< Numbers 15 >

1 Olúwa sọ fún Mose pé,
I PAN powiedział do Mojżesza:
2 “Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, ‘Nígbà tí ẹ bá dé ilẹ̀ tí èmi ó fún yin gẹ́gẹ́ bí ibùgbé
Przemów do synów Izraela i powiedz im: Gdy przyjdziecie do ziemi waszego mieszkania, którą wam daję;
3 tí ẹ̀yin ó bá sì ṣe ẹbọ iná sí Olúwa ẹbọ sísun, tàbí ẹbọ, láti san ẹ̀jẹ́ pàtàkì tàbí ọrẹ àtinúwá, tàbí nínú àjọ yín, láti ṣe òórùn dídùn sí Olúwa nínú agbo ẹran tàbí ọ̀wọ́ ẹran,
I będziecie chcieli złożyć PANU ofiarę spalaną na całopalenie, ofiarę bądź poślubioną, bądź dobrowolną lub też w wasze uroczyste święta, aby złożyć PANU miłą woń z wołów albo z owiec;
4 nígbà náà ni kí ẹni tí ó bá mú ọrẹ rẹ̀ wá, yóò tún mú ẹbọ ohun jíjẹ ìdámẹ́wàá òsùwọ̀n ìyẹ̀fun kíkúnná pẹ̀lú ìdámẹ́rin òsùwọ̀n òróró wá síwájú Olúwa.
To niech składający PANU ofiarę złoży na ofiarę pokarmową dziesiątą część efy mąki pszennej zmieszanej z czwartą częścią hinu oliwy.
5 Pẹ̀lú ọ̀dọ́-àgùntàn kọ̀ọ̀kan yálà fún ọrẹ tàbí ẹbọ sísun ni, kí ẹ pèsè ìdámẹ́rin òsùwọ̀n wáìnì gẹ́gẹ́ bí ohun mímu.
A czwartą część hinu wina na ofiarę z płynów przygotujesz przy całopaleniu lub innej ofierze na każde jagnię.
6 “‘Fún àgbò kan ni kí ẹ pèsè ọrẹ ohun jíjẹ ìdá méjì nínú mẹ́wàá òsùwọ̀n ìyẹ̀fun kíkúnná tí a fi ìdákan nínú mẹ́ta òsùwọ̀n òróró pò.
Przy baranie zaś złożysz na ofiarę pokarmową dwie dziesiąte efy mąki pszennej zmieszanej z trzecią częścią hinu oliwy.
7 Àti ìdákan nínú mẹ́ta òsùwọ̀n wáìnì fún ọrẹ ohun mímu gẹ́gẹ́ bí òórùn dídùn sí Olúwa.
A na ofiarę z płynów złożysz jedną trzecią hinu wina jako miłą woń dla PANA.
8 “‘Nígbà tí ẹ bá sì pèsè ọ̀dọ́ akọ màlúù fún ọrẹ tàbí ẹbọ sísun, láti fi san ẹ̀jẹ́ tàbí fún ọrẹ àlàáfíà sí Olúwa,
Gdy zaś będziesz składał cielca na ofiarę całopalną lub na ofiarę wypełnienia ślubu albo na ofiarę pojednawczą dla PANA;
9 ẹni náà yóò mú ọ̀dọ́ akọ màlúù náà wá pẹ̀lú ọrẹ ohun jíjẹ, ìdámẹ́ta nínú mẹ́wàá òsùwọ̀n ìyẹ̀fun ìyẹ̀fun kíkúnná tí a fi ìdajì òsùwọ̀n òróró pò.
Wtedy wraz z cielcem złożysz na ofiarę pokarmową trzy dziesiąte efy mąki pszennej zmieszanej z połową hinu oliwy.
10 Kí ó tún mú ìdajì òsùwọ̀n wáìnì wá fún ọrẹ ohun mímu. Yóò jẹ́ ọrẹ àfinásun, àní òórùn dídùn sí Olúwa.
Na ofiarę pokarmową złożysz też połowę hinu wina, na ofiarę spalaną [jako] miłą woń dla PANA.
