< Numbers 10 >

1 Olúwa sọ fún Mose pé,
Potem PAN powiedział do Mojżesza:
2 “Ṣe fèrè fàdákà méjì pẹ̀lú fàdákà lílù, kí o máa lò ó láti máa fi pe ìjọ ènìyàn àti láti máa fi darí ìrìnàjò lọ sí ibùdó yín.
Zrób sobie dwie srebrne trąby. Wykonasz je robotą kutą, a będą ci służyć do zwoływania ludu i do nawoływania w drogę obozów.
3 Nígbà tí o bá fọn méjèèjì gbogbo ìjọ ènìyàn yóò pé síwájú rẹ ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé.
A gdy w nie zadmą, wtedy cały lud zgromadzi się do ciebie, u wejścia do Namiotu Zgromadzenia.
4 Bí ó bá jẹ́ ọ̀kan ni o fọn, nígbà náà ni àwọn olórí ẹ̀yà Israẹli yóò péjọ síwájú rẹ.
A jeśli zadmą [tylko] w jedną [trąbę], zejdą się do ciebie wodzowie, naczelnicy tysięcy Izraela.
5 Nígbà tí o bá fun ìpè ìdágìrì, àwọn ẹ̀yà tó pa ibùdó sí ìhà ìlà-oòrùn ni yóò gbéra.
Gdy zatrąbicie, wydając urwany [dźwięk], wtedy wyruszą obozy rozłożone po stronie wschodniej.
6 Nígbà tí o bá fun ìpè ìdágìrì kejì, ibùdó tó wà ní ìhà gúúsù ni yóò gbéra. Ìpè ìdágìrì yìí ni yóò jẹ́ àmì fún gbígbéra.
A gdy drugi raz zatrąbicie, wydając urwany głos, wyruszą obozy rozłożone po stronie południowej. Będą trąbić, wydając urwany dźwięk, kiedy mają wyruszyć.
7 Nígbà tí o bá fẹ́ pe ìjọ ènìyàn jọ, fun fèrè nìkan, má ṣe fun ti ìdágìrì pẹ̀lú rẹ̀.
Ale gdy będziecie zwoływać lud, zatrąbicie bez wydawania urywanego dźwięku.
8 “Àwọn ọmọ Aaroni tí í ṣe àlùfáà ni kí ó máa fun fèrè. Èyí yóò jẹ́ ìlànà láéláé fún yín àti fún ìran tó ń bọ̀.
A synowie Aarona, kapłani, zadmą w trąby. Będzie to wieczysta ustawa dla was przez wszystkie wasze pokolenia.
9 Nígbà tí ẹ bá lọ jagun pẹ̀lú àwọn ọ̀tá tó ń ni yín lára ní ilẹ̀ yín, ẹ fun ìpè ìdágìrì pẹ̀lú fèrè. A ó sì rántí yín níwájú Olúwa, Ọlọ́run yín yóò sì gbà yín lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá yín.
A gdy w waszej ziemi wyruszycie na wojnę przeciw wrogowi, który was gnębi, zadmiecie w trąby urwanym dźwiękiem; a przypomnicie się PANU, waszemu Bogu, i zostaniecie wybawieni od waszych wrogów.
10 Bẹ́ẹ̀ náà ni ní ọjọ́ ayọ̀ yín, ní gbogbo àjọ̀dún tí a yàn àti ní ìbẹ̀rẹ̀ oṣù yín, ni kí ẹ máa fun fèrè lórí ẹbọ sísun àti ọrẹ àlàáfíà yín, wọn yóò sì jẹ́ ìrántí fún yín níwájú Ọlọ́run. Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.”
Także w dniu waszej radości, w wasze uroczyste święta oraz podczas waszych nowiów zadmiecie w trąby przy waszych ofiarach całopalnych i przy waszych ofiarach pojednawczych; będą one dla was pamiątką przed waszym Bogiem. Ja jestem PAN, wasz Bóg.
11 Ní ogúnjọ́ oṣù kejì, ní ọdún kejì ni ìkùùkuu kúrò lórí tabanaku ẹ̀rí.
I w drugim roku, drugiego miesiąca, dwudziestego dnia tego miesiąca uniósł się obłok znad Przybytku Świadectwa.
