< Matthew 13 >

1 Ní ọjọ́ kan náà, Jesu kúrò ní ilé, ó jókòó sí etí Òkun.
Isti dan je Jezus odšel iz hiše in se usedel ob morski obali.
2 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn péjọ sọ́dọ̀ rẹ̀, tó bẹ́ẹ̀ tí ó fi bọ́ sínú ọkọ̀ ojú omi, ó jókòó, gbogbo ènìyàn sì dúró létí Òkun.
In k njemu so bile zbrane skupaj velike množice, tako da je odšel na ladjo in se usedel, vsa množica pa je stala na bregu.
3 Nígbà náà ni ó fi ọ̀pọ̀lọpọ̀ òwe bá wọn sọ̀rọ̀, wí pé, “Àgbẹ̀ kan jáde lọ gbin irúgbìn sínú oko rẹ̀.
In v prispodobah jim je govoril mnoge besede, rekoč: »Glejte, sejalec je odšel sejat
4 Bí ó sì ti gbin irúgbìn náà, díẹ̀ bọ́ sí ẹ̀bá ọ̀nà, àwọn ẹyẹ sì wá, wọ́n sì jẹ ẹ́.
in ko je sejal, je nekaj semen padlo poleg poti in prišla je perjad ter jih požrla.
5 Díẹ̀ bọ́ sórí ilẹ̀ orí àpáta, níbi ti kò sí erùpẹ̀ púpọ̀. Àwọn irúgbìn náà sì dàgbàsókè kíákíá, nítorí erùpẹ̀ kò pọ̀ lórí wọn.
Nekaj jih je padlo na kamnita mesta, kjer niso imela veliko zemlje in so nemudoma pognala, ker niso imela globine zemlje
6 Ṣùgbọ́n nígbà tí oòrùn gòkè, oòrùn gbígbóná jó wọn, gbogbo wọn sì rọ, wọ́n kú nítorí wọn kò ni gbòǹgbò.
in ko je bilo sonce zgoraj, so bila ožgana in ker niso imela korenine, so ovenela.
7 Àwọn irúgbìn mìíràn bọ́ sí àárín ẹ̀gún, ẹ̀gún sì dàgbà, ó sì fún wọn pa.
In nekaj jih je padlo med trnje in trnje je pognalo ter jih zadušilo.
8 Ṣùgbọ́n díẹ̀ tó bọ́ sórí ilẹ̀ rere, ó sì so èso, òmíràn ọgọ́rùn-ún, òmíràn ọgọ́tọ̀ọ̀ta, òmíràn ọgbọọgbọ̀n, ni ìlọ́po èyí ti ó gbìn.
Toda druga so padla v dobro zemljo in obrodila sad, nekatera stoternega, nekatera šestdeseternega, nekatera trideseternega.
9 Ẹni tí ó bá létí, kí ó gbọ́.”
Kdor ima ušesa, da slišijo, naj posluša.«
10 Àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ tọ̀ ọ́ wá, wọ́n bí i pé, “Èéṣe tí ìwọ ń fi òwe bá àwọn ènìyàn sọ̀rọ̀?”
In prišli so učenci ter mu rekli: »Zakaj jim govoriš v prispodobah?«
11 Ó sì da wọn lóhùn pé, “Ẹ̀yin ni a ti fi fún láti mọ ohun ìjìnlẹ̀ ìjọba ọ̀run, ṣùgbọ́n kì í ṣe fún wọn.
Odgovoril je in jim rekel: »Ker je vam dano spoznati skrivnosti nebeškega kraljestva, toda njim to ni dano.
12 Ẹnikẹ́ni tí ó ní, òun ni a ó fún sí i, yóò sì ní lọ́pọ̀lọ́pọ̀. Ṣùgbọ́n lọ́wọ́ ẹni tí kò ní, ni a ó ti gbà èyí kékeré tí ó ní náà.
Kajti kdorkoli ima, njemu bo dano in imel bo večje obilje; toda kdorkoli nima, bo od njega vzeto proč celó to, kar ima.
13 Ìdí nìyìí tí mo fi ń fi òwe bá wọn sọ̀rọ̀: “Ní ti rí rí, wọn kò rí; ní ti gbígbọ́ wọn kò gbọ́, bẹ́ẹ̀ ni kò sì yé wọn.
Zatorej jim govorim v prispodobah, ker gledajo, a ne vidijo in poslušajo, a ne slišijo niti ne razumejo.
14 Sí ara wọn ni a ti mú àsọtẹ́lẹ̀ wòlíì Isaiah ṣẹ: “‘Ní gbígbọ́ ẹ̀yin yóò gbọ́ ṣùgbọ́n kì yóò sì yé yín; ní rí rí ẹ̀yin yóò rí, ṣùgbọ́n ẹ̀yin kì yóò sì mòye.