11 Báyìí ni kí ẹ ṣe pèsè ọ̀dọ́ akọ màlúù tàbí àgbò, ọ̀dọ́-àgùntàn tàbí ọmọ ewúrẹ́.
Tak należy postąpić przy każdym wole, przy każdym baranie, jagnięciu lub koźlęciu.
12 Ẹ ṣe bẹ́ẹ̀ fún ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn, iyekíye tí ẹ̀yin ìbá à pèsè.
Według liczby, którą składacie, tak uczynicie z każdą ich sztuką według ich liczby.
13 “‘Ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ́ ọmọ bíbí ilẹ̀ yín ni kí ó máa ṣe àwọn nǹkan wọ̀nyí nígbà tí ó bá mú ọrẹ àfinásun gẹ́gẹ́ bí òórùn dídùn wá fún Olúwa.
Każdy rodowity mieszkaniec postąpi w ten sposób, gdy będzie składał ofiarę spalaną jako miłą woń dla PANA.
14 Bí àlejò kan bá ń gbé láàrín yín ní gbogbo ìran yín, bí irú ẹni bẹ́ẹ̀ bá fẹ́ mú ọrẹ àfinásun bí òórùn dídùn wá fún Olúwa, gbogbo bí ẹ bá ṣe ń ṣe náà ni kí ó ṣe.
A jeśli obcy gości u was lub mieszka z wami od pokoleń i będzie chciał złożyć ofiarę spalaną jako miłą woń dla PANA, uczyni to tak, jak [wy] czynicie.
15 Gbogbo ìjọ ènìyàn gbọdọ̀ ní òfin kan náà fún ọmọ bíbí ilẹ̀ yín àti fún àwọn àlejò tó ń gbé láàrín yín, èyí jẹ́ ìlànà títí láé fún àwọn ìran tó ń bọ̀. Ẹ̀yin àti àlejò tó ń gbé láàrín yín sì jẹ́ bákan náà níwájú Olúwa.
Będzie jedna ustawa dla was i dla przybysza, który mieszka [wśród was]; będzie to ustawa wieczysta przez wszystkie wasze pokolenia. Przybysz będzie przed PANEM tak jak wy.
16 Òfin kan àti ìlànà kan ni yóò wà fún yín àti fún àwọn àlejò tí ń gbé láàrín yín.’”
Będzie jedno prawo i jeden sąd dla was i przybysza, który mieszka wśród was.
17 Olúwa sọ fún Mose pé,
I PAN powiedział do Mojżesza:
18 “Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, ‘Nígbà tí ẹ bá dé ilẹ̀ tí mo ń mú yín lọ.
Przemów do synów Izraela i powiedz im: Gdy wejdziecie do ziemi, do której was wprowadzę;
19 Tí ẹ sì jẹ oúnjẹ ilẹ̀ náà, ẹ mú nínú rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọrẹ ìgbésókè wá fún Olúwa.
A będziecie jeść chleb tej ziemi, to złożycie PANU ofiarę wzniesienia.
20 Ẹ mú àkàrà wá nínú àkọ́so oúnjẹ yín wá gẹ́gẹ́ bí ọrẹ ìgbésókè sí Olúwa, ọrẹ láti inú ilẹ̀ ìpakà yín.
Złożycie jako ofiarę wzniesienia placek z pierwocin waszych ciast; złożycie go tak jak ofiarę wzniesienia z klepiska.
21 Nínú àkọ́so oúnjẹ yín ni kí ẹ ti máa mú ọrẹ ìgbésókè yìí fún Olúwa.
Będziecie składać PANU ofiarę wzniesienia z pierwocin waszych ciast przez wszystkie wasze pokolenia.
22 “‘Bí ẹ bá kùnà láìròtẹ́lẹ̀ láti pa àwọn òfin tí Olúwa fún Mose mọ́,
A gdybyście zbłądzili i nie wypełnili wszystkich tych przykazań, które PAN nadał przez Mojżesza;
23 èyí ni gbogbo òfin tí Olúwa fún yín láti ẹnu Mose láti ọjọ́ tí Olúwa ti fún yín àti títí dé ìran tó ń bọ̀.