12 Àwọn ọmọ Israẹli sì gbéra kúrò ní aginjù Sinai wọ́n sì rin ìrìnàjò wọn káàkiri títí tí ìkùùkuu fi dúró sí aginjù Parani.
I synowie Izraela wyruszyli z pustyni Synaj, a obłok zatrzymał się na pustyni Paran.
13 Wọ́n gbéra nígbà àkọ́kọ́ yìí nípa àṣẹ Olúwa láti ẹnu Mose.
I po raz pierwszy wyruszyli tak, jak PAN rozkazał przez Mojżesza.
14 Àwọn ìpín ti ibùdó Juda ló kọ́kọ́ gbéra tẹ̀lé wọn lábẹ́ ogun wọn Nahiṣoni ọmọ Amminadabu ni ọ̀gágun wọn.
Pierwsza ruszyła chorągiew obozu synów Judy według swoich zastępów, a na czele jego wojska [był] Nachszon, syn Amminadaba.
15 Netaneli ọmọ Suari ni ọ̀gágun ti ẹ̀yà Isakari;
Na czele wojska pokolenia synów Issachara [był] Netaneel, syn Suara.
16 Eliabu ọmọ Heloni ni ọ̀gágun ni ìpín ti ẹ̀yà Sebuluni.
Na czele wojska pokolenia synów Zebulona [był] Eliab, syn Chelona.
17 Nígbà náà ni wọ́n sọ tabanaku kalẹ̀ àwọn ọmọ Gerṣoni àti Merari tó gbé àgọ́ sì gbéra.
Potem złożono przybytek i wyruszyli synowie Gerszona i synowie Merariego, niosąc przybytek.
18 Àwọn ìpín ti ibùdó ti Reubeni ló gbéra tẹ̀lé wọn, lábẹ́ ọ̀págun wọn. Elisuri ọmọ Ṣedeuri ni ọ̀gágun wọn.
Następnie ruszyła chorągiew obozu Rubena według swoich zastępów, a na czele jego wojska [był] Elizur, syn Szedeura.
19 Ṣelumieli ọmọ Suriṣaddai ni ọ̀gágun ti ẹ̀yà Simeoni.
Na czele wojska pokolenia synów Symeona [był] Szelumiel, syn Suriszaddaja.
20 Eliasafu ọmọ Deueli ni ọ̀gágun ìpín ti ẹ̀yà Gadi.
Na czele wojska pokolenia synów Gada [był] Eliasaf, syn Duela.
21 Nígbà náà ni àwọn ọmọ Kohati tí ń ru ohun mímọ́ náà gbéra. Àwọn ti àkọ́kọ́ yóò sì ti gbé tabanaku dúró kí wọn tó dé.
Następnie wyruszyli Kehatyci, niosąc świątynię. Zanim przyszli, [inni] ustawiali przybytek.
22 Àwọn ìpín tó wà ní ibùdó Efraimu ló tún kàn lábẹ́ ọ̀págun wọn. Eliṣama ọmọ Ammihudu ni ọ̀gágun wọn.
Potem ruszyła chorągiew obozu synów Efraima według swoich zastępów, a na czele jego wojska był Eliszama, syn Ammihuda.
23 Gamalieli ọmọ Pedasuri ni ọ̀gágun ìpín ti ẹ̀yà Manase.
Na czele wojsk pokolenia synów Manassesa [był] Gamliel, syn Pedahsura.
24 Abidani ọmọ Gideoni ni ọ̀gágun ìpín ti ẹ̀yà Benjamini.
Na czele wojska pokolenia synów Beniamina [był] Abidan, syn Gideoniego.
25 Lákòótan, àwọn ọmọ-ogun tó ń mójútó ẹ̀yìn ló tún kàn, àwọn ni ìpín ti ibùdó Dani lábẹ́ ọ̀págun wọn. Ahieseri ọmọ Ammiṣaddai ni ọ̀gágun wọn.
