìkí nínú ìjọ tí ó jẹ́ ọlọ̀tẹ̀ sí Mose àti Aaroni tí ó sì wà lára àwọn ẹgbẹ́ Kora nígbà tí wọ́n bá Olúwa jà.
and the sons of Eliab were Nemuel, and Dathan, and Abiram. This is that Dathan and Abiram, summoned of the assembly, who contended against Moses and against Aaron in the band of Korah, when they contended against Jehovah.
10 Ilẹ̀ sì la ẹnu rẹ̀, ó sì gbé wọn mì pọ̀ pẹ̀lú Kora, nígbà tí ẹgbẹ́ rẹ̀ kú níbi tí iná ti run àwọn àádọ́ta lé nígba ọkùnrin. Tí wọ́n sì di àmì ìkìlọ̀.
And the earth opened its mouth, and swallowed them up together with Korah, when that band died, when the fire devoured the two hundred and fifty men; and they became a sign.
11 Àwọn ọmọ Kora, bí ó ti wù kí ó rí, wọn kò kú.
But the children of Korah died not.
12 Àwọn ọmọ ìran Simeoni bí ìdílé wọn: ti Nemueli, ìdílé Nemueli; ti Jamini, ìdílé Jamini; ti Jakini, ìdílé Jakini;
The sons of Simeon, after their families: of Nemuel, the family of the Nemuelites; of Jamin, the family of the Jaminites; of Jachin, the family of the Jachinites;
13 ti Sera, ìdílé Sera; tí Saulu, ìdílé Saulu.
of Zerah, the family of the Zarhites; of Saul, the family of the Saulites.
14 Wọ̀nyí ni ìdílé àwọn ọmọ Simeoni, ẹgbẹ̀rún méjìlélógún ó lé igba ọkùnrin.
These are the families of the Simeonites, twenty-two thousand two hundred.
15 Àwọn ọmọ Gadi bí ìdílé wọn: ti Sefoni, ìdílé Sefoni; ti Haggi, ìdílé Haggi; ti Ṣuni, ìdílé Ṣuni;
The children of Gad, after their families: of Zephon, the family of the Zephonites; of Haggi, the family of the Haggites; of Shuni, the family of the Shunites;
16 ti Osni, ìdílé Osni; ti Eri, ìdílé Eri;
of Ozni, the family of the Oznites; of Eri, the family of the Erites;
17 ti Arodi, ìdílé Arodi; ti Areli, ìdílé Areli.
of Arod, the family of the Arodites; of Areli, the family of the Arelites.
18 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Gadi tí iye wọn sì jẹ́ ọ̀kẹ́ méjì ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta.
These are the families of the children of Gad according to those that were numbered of them, forty thousand five hundred.
19 Àwọn ọmọ Juda ni Eri àti Onani, ṣùgbọ́n Eri àti Onani kú ní ilẹ̀ Kenaani.
The sons of Judah: Er and Onan; and Er and Onan died in the land of Canaan.
20 Àti àwọn ọmọ Juda gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn: ti Ṣela, ìdílé Ṣela; ti Peresi, ìdílé Peresi; ti Sera, ìdílé Sera.
And the sons of Judah, after their families: of Shelah, the family of the Shelanites; of Pherez, the family of the Pharzites; of Zerah, the family of the Zarhites.
21 Àwọn ọmọ Peresi: ti Hesroni, ìdílé Hesroni; ti Hamulu, ìdílé Hamulu.
And the sons of Pherez: of Hezron, the family of the Hezronites; of Hamul, the family of the Hamulites.
22 Wọ̀nyí ni ìdílé Juda; gẹ́gẹ́ bí àwọn tí a kà nínú wọn tí iye wọn sì jẹ́ ẹgbàá méjìdínlógójì ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta.
These are the families of Judah according to those that were numbered of them, seventy-six thousand five hundred.
23 Àwọn ọmọ Isakari gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn: ti Tola, ìdílé Tola; ti Pufa, ìdílé Pufa;
The sons of Issachar, after their families: of Tola, the family of the Tolaites; of Puah, the family of the Punites;
24 ti Jaṣubu, ìdílé Jaṣubu; ti Ṣimroni, ìdílé Ṣimroni.
of Jashub, the family of the Jashubites; of Shimron, the family of the Shimronites.
