< Matthew 21 >

1 Bí wọ́n ti súnmọ́ Jerusalẹmu, tí wọ́n dé itòsí ìlú Betfage ní orí òkè Olifi, Jesu sì rán àwọn ọmọ-ẹ̀yìn méjì,
ⲁ̅ⲞⲨⲞϨ ϨⲞⲦⲈ ⲈⲦⲀⲨϦⲰⲚⲦ ⲈⲒⲈⲢⲞⲤⲀⲖⲎⲘ ⲀⲨⲒ ⲈⲂⲎⲐⲪⲀⲄⲎ ϦⲀⲦⲈⲚ ⲠⲒⲦⲰⲞⲨ ⲚⲦⲈⲚⲒϪⲰⲒⲦ ⲦⲞⲦⲈ ⲀⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲞⲨⲰⲢⲠ ⲘⲘⲀⲐⲎⲦⲎⲤ Ⲃ-
2 Ó wí fún wọn pé, “Ẹ lọ sí ìletò tó wà ni tòsí yín, ẹ̀yin yóò rí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ kan ti wọ́n so pẹ̀lú ọmọ rẹ̀ lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀. Ẹ tú wọn, kí ẹ sì mú wọn wá fún mi.
ⲃ̅ⲈϤϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ⲚⲰⲞⲨ ϪⲈ ⲘⲀϢⲈ ⲚⲰⲦⲈⲚ ⲈⲠⲀⲒϮⲘⲒ ⲈⲦⲬⲎ ⲘⲠⲈⲦⲈⲚⲘⲐⲞ ⲞⲨⲞϨ ⲈⲢⲈⲦⲈⲚⲈϪⲒⲘⲒ ⲚⲞⲨⲈⲰ ⲈⲤⲤⲞⲚϨ ⲚⲈⲘ ⲞⲨⲤⲎϪ ⲚⲈⲘⲀⲤ ⲂⲞⲖⲞⲨ ⲀⲚⲒⲦⲞⲨ ⲚⲎⲒ.
3 Bí ẹnikẹ́ni bá sì béèrè ìdí tí ẹ fi ń ṣe bẹ́ẹ̀, ẹ sá à wí pé, Olúwa fẹ́ lo wọn, òun yóò sì rán wọn lọ.”
ⲅ̅ⲀⲢⲈϢⲀⲚ ⲞⲨⲀⲒ ⲆⲈ ⲤⲀϪⲒ ⲚⲈⲘⲰⲦⲈⲚ ⲀϪⲞⲤ ϪⲈ ⲠϬⲞⲒⲤ ⲠⲈⲦⲈⲢⲬⲢⲒⲀ ⲘⲘⲰⲞⲨ ϤⲚⲀⲞⲨⲞⲢⲠⲞⲨ ⲆⲈ ⲤⲀⲦⲞⲦϤ.
4 Èyí ṣẹlẹ̀ láti mú àsọtẹ́lẹ̀ wòlíì ṣẹ pé:
ⲇ̅ⲪⲀⲒ ⲆⲈ ⲀϤϢⲰⲠⲒ ϨⲒⲚⲀ ⲚⲦⲈϤϪⲰⲔ ⲈⲂⲞⲖ ⲚϪⲈⲪⲎ ⲈⲦⲀϤϪⲞϤ ⲈⲂⲞⲖ ϨⲒⲦⲞⲦϤ ⲘⲠⲒⲠⲢⲞⲪⲎⲦⲎⲤ ⲈϤϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ.
5 “Ẹ sọ fún ọmọbìnrin Sioni pé, ‘Wò ó, ọba rẹ ń bọ̀ wá sí ọ̀dọ̀ rẹ, ní ìrẹ̀lẹ̀, ó ń gun kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àti lórí ọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.’”
ⲉ̅ϪⲈ ⲀϪⲞⲤ ⲚⲦϢⲈⲢⲒ ⲚⲤⲒⲰⲚ ϪⲈ ⲒⲤ ⲠⲈⲞⲨⲢⲞ ϤⲚⲎⲞⲨ ⲚⲈⲈⲞⲨⲢⲈⲘⲢⲀⲨϢ ⲠⲈ ⲈϤⲦⲀⲖⲎ ⲞⲨⲦ ⲈⲞⲨⲈⲰ ⲚⲈⲘ ⲞⲨⲤⲎϪ ⲠϢⲎⲢⲒ ⲚⲞⲨⲈⲰ.
6 Àwọn ọmọ-ẹ̀yìn náà sí lọ, wọ́n ṣe bí Jesu ti sọ fún wọn.
ⲋ̅ⲈⲦⲀⲨϢⲈ ⲚⲰⲞⲨ ⲚϪⲈⲚⲈϤⲘⲀⲐⲎⲦⲎⲤ ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀⲨⲒⲢⲒ ⲔⲀⲦⲀ ⲪⲢⲎϮ ⲈⲦⲀ ⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲞⲨⲀϨⲤⲀϨⲚⲒ ⲚⲰⲞⲨ.
7 Wọ́n sì mú kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ náà pẹ̀lú ọmọ rẹ̀, wọ́n tẹ́ aṣọ lé e, Jesu si jókòó lórí rẹ̀.
ⲍ̅ⲀⲨⲒⲚⲒ ⲚϮⲈⲰ ⲚⲈⲘ ⲠⲒⲤⲎϪ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲨⲦⲀⲖⲞ ⲚⲚⲞⲨϨⲂⲰⲤ ⲈⲢⲰⲞⲨ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲨⲐⲢⲈϤϨⲈⲘⲤⲒ ⲤⲀⲠϢⲰⲒ ⲘⲘⲰⲞⲨ.