In v njih se je izpolnila Izaijeva prerokba, ki pravi: ›S poslušanjem boste slišali, pa ne boste razumeli; in gledali boste ter videli, pa ne boste zaznali;
15 Nítorí àyà àwọn ènìyàn yìí sébọ́ etí wọn sì wúwo láti gbọ́ ojú wọn ni wọ́n sì dì nítorí kí àwọn má ba à fi ojú wọn rí kí wọ́n má ba à fi etí wọn gbọ́ kí wọn má ba à fi àyà wọn mọ̀ òye, kí wọn má ba à yípadà, kí èmi ba à le mú wọn láradá.’
kajti srce teh ljudi je otopelo in njihova ušesa so naglušna in svoje oči so zaprli, da ne bi lahko kadarkoli s svojimi očmi videli in s svojimi ušesi slišali in bi s svojim srcem razumeli ter bi bili spreobrnjeni in bi jih jaz ozdravil.
16 Ṣùgbọ́n ìbùkún ni fún ojú yín, nítorí wọ́n ríran, àti fún etí yín, nítorí ti wọ́n gbọ́.
Toda blagoslovljene so vaše oči, ker vidijo, in vaša ušesa, ker slišijo.
17 Lóòótọ́ ni mo wí fún yín, ọ̀pọ̀ àwọn wòlíì àti ènìyàn Ọlọ́run ti fẹ́ rí ohun tí ẹ̀yin ti rí, ki wọ́n sì gbọ́ ohun tí ẹ ti gbọ́, ṣùgbọ́n kò ṣe é ṣe fún wọn.
Kajti resnično, povem vam: ›Da je veliko prerokov in pravičnih ljudi želelo videti te stvari, ki jih vi vidite, pa jih niso videli; in slišati te besede, ki jih vi slišite, pa jih niso slišali.‹
18 “Nítorí náà, ẹ fi etí sí ohun tí òwe afúnrúgbìn túmọ̀ sí,
Poslušajte torej prispodobo o sejalcu.
19 nígbà tí ẹnikẹ́ni bá gbọ́ ọ̀rọ̀ nípa ìjọba ọ̀run ṣùgbọ́n tí kò yé e, lẹ́yìn náà èṣù á wá, a sì gba èyí tí a fún sí ọkàn rẹ̀ kúrò. Èyí ni irúgbìn ti a fún sí ẹ̀bá ọ̀nà.
Kadar kdorkoli sliši besedo o kraljestvu, pa je ne razume, potem pride ta zlobni in izdere to, kar je bilo posejano v njegovo srce. To je tisti, ki je seme sprejel poleg poti.
20 Ẹni tí ó sì gba irúgbìn tí ó bọ́ sí ilẹ̀ orí àpáta, ni ẹni tí ó gbọ́ ọ̀rọ̀ náà, lọ́gán, ó sì fi ayọ̀ gba ọ̀rọ̀ náà.
Toda kdor je seme sprejel na kamnita mesta, je isti kakor kdor sliši besedo in jo takoj z radostjo sprejme,
21 Ṣùgbọ́n nítorí kò ní gbòǹgbò, ó wà fún ìgbà díẹ̀; nígbà tí wàhálà àti inúnibíni bá dìde nítorí ọ̀rọ̀ náà ní ojú kan náà yóò sì kọsẹ̀.
vendar v sebi nima korenine, toda nekaj časa vztraja. Ko pa zaradi besede nastane stiska ali preganjanje, on v kratkem greši.
22 Ẹni tí ó si gba irúgbìn tí ó bọ́ sí àárín ẹ̀gún ni ẹni tí ó gbọ́ ọ̀rọ̀ náà, ṣùgbọ́n àwọn àníyàn ayé yìí, ìtànjẹ, ọrọ̀ sì fún ọ̀rọ̀ náà pa, ọ̀rọ̀ náà kò so èso nínú rẹ̀. (aiōn g165)
Tudi tisti, ki je seme sprejel med trnje, je tisti, ki sliši besedo. Skrb tega sveta in zapeljivost bogastev pa zadušita besedo in on postaja brez sadu. (aiōn g165)
23 Ṣùgbọ́n ẹni tí ó gba irúgbìn tí ó bọ́ sí orí ilẹ̀ rere ni ẹni tí ó gbọ́ ọ̀rọ̀ náà, tí ó sì yé e; òun sì so èso òmíràn ọgọ́rọ̀ọ̀rùn, òmíràn ọgọ́tọ̀ọ̀ta, òmíràn ọgbọọgbọ̀n.”
