< Nehemiah 7 >

1 Lẹ́yìn ìgbà tí a tún odi mọ tán tí mo sì ri àwọn ìlẹ̀kùn sí ààyè wọn, a sì yan àwọn aṣọ́bodè, àwọn akọrin àti àwọn Lefi.
And it came to pass, when the wall was built, and I had set up the doors, —and the doorkeepers and the singers and the Levites had been appointed,
2 Mo fún Hanani arákùnrin mi pẹ̀lú Hananiah olórí ilé ìṣọ́ ní àṣẹ lórí Jerusalẹmu, nítorí tí ó jẹ́ ènìyàn olóòtítọ́, ó sì bẹ̀rù Ọlọ́run jù bí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn ti ṣe lọ.
that I gave Hanani my brother, and Hananiah captain of the castle, charge over Jerusalem, for, he, was a truly faithful man, and revered God above many.
3 Mo sọ fún wọn pé, “A kò gbọdọ̀ ṣí ìlẹ̀kùn Jerusalẹmu títí oòrùn yóò fi mú. Nígbà tí àwọn aṣọ́bodè bá sì wà lẹ́nu iṣẹ́, jẹ́ kí wọn ti ìlẹ̀kùn kí wọn sì há wọn. Bákan náà, yàn nínú àwọn tí ń gbé Jerusalẹmu gẹ́gẹ́ bí olùṣọ́. Àwọn mìíràn níbi tí a pín wọn sí àti àwọn mìíràn ní tòsí ilé e wọn.”
And I said unto them, Let not the gates of Jerusalem be opened until, hot, be the sun, and, while they are standing by, let them close the doors, and make them fast, —setting watches, of the inhabitants of Jerusalem, every one in his watch, and every one over against his own house.
4 Ìlú náà tóbi ó sì ní ààyè, ṣùgbọ́n ènìyàn inú rẹ̀ kéré, a kò sì tí ì tún àwọn ilé inú rẹ̀ kọ́.
Now, the city, was broad on both hands, and large, but, the people, were few in the midst thereof, —and the houses had not been built.
5 Nígbà náà ni Ọlọ́run mi fi sí mi ní ọkàn láti kó àwọn ọlọ́lá, àwọn ìjòyè, àti àwọn ènìyàn jọ fún ìforúkọsílẹ̀ ní ìdílé ìdílé. Mo rí ìwé àkọsílẹ̀ ìtàn ìran àwọn tí ó kọ́ gòkè padà wá láti ìgbèkùn. Èyí ni ohun tí mo rí tí a kọ sínú ìwé náà.
So then my God put it into my heart, and I gathered together the nobles and the deputies and the people, to register their genealogy, —then found I a register roll, of them who came up at the first, and found written therein: —
6 Èyí ni àwọn ènìyàn agbègbè náà tí wọ́n sọ̀kalẹ̀ wá láti ìgbèkùn, àwọn tí Nebukadnessari ọba Babeli ti kó ní ìgbèkùn (wọ́n padà sí Jerusalẹmu àti Juda, olúkúlùkù sí ìlú u rẹ̀.
These, are the sons of the province, who came up from among the Captives of the Exile, whom Nebuchadnezzar king of Babylon did exile, —but they came back to Jerusalem and to Judah, every one to his own city;
7 Wọ́n jọ rìn wá pẹ̀lú u Serubbabeli, Jeṣua, Nehemiah, Asariah, Raamiah, Nahamani, Mordekai, Bilṣani, Misperi, Bigfai, Nehumu, àti Baanah). Àkọsílẹ̀ orúkọ àwọn ọkùnrin Israẹli,
who came in with Zerubbabel, Jeshua, Nehemiah, Azariah, Raamiah, Nahamani, Mordecai, Bilshan, Mispereth, Bigvai, Nehum, Baanah, —the number of the men of the people of Israel.