8 Ọ̀pọ̀ ìjọ ènìyàn sì tẹ́ aṣọ wọn sí ojú ọ̀nà níwájú rẹ̀, ẹlòmíràn ṣẹ́ ẹ̀ka igi wẹ́wẹ́ wọ́n sì tẹ́ wọn sí ojú ọ̀nà.
ⲏ̅ⲠϨⲞⲨⲞ ⲆⲈ ⲚⲚⲒⲘⲎϢ ⲀⲨⲪⲰⲢϢ ⲚⲚⲞⲨϨⲂⲰⲤ ϨⲒ ⲠⲒⲘⲰⲒⲦ ϨⲀⲚⲔⲈⲬⲰⲞⲨⲚⲒ ⲀⲨⲔⲰⲢϪ ⲚϨⲀⲚϪⲀⲖ ⲈⲂⲞⲖ ϨⲒ ⲚⲒϢϢⲎⲚ ⲀⲨⲪⲞⲢϢⲞⲨ ϨⲒ ⲠⲒⲘⲰⲒⲦ.
9 Ọ̀pọ̀ ènìyàn ń lọ níwájú rẹ̀ àti lẹ́yìn rẹ̀ pẹ̀lú ń kígbe pé, “Hosana fún ọmọ Dafidi!” “Olùbùkún ni fún ẹni tí ó ń bọ̀ ní orúkọ Olúwa!” “Hosana ní ibi gíga jùlọ!”
ⲑ̅ⲚⲒⲘⲎϢ ⲆⲈ ⲀⲨⲘⲞϢⲒ ϦⲀϪⲰϤ ⲚⲈⲘ ⲚⲎ ⲈⲚⲀⲨⲘⲞϢⲒ ⲚⲤⲰϤ ⲚⲀⲨⲰϢ ⲈⲂⲞⲖ ⲈⲨϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ϪⲈ ⲰⲤⲀⲚⲚⲀ ⲠϢⲎⲢⲒ ⲚⲆⲀⲨⲒⲆ ϤⲤⲘⲀⲢⲰⲞⲨⲦ ⲚϪⲈⲠⲈⲐⲚⲎⲞⲨ ϦⲈⲚⲪⲢⲀⲚ ⲘⲠϬⲞⲒⲤ ⲰⲤⲀⲚⲚⲀ ϦⲈⲚⲚⲎ ⲈⲦϬⲞⲤⲒ.
10 Bí Jesu sì ti ń wọ Jerusalẹmu, gbogbo ìlú mì tìtì, àwọn ènìyàn bẹ̀rẹ̀ sí í bi ara wọn pé, “Ta nìyìí?”
ⲓ̅ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀϤⲒ ⲈϦⲞⲨⲚ ⲈⲒⲈⲢⲞⲤⲀⲖⲎⲘ ⲀⲤⲘⲞⲚⲘⲈⲚ ⲚϪⲈϮⲂⲀⲔⲒ ⲦⲎⲢⲤ ⲈⲨϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ϪⲈ ⲚⲒⲘ ⲠⲈ ⲪⲀⲒ.
11 Ọ̀pọ̀ ènìyàn sì dáhùn pé, “Èyí ni Jesu, wòlíì náà láti Nasareti ti Galili.”
ⲓ̅ⲁ̅ⲚⲒⲘⲎϢ ⲆⲈ ⲚⲀⲨϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ϪⲈ ⲪⲀⲒ ⲠⲈ ⲠⲒⲠⲢⲞⲪⲎⲦⲎⲤ ⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲠⲒⲢⲈⲘⲚⲀⲌⲀⲢⲈⲐ ⲚⲦⲈϮⲄⲀⲖⲒⲖⲈⲀ.
12 Jesu sì wọ inú tẹmpili, Ó sì lé àwọn ti ń tà àti àwọn tí ń rà níbẹ̀ jáde. Ó yí tábìlì àwọn onípàṣípàrọ̀ owó dànù, àti tábìlì àwọn tí ó ń ta ẹyẹlé.
ⲓ̅ⲃ̅ⲞⲨⲞϨ ⲀϤϢⲈ ⲚⲀϤ ⲚϪⲈⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲈϦⲞⲨⲚ ⲈⲠⲒⲈⲢⲪⲈⲒ ⲞⲨⲞϨ ⲀϤϨⲒⲞⲨⲒ ⲈⲂⲞⲖ ⲚⲞⲨⲞⲚ ⲚⲒⲂⲈⲚ ⲈⲦϮ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲠⲒⲈⲢⲪⲈⲒ ⲚⲈⲘ ⲚⲎ ⲈⲦϢⲰⲠ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲒⲦⲢⲀⲠⲈⲌⲀ ⲚⲦⲈⲚⲒⲢⲈϤⲈⲢⲔⲈⲢⲘⲀ ⲀϤⲪⲞⲚϪⲞⲨ ⲚⲈⲘ ⲚⲒⲔⲀⲐⲈⲆⲢⲀ ⲚⲦⲈⲚⲎ ⲈⲦϮ ϬⲢⲞⲘⲠⲒ ⲈⲂⲞⲖ.
13 Ó wí fún wọn pé, “A sá à ti kọ ọ́ pé, ‘Ilé àdúrà ni a ó máa pe ilé mi,’ ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti sọ ọ́ di ibùdó àwọn ọlọ́ṣà.”
ⲓ̅ⲅ̅ⲞⲨⲞϨ ⲠⲈϪⲀϤ ⲚⲰⲞⲨ ϪⲈ ⲤⲤϦⲎⲞⲨⲦ ϪⲈ ⲠⲀⲎⲒ ⲈⲨⲈⲘⲞⲨϮ ⲈⲢⲞϤ ϪⲈ ⲞⲨⲎⲒ ⲘⲠⲢⲞⲤⲈⲨⲬⲎ ⲚⲐⲰⲦⲈⲚ ⲆⲈ ⲦⲈⲦⲈⲚⲒⲢⲒ ⲘⲘⲞϤ ⲘⲘⲀⲚⲬⲰⲠ ⲚⲤⲞⲚⲒ.