Toda kdor je seme sprejel v dobro zemljo, je tisti, ki sliši besedo in jo razume, ki prav tako prinaša sad in obrodi, eden stoternega, drugi šestdeseternega, [spet] drugi trideseternega.«
24 Jesu tún pa òwe mìíràn fún wọn: “Ìjọba ọ̀run dàbí àgbẹ̀ kan tí ó gbin irúgbìn rere sí oko rẹ̀,
Podal jim je drugo prispodobo, rekoč: »Nebeško kraljestvo je podobno človeku, ki je na svojo njivo posejal dobro seme.
25 ṣùgbọ́n ní òru ọjọ́ kan, nígbà tí ó sùn, ọ̀tá rẹ̀ wá sí oko náà ó sì gbin èpò sáàrín alikama, ó sì bá tirẹ̀ lọ.
Toda medtem ko so ljudje spali, je prišel njegov sovražnik in med pšenico posejal plevel ter odšel svojo pot.
26 Nígbà tí alikama náà bẹ̀rẹ̀ sí dàgbà, tí ó sì so èso, nígbà náà ni èpò náà fi ara hàn.
Toda ko je bilka pognala in obrodila sad, potem se je prikazal tudi plevel.
27 “Àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ àgbẹ̀ náà wá, wọ́n sọ fún un pé, ‘Ọ̀gá, irúgbìn rere kọ́ ni ìwọ ha gbìn sí oko rẹ nì? Báwo ni èpò ṣe wà níbẹ̀ nígbà náà?’
Služabniki hišnega gospodarja so torej prišli in mu rekli: ›Gospod, ali nisi v svojo njivo posejal dobrega semena? Od kod ima potem le-ta plevel?‹
28 “Ó sọ fún wọn pé, ‘Ọ̀tá ni ó ṣe èyí.’ “Àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ tún bí i pé, ‘Ǹjẹ́ ìwọ ha fẹ́ kí a fa èpò náà tu kúrò?’
Rekel jim je: ›To je storil sovražnik.‹ Služabniki so mu rekli: ›Hočeš potem, da gremo in ga poberemo?‹
29 “Ó dá wọn lóhùn pé, ‘Rárá, nítorí bí ẹ̀yin bá ń tu èpò kúrò, ẹ ó tu alikama dànù pẹ̀lú rẹ̀.
Toda rekel je: ›Ne, da ne bi, medtem ko pobirate plevel, z njim izruvali tudi pšenice.
30 Ẹ jẹ́ kí àwọn méjèèjì máa dàgbà pọ̀, títí di àsìkò ìkórè. Èmi yóò sọ fún àwọn olùkórè náà láti kọ́kọ́ ṣa àwọn èpò kúrò kí wọ́n sì dìwọ́n ní ìtí, kí a sì sun wọn, kí wọ́n sì kó alikama sínú àká mi.’”
Naj oboje skupaj raste do žetve, in ob času žetve bom rekel žanjcem: ›Zberite skupaj najprej plevel in ga povežite v svežnje za sežig, toda pšenico zberite v moj skedenj.‹«
31 Jesu tún pa òwe mìíràn fún wọn: “Ìjọba ọ̀run dàbí èso hóró musitadi, èyí tí ọkùnrin kan mú tí ó gbìn sínú oko rẹ̀.
Podal jim je drugo prispodobo, rekoč: »Nebeško kraljestvo je podobno zrnu gorčičnega semena, ki ga je človek vzel in posejal na svoji njivi;
32 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ èso tí ó kéré púpọ̀ láàrín èso rẹ̀, síbẹ̀ ó wá di ohun ọ̀gbìn tí ó tóbi jọjọ. Ó sì wá di igi tó bẹ́ẹ̀ tí àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run sì wá, wọ́n sì fi ẹ̀ka rẹ ṣe ibùgbé.”
ki je zares najmanjše od vseh semen, toda ko to zraste, je največje med zelišči in postane drevo, tako da pridejo ptice neba in prenočujejo na njegovih vejah.«
33 Ó tún pa òwe mìíràn fún wọn: “Ìjọba ọ̀run dàbí ìwúkàrà tí obìnrin kan mú tí ó pò mọ́ ìyẹ̀fun púpọ̀ títí tí gbogbo rẹ fi di wíwú.”
Povedal jim je drugo prispodobo: »Nebeško kraljestvo je podobno kvasu, ki ga je ženska vzela in skrila v treh merah moke, dokler ni bilo vse prekvašeno.«
34 Òwe ni Jesu fi sọ nǹkan wọ̀nyí fún àwọn ènìyàn, òwe ni ó fi bá wọn sọ gbogbo ọ̀rọ̀ tó sọ.