8 àwọn ọmọ Paroṣi jẹ́ ẹgbàá ó lé méjìléláàádọ́sàn-án
The sons of Parosh, two thousand, one hundred, and seventy-two;
9 Ṣefatia jẹ́ òjìdínnírinwó ó lé méjìlá
The sons of Shephatiah, three hundred, and seventy-two;
10 Arah jẹ́ ẹgbẹ̀tàléláàádọ́ta ó lé méjì
The sons of Arah, six hundred, and fifty-two;
11 Pahati-Moabu (láti ipasẹ̀ ọmọ Jeṣua àti Joabu) jẹ́ ẹgbàá mẹ́rìnlá ó lé méjìdínlógún
The sons of Pahath-moab, belonging to the sons of Jeshua and Joab, two thousand, eight hundred, and eighteen;
12 Elamu jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀fà ó lé mẹ́rin
The sons of Elam, a thousand, two hundred and fifty-four;
13 Sattu jẹ́ òjìlélẹ́gbẹ̀rin ó lé márùn-ún
The sons of Zattu, eight hundred, and forty-five;
14 Sakkai jẹ́ òjìdínlẹ́gbẹ̀rin
The sons of Zaccai, seven hundred, and sixty;
15 Binnui jẹ́ òjìlélẹ́gbẹ̀ta ó lé mẹ́jọ
The sons of Binnui, six hundred, and forty-eight;
16 Bebai jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó lé méjìdínlọ́gbọ̀n
The sons of Bebai, six hundred, and twenty-eight;
17 Asgadi jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó dín méjìdínlọ́gọ́rin
The sons of Azgad, two thousand, three hundred, and twenty-two;
18 Adonikami jẹ́ ọ̀tàlélẹ́gbẹ̀ta ó lé méje
The sons of Adonikam, six hundred, and sixty-seven;
19 Bigfai jẹ́ ẹgbàá ó lé mẹ́tàdínláàádọ́rin
The sons of Bigvai, two thousand, and sixty-seven;
20 Adini jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀ta ó lé márùn-ún
The sons of Adin, six hundred, and fifty-five;
21 Ateri (láti ipasẹ̀ Hesekiah) jẹ́ méjìdínlọ́gọ́rùn-ún
The sons of Ater, pertaining to Hezekiah, ninety-eight;
22 Haṣumu jẹ́ ọ̀rìndínnírinwó ó lé mẹ́jọ
The sons of Hashum, three hundred, and twenty-eight;
23 Besai jẹ́ ọ̀rìndínnírinwó ó lé mẹ́rin
The sons of Bezai, three hundred, and twenty-four;
24 Harifu jẹ́ méjìléláàádọ́fà
The sons of Hariph, a hundred, and twelve;
25 Gibeoni jẹ́ márùndínlọ́gọ́rùn.
The sons of Gibeon, ninety-five;
26 Àwọn ọmọ Bẹtilẹhẹmu àti Netofa jẹ́ igba ó dín méjìlélógún
The men of Bethlehem, and Netophah, a hundred, and eighty-eight;
27 Anatoti jẹ́ méjìdínláàádóje
The men of Anathoth, a hundred, and twenty-eight;
28 Beti-Asmafeti jẹ́ méjìlélógójì
The men of Beth-azmaveth, forty-two;
29 Kiriati-Jearimu, Kefira, àti Beeroti jẹ́ ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rin ó lé mẹ́ta
The men of Kiriath-jearim, Chephirah and Beeroth, seven hundred, and forty-three;
30 Rama àti Geba jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó lé mọ́kànlélógún
The men of Ramah and Geba, six hundred, and twenty-one;
31 Mikmasi jẹ́ méjìlélọ́gọ́fà
The men of Mickmas, a hundred, and twenty-two;
32 Beteli àti Ai jẹ́ mẹ́tàlélọ́gọ́fà
The men of Bethel and Ai, a hundred and twenty-three;
33 Nebo mìíràn jẹ́ méjìléláàádọ́ta
The men of the other Nebo, fifty-two;
34 Elamu mìíràn jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé mẹ́rìnléláàádọ́ta
The sons of the other Elam, a thousand, two hundred, and fifty-four;
35 Harimu jẹ́ ọ̀rìndínnírinwó
The sons of Harim, three hundred, and twenty;
36 Jeriko jẹ́ ọ̀tàdínnírinwó ó lé márùn-ún.
The sons of Jericho, three hundred, and forty-five;
37 Lodi, Hadidi, àti Ono jẹ́ ọ̀rìndínlẹ́gbẹ̀rin ó lé ọ̀kan
The sons of Lod, Hadid and One, seven hundred, and twenty-one;
38 Senaa jẹ́ ẹgbàajì ó dín àádọ́rin.
The sons of Senaah, three thousand, nine hundred, and thirty;
39 Àwọn àlùfáà: àwọn ọmọ Jedaiah (láti ipasẹ̀ ìdílé Jeṣua) jẹ́ ogún dín lẹ́gbẹ̀rin ó dín méje
The priests, The sons of Jedaiah, of the house of Jeshua, nine hundred, and seventy-three;
40 Immeri jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀rún ó lé méjì
The sons of Immer, a thousand, and fifty-two;
41 Paṣuri jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé mẹ́tàdínláàádọ́ta
The sons of Pashhur, a thousand, two hundred, and forty-seven;
42 Harimu jẹ́ ẹgbẹ̀rún ó lé mẹ́tàdínlógún.
The sons of Harim, a thousand, and seventeen;
43 Àwọn ọmọ Lefi: àwọn ọmọ Jeṣua (láti ipasẹ̀ Kadmieli, láti ipasẹ̀ Hodafiah) jẹ́ mẹ́rìnléláàádọ́rin.