14 A sì mú àwọn afọ́jú àti àwọn arọ wá sọ́dọ̀ rẹ̀ ní tẹmpili, ó sì mú wọ́n láradá.
ⲓ̅ⲇ̅ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀⲨⲒ ϨⲀⲢⲞϤ ⲚϪⲈϨⲀⲚⲂⲈⲖⲖⲈⲨ ⲚⲈⲘ ϨⲀⲚϬⲀⲖⲈⲨ ϦⲈⲚⲠⲒⲈⲢⲪⲈⲒ ⲀϤⲈⲢⲪⲀϦⲢⲒ ⲈⲢⲰⲞⲨ.
15 Ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn olórí àlùfáà àti àwọn olùkọ́ òfin rí àwọn iṣẹ́ ìyanu ńlá wọ̀nyí, ti wọ́n sì tún ń gbọ́ tí àwọn ọmọdé ń kígbe nínú tẹmpili pé, “Hosana fún ọmọ Dafidi,” inú bí wọn.
ⲓ̅ⲉ̅ⲈⲦⲀⲨⲚⲀⲨ ⲆⲈ ⲚϪⲈⲚⲒⲀⲢⲬⲒⲈⲢⲈⲨⲤ ⲚⲈⲘ ⲚⲒⲤⲀϦ ⲈⲚⲒϢⲪⲎⲢⲒ ⲈⲦⲀϤⲀⲒⲦⲞⲨ ⲚⲈⲘ ⲚⲒⲀⲖⲰⲞⲨⲒ ⲈⲦⲰϢ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲠⲒⲈⲢⲪⲈⲒ ⲈⲨϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ϪⲈ ⲰⲤⲀⲚⲚⲀ ⲠϢⲎⲢⲒ ⲚⲆⲀⲨⲒⲆ ⲀⲨⲬⲢⲈⲘⲢⲈⲘ.
16 Wọ́n sì bí i pé, “Ǹjẹ́ ìwọ gbọ́ nǹkan tí àwọn ọmọdé wọ̀nyí ń sọ?” Jesu sí dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, àbí ẹ̀yin kò kà á pé, “‘Láti ẹnu àwọn ọmọdé àti àwọn ọmọ ọmú, ni a ó ti máa yìn mí’?”
ⲓ̅ⲋ̅ⲞⲨⲞϨ ⲠⲈϪⲰⲞⲨ ⲚⲀϤ ϪⲈ ⲔⲤⲰⲦⲈⲘ ⲀⲚ ϪⲈ ⲞⲨ ⲠⲈⲦⲈ ⲚⲀⲒ ϪⲰ ⲘⲘⲞϤ ⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲆⲈ ⲠⲈϪⲀϤ ⲚⲰⲞⲨ ϪⲈ ⲤⲈ ⲘⲠⲈⲦⲈⲚⲰϢ ⲈⲚⲈϨ ϦⲈⲚⲚⲒⲄⲢⲀⲪⲎ ϪⲈ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲢⲰⲞⲨ ⲚϨⲀⲚⲔⲞⲨϪⲒ ⲚⲀⲖⲰⲞⲨⲒ ⲚⲈⲘ ⲚⲎ ⲈⲐⲞⲨⲈⲘϬⲒ ⲀⲔⲤⲈⲂⲦⲈ ⲠⲒⲤⲘⲞⲨ.
17 Ó sì fi wọ́n sílẹ̀, ó lọ sí Betani. Níbẹ̀ ni ó dúró ní òru náà.
ⲓ̅ⲍ̅ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀϤⲬⲀⲨ ⲀϤⲒ ⲤⲀⲂⲞⲖ ⲚϮⲂⲀⲔⲒ ⲈⲂⲎⲐⲀⲚⲒⲀ ⲀϤⲚⲔⲞⲦ ⲘⲘⲀⲨ.
18 Ní òwúrọ̀ bí ó ṣe ń padà sí ìlú, ebi ń pa á.
ⲓ̅ⲏ̅ⲈⲦⲀ ⲦⲞⲞⲨⲒ ⲆⲈ ϢⲰⲠⲒ ⲀϤⲦⲀⲤⲐⲞ ⲈϮⲂⲀⲔⲒ ⲀϤϨⲔⲞ.
19 Ó sì ṣàkíyèsí igi ọ̀pọ̀tọ́ kan lẹ́bàá ojú ọ̀nà, ó sì lọ wò ó bóyá àwọn èso wà lórí rẹ̀, ṣùgbọ́n kò sí ẹyọ kan, ewé nìkan ni ó wà lórí rẹ̀. Nígbà náà ni ó sì wí fún igi náà pé, “Kí èso má tún so lórí rẹ mọ́ láti òní lọ àti títí láé.” Lójúkan náà igi ọ̀pọ̀tọ́ náà sì gbẹ. (aiōn g165)
ⲓ̅ⲑ̅ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀϤⲚⲀⲨ ⲈⲞⲨⲂⲰ ⲚⲔⲈⲚⲦⲈ ϨⲒ ⲠⲒⲘⲰⲒⲦ ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀϤⲒ ϨⲀⲢⲞⲤ ⲘⲠⲈϤϪⲈⲘ ϨⲖⲒ ϨⲒⲰⲦⲤ ⲈⲂⲎⲖ ⲈϨⲀⲚϪⲰⲂⲒ ⲘⲘⲀⲨⲀⲦⲞⲨ ⲞⲨⲞϨ ⲠⲈϪⲀϤ ⲚⲀⲤ ϪⲈ ⲚⲚⲈ ⲞⲨⲦⲀϨ ⲒⲈⲂⲞⲖ ⲚϦⲎϮ ϢⲀ ⲈⲚⲈϨ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲤϢⲰⲞⲨⲒ ⲚϪⲈϮⲂⲰ ⲚⲔⲈⲚⲦⲈ ⲒⲤϪⲈⲚ ϮⲞⲨⲚⲞⲨ ⲈⲦⲈⲘⲘⲀⲨ. (aiōn g165)
20 Nígbà tí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ rí èyí, ẹnu yà wọn, wọ́n béèrè pé, “Báwo ni igi ọ̀pọ̀tọ́ náà ṣe gbẹ kíákíá?”