25 Wọ̀nyí ni ìdílé Isakari gẹ́gẹ́ bí àwọn tí a kà nínú wọn tí iye wọn sì jẹ́ ẹgbàá méjìlélọ́gbọ̀n ó lé ọ̀ọ́dúnrún.
These are the families of Issachar according to those that were numbered of them, sixty-four thousand three hundred.
26 Àwọn ọmọ Sebuluni gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn: ti Seredi, ìdílé Seredi; ti Eloni, ìdílé Eloni; ti Jaleeli, ìdílé Jaleeli.
The sons of Zebulun, after their families: of Sered, the family of the Sardites; of Elon, the family of the Elonites; of Jahleel, the family of the Jahleelites.
27 Wọ̀nyí ni ìdílé àwọn ọmọ Sebuluni gẹ́gẹ́ bí àwọn tí a kà nínú wọn tí iye wọn sì jẹ́ ọ̀kẹ́ mẹ́ta ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta.
These are the families of the Zebulunites according to those that were numbered of them, sixty thousand five hundred.
28 Àwọn ọmọ Josẹfu gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn; Manase àti Efraimu.
The sons of Joseph, after their families: Manasseh and Ephraim.
29 Àwọn ọmọ Manase: ti Makiri, ìdílé Makiri (Makiri sì bí Gileadi); ti Gileadi, ìdílé àwọn ọmọ Gileadi.
The sons of Manasseh: of Machir, the family of the Machirites (and Machir begot Gilead); of Gilead, the family of the Gileadites.
30 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Gileadi: ti Ieseri, ìdílé Ieseri; ti Heleki, ìdílé Heleki
These are the sons of Gilead: of Jeezer, the family of the Jeezerites; of Helek, the family of the Helkites;
31 àti ti Asrieli, ìdílé Asrieli; àti ti Ṣekemu, ìdílé Ṣekemu;
and of Asriel, the family of the Asrielites; and of Shechem, the family of the Shechemites;
32 àti Ṣemida, ìdílé àwọn ọmọ Ṣemida; àti ti Heferi, ìdílé àwọn ọmọ Heferi.
and of Shemida, the family of the Shemidaites; and of Hepher, the family of the Hepherites.
33 (Selofehadi ọmọ Heferi kò sì ni ọmọkùnrin, bí kò ṣe ọmọbìnrin; orúkọ àwọn ọmọbìnrin ni Mahila, Noa, àti Hogla, Milka àti Tirsa).
— And Zelophehad the son of Hepher had no sons, but daughters; and the names of the daughters of Zelophehad were Mahlah, and Noah, Hoglah, Milcah, and Tirzah.
34 Wọ̀nyí ni ìdílé Manase tí iye wọn sì jẹ́ ẹgbàá mẹ́rìndínlọ́gbọ̀n ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin.
— These are the families of Manasseh; and those that were numbered of them, fifty-two thousand seven hundred.
35 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Efraimu gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn: láti ọ̀dọ̀ Ṣutelahi, ìdílé àwọn ọmọ Ṣutelahi; ti Bekeri, ìdílé àwọn ọmọ Bekeri; ti Tahani, ìdílé àwọn ọmọ Tahani.
These are the sons of Ephraim, after their families: of Shuthelah, the family of the Shuthalhites; of Becher, the family of the Bachrites; of Tahan, the family of the Tahanites.
36 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Ṣutelahi: ti Erani, ìdílé àwọn ọmọ Erani.
And these are the sons of Shuthelah: of Eran, the family of the Eranites.
37 Wọ̀nyí ni ìdílé àwọn ọmọ Efraimu, àwọn tí a kà nínú wọn sì jẹ́ ẹgbàá mẹ́rìndínlógún ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta. Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Josẹfu gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn.
These are the families of the sons of Ephraim according to those that were numbered of them, thirty-two thousand five hundred. These are the sons of Joseph after their families.
38 Àwọn ọmọ Benjamini gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn nìyìí: tí Bela, ìdílé àwọn ọmọ Bela; ti Aṣbeli, ìdílé àwọn ọmọ Aṣbeli; ti Ahiramu, ìdílé àwọn ọmọ Ahiramu;
The sons of Benjamin, after their families: of Bela, the family of the Belaites; of Ashbel, the family of the Ashbelites; of Ahiram, the family of the Ahiramites;
39 ti Ṣufamu, ìdílé àwọn ọmọ Ṣufamu; ti Hufamu, ìdílé àwọn ọmọ Hufamu.
of Shephupham, the family of the Shuphamites; of Hupham, the family of the Huphamites.