Tego wszystkiego, co PAN wam rozkazał przez Mojżesza, od tego dnia, w którym PAN to nakazał, i potem przez wszystkie wasze pokolenia;
24 Bí ẹ̀ṣẹ̀ bá wáyé láìròtẹ́lẹ̀ láìjẹ́ pé ìjọ ènìyàn mọ̀ sí i, nígbà náà ni kí gbogbo ìjọ ènìyàn mú ọ̀dọ́ akọ màlúù kan wá fún ẹbọ sísun bí òórùn dídùn sí Olúwa, pẹ̀lú ọrẹ ohun jíjẹ àti ọrẹ ohun mímu rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìlànà, pẹ̀lú akọ ewúrẹ́ fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀.
Jeśli popełniono ten błąd nieświadomie przez zgromadzenia, to całe zgromadzenie złoży jednego młodego cielca na całopalenie, na miłą woń dla PANA, wraz z jego ofiarą pokarmową i ofiarą z płynów według zwyczaju, oraz jednego kozła ze stada na ofiarę za grzech.
25 Àlùfáà yóò sì ṣe ètùtù, fun gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli, a ó sì dáríjì wọ́n, nítorí ẹ̀ṣẹ̀ àìròtẹ́lẹ̀, wọ́n sì ti mú ọrẹ àfinásun wá fún Olúwa nítorí ẹ̀ṣẹ̀ tí wọ́n ṣẹ̀.
I kapłan dokona przebłagania za całe zgromadzenie synów Izraela, i będzie im przebaczone, gdyż stało się [to] nieświadomie. A oni przyniosą PANU swoją ofiarę na ofiarę spalaną i swoją ofiarę za grzech przed PANEM za swój błąd.
26 A ó dárí jí gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli àti àwọn àjèjì tí ń gbé ní àárín wọn nítorí pé ní àìròtẹ́lẹ̀ ni wọ́n sẹ ẹ̀ṣẹ̀ náà.
I będzie przebaczone całemu zgromadzeniu synów Izraela i przybyszowi, który mieszka pośród nich, ponieważ cały lud popełnił to nieświadomie.
27 “‘Ṣùgbọ́n bí ó bá jẹ́ pé ẹnìkan ló sẹ̀ ní àìròtẹ́lẹ̀, kí ó mú abo ewúrẹ́ ọlọ́dún kan wá fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀.
A jeśli tylko jedna osoba zgrzeszy nieświadomie, wtedy przyniesie roczną kozę na ofiarę za grzech;
28 Àlùfáà yóò ṣe ètùtù níwájú Olúwa fún ẹni tó ṣẹ̀ láìròtẹ́lẹ̀, tí wọ́n bá ṣe ètùtù fún un, a ó sì dáríjì í.
I kapłan dokona przebłagania za człowieka, który zbłądził, grzesząc wobec PANA nieświadomie; dokona za niego przebłagania i będzie mu przebaczone.
29 Òfin kan kí ẹ̀yin kí ó ní fún ẹnikẹ́ni tó bá ṣẹ̀ ní àìmọ̀, àti fún àwọn ẹni tí a bí nínú àwọn ọmọ Israẹli, àti fún àlejò tí ń ṣe àtìpó.
Będzie jedno prawo dla tego, który grzeszy nieświadomie, zarówno dla rodowitego mieszkańca wśród synów Izraela, jak i dla przybysza, który mieszka pośród nich.
30 “‘Ṣùgbọ́n bí ẹnikẹ́ni bá mọ̀ ọ́n mọ̀ dẹ́ṣẹ̀ yálà ó jẹ́ ọmọ bíbí ilẹ̀ yín tàbí àlejò, irú ẹni bẹ́ẹ̀ ti kó ẹ̀gàn bá orúkọ Olúwa, a ó sì gé irú ẹni bẹ́ẹ̀ kúrò lára àwọn ènìyàn rẹ̀.