The Levites, The sons of Jeshua, of Kadmiel, of the sons of Hodevah, seventy-four;
44 Àwọn akọrin: àwọn ọmọ Asafu jẹ́ méjìdínláàádọ́jọ.
The singers, The sons of Asaph, a hundred, and forty-eight;
45 Àwọn aṣọ́nà: àwọn ọmọ Ṣallumu, Ateri, Talmoni, Akkubu, Hatita, àti Ṣobai jẹ́ méjìdínlógóje.
The doorkeepers, The sons of Shallum, the sons of Ater, the sons of Talmon, the sons of Akkub, the sons of Hatita, the sons of Shobai, a hundred, and thirty-eight;
46 Àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili. Àwọn ọmọ Siha, Hasufa, Tabboati,
The Nethinim, The sons of Ziha, the sons of Hasupha, the sons of Tabbaoth;
47 Kerosi, Sia, Padoni,
the sons of Keros, the sons of Sia, the sons of Padon;
48 Lebana, Hagaba, Ṣalmai,
the sons of Lebana, the sons of Hagaba, the sons of Salmai;
49 Hanani, Giddeli, Gahari,
the sons of Hanan, the sons of Giddel, the sons of Gahar;
50 Reaiah, Resini, Nekoda,
the sons of Reaiah, the sons of Rezin, the sons of Nekoda;
51 Gassamu, Ussa, Pasea,
the sons of Gazzam, the sons of Uzza, the sons of Paseah;
52 Besai, Mehuni, Nefisimu,
the sons of Besai, the sons of Meunim, the sons of Nephushesim;
53 Bakbu, Hakufa, Harhuri,
the sons of Bakbuk, the sons of Hakupha, the sons of Harhur;
54 Basluti, Mehida, Harṣa,
the sons of Bazlith, the sons of Mehida, the sons of Harsha;
55 Barkosi, Sisera, Tema,
the sons of Barkos, the sons of Sisera, the sons of Temah;
56 Nesia, àti Hatifa.
the sons of Neziah, the sons of Hatipha.
57 Àwọn ọmọ àwọn ìránṣẹ́ Solomoni: àwọn ọmọ Sotai, Sofereti; Perida,
The Sons of the Servants of Solomon, The sons of Sotai, the sons of Sophereth, the sons of Perida;
58 Jaala, Darkoni, Giddeli,
the sons of Jaala, the sons of Darkon, the sons of Giddel;
59 Ṣefatia, Hattili, Pokereti-Haṣṣebaimu, àti Amoni.
the sons of Shephatiah, the sons of Hattil, the sons of Pochereth-hazzebaim, the sons of Amon.
60 Àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili àti àwọn ọmọ ìránṣẹ́ Solomoni jẹ́ irinwó ó dín mẹ́jọ.
All the Nethinim, and the Sons of the Servants of Solomon, were three hundred, and ninety-two.
61 Àwọn wọ̀nyí gòkè wá láti àwọn ìlú ti Teli-Mela, Teli-Harṣa, Kerubu, Addoni àti Immeri, ṣùgbọ́n wọn kò lè sọ pẹ̀lú ìdánilójú pé ìdílé àwọn wá láti ara ìran ẹ̀yà Israẹli.
And, these, are they who came up from Tel-melah, Tel-harsha, Cherub, Addon, and Immer, —but they could not tell their ancestral house, nor their seed, whether, of Israel, they were:
62 Àwọn ọmọ Delaiah, Tobiah àti Nekoda jẹ́ òjìlélẹ́gbẹ̀ta ó lé méjì.
the sons of Delaiah, the sons of Tobiah, the sons of Nekoda, —six hundred and forty-two,
63 Lára àwọn àlùfáà ni: àwọn ọmọ Hobaiah, Hakosi àti Barsillai (ọkùnrin tí ó fẹ́ ọmọbìnrin Barsillai ará Gileadi, ẹni tí a ń fi orúkọ yìí pè).