40 Àwọn ọmọ Bela ní ipasẹ̀ Ardi àti Naamani nìyìí: ti Ardi, ìdílé àwọn ọmọ Ardi; ti Naamani, ìdílé àwọn ọmọ Naamani.
And the sons of Bela were Ard and Naaman; [of Ard] the family of the Ardites; of Naaman, the family of the Naamites.
41 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Benjamini; gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn; àti àwọn tí a kà nínú wọn jẹ́ ẹgbàá méjìlélógún ó lé ẹgbẹ̀jọ.
These are the sons of Benjamin after their families; and they that were numbered of them were forty-five thousand six hundred.
42 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Dani gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn: ti Ṣuhamu, ìdílé àwọn ọmọ Ṣuhamu. Wọ̀nyí ni ìdílé Dani gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn.
These are the sons of Dan, after their families: of Shuham, the family of the Shuhamites. These are the families of Dan after their families.
43 Gbogbo ìdílé àwọn ọmọ Ṣuhamu, gẹ́gẹ́ bí àwọn tí a kà nínú wọn jẹ́ ẹgbàá méjìlélọ́gbọ̀n ó lé irinwó.
All the families of the Shuhamites, according to those that were numbered of them, were sixty-four thousand four hundred.
44 Ti àwọn ọmọ Aṣeri gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn: ti Imina, ìdílé àwọn ọmọ Imina; ti Iṣfi, ìdílé àwọn ọmọ Iṣfi; ti Beriah, ìdílé àwọn ọmọ Berii.
The sons of Asher, after their families: of Jimnah, the family of the Jimnites; of Jishvi, the family of the Jishvites; of Beriah, the family of the Beriites.
45 Ti àwọn ọmọ Beriah: ti Heberi, ìdílé àwọn ọmọ Heberi; ti Malkieli, ìdílé àwọn ọmọ Malkieli.
Of the sons of Beriah: of Heber, the family of the Heberites; of Malchiel, the family of the Malchielites.
46 (Orúkọ ọmọ Aṣeri obìnrin nì jẹ́ Sera.)
And the name of the daughter of Asher was Serah.
47 Wọ̀nyí ni ìdílé àwọn ọmọ Aṣeri gẹ́gẹ́ bí àwọn tí a kà nínú wọn jẹ́ ẹgbàá mẹ́rìndínlọ́gbọ̀n ó lé egbèje.
These are the families of the sons of Asher according to those that were numbered of them, fifty-three thousand four hundred.
48 Ti àwọn ọmọ Naftali gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn: ti Jasieli, ìdílé àwọn ọmọ Jaseeli: ti Guni, ìdílé àwọn ọmọ Guni;
The sons of Naphtali, after their families: of Jahzeel, the family of the Jahzeelites; of Guni, the family of the Gunites;
49 ti Jeseri, ìdílé àwọn ọmọ Jeṣeri; ti Ṣillemu, ìdílé àwọn ọmọ Ṣillemu.
of Jezer, the family of the Jezerites; of Shillem, the family of the Shillemites.
50 Wọ̀nyí ni ìdílé ti Naftali gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn, àwọn tí a kà nínú wọn jẹ́ ẹgbàá méjìlélógún ó lé egbèje.
These are the families of Naphtali, according to their families; and they that were numbered of them were forty-five thousand four hundred.
51 Àpapọ̀ iye tí a kà nínú àwọn ọmọ Israẹli jẹ́ ọgbọ̀n ọ̀kẹ́ ó lé ẹgbẹ̀sán dín làádọ́rin.
These were the numbered of the children of Israel, six hundred and one thousand seven hundred and thirty.
52 Olúwa sọ fún Mose pé,
And Jehovah spoke to Moses, saying,
53 “Ilẹ̀ náà gbọdọ̀ jẹ́ pínpín fún wọn gẹ́gẹ́ bí ogún wọn gẹ́gẹ́ bí iye orúkọ wọn.
Unto these shall the land be divided for an inheritance according to the number of the names;
54 Fún àwọn ọ̀pọ̀ ni kí ìwọ ó fún ní ogún ìlú púpọ̀ àti fún àwọn tí ó kéré ni kí ìwọ ó fi kékeré fún, ẹnìkọ̀ọ̀kan gbọdọ̀ gba ogún ìbí tirẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ènìyàn tí a kọ.
to the many thou shalt increase their inheritance, and to the few thou shalt diminish their inheritance; to every one shall his inheritance be given according to those that were numbered of him.