Następnie ruszyła chorągiew obozu synów Dana, tworząc tylną straż wszystkich obozów, według swoich zastępów, a na czele jego wojska był Achiezer, syn Ammiszaddaja.
26 Pagieli ọmọ Okanri ni ìpín ti ẹ̀yà Aṣeri,
Na czele wojska pokolenia synów Aszera [był] Pagiel, syn Okrana.
27 Ahira ọmọ Enani ni ọ̀gágun ti ẹ̀yà Naftali.
Na czele wojska pokolenia synów Neftalego [był] Achira, syn Enana.
28 Báyìí ni àwọn ọmọ Israẹli ṣe tò jáde gẹ́gẹ́ bí ogun nígbà tí wọ́n bẹ̀rẹ̀ ìrìnàjò wọn.
Taki był [porządek] marszu synów Izraela według ich zastępów i tak ruszali.
29 Mose sì sọ fún Hobabu ọmọ Reueli ará Midiani tí í ṣe àna rẹ̀ pé, “A ń gbéra láti lọ sí ibi tí Olúwa sọ pé, ‘Èmi ó fi fún un yín.’ Bá wa lọ, àwa ó ṣe ọ́ dáradára nítorí pé Olúwa ti ṣèlérí ohun rere fún Israẹli.”
Potem Mojżesz powiedział do Chobaba, syna Reuela Midianity, swego teścia: Wyruszamy do miejsca, o którym PAN powiedział: Dam je wam. Chodź z nami, a wyświadczymy ci dobro, ponieważ PAN obiecał [wiele] dobrego Izraelowi.
30 Ó sì dáhùn pé, “Rárá, èmi kò ní bá yín lọ, mò ń padà lọ sí ilẹ̀ mi àti sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn mi.”
Ten mu odpowiedział: Nie pójdę, lecz wrócę do mojej ziemi i do mojej rodziny.
31 Mose sì sọ pé, “Jọ̀wọ́ ma fi wá sílẹ̀, ìwọ mọ ibi tí a lè pa ibùdó sí nínú aginjù, ìwọ yóò sì jẹ́ ojú fún wa.
Mojżesz powiedział: Proszę, nie opuszczaj nas, bo ty wiesz, gdzie na pustyni możemy rozbić obóz, i możesz być naszym przewodnikiem.
32 Bí o bá bá wa lọ, a ó sì pín fún ọ nínú ohun rere yówù tí Olúwa bá fún wa.”
Jeśli pójdziesz z nami, wyświadczymy ci to dobro, które PAN nam uczyni.
33 Wọ́n sì gbéra láti orí òkè Olúwa ní ìrìn ọjọ́ mẹ́ta. Àpótí ẹ̀rí Olúwa ń lọ níwájú wọn fún gbogbo ọjọ́ mẹ́ta yìí láti wá ibi ìsinmi fún wọn.
I wyruszyli od góry PANA w drogę na trzy dni, a arka przymierza PANA szła przed nimi podczas tych trzech dni drogi, aby upatrzyć dla nich [miejsce] odpoczynku.
34 Ìkùùkuu Olúwa wà lórí wọn lọ́sàn nígbà tí wọ́n gbéra kúrò ní ibùdó.
A obłok PANA był nad nimi za dnia, gdy wyruszali z obozu.
35 Nígbàkígbà tí àpótí ẹ̀rí bá gbéra Mose yóò sì wí pé, “Dìde, Olúwa! Kí a tú àwọn ọ̀tá rẹ ká, kí àwọn tí ó kórìíra rẹ sì sálọ níwájú rẹ.”
A gdy arka miała ruszyć, wtedy Mojżesz mówił: Powstań, PANIE, a niech rozproszą się twoi wrogowie i niech uciekają przed tobą ci, którzy cię nienawidzą.
36 Nígbàkígbà tí àpótí ẹ̀rí bá sinmi yóò wí pé, “Padà, Olúwa, sọ́dọ̀ àwọn àìmoye ẹgbẹẹgbẹ̀rún Israẹli.”
Gdy zaś się zatrzymywała, wtedy mówił: Wróć, PANIE, do niezliczonych tysięcy Izraela.

< Numbers 10 >