< Matthew 11 >

1 Lẹ́yìn ìgbà tí Jesu sì ti parí ọ̀rọ̀ tí ó ń sọ fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ méjìlá, ó ti ibẹ̀ rékọjá láti máa kọ́ni àti láti máa wàásù ní àwọn ìlú Galili gbogbo.
AND it was that when Jeshu had finished instructing his twelve disciples, he removed from thence to teach and preach in their cities.
2 Nígbà tí Johanu gbọ́ ohun tí Kristi ṣe nínú ẹ̀wọ̀n, ó rán àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀
But Juchanon, when he heard in the house of the bound the works of the Meshicha, sent by his disciples,
3 láti béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Ṣe ìwọ ni ẹni tó ń bọ̀ wá tàbí kí a máa retí ẹlòmíràn?”
and said to him, Art thou He that cometh, or another are we to expect?
4 Jesu dáhùn ó wí pé, “Ẹ padà lọ, ẹ sì sọ fún Johanu ohun tí ẹ̀yin gbọ́, àti èyí tí ẹ̀yin rí.
Jeshu answered and said to them, Go, recount to Juchanon these things which you hear and see;
5 Àwọn afọ́jú ń ríran, àwọn amúnkùn ún rìn, a ń wẹ àwọn adẹ́tẹ̀ mọ́ kúrò nínú ẹ̀tẹ̀ wọn, àwọn adití ń gbọ́rọ̀, a ń jí àwọn òkú dìde, a sì ń wàásù ìyìnrere fún àwọn òtòṣì.
(that) the blind see, the lame are walking, the lepers are made clean, the deaf hear, the dead arise, and the poor are evangelized;
6 Alábùkún fún ni ẹni tí kò rí ohun ìkọ̀sẹ̀ nípa mi.”
and blessed is he who shall not be offended with me.
7 Nígbà tí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn Johanu ti lọ tán, Jesu bẹ̀rẹ̀ sí í sọ fún ọ̀pọ̀ ènìyàn nípa ti Johanu: “Kí ni ẹ̀yin jáde lọ wò ní aginjù? Ewéko tí afẹ́fẹ́ ń mi?
But when they were gone, Jeshu began to speak to the assembly concerning Juchanon: What went you forth into the waste to see? a reed that by the wind was shaken?
8 Bí kò bá ṣe bẹ́ẹ̀, kí ni ẹ̀yin lọ òde lọ í wò? Ọkùnrin tí a wọ̀ ni aṣọ dáradára? Rárá àwọn ti ó wọ aṣọ dáradára wà ní ààfin ọba.
And if not, what went you forth to see? a man clothed in soft vestments? Behold, they who are softly clothed are in the house of kings.
9 Àní kí ní ẹ jáde láti lọ wò? Wòlíì? Bẹ́ẹ̀ ni, mo wí fún yín, ó sì ju wòlíì lọ.”
And if not, what went you forth to see? a prophet? I tell you, Yes; and more than a prophet.
10 Èyí ni ẹni tí a ti kọ̀wé rẹ̀ pé: “‘Èmi yóò rán ìránṣẹ́ mi síwájú rẹ, ẹni tí yóò tún ọ̀nà rẹ ṣe níwájú rẹ.’
For this is he concerning whom it is written, Behold, I send my angel before thy face, to prepare the way before thee.
11 Lóòótọ́ ni mó wí fún yín, nínú àwọn tí a bí nínú obìnrin, kò sí ẹni tí ó tí í dìde tí ó ga ju Johanu onítẹ̀bọmi lọ, síbẹ̀ ẹni tí ó kéré jù ní ìjọba ọ̀run ni ó pọ̀jù ú lọ.
Amen I say to you, there hath not arisen among them born of women who greater than Juchanon the Baptizer: yet, the least in the kingdom of heaven is greater than he.
12 Láti ìgbà ọjọ́ Johanu onítẹ̀bọmi títí di àkókò yìí ni ìjọba ọ̀run ti di à fi agbára wọ̀, àwọn alágbára ló ń fi ipá gbà á.
But from the days of Juchanon the Baptizer until now, the kingdom of the heavens by violence is taken, and the violent ones seize it.
13 Nítorí náà gbogbo òfin àti wòlíì ni ó sọtẹ́lẹ̀ kí Johanu kí ó tó dé.
For all the prophets and the law prophesied until Juchanon;
14 Bí ẹ̀yin yóò bá gbà á, èyí ni Elijah tó ń bọ̀ wá.
and if you are willing, receive, that he is Elia who was to come.
15 Ẹni tí ó bá ní etí, kí ó gbọ́.
Whoever hath ears to hear, he shall hear.
16 “Kí ni èmi ìbá fi ìran yìí wé? Ó dàbí àwọn ọmọ kékeré tí ń jókòó ní ọjà tí wọ́n sì ń ké pe àwọn ẹlẹgbẹ́ wọn:
BUT to what shall I compare this generation? It is like children who sit in the public place, and cry to their companions,
17 “‘Àwa ń fun fèrè fún yín, ẹ̀yin kò jó; àwa kọrin ọ̀fọ̀ ẹ̀yin kò káàánú.’
and say, We have sung to you, and you have not danced; we have wailed unto you, and you have not mourned.
