< Numbers 23 >

1 Balaamu wí fún Balaki pé, “Kọ́ pẹpẹ méje fún mi níbí, kí o sì mú akọ màlúù méje àti àgbò méje wá fún mi.”
I Balaam powiedział do Balaka: Zbuduj mi tu siedem ołtarzy i przygotuj mi tu siedem cielców i siedem baranów.
2 Balaki ṣe bí Balaamu ti sọ, àwọn méjèèjì fi akọ màlúù kọ̀ọ̀kan àti àgbò kọ̀ọ̀kan rú ẹbọ lórí pẹpẹ kọ̀ọ̀kan.
Uczynił więc Balak tak, jak powiedział Balaam; potem Balak i Balaam ofiarowali po [jednym] cielcu i [jednym] baranie na [każdym] ołtarzu.
3 Nígbà náà Balaamu sọ fún Balaki pé, “Dúró ti ẹbọ sísun rẹ kí èmi sì lọ sí ẹ̀gbẹ́ kan. Bóyá Olúwa yóò farahàn mí. Ohunkóhun tí ó bá fihàn mí, èmi yóò wí fún ọ.” Nígbà náà ó sì lọ sí ibi gíga.
Wtedy Balaam powiedział do Balaka: Pozostań przy swoim całopaleniu, a ja pójdę; może PAN spotka się ze mną, a cokolwiek mi objawi, powiem ci. I poszedł na wzgórze.
4 Ọlọ́run sì pàdé rẹ̀, Balaamu sì sọ pé, “Mo tí ṣe pẹpẹ méje, lórí pẹpẹ kọ̀ọ̀kan mo ti fi akọ màlúù àti àgbò kọ̀ọ̀kan rú ẹbọ.”
I Bóg spotkał się z Balaamem; i [Balaam] powiedział do niego: Postawiłem siedem ołtarzy i ofiarowałem po [jednym] cielcu i [jednym] baranie na [każdym] ołtarzu.
5 Olúwa sì fi ọ̀rọ̀ sí ẹnu Balaamu ó wí pé, “Padà sí ọ̀dọ̀ Balaki kí o sì jẹ́ iṣẹ́ yìí fún un.”
Wówczas PAN włożył słowa w usta Balaama i powiedział: Wróć do Balaka i tak [mu] powiedz.
6 Ó sì padà sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ ó sì ba tí ó dúró ti ẹbọ sísun rẹ̀, pẹ̀lú gbogbo àwọn ìjòyè Moabu.
I wrócił do niego, a oto stał przy swoim całopaleniu, on i wszyscy książęta Moabu.
7 Nígbà náà ni Balaamu sọ ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ jáde wí pé, “Balaki mú mi láti Aramu wá, ọba Moabu láti òkè ìlà-oòrùn wá Ó wí pé, ‘Wá fi Jakọbu bú fún mi; wá, kí o sì jẹ́rìí sí Israẹli.’
I rozpoczął swą przypowieść, mówiąc: Balak, król Moabu, sprowadził mnie z Aramu, z gór wschodnich [tymi słowy]: Przyjdź, przeklnij mi Jakuba, przyjdź, złorzecz Izraelowi.
8 Báwo ní èmi ó ṣe fi bú àwọn tí Ọlọ́run kò fi bú? Báwo ni èmi ó ṣe bá wọn wí àwọn tí Olúwa kò bá wí?
Jakże mam przeklinać tego, kogo Bóg nie przeklął? I jak mam złorzeczyć temu, komu PAN nie złorzeczył?
9 Láti ṣóńṣó ibi gíga orí àpáta ni mo ti rí wọn, láti orí ibi gíga ni mo ti ń wò wọ́n. Mo rí àwọn ènìyàn tí ń gbé lọ́tọ̀ wọn kò sì ka ará wọn kún ara àwọn orílẹ̀-èdè.
Gdyż widzę go ze szczytu skał, spoglądam na niego z pagórków; oto [ten] lud będzie mieszkać osobno, do innych narodów nie będzie zaliczony.