ⲕ̅ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀⲨⲚⲀⲨ ⲚϪⲈⲚⲒⲘⲀⲐⲎⲦⲎⲤ ⲀⲨⲈⲢϢⲪⲎⲢⲒ ⲈⲨϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ϪⲈ ⲠⲰⲤ ⲀⲦⲀⲒⲂⲰ ⲚⲔⲈⲚⲦⲈ ϢⲰⲞⲨⲒ ⲚⲦⲀⲒⲞⲨⲚⲞⲨ.
21 Jesu wí fún wọn pé, “Lóòótọ́ ni mo wí fún yín, bí ẹ̀yin bá lè ní ìgbàgbọ́ láìṣiyèméjì, nígbà náà ẹ̀yin yóò lè ṣe irú ohun tí a ṣe sí igi ọ̀pọ̀tọ́, ẹ̀yin yóò lè sọ fún òkè yìí pé, ‘Yí ipò padà sínú Òkun,’ yóò sì rí bẹ́ẹ̀.
ⲕ̅ⲁ̅ⲀϤⲈⲢⲞⲨⲰ ⲆⲈ ⲚϪⲈⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲠⲈϪⲀϤ ⲚⲰⲞⲨ ϪⲈ ⲀⲘⲎⲚ ϮϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ⲚⲰⲦⲈⲚ ϪⲈ ⲈϢⲰⲠ ⲈⲞⲨⲞⲚⲦⲈⲦⲈⲚ ⲚⲀϨϮ ⲘⲘⲀⲨ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲦⲈⲦⲈⲚϢⲦⲈⲘⲈⲢϨⲎ ⲦⲂ ⲘⲪⲀ ⲦⲀⲒⲂⲰ ⲚⲔⲈⲚⲦⲈ ⲘⲘⲀⲨⲀⲦϤ ⲀⲚ ⲠⲈ ⲈⲦⲈⲦⲈⲚⲚⲀⲀⲒϤ ⲀⲖⲖⲀ ⲀⲢⲈⲦⲈⲚϢⲀⲚϪⲞⲤ ⲘⲠⲀⲒⲦⲰⲞⲨ ϪⲈ ϤⲒⲦⲔ ⲞⲨⲞϨ ⲘⲀϢⲈ ⲚⲀⲔ ⲈⲪⲒⲞⲘ ⲈⲤⲈϢⲰⲠⲒ
22 Bí ẹ̀yin bá gbàgbọ́, ẹ̀yin lè rí ohunkóhun tí ẹ bá béèrè nínú àdúrà gbà.”
ⲕ̅ⲃ̅ⲞⲨⲞϨ ϨⲰⲂ ⲚⲒⲂⲈⲚ ⲈⲦⲈⲦⲈⲚⲚⲀⲈⲢⲈⲦⲒⲚ ⲘⲘⲞϤ ϦⲈⲚⲞⲨⲠⲢⲞⲤⲈⲨⲬⲎ ⲈⲢⲈⲦⲈⲚⲚⲀϨϮ ⲈⲢⲈⲦⲈⲚⲈϬⲒⲦⲞⲨ.
23 Jesu wọ tẹmpili, nígbà tí ó ń kọ́ni, àwọn olórí àlùfáà àti àwọn àgbàgbà Júù tọ̀ ọ́ wá. Wọ́n béèrè pé “nípa àṣẹ wo ni o fi ń ṣe àwọn nǹkan wọ̀nyí? Ta ni ó sì fún ọ ni àṣẹ yìí?”
ⲕ̅ⲅ̅ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀϤⲒ ⲈϦⲞⲨⲚ ⲈⲠⲒⲈⲢⲪⲈⲒ ⲀⲨⲒ ϨⲀⲢⲞϤ ⲈϤϮⲤⲂⲰ ⲚϪⲈⲚⲒⲀⲢⲬⲒⲈⲢⲈⲨⲤ ⲚⲈⲘ ⲚⲒⲠⲢⲈⲤⲂⲨⲦⲈⲢⲞⲤ ⲚⲦⲈⲠⲒⲖⲀⲞⲤ ⲈⲨϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ϪⲈ ⲀⲔⲒⲢⲒ ⲚⲚⲀⲒ ϦⲈⲚⲀϢ ⲚⲈⲢϢⲒϢⲒ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲒⲘ ⲠⲈⲦⲀϤϮ ⲘⲠⲀⲒⲈⲢϢⲒϢⲒ ⲚⲀⲔ.
24 Jesu sì dáhùn ó sì wí fún wọn pé, “Èmi yóò si bí yin léèrè ohun kan, bí ẹ̀yin bá lé sọ fún mi, nígbà náà èmi yóò sọ fún yín, àṣẹ tí Èmi fi ń ṣe àwọn nǹkan wọ̀nyí.