And, of the priests, the sons of Hobaiah, the sons of Hakkoz, —the sons of Barzillai, who had taken of the daughters of Barzillai the Gileadite to wife, and was called after their name.
64 Àwọn wọ̀nyí wá àkọsílẹ̀ orúkọ ìran wọn, ṣùgbọ́n wọn kò rí í níbẹ̀, fún ìdí èyí, a yọ wọ́n kúrò nínú àwọn tí ń ṣiṣẹ́ àlùfáà gẹ́gẹ́ bí aláìmọ́.
These, sought their writing wherein they were registered, but it was not found, —so they were desecrated out of the priesthood;
65 Baálẹ̀ sọ fún wọn nítorí náà pé wọn kò gbọdọ̀ kópa nínú jíjẹ oúnjẹ mímọ́ títí tí àlùfáà tí yóò wá tí ń ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́ pẹ̀lú Urimu àti Tumimu yóò fi dé.
and the governor told them, they must not eat of the most holy things, —until there should stand up a priest, with Lights and Perfections.
66 Gbogbo ìjọ ènìyàn náà jẹ́ ẹgbàá mọ́kànlélógún ó lé òjìdínnírinwó,
All the gathered host together, was forty-two thousand, three hundred, and sixty;
67 yàtọ̀ sí àwọn ìránṣẹ́kùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin tí wọ́n jẹ́ ẹgbẹ̀ta dín lẹ́gbàárin ó dín ẹ̀tàlélọ́gọ́ta; wọ́n sì tún ní àwọn akọrin ọkùnrin àti obìnrin tí wọ́n jẹ́ òjìlúgba ó lé márùn-ún.
besides, their men-servants and maid-servants, were these, seven thousand, three hundred, and thirty-seven, —and, to them, pertained, singing-men and singing-women, two hundred, and forty-five:
68 Ẹṣin wọn jẹ́ ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rin ó dín mẹ́rin, ìbákasẹ wọn jẹ́ òjìlúgba ó dín márùn-ún;
their horses, were seven hundred, and thirty-six, —their mules, two hundred, and forty-five;
69 ìbákasẹ wọn jẹ́ òjìlénírinwó ó dín márùn-ún; kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wọ́n jẹ́ ẹgbẹ̀rìnlélọ́gbọ̀n ó dín ọgọ́rin.
camels, four hundred, and thirty-five, —asses, six thousand, seven hundred, and twenty.
70 Díẹ̀ lára àwọn olórí ìdílé náà kópa nínú ṣíṣe iṣẹ́ náà. Baálẹ̀ fún ilé ìṣúra ní ẹgbẹ̀rún dariki wúrà, àádọ́ta àwo koto àti ọ̀rìndínlẹ́gbẹ̀ta lé mẹ́wàá ẹ̀wù fún àwọn àlùfáà.
And, a portion of the ancestral chiefs, gave unto the work, —the governor, gave unto the treasury, of gold, a thousand darics, tossing bowls, fifty, tunics for priests, five hundred, and thirty;
71 Díẹ̀ lára àwọn olórí ìdílé fún ilé ìṣúra ní ogún ẹgbẹ̀rún dariki wúrà àti ẹgbọ̀kànlá mina fàdákà.
and, some of the ancestral chiefs, gave unto the treasury of the work, of gold, twenty thousand darics, —and, of silver, two thousand and two hundred manehs;
72 Àròpọ̀ gbogbo ohun tí àwọn ènìyàn tókù fi sílẹ̀ jẹ́ ogún ẹgbẹ̀rún dariki wúrà, ẹgbẹ̀rún méjì mina fàdákà àti ẹẹ́tàdínláàdọ́rin ẹ̀wù fún àwọn àlùfáà.
and, that which the rest of the people gave, was, of gold, twenty thousand darics, and, of silver, two thousand manehs, —and, tunics for priests, sixty-seven.
73 Àwọn àlùfáà, àwọn Lefi, àwọn aṣọ́bodè, àwọn akọrin, àwọn ènìyàn díẹ̀, àwọn ìránṣẹ́ ilé Ọlọ́run, àti gbogbo ènìyàn Israẹli wà ní ìlú wọn. Nígbà tí ó di oṣù keje, tí àwọn ọmọ Israẹli sì ti wà nínú ìlú u wọn,
So the priests and the Levites and the door-keepers and the singers and some of the people, and the Nethinim and all Israel, took up their abode in their cities. And, when the seventh month arrived, the sons of Israel were in their cities.

< Nehemiah 7 >