10 Ta ni ó lè ka eruku Jakọbu tàbí ka ìdámẹ́rin Israẹli? Jẹ́ kí èmi kú ikú olódodo, kí ìgbẹ̀yìn mi kí ó dà bí tirẹ̀!”
Któż policzy proch Jakuba, [któż] policzy [choćby] czwartą część Izraela? Niech umrę śmiercią sprawiedliwych i niech mój koniec będzie taki jak ich.
11 Balaki sọ fún Balaamu pé, “Kí lo ṣe fún mi? Mo gbé ọ wá láti fi àwọn ọ̀tá mi bú, ṣùgbọ́n o kò ṣe nǹkan kan, ṣùgbọ́n o bùkún wọn!”
Wtedy Balak powiedział do Balaama: Cóż mi uczyniłeś? Sprowadziłem cię, abyś przeklął moich wrogów, a oto ty [im] wielce błogosławiłeś.
12 Ó sì dáhùn wí pé, “Ṣé kí n má sọ nǹkan tí Olúwa fi sí mi lẹ́nu?”
A on odpowiedział: Czy nie mam pilnować tego, by mówić to, co PAN włożył w moje usta?
13 Nígbà náà Balaki sọ fún un pé, “Wá pẹ̀lú mi sí ibòmíràn tí o ti lè rí wọn; wà á rí díẹ̀, ṣùgbọ́n kì í ṣe gbogbo wọn. Láti ibẹ̀, wá fi wọ́n bú fún mi.”
I Balak powiedział do niego: Chodź, proszę, ze mną na inne miejsce, z którego będziesz mógł ich widzieć; zobaczysz tylko ich skraj, wszystkich nie zobaczysz. Przeklnij mi ich stamtąd.
14 Ó sì lọ sí pápá Sofimu ní orí òkè Pisga, ó sì kọ́ pẹpẹ méje síbẹ̀ ó sì fi akọ màlúù àti àgbò kọ̀ọ̀kan rú ẹbọ lórí pẹpẹ kọ̀ọ̀kan.
I zaprowadził go na pole Sofim, na szczyt góry Pizga; tam zbudował siedem ołtarzy i ofiarował po [jednym] cielcu i [jednym] baranie na [każdym] ołtarzu.
15 Balaamu ṣo fún Balaki pé, “Dúró níbí ti ẹbọ sísun rẹ nígbà tí mo bá lọ pàdé rẹ̀ níbẹ̀.”
I powiedział do Balaka: Pozostań tu przy swoim całopaleniu, a ja pójdę tam na spotkanie [PANA].
16 Olúwa pàdé Balaamu ó sì fi ọ̀rọ̀ sí ní ẹnu wí pé, “Padà lọ sí ọ̀dọ̀ Balaki kí o sì jíṣẹ́ fún un.”
I PAN wyszedł na spotkanie z Balaamem, włożył słowa w jego usta i powiedział: Wróć do Balaka i tak [mu] powiedz.
17 Nígbà náà ó lọ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ ó sì bá à tí ó dúró ti ẹbọ sísun rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ìjòyè Moabu. Balaki sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Kí ni Olúwa wí?”
Przyszedł więc do niego, a oto on stał przy swoim całopaleniu, a z nim książęta Moabu. I Balak zapytał go: Cóż ci PAN powiedział?
18 Nígbà náà ó bẹ̀rẹ̀ ọ̀rọ̀ sísọ, “Dìde, Balaki; kí o sì gbọ́ mi ọmọ Sippori.
I rozpoczął swą przypowieść tymi słowy: Wstań, Balaku, i słuchaj; nakłoń swego ucha, synu Sippora.
19 Ọlọ́run kì í ṣe ènìyàn, tí yóò fi purọ́, tàbí ọmọ ènìyàn, tí ó lè yí ọkàn rẹ̀ padà. Ǹjẹ́ ó sọ̀rọ̀ kí ó má ṣe é? Ǹjẹ́ ó ti ṣèlérí kí ó má mu un ṣẹ?
Bóg nie jest człowiekiem, aby miał kłamać, ani synem człowieczym, żeby miał żałować. Czy on powie [coś], a [tego] nie uczyni? Czy wypowie, a nie spełni?