ⲕ̅ⲇ̅ⲀϤⲈⲢⲞⲨⲰ ⲚϪⲈⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲠⲈϪⲀϤ ⲚⲰⲞⲨ ϪⲈ ϮⲚⲀϢⲈⲚ ⲐⲎⲚⲞⲨ ϨⲰ ⲈⲞⲨⲤⲀϪⲒ ⲈϢⲰⲠ ⲀⲢⲈⲦⲈⲚϢⲀⲚⲦⲀⲘⲞⲒ ⲈⲢⲞϤ ⲀⲚⲞⲔ ϨⲰ ϮⲚⲀⲦⲀⲘⲰⲦⲈⲚ ϪⲈ ⲀⲒⲒⲢⲒ ⲚⲚⲀⲒ ϦⲈⲚⲀϢ ⲚⲈⲢϢⲒϢⲒ.
25 Níbo ni ìtẹ̀bọmi Johanu ti wa? Láti ọ̀run wá ni, tàbí láti ọ̀dọ̀ ènìyàn.” Wọ́n sì bá ara wọn gbèrò pé, “Bí àwa bá wí pé láti ọ̀run wá ni, òun yóò wí fún wa pé, ‘Èéha ti ṣe tí ẹ̀yin kò fi gbà á gbọ́?’
ⲕ̅ⲉ̅ⲠⲒⲰⲘⲤ ⲚⲦⲈⲒⲰⲀⲚⲚⲎⲤ ⲚⲈⲞⲨⲈⲂⲞⲖ ⲐⲰⲚ ⲠⲈ ⲞⲨⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲦⲪⲈ ⲠⲈ ϢⲀⲚ ⲞⲨⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲚⲒⲢⲰⲘⲒ ⲠⲈ ⲚⲐⲰⲞⲨ ⲆⲈ ⲚⲀⲨⲘⲞⲔⲘⲈⲔ ⲚϦⲢⲎⲒ ⲚϦⲎⲦⲞⲨ ⲈⲨϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ϪⲈ ⲈϢⲰⲠ ⲀⲚϢⲀⲚϪⲞⲤ ϪⲈ ⲞⲨⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲦⲪⲈ ⲠⲈ ϤⲚⲀϪⲞⲤ ⲚⲀⲚ ϪⲈ ⲈⲐⲂⲈⲞⲨ ⲘⲠⲈⲦⲈⲚⲚⲀϨϮ ⲈⲢⲞϤ.
26 Ní ìdàkejì, bí àwa bá sì sọ pé, ‘Láti ọ̀dọ̀ ènìyàn, àwa bẹ̀rù ìjọ ènìyàn, nítorí gbogbo wọ́n ka Johanu sí wòlíì.’”
ⲕ̅ⲋ̅ⲈϢⲰⲠ ⲆⲈ ⲀⲚϢⲀⲚϪⲞⲤ ϪⲈ ⲞⲨⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲚⲒⲢⲰⲘⲒ ⲦⲈⲚⲈⲢϨⲞϮ ϦⲀⲦϨⲎ ⲘⲠⲒⲘⲎϢ ⲒⲰⲀⲚⲚⲎⲤ ⲄⲀⲢ ⲚⲦⲞⲦⲞⲨ ϨⲰⲤ ⲞⲨⲠⲢⲞⲪⲎⲦⲎⲤ.
27 Nítorí náà wọ́n sì dá Jesu lóhùn pé, “Àwa kò mọ̀.” Nígbà náà ni ó wí pé, “Nítorí èyí, èmi kò ní sọ àṣẹ tí èmi fi ń ṣe nǹkan wọ̀nyí fún yín.
ⲕ̅ⲍ̅ⲞⲨⲞϨ ⲀⲨⲈⲢⲞⲨⲰ ⲠⲈϪⲰⲞⲨ ⲚⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ϪⲈ ⲦⲈⲚⲈⲘⲒ ⲀⲚ ⲠⲈϪⲀϤ ⲆⲈ ⲚⲰⲞⲨ ϪⲈ ⲞⲨⲆⲈ ⲀⲚⲞⲔ ϨⲰ ϮⲚⲀⲦⲀⲘⲰⲦⲈⲚ ⲀⲚ ϪⲈ ⲀⲒⲒⲢⲒ ⲚⲚⲀⲒ ϦⲈⲚⲀϢ ⲚⲈⲢϢⲒϢⲒ.
28 “Kí ni ẹ rò nípa eléyìí? Ọkùnrin kan ti ó ní àwọn ọmọkùnrin méjì. Ó sọ fún èyí ẹ̀gbọ́n pé, ‘Ọmọ, lọ ṣiṣẹ́ nínú ọgbà àjàrà lónìí.’
ⲕ̅ⲏ̅ⲞⲨ ⲆⲈ ⲠⲈⲦⲈⲦⲈⲚⲘⲈⲨⲒ ⲈⲢⲞϤ ⲚⲈⲞⲨⲞⲚ ⲞⲨⲢⲰⲘⲒ ⲈⲞⲨⲞⲚⲦⲈϤ ϢⲎⲢⲒ ⲂⲘⲘⲀⲨ ⲀϤⲒ ϨⲀ ⲠⲒϨⲞⲨⲒⲦ ⲠⲈϪⲀϤ ⲚⲀϤ ϪⲈ ⲠⲀϢⲎⲢⲒ ⲘⲀϢⲈ ⲚⲀⲔ ⲘⲪⲞⲞⲨ ⲀⲢⲒϨⲰⲂ ϦⲈⲚⲠⲒⲒⲀϨⲀⲖⲞⲖⲒ.
29 “Ó sì dá baba rẹ̀ lóhùn pé, ‘Èmi kò ní í lọ,’ ṣùgbọ́n níkẹyìn ó yí ọkàn padà, ó sì lọ.