18 Nítorí Johanu wá kò bá a yín jẹ bẹ́ẹ̀ ni kò mu, ẹ̀yin sì wí pé, ‘Ó ní ẹ̀mí èṣù.’
For Juchanon came neither eating nor drinking, and they say, He hath a devil.
19 Ọmọ Ènìyàn wá bá a yín jẹun, ó sì bá yin mu, wọ́n wí pé, ‘Ọ̀jẹun àti ọ̀mùtí; ọ̀rẹ́ àwọn agbowó òde àti àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀.’ Ṣùgbọ́n a dá ọgbọ́n láre nípa ìṣe rẹ̀.”
The Son of man came eating and drinking, and they say, See a man a devourer, a wine-drinker, a friend of tribute-takers and of sinners. But justified is wisdom by her servants.
20 Nígbà náà ni Jesu bẹ̀rẹ̀ sí í bá ìlú tí ó ti ṣe ọ̀pọ̀ iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ wí, nítorí wọn kò ronúpìwàdà.
Then began Jeshu to reproach those cities in which were done many of his miracles, and which did not repent,
21 Ó wí pé, “Ègbé ni fún ìwọ Korasini, ègbé ni fún ìwọ Betisaida! Ìbá ṣe pé a ti ṣe àwọn iṣẹ́ ìyanu tí a ṣe nínú yín ní a ṣe ni Tire àti Sidoni, àwọn ènìyàn wọn ìbá ti ronúpìwàdà ti pẹ́ nínú aṣọ ọ̀fọ̀ àti eérú.
saying, Woe to thee, Korazin! woe to thee, Bethtsaida! for if in Tsur and in Tsaidon those miracles had been done which have been performed in you, they would a while ago in sackcloth and ashes have repented.
22 Ṣùgbọ́n mo wí fún yín, yóò sàn fún Tire àti Sidoni ní ọjọ́ ìdájọ́ jù fún yín.
But I say to you, that for Tsur and Tsaidon it shall be more tolerable in the day of judgment than for you.
23 Àti ìwọ Kapernaumu, a ó ha gbé ọ ga sókè ọ̀run? Rárá, a ó rẹ̀ ọ́ sílẹ̀ sí ipò òkú. Nítorí, ìbá ṣe pé a ti ṣe iṣẹ́ ìyanu tí a ṣe nínú rẹ ní Sodomu, òun ìbá wà títí di òní. (Hadēs g86)
And thou, Kaphernachum, who unto heaven art exalted, unto Shiul shalt be brought down; for if in Sadum had been done those miracles which have been done in thee, it would have stood until this day. (Hadēs g86)
24 Lóòótọ́ yóò sàn fún ilẹ̀ Sodomu ní ọjọ́ ìdájọ́ jù fún ìwọ lọ.”
But I tell you that for the land of Sadum it shall be more tolerable in the day of judgment than for thee.
25 Nígbà náà ni Jesu wí pé, “Mo yìn ọ Baba, Olúwa ọ̀run àti ayé, nítorí ìwọ ti fi òtítọ́ yìí pamọ́ fún àwọn tó jẹ́ ọlọ́gbọ́n àti amòye, Ìwọ sì ti fi wọ́n hàn fún àwọn ọmọ wẹ́wẹ́.
IN that time Jeshu answered and said, I praise thee, my Father, the Lord of the heavens and of the earth, that thou hast concealed these (things) from the wise and prudent, but hast revealed them unto little children.
26 Bẹ́ẹ̀ ni, Baba, nítorí ó wù ọ́ láti ṣe bẹ́ẹ̀.
Yes, my Father, for thus was it pleasing before thee!
27 “Ohun gbogbo ni Baba mi ti fi sí ìkáwọ́ mi. Kò sí ẹni tí ó mọ ọmọ bí kò ṣe Baba, bẹ́ẹ̀ ni kò sí ẹnikẹ́ni tí ó mọ Baba, bí kò ṣe ọmọ, àti àwọn tí ọmọ yan láti fi ara hàn fún.
All things are delivered to me from my Father; and no man knoweth the Son but the Father; also the Father no man knoweth, except the Son, and he (to) whom the Son pleaseth to reveal (him).
28 “Ẹ wá sọ́dọ̀ mi gbogbo ẹ̀yin tí ń ṣiṣẹ́ tí a sì di ẹrù wíwúwo lé lórí, èmi yóò sì fún yín ní ìsinmi.
Come unto me, all you (who) are wearied and bearing burdens, and I will give you rest.
29 Ẹ gbé àjàgà mi wọ̀. Ẹ kọ́ ẹ̀kọ́ lọ́dọ̀ mi nítorí onínútútù àti onírẹ̀lẹ̀ ọkàn ni èmi, ẹ̀yin yóò sì ri ìsinmi fún ọkàn yín.
Bear my yoke upon you, and learn of me; for I am peaceful and lowly in my heart, and you shall find repose for your souls.
30 Nítorí àjàgà mi rọrùn ẹrù mi sì fúyẹ́.”
For my yoke is kindly, and my burden is light.

< Matthew 11 >