20 Èmi gba àṣẹ láti bùkún; Ó sì ti bùkún, èmi kò sì lè yípadà.
Oto otrzymałem [rozkaz], żeby błogosławić; on błogosławił, a [ja] tego nie mogę odwrócić.
21 “Kò rí ẹ̀ṣẹ̀ kankan nínú Jakọbu, kò sì rí búburú kankan nínú Israẹli. Olúwa Ọlọ́run wọn sì wà pẹ̀lú wọn. Ìhó ọba sì wà pẹ̀lú wọn.
Nie dostrzegł nieprawości w Jakubie ani nie widział przestępstwa w Izraelu. PAN, jego Bóg, jest z nim, a okrzyk króla – przy nim.
22 Ọlọ́run mú wọn jáde láti Ejibiti wá, wọ́n ní agbára màlúù ẹhànnà.
Bóg wyprowadził ich z Egiptu, jego moc jest jak u jednorożca.
23 Kò ní àfọ̀ṣẹ sí Jakọbu, tàbí àfọ̀ṣẹ sí àwọn Israẹli. Nísinsin yìí a ó sọ nípa ti Jakọbu àti Israẹli, ‘Wo ohun tí Ọlọ́run ti ṣe!’
Nie ma bowiem zaklęcia przeciw Jakubowi ani wróżby przeciw Izraelowi. Już od tego czasu będzie się mówić o Jakubie i o Izraelu: Czego dokonał Bóg!
24 Àwọn ènìyàn náà yóò dìde bí abo kìnnìún; wọ́n yóò sì gbé ara wọn sókè bí i kìnnìún òun kì yóò sì dùbúlẹ̀ títí yóò fi jẹ ohun ọdẹ títí yóò sì fi mu nínú ẹ̀jẹ̀ ohun pípa.”
Oto lud powstanie jak silny lew, jak młody lew się podnosi; nie położy się, aż pożre zdobycz i wypije krew zabitych.
25 Nígbà náà ni Balaki wí fún Balaamu pé, “O kò kúkú fi wọ́n bú, bẹ́ẹ̀ ni o kò súre fún wọn rárá!”
Wtedy Balak powiedział do Balaama: Ani ich nie przeklinaj więcej, ani im też nie błogosław.
26 Balaamu dáhùn ó sì wí fún Balaki pé, “Ǹjẹ́ èmi kò ha ti wí fún ọ pé, gbogbo èyí tí Olúwa bá sọ, òun ni èmi yóò ṣe?”
I Balaam odpowiedział Balakowi: Czy nie powiedziałem ci, że cokolwiek powie PAN, to uczynię?
27 Nígbà náà Balaki sọ fún Balaamu pé, “Wá jẹ́ kí èmi kí ó mú ọ lọ sí ibòmíràn bóyá yóò tẹ́ Ọlọ́run lọ́rùn kí ó fi wọ́n bú láti ibẹ̀ lọ.”
Balak powiedział do Balaama: Chodź, proszę, zaprowadzę cię na inne miejsce, może się spodoba Bogu, żebyś ich stamtąd przeklął.
28 Balaki gbé Balaamu wá sí orí òkè Peori, tí ó kọjú sí aginjù.
Wtedy Balak [wziął] Balaama na szczyt Peor, który wznosi się nad pustynią.
29 Balaamu sì wí fún Balaki pé, “Mọ pẹpẹ méje fún mi níbí kí o sì pèsè akọ màlúù àti àgbò fún mi.”
I Balaam powiedział do Balaka: Zbuduj mi siedem ołtarzy i przygotuj mi tu siedem cielców i siedem baranów.
30 Balaki sì ṣe bí Balaamu ti sọ fún un, ó sì gbé akọ màlúù kan àti àgbò lórí pẹpẹ kọ̀ọ̀kan.
Balak uczynił więc tak, jak [mu] rozkazał Balaam, i ofiarował po [jednym] cielcu i [jednym] baranie [na każdym] ołtarzu.

< Numbers 23 >