ⲕ̅ⲑ̅ⲚⲐⲞϤ ⲆⲈ ⲀϤⲈⲢⲞⲨⲰ ⲠⲈϪⲀϤ ϪⲈ ⲀⲚⲞⲔ ⲠⲀϬⲞⲒⲤ ⲞⲨⲞϨ ⲘⲠⲈϤϢⲈ ⲚⲀϤ.
30 “Nígbà náà ni baba yìí tún sọ fún èyí àbúrò pé, ‘Lọ ṣiṣẹ́ ní oko.’ Ọmọ náà sì sọ pé, ‘Èmi yóò lọ, baba,’ ṣùgbọ́n kò lọ rárá.
ⲗ̅ⲀϤⲒ ϨⲀ ⲠⲒⲘⲀϨⲂ ⲀϤϪⲞⲤ ⲚⲀϤ ⲞⲚ ⲘⲠⲀⲒⲢⲎϮ ⲚⲐⲞϤ ⲆⲈ ⲀϤⲈⲢⲞⲨⲰ ⲠⲈϪⲀϤ ϪⲈ ⲚϮⲞⲨⲰϢ ⲀⲚ ⲈⲠϦⲀⲈ ⲆⲈ ⲈⲦⲀϤⲞⲨⲈⲘϨⲐⲎϤ ⲀϤϢⲈ ⲚⲀϤ.
31 “Nínú àwọn méjèèjì yìí, èwo ni ó ṣe ìfẹ́ baba wọn?” Gbogbo wọn sì fohùn ṣọ̀kan pé, “Èyí ẹ̀gbọ́n ni.” Jesu wí fún wọn pé, “Lóòótọ́ ni mo wí fún yín, àwọn agbowó òde àti àwọn panṣágà yóò wọ ìjọba ọ̀run síwájú yín.
ⲗ̅ⲁ̅ⲚⲒⲘ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲠⲒⲂ ⲀϤⲈⲢ ⲠⲈⲦⲈϨⲚⲈ ⲠⲈϤⲒⲰⲦ ⲠⲈϪⲰⲞⲨ ϪⲈ ⲠⲒϦⲀⲈ ⲠⲈϪⲈ ⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲚⲰⲞⲨ ϪⲈ ⲀⲘⲎⲚ ϮϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ⲚⲰⲦⲈⲚ ϪⲈ ⲠⲒⲦⲈⲖⲰⲚⲎⲤ ⲚⲈⲘ ⲚⲒⲠⲞⲢⲚⲞⲤ ⲤⲈⲚⲀⲈⲢϢⲞⲢⲠ ⲈⲢⲰⲦⲈⲚ ⲈϮⲘⲈⲦⲞⲨⲢⲞ ⲚⲦⲈⲪⲚⲞⲨϮ.
32 Nítorí Johanu tọ́ yin wá láti fi ọ̀nà òdodo hàn yín, ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò gbà á gbọ́, ṣùgbọ́n àwọn agbowó òde àti àwọn panṣágà ronúpìwàdà, bí ó tilẹ̀ ṣe pé ẹ rí àwọn ohun tí ń ṣẹlẹ̀ wọ̀nyí, ẹ kọ̀ láti ronúpìwàdà, ẹ kò gbà á gbọ́.”
ⲗ̅ⲃ̅ⲀϤⲒ ⲄⲀⲢ ϨⲀⲢⲰⲦⲈⲚ ⲚϪⲈⲒⲰⲀⲚⲚⲎⲤ ϦⲈⲚⲠⲒⲘⲰⲒⲦ ⲚⲦⲈϮⲘⲈⲐⲘⲎⲒ ⲞⲨⲞϨ ⲘⲠⲈⲦⲈⲚⲚⲀϨϮ ⲈⲢⲞϤ ⲚⲒⲦⲈⲖⲰⲚⲎⲤ ⲆⲈ ⲚⲈⲘ ⲚⲒⲠⲞⲢⲚⲞⲤ ⲀⲨⲚⲀϨϮ ⲈⲢⲞϤ ⲚⲐⲰⲦⲈⲚ ⲆⲈ ⲀⲢⲈⲦⲈⲚⲚⲀⲨ ⲞⲨⲆⲈ ⲘⲠⲈⲦⲈⲚⲞⲨⲈⲘϨⲐⲎⲦⲈⲚ ⲈⲠϦⲀⲈ ⲈⲠϪⲒⲚⲚⲀϨϮ ⲈⲢⲞϤ.
33 “Ẹ gbọ́ òwe mìíràn, Baálé ilé kan tí ó gbin ọgbà àjàrà, ó ṣe ọgbà yìí ká, ó wá ibi ìfúntí sínú rẹ̀, ó kọ́ ilé ìṣọ́. Ó sì fi oko náà ṣe àgbàtọ́jú fún àwọn àgbẹ̀ kan, ó sì lọ sí ìrìnàjò.
ⲗ̅ⲅ̅ⲤⲰⲦⲈⲘ ⲈⲔⲈⲠⲀⲢⲀⲂⲞⲖⲎ ⲚⲈⲞⲨⲞⲚ ⲞⲨⲢⲰⲘⲒ ⲚⲚⲈⲂⲒⲞϨⲒ ⲈⲀϤϬⲞ ⲚⲞⲨⲒⲀϨⲀⲖⲞⲖⲒ ⲞⲨⲞϨ ⲀϤⲦⲀⲔⲦⲞ ⲚⲞⲨϪⲞⲒ ⲈⲢⲞϤ ⲞⲨⲞϨ ⲀϤϢⲰⲔ ⲚⲞⲨϨⲢⲰⲦ ⲚϦⲎⲦϤ ⲞⲨⲞϨ ⲀϤⲔⲰⲦ ⲚⲞⲨⲠⲨⲢⲄⲞⲤ ⲚϦⲎⲦϤ ⲞⲨⲞϨ ⲀϤⲦⲎⲒϤ ⲈⲦⲞⲦⲞⲨ ⲚϨⲀⲚⲞⲨⲒⲎ ⲞⲨⲞϨ ⲀϤϢⲈ ⲚⲀϤ ⲈⲠϢⲈⲘⲘⲞ.