Vse te besede je Jezus množici govoril v prispodobah; brez prispodobe pa jim ni govoril,
35 Kí ọ̀rọ̀ tí a ti ẹnu àwọn wòlíì sọ lé wá sí ìmúṣẹ pé: “Èmi yóò ya ẹnu mi láti fi òwe sọ̀rọ̀. Èmi yóò sọ àwọn ohun tí ó fi ara sin láti ìpilẹ̀ṣẹ̀ ayé wá.”
da bi se lahko izpolnilo, kar je bilo rečeno po preroku, rekoč: »Svoja usta bom odprl v prispodobah, izrekel bom besede, ki so bile od ustanovitve sveta hranjene na skrivnem.«
36 Lẹ́yìn náà ó sì fi ọ̀pọ̀ ènìyàn sílẹ̀ lóde, ó wọ ilé lọ. Àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ tọ̀ ọ́ wá, wọn wí pé, “Ṣàlàyé òwe èpò inú oko fún wa.”
Tedaj je Jezus množico poslal proč in odšel v hišo, in njegovi učenci so prišli k njemu, rekoč: »Pojasni nam prispodobo o poljskem plevelu.«
37 Ó sì dá wọn lóhùn pé, “Ọmọ Ènìyàn ni ẹni tí ó ń fúnrúgbìn rere.
Odgovoril je in jim rekel: »Kdor seje dobro seme, je Sin človekov.
38 Ayé ni oko náà; irúgbìn rere ni àwọn ènìyàn ti ìjọba ọ̀run. Èpò ni àwọn ènìyàn tí wọ́n jẹ́ ti èṣù,
Njiva je svet. Dobro seme so otroci kraljestva, toda plevel so otroci zlobnega.
39 ọ̀tá tí ó gbin àwọn èpò sáàrín alikama ni èṣù. Ìkórè ni òpin ayé, àwọn olùkórè sì ní àwọn angẹli. (aiōn g165)
Sovražnik, ki jih je posejal, je hudič. Žetev je konec sveta, žanjci pa so angeli. (aiōn g165)
40 “Gẹ́gẹ́ bí a ti kó èpò jọ, tí a sì sun ún nínú iná, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni yóò rí ní ìgbẹ̀yìn ayé. (aiōn g165)
Kakor je torej plevel pobran in v ognju sežgan, tako bo ob koncu tega sveta. (aiōn g165)
41 Ọmọ Ènìyàn yóò ran àwọn angẹli rẹ̀, wọn yóò sì kó gbogbo ohun tó ń mú ni dẹ́ṣẹ̀ kúrò ní ìjọba rẹ̀ àti gbogbo ènìyàn búburú.
Sin človekov bo poslal svoje angele in iz njegovega kraljestva bodo pobrali vse stvari, ki so padle v greh in tiste, ki počno krivičnost;
42 Wọn yóò sì sọ wọ́n sí inú iná ìléru, níbi ti ẹkún òun ìpayínkeke yóò gbé wà.
in vrgli jih bodo v ognjeno talilno peč. Tam bo tarnanje in škripanje z zobmi.
43 Nígbà náà ni àwọn olódodo yóò máa ràn bí oòrùn ní ìjọba Baba wọn. Ẹni tí ó bá létí, jẹ́ kí ó gbọ́.
Potem bodo pravični zasijali kakor sonce v kraljestvu svojega Očeta. Kdor ima ušesa, da slišijo, naj posluša.
44 “Ìjọba ọ̀run sì dàbí ìṣúra kan tí a fi pamọ́ sínú oko. Nígbà tí ọkùnrin kan rí i ó tún fi í pamọ́. Nítorí ayọ̀ rẹ̀, ó ta gbogbo ohun ìní rẹ̀, ó ra oko náà.
Ponovno, nebeško kraljestvo je podobno zakladu, skritemu na njivi. Ko ga je človek našel, ga skrije in zaradi radosti gre in proda vse, kar ima in to polje kupi.
45 “Bákan náà ni ìjọba ọ̀run dàbí oníṣòwò kan tí ó ń wá òkúta olówó iyebíye láti rà.
Ponovno, nebeško kraljestvo je podobno trgovcu, ki išče lepe bisere,
46 Nígbà tí ó rí ọ̀kan tí ó ni iye lórí, ó lọ láti ta gbogbo ohun ìní rẹ̀ láti le rà á.
ki je, ko je našel en biser velike vrednosti, šel in prodal vse, kar je imel ter ga kupil.