Lecz człowiek, który bezczelnie zgrzeszy świadomie, zarówno rodowity mieszkaniec, jak i przybysz, znieważa PANA; człowiek ten zostanie wykluczony spośród swego ludu.
31 Nítorí pé ẹni náà ti kẹ́gàn ọ̀rọ̀ Olúwa ó sì ti rú òfin rẹ̀, a gbọdọ̀ gé irú ẹni bẹ́ẹ̀ kúrò láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀; ẹ̀bi rẹ̀ yóò sì wà lórí rẹ̀.’”
Wzgardził bowiem słowem PANA i złamał jego przykazanie; taki człowiek musi zostać wykluczony; na nim [ciąży] jego nieprawość.
32 Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli wà nínú aginjù, wọ́n rí ọkùnrin kan tí ń ṣá igi ní ọjọ́ Ìsinmi.
A gdy synowie Izraela byli na pustyni, spotkali człowieka zbierającego drwa w dzień szabatu.
33 Àwọn tó sì rí i níbi tó ti ń ṣá igi wọ́n sì mú un wá sí ọ̀dọ̀ Mose àti Aaroni àti síwájú gbogbo ìjọ ènìyàn,
I ci, którzy go spotkali zbierającego drwa, przyprowadzili go do Mojżesza i Aarona, i do całego zgromadzenia.
34 wọ́n fi sí ìpamọ́ nítorí pé ohun tí wọn ó ṣe fún un kò tí ì yé wọn.
I osadzili go pod strażą, bo jeszcze im nie oznajmiono, jak należy z takim postąpić.
35 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Kíkú ni ọkùnrin náà yóò kú kí gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli sọ ọ́ lókùúta pa ní ẹ̀yìn ibùdó.”
Wtedy PAN powiedział do Mojżesza: Ten człowiek musi ponieść śmierć; niech całe zgromadzenie go ukamienuje poza obozem.
36 Wọ́n mú un jáde sí ẹ̀yìn ibùdó, gbogbo ìjọ ènìyàn sì sọ ọ́ lókùúta pa, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
Całe zgromadzenie wyprowadziło go poza obóz i ukamienowało, i umarł, jak PAN rozkazał Mojżeszowi.
37 Olúwa sọ fún Mose pé,
I PAN powiedział do Mojżesza:
38 “Bá àwọn ọmọ Israẹli sọ̀rọ̀, kí o sọ fún wọn pé: ‘Títí dé àwọn ìran tó ń bọ̀ ni kí wọn máa ṣe wajawaja sí etí aṣọ wọn, kí wọn sì fi okùn tẹ́ẹ́rẹ́ aláwọ̀ búlúù sí wajawaja kọ̀ọ̀kan.
Przemów do synów Izraela i powiedz im, aby robili sobie frędzle na skrajach swoich szat przez wszystkie pokolenia, a do frędzli niech przyprawią sznurek z błękitnej [tkaniny].
39 Wajawaja yìí ni ẹ sì máa wọ̀ láti lè mú yín rántí gbogbo òfin Olúwa, kí ẹ bá à lè ṣe wọ́n, kí ẹ sì má bá à ṣe àgbèrè nípa títẹ̀lé ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ọkàn àti ojú yín.
I będziecie mieć te frędzle, żebyście na nie spoglądali i przypominali sobie wszystkie przykazania PANA, aby je wypełnić, a nie podążali za własnym sercem i własnymi oczami, za którymi idąc, cudzołożylibyście;
40 Nígbà náà ni ẹ ó gbọ́rọ̀ láti pa gbogbo òfin mi mọ́, ẹ ó sì jẹ́ mímọ́ sí Ọlọ́run yín.
Abyście pamiętali i wypełniali wszystkie moje przykazania, i byli święci dla waszego Boga.
41 Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín tí ó mú yín jáde láti Ejibiti láti jẹ́ Ọlọ́run yín. Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.’”
Ja [jestem] PAN, wasz Bóg, który was wyprowadził z ziemi Egiptu, aby być waszym Bogiem. Ja [jestem] PAN, wasz Bóg.

< Numbers 15 >