< Malachi 3 >

1 “Wò ó, Èmi yóò ran ìránṣẹ́ mi, yóò tún ọ̀nà ṣe ṣáájú mi. Nígbà náà ni Olúwa, tí ẹ̀yin ń wa, yóò dé ni òjijì sí tẹmpili rẹ̀; àní oníṣẹ́ májẹ̀mú náà, tí inú yín dùn sí, yóò dé,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
Oto posyłam mego posłańca, który przygotuje drogę przed moim obliczem. I nagle przybędzie do swojej świątyni Pan, którego wy szukacie, Posłaniec przymierza, którego wy pragniecie. Oto przyjdzie, mówi PAN zastępów.
2 Ṣùgbọ́n ta ni o lè fi ara da ọjọ́ dídé rẹ̀? Ta ni yóò sì dúró nígbà tí ó bá fi ara hàn? Nítorí òun yóò dàbí iná ẹni tí ń da fàdákà àti bi ọṣẹ alágbàfọ̀.
Lecz któż będzie mógł znieść dzień jego przyjścia? I kto się ostanie, gdy on się ukaże? [Jest] bowiem jak ogień złotnika i jak mydło foluszników.
3 Òun yóò sì jókòó bí ẹni tí n yọ́, tí ó sì ń da fàdákà; yóò wẹ àwọn ọmọ Lefi mọ́, yóò sì tún wọn dàbí wúrà àti fàdákà, kí wọn bá a lè mú ọrẹ òdodo wá fún Olúwa,
I zasiądzie jako ten, kto roztapia i oczyszcza srebro: oczyści synów Lewiego, oczyści ich jak złoto i srebro i będą składać PANU ofiarę w sprawiedliwości.
4 nígbà náà ni ọrẹ Juda àti ti Jerusalẹmu yóò jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà fún Olúwa, gẹ́gẹ́ bí ti ọjọ́ àtijọ́, àti gẹ́gẹ́ bí ọdún ìgbàanì.
Wtedy ofiara Judy i Jerozolimy będzie miła PANU, jak za dawnych dni i jak za lat minionych.
5 “Èmi ó sì súnmọ́ yin fún ìdájọ́. Èmi yóò sì yára ṣe ẹlẹ́rìí sí àwọn oṣó, sí àwọn panṣágà, sí àwọn abúra èké, àti àwọn tí ó fi ọ̀yà alágbàṣe pọn wọn lójú, àti àwọn tí ó ni àwọn opó àti àwọn aláìní baba lára, àti sí ẹni tí kò jẹ́ kí àjèjì rí ìdájọ́ òdodo gbà, tí wọn kò sì bẹ̀rù mi,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
I zbliżę się do was na sąd, i będę rychłym świadkiem przeciwko czarownikom, przeciwko cudzołożnikom, przeciwko krzywoprzysięzcom, przeciwko tym, którzy uciskają najemników przy ich zapłatach oraz wdowy i sieroty i krzywdzą cudzoziemca, a nie boją się mnie, mówi PAN zastępów.
6 “Èmi Olúwa kò yípadà. Nítorí náà ni a kò ṣe run ẹ̀yin ọmọ Jakọbu.
Gdyż ja, PAN, nie zmieniam się, dlatego wy, synowie Jakuba, nie zostaliście zniszczeni.
7 Láti ọjọ́ àwọn baba ńlá yín wá ni ẹ̀yin tilẹ̀ ti kọ ẹ̀yìn sí ìlànà mi, tí ẹ kò sì pa wọ́n mọ́. Ẹ padà wá sí ọ̀dọ̀ mi, Èmi yóò sì padà sí ọ̀dọ̀ yín,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí. “Ṣùgbọ́n ẹ̀yin béèrè pé, ‘Báwo ni àwa yóò ṣe padà?’
Od dni waszych ojców odstępowaliście od moich ustaw i nie przestrzegaliście [ich]. Zawróćcie do mnie, a ja zawrócę do was, mówi PAN zastępów. Ale wy mówicie: Pod jakim względem mamy zawrócić?
8 “Ènìyàn yóò ha ja Ọlọ́run ni olè bí? Síbẹ̀ ẹ̀yin ti jà mí ní olè. “Ṣùgbọ́n ẹ̀yin béèrè pé, ‘Báwo ni àwa ṣe jà ọ́ ní olè?’ “Nípa ìdámẹ́wàá àti ọrẹ.
Czy człowiek okradnie Boga? Wy jednak mnie okradacie. Lecz mówicie: Z czego cię okradamy? Z dziesięcin i ofiar.