34 Nígbà ti àkókò ìkórè súnmọ́, ó rán àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ sí àwọn àgbẹ̀ náà láti gba èyí ti ó jẹ tirẹ̀ wá.
ⲗ̅ⲇ̅ϨⲞⲦⲈ ⲆⲈ ⲈⲦⲀϤϦⲰⲚⲦ ⲚϪⲈⲠⲤⲎⲞⲨ ⲚⲦⲈⲚⲒⲞⲨⲦⲀϨ ⲀϤⲞⲨⲰⲢⲠ ⲚⲚⲈϤⲈⲂⲒⲀⲒⲔ ϨⲀ ⲚⲒⲞⲨⲒⲎ ⲈϬⲒ ⲚⲚⲈϤⲞⲨⲦⲀϨ.
35 “Ṣùgbọ́n àwọn alágbàtọ́jú sì mú àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀, wọn lu ẹni kìn-ín-ní, wọn pa èkejì, wọ́n si sọ ẹ̀kẹta ní òkúta.
ⲗ̅ⲉ̅ⲞⲨⲞϨ ⲀⲚⲒⲞⲨⲒⲎ ϬⲒ ⲚⲚⲈϤⲈⲂⲒⲀⲒⲔ ⲞⲨⲀⲒ ⲘⲈⲚ ⲀⲨϨⲒⲞⲨⲒ ⲈⲢⲞϤ ⲔⲈⲞⲨⲀⲒ ⲆⲈ ⲀⲨϦⲞⲐⲂⲈϤ ⲔⲈⲞⲨⲀⲒ ⲆⲈ ⲀⲨϨⲒⲰⲚⲒ ⲈⲢⲞϤ.
36 Ó sì tún rán àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ mìíràn àwọn tí ó ju ti ìṣáájú lọ. Wọ́n sì túnṣe bí ti àkọ́kọ́ sí àwọn wọ̀nyí pẹ̀lú.
ⲗ̅ⲋ̅ⲠⲀⲖⲒⲚ ⲞⲚ ⲀϤⲦⲀⲞⲨⲞ ⲚϨⲀⲚⲔⲈⲈⲂⲒⲀⲒⲔ ⲈⲨⲞϢ ⲈⲚⲒϨⲞⲨⲀϮ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲨⲒⲢⲒ ⲚⲰⲞⲨ ⲞⲚ ⲘⲠⲀⲒⲢⲎϮ.
37 Níkẹyìn, baálé ilé yìí rán ọmọ rẹ̀ pàápàá sí wọn. Ó wí pé, ‘Wọn yóò bu ọlá fún ọmọ mi.’
ⲗ̅ⲍ̅ⲈⲠϦⲀⲈ ⲆⲈ ⲀϤⲞⲨⲰⲢⲠ ⲘⲠⲈϤϢⲎⲢⲒ ϨⲀⲢⲰⲞⲨ ⲈϤϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ϪⲈ ⲤⲈⲚⲀϢⲪⲒⲦ ϦⲀⲦϨⲎ ⲘⲠⲀϢⲎⲢⲒ.
38 “Ṣùgbọ́n bí àwọn alágbàtọ́jú wọ̀nyí ti rí ọmọ náà lókèèrè, wọ́n wí fún ara wọn pé, ‘Èyí ni àrólé náà. Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a pa á, kí a sì jogún rẹ̀.’
ⲗ̅ⲏ̅ⲚⲒⲞⲨⲒⲎ ⲆⲈ ⲈⲦⲀⲨⲚⲀⲨ ⲈⲠⲒϢⲎⲢⲒ ⲠⲈϪⲰⲞⲨ ⲚϦⲢⲎⲒ ⲚϦⲎⲦⲞⲨ ϪⲈ ⲪⲀⲒ ⲠⲈ ⲠⲒⲔⲖⲎ ⲢⲞⲚⲞⲘⲞⲤ ⲀⲘⲰⲒⲚⲒ ⲚⲦⲈⲚϦⲞⲐⲂⲈϤ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲦⲈⲚϬⲒ ⲚⲦⲈϤⲔⲖⲎⲢⲞⲚⲞⲘⲒⲀ.
39 Wọ́n sì wọ́ ọ jáde kúrò nínú ọgbà àjàrà náà, wọ́n sì pa á.
ⲗ̅ⲑ̅ⲞⲨⲞϨ ⲀⲨϬⲒⲦϤ ⲀⲨϨⲒⲦϤ ⲤⲀⲂⲞⲖ ⲘⲠⲒⲒⲀϨⲀⲖⲞⲖⲒ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲨϦⲞⲐⲂⲈϤ.
40 “Ǹjẹ́ nígbà tí olúwa ọgbà àjàrà bá dé, kí ni yóò ṣe sí àwọn olùṣọ́gbà wọ̀n-ọn-nì?”
ⲙ̅ⲈϢⲰⲠ ⲀϤϢⲀⲚⲒ ⲚϪⲈⲠϬⲞⲒⲤ ⲘⲠⲒⲒⲀϨⲀⲖⲞⲖⲒ ⲞⲨ ⲠⲈⲦⲈϤⲚⲀⲀⲒϤ ⲚⲚⲒⲞⲨⲒⲎ ⲈⲦⲈⲘⲘⲀⲨ.
41 Wọ́n wí pé, “Òun yóò pa àwọn ènìyàn búburú náà run, yóò sì fi ọgbà àjàrà rẹ̀ fún àwọn alágbàtọ́jú mìíràn tí yóò fún un ní èso tirẹ̀ lásìkò ìkórè.”