55 Rí dájú pé ilẹ̀ yìí gbọdọ̀ jẹ́ fífi ìbò pín gẹ́gẹ́ bí wọn sì ti pọ̀ tó. Gẹ́gẹ́ bí orúkọ ẹ̀yà àwọn baba wọn ni kí wọn kí ó ni í.
Notwithstanding the land shall be divided by lot; according to the names of the tribes of their fathers shall they inherit;
56 Olúkúlùkù ogún ìní ni a gbọdọ̀ fi ìbò pín gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti pọ̀ tó láàrín ńlá àti kékeré.”
according to lot shall his inheritance be divided to each, be they many or few in number.
57 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Lefi tí a kà nínú wọn gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn: ti Gerṣoni, ìdílé àwọn ọmọ Gerṣoni; ti Kohati, ìdílé àwọn ọmọ Kohati; ti Merari, ìdílé àwọn ọmọ Merari.
And these are the numbered of the Levites, after their families: of Gershon, the family of the Gershonites; of Kohath, the family of the Kohathites; of Merari, the family of the Merarites.
58 Wọ̀nyí ni ìdílé àwọn ọmọ Lefi; ìdílé àwọn ọmọ Libni, ìdílé àwọn ọmọ Hebroni, ìdílé àwọn ọmọ Mahili, ìdílé àwọn ọmọ Muṣi, ìdílé àwọn ọmọ Kora. (Kohati ni baba Amramu,
These are the families of the Levites: the family of the Libnites, the family of the Hebronites, the family of the Mahlites, the family of the Mushites, the family of the Korahites. — And Kohath begot Amram.
59 orúkọ aya Amramu sì ń jẹ́ Jokebedi, ọmọbìnrin Lefi, tí ìyá rẹ̀ bí fún Lefi ní Ejibiti. Òun sì bí Aaroni, Mose, àti Miriamu arábìnrin wọn fún Amramu.
And the name of Amram's wife was Jochebed, the daughter of Levi, who was born to Levi in Egypt; and she bore to Amram Aaron and Moses, and Miriam their sister.
60 Aaroni ni baba Nadabu àti Abihu, Eleasari àti Itamari.
And to Aaron were born Nadab, and Abihu, Eleazar, and Ithamar.
61 Ṣùgbọ́n Nadabu àti Abihu kú, nígbà tí wọ́n rú ẹbọ níwájú Olúwa nígbà tí wọ́n mú iná àjèjì wá.)
And Nadab and Abihu died, when they presented strange fire before Jehovah.
62 Gbogbo àwọn ọmọkùnrin Lefi láti oṣù kan àti ju bẹ́ẹ̀ lọ ẹgbẹ̀rún méjìlélógún ó lé lẹ́gbẹ̀rún. Wọn kò ka wọ́n mọ́ àwọn ọmọ Israẹli tókù nítorí tí wọ́n kò gba ogún ìní lára wọn.
And those that were numbered of the [Levites] were twenty-three thousand, all males from a month old and upward; for they were not numbered among the children of Israel, because there was no inheritance given them among the children of Israel.
63 Àwọn wọ̀nyí ni Mose àti Eleasari àlùfáà kà nígbà tí wọ́n ka àwọn ọmọ Israẹli ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu lẹ́bàá odò Jordani létí Jeriko.
These are they that were numbered by Moses and Eleazar the priest, who numbered the children of Israel in the plains of Moab, by the Jordan of Jericho.
64 Kò sí ẹnìkan nínú àwọn tí Mose àti Aaroni àlùfáà kà nígbà tí wọ́n ka àwọn ọmọ Israẹli ní aginjù Sinai.
But among these there was not a man numbered by Moses and Aaron the priest, who numbered the children of Israel in the wilderness of Sinai.
65 Nítorí Olúwa ti sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé kíkú ni wọn yóò kú sí aginjù, kò sì sí ẹnìkankan nínú wọn tí kò kú àfi Kalebu ọmọ Jefunne, àti Joṣua ọmọ Nuni.
For Jehovah had said of them, They shall surely die in the wilderness. And there was not left a man of them, save Caleb the son of Jephunneh, and Joshua the son of Nun.

< Numbers 26 >