47 “Bákan náà, a sì tún lè fi ìjọba ọ̀run wé àwọ̀n kan tí a jù sínú odò, ó sì kó onírúurú ẹja.
Ponovno, nebeško kraljestvo je podobno mreži, ki je bila vržena v morje in je zajela od vseh vrst,
48 Nígbà tí àwọ̀n náà sì kún, àwọn apẹja fà á sókè sí etí bèbè Òkun, wọ́n jókòó, wọ́n sì ṣa àwọn èyí tí ó dára sínú apẹ̀rẹ̀, ṣùgbọ́n wọ́n da àwọn tí kò dára nù.
ki so jo, ko je bila polna, odvlekli do obale in se usedli ter dobre zbrali v posode, toda slabe so vrgli proč.
49 Bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni yóò rí ní ìgbẹ̀yìn ayé. Àwọn angẹli yóò wá láti ya àwọn ènìyàn búburú kúrò lára àwọn olódodo. (aiōn g165)
Tako bo torej ob koncu sveta. Prišli bodo angeli in zlobne bodo oddvojili od pravičnih, (aiōn g165)
50 Wọn ó sì ju àwọn ènìyàn búburú sínú iná ìléru náà, ní ibi ti ẹkún àti ìpayínkeke yóò gbé wà.”
in jih vrgli v ognjeno talilno peč. Tam bo tarnanje in škripanje z zobmi.«
51 Jesu bí wọn léèrè pé, “Ǹjẹ́ gbogbo nǹkan wọ̀nyí yé yín.” Wọ́n dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, ó yé wa.”
Jezus jim reče: »Ste razumeli vse te besede?« Rečejo mu: »Da, Gospod.«
52 Ó wí fún wọn pé, “Nítorí náà ni olúkúlùkù olùkọ́ òfin tí ó ti di ọmọ-ẹ̀yìn ní ìjọba ọ̀run ṣe dàbí ọkùnrin kan tí í ṣe baálé ilé, tí ó mú ìṣúra tuntun àti èyí tí ó ti gbó jáde láti inú yàrá ìṣúra rẹ̀.”
Tedaj jim je rekel: »Zato je vsak pisar, ki je poučen o nebeškem kraljestvu, podoben človeku, ki je hišni gospodar, ki prinaša iz svojega zaklada nove in stare stvari.«
53 Lẹ́yìn ti Jesu ti parí òwe wọ̀nyí, ó ti ibẹ̀ kúrò.
In pripetilo se je, ko je Jezus zaključil te prispodobe, da je odšel od tam.
54 Ó wá sí ìlú òun tìkára rẹ̀, níbẹ̀ ni ó ti ń kọ́ àwọn ènìyàn nínú Sinagọgu, ẹnu sì yà wọ́n. Wọ́n béèrè pé, “Níbo ni ọkùnrin yìí ti mú ọgbọ́n yìí àti iṣẹ́ ìyanu wọ̀nyí wá?
In ko je prišel v svojo lastno deželo, jih je v njihovi sinagogi učil, do take mere, da so bili osupli in govorili: »Od kod ima ta človek to modrost in ta mogočna dela?
55 Kì í ha ṣe ọmọ gbẹ́nàgbẹ́nà ni èyí bí? Ìyá rẹ̀ ha kọ́ ni à ń pè ní Maria bí? Arákùnrin rẹ̀ ha kọ́ ni Jakọbu, Josẹfu, Simoni àti Judasi bí?
Ali ni to tesarjev sin? Ali ni njegova mati imenovana Marija? In njegovi bratje Jakob in Jožef in Simon in Juda?
56 Àwọn arábìnrin rẹ̀ gbogbo ha kọ́ ni ó ń bá wa gbé níhìn-ín yìí, nígbà náà níbo ni ọkùnrin yìí ti rí àwọn nǹkan wọ̀nyí?”
In njegove sestre ali niso vse z nami? Od kod ima potem ta človek vse te stvari?«
57 Inú bí wọn sí i. Ṣùgbọ́n Jesu wí fún wọn pé, “Wòlíì a máa lọ́lá ní ibòmíràn, àfi ní ilé ara rẹ̀ àti ní ìlú ara rẹ̀ nìkan ni wòlíì kò ti lọ́lá.”
In pohujševali so se nad njim. Toda Jezus jim je rekel: »Prerok ni brez spoštovanja, razen v svoji lastni deželi in v svoji lastni hiši.«
58 Nítorí náà kò ṣe iṣẹ́ ìyanu kankan níbẹ̀, nítorí àìnígbàgbọ́ wọn.
In tam zaradi njihove nevere ni storil veliko mogočnih del.

< Matthew 13 >