ⲙ̅ⲁ̅ⲠⲈϪⲰⲞⲨ ⲚⲀϤ ϪⲈ ⲚⲒⲔⲀⲔⲰⲤ ⲈϤⲈⲦⲀⲔⲰⲞⲨ ⲚⲔⲀⲔⲰⲤ ⲞⲨⲞϨ ⲠⲒⲒⲀϨⲀⲖⲞⲖⲒ ⲈϤⲈⲦⲎⲒϤ ⲈⲦⲞⲦⲞⲨ ⲚϨⲀⲚⲔⲈⲞⲨⲒⲎ ⲚⲎ ⲈⲐⲚⲀϮ ⲚⲚⲈϤⲞⲨⲦⲀϨ ⲚⲀϤ ϦⲈⲚⲠⲞⲨⲤⲎⲞⲨ.
42 Jesu wí fún wọ́n pé, “Àbí ẹ̀yin kò kà á nínú Ìwé Mímọ́ pé: “‘Òkúta tí àwọn ọ̀mọ̀lé kọ̀sílẹ̀, ni ó di pàtàkì igun ilé; iṣẹ́ Olúwa ni èyí, ó sì jẹ́ ìyanu ní ojú wa’?
ⲙ̅ⲃ̅ⲞⲨⲞϨ ⲠⲈϪⲈ ⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲚⲰⲞⲨ ϪⲈ ⲘⲠⲈⲦⲈⲚⲰϢ ⲈⲚⲈϨ ϦⲈⲚⲚⲒⲄⲢⲀⲪⲎ ϪⲈ ⲠⲒⲰⲚⲒ ⲈⲦⲀⲨϢⲞϢϤ ⲚϪⲈⲚⲎ ⲈⲦⲔⲰⲦ ⲪⲀⲒ ⲀϤϢⲰⲠⲒ ⲚϪⲰϪ ⲚⲖⲀⲔϨ ⲈⲦⲀ ⲪⲀⲒ ϢⲰⲠⲒ ⲈⲂⲞⲖ ϨⲒⲦⲈⲚ ⲠϬⲞⲒⲤ ⲞⲨⲞϨ ϤⲞⲒ ⲚϢⲪⲎⲢⲒ ϦⲈⲚⲚⲈⲚⲂⲀⲖ.
43 “Nítorí náà èmi wí fún yín, a ó gba ìjọba Ọlọ́run lọ́wọ́ yín, a ó sì fi fún àwọn orílẹ̀-èdè tí yóò máa mú èso rẹ̀ wá.
ⲙ̅ⲅ̅ⲈⲐⲂⲈⲪⲀⲒ ϮϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ⲚⲰⲦⲈⲚ ϪⲈ ϮⲘⲈⲦⲞⲨⲢⲞ ⲚⲦⲈⲪⲚⲞⲨϮ ⲈⲨⲈⲞⲖⲤ ⲚⲦⲈⲚ ⲐⲎⲚⲞⲨ ⲞⲨⲞϨ ⲈⲨⲈⲦⲎⲒⲤ ⲚⲔⲈⲈⲐⲚⲞⲤ ⲪⲎ ⲈⲐⲚⲀⲒⲢⲒ ⲚⲚⲈⲤⲞⲨⲦⲀϨ.
44 Ẹni tí ó bá ṣubú lu òkúta yìí yóò di fífọ́, ṣùgbọ́n ẹni tí òun bá ṣubú lù yóò lọ̀ ọ́ lúúlúú.”
ⲙ̅ⲇ̅ⲞⲨⲞϨ ⲪⲎ ⲈⲐⲚⲀϨⲈⲒ ⲈϪⲈⲚ ⲠⲀⲒⲰⲚⲒ ⲈϤⲈⲖⲀⲤϤ ⲞⲨⲞϨ ⲪⲎ ⲆⲈ ⲈⲦⲈϤⲚⲀϨⲈⲒ ⲈϪⲰϤ ⲈϤⲈϢⲀϢϤ ⲈⲂⲞⲖ.
45 Nígbà tí àwọn olórí àlùfáà àti àwọn Farisi gbọ́ òwe Jesu, wọ́n mọ̀ wí pé ó ń sọ̀rọ̀ nípa àwọn.
ⲙ̅ⲉ̅ⲈⲦⲀⲨⲤⲰⲦⲈⲘ ⲆⲈ ⲚϪⲈⲚⲒⲀⲢⲬⲒⲈⲢⲈⲨⲤ ⲚⲈⲘ ⲚⲒⲪⲀⲢⲒⲤⲈⲞⲤ ⲈⲚⲈϤⲠⲀⲢⲀⲂⲞⲖⲎ ⲀⲨⲈⲘⲒ ϪⲈ ⲀϤϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ⲈⲐⲂⲎⲦⲞⲨ.
46 Wọn wá ọ̀nà láti mú un, ṣùgbọ́n wọn bẹ̀rù ọ̀pọ̀ ènìyàn tí wọ́n gba Jesu gẹ́gẹ́ bí wòlíì.
ⲙ̅ⲋ̅ⲞⲨⲞϨ ⲚⲀⲨⲔⲰϮ ⲈⲀⲘⲞⲚⲒ ⲘⲘⲞϤ ⲠⲈ ⲀⲨⲈⲢϨⲞϮ ϦⲀⲦϨⲎ ⲘⲠⲒⲘⲎϢ ϪⲈ ⲚⲀϤⲬⲎ ⲚⲦⲞⲦⲞⲨ ⲠⲈ ϨⲰⲤ ⲞⲨⲠⲢⲞⲪⲎⲦⲎⲤ.

< Matthew 21 >