9 Ríré ni a ó fi yín ré: gbogbo orílẹ̀-èdè yìí, nítorí ẹ̀yin ti jà mi lólè.
Jesteście zupełnie przeklęci, ponieważ mnie okradacie, wy [i] cały wasz naród.
10 Ẹ mú gbogbo ìdámẹ́wàá wá sí ilé ìṣúra, kí oúnjẹ bá à lè wà ní ilé mi, ẹ fi èyí dán mi wò,” ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “kí ẹ sì wò bí èmi kò bá ní sí àwọn fèrèsé ọ̀run fún yin, kí èmi sì tú ìbùkún àkúnwọ́sílẹ̀ jáde fún yín, tó bẹ́ẹ̀ tí kì yóò sì ààyè láti gbà á.
Przynieście całą dziesięcinę do spichlerza, aby żywność była w moim domu, a doświadczcie mnie teraz w tym, mówi PAN zastępów, czy wam nie otworzę okien niebios i nie wyleję na was błogosławieństwa, tak że nie będziecie mieli gdzie go podziać;
11 Èmi yóò sì bá kòkòrò ajẹnirun wí nítorí yín, òun kò sì ni run èso ilẹ̀ yín, bẹ́ẹ̀ ni àjàrà inú oko yín kò ní rẹ̀ dànù,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
I zgromię ze względu na was tego, który pożera, a nie popsuje wam plonu ziemi i winorośl nie będzie pozbawiona owocu na polu, mówi PAN zastępów.
12 “Nígbà náà ni gbogbo orílẹ̀-èdè yóò sì pè yín ni alábùkún fún, nítorí tiyín yóò jẹ́ ilẹ̀ tí ó wu ni,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
I wszystkie narody będą was nazywać błogosławionymi, bo będziecie ziemią rozkoszną, mówi PAN zastępów.
13 “Ẹ̀yin ti sọ ọ̀rọ̀ líle sí mi,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí. “Síbẹ̀ ẹ̀yin béèrè pé, ‘Ọ̀rọ̀ kín ni àwa sọ sí ọ?’
Zuchwałe są wasze słowa przeciwko mnie, mówi PAN. Wy jednak mówicie: Cóż powiedzieliśmy przeciwko tobie?
14 “Ẹ̀yin ti wí pé, ‘Asán ni láti sin Ọlọ́run. Kí ni àwa jẹ ní èrè, nígbà tí àwa ti pa ìlànà rẹ mọ́, tí àwa sì ń rìn kiri bí ẹni tí ń ṣọ̀fọ̀ ní iwájú Olúwa àwọn ọmọ-ogun?
Mówiliście: Na próżno służyć Bogu. Co za pożytek z tego, że przestrzegaliśmy jego przykazań i chodziliśmy smutni przed PANEM zastępów?
15 Ṣùgbọ́n ní ìsinsin yìí àwa pé agbéraga ni alábùkún fún. Ní òtítọ́ ni àwọn ti ń ṣe búburú ń gbèrú sí i, kódà àwọn ti ó dán Ọlọ́run wò ni a dá sí.’”
A teraz pysznych mamy za błogosławionych, ponieważ ci się budują, którzy czynią niegodziwość, a ci, którzy kuszą Boga, są wybawieni.
16 Nígbà náà ni àwọn tí ó bẹ̀rù Olúwa ń ba ara wọn sọ̀rọ̀, Olúwa sì tẹ́tí sí i, ó sì gbọ́. A sì kọ ìwé ìrántí kan níwájú rẹ̀, fún àwọn tí o bẹ̀rù Olúwa, tiwọn sì bọ̀wọ̀ fún orúkọ rẹ̀.
Wtedy rozmawiali [o tym] między sobą ci, którzy się bali PANA. PAN zobaczył [to] i usłyszał, i napisano księgę wspomnień przed nim [z powodu] tych, którzy się boją PANA i rozmyślają o jego imieniu.
17 “Wọn yóò sì jẹ́ tèmi,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “ni ọjọ́ náà, tí èmi ó dá; èmi yóò sì da wọ́n sí gẹ́gẹ́ bí ènìyàn tí máa ń dá ọmọ rẹ̀ tí yóò sìn ín sí.
Oni będą moimi, mówi PAN zastępów, w dniu, kiedy uczynię ich moją własnością. Zlituję się nad nimi, jak się lituje ojciec nad swoim synem, który mu służy.
18 Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò rí ìyàtọ̀, ìyàtọ̀ láàrín olódodo àti ẹni búburú, láàrín ẹni tí ń sìn Ọlọ́run, àti ẹni tí kò sìn ín.
Wtedy zawrócicie i zobaczycie różnicę między sprawiedliwym i bezbożnym, między tym, który służy Bogu, [i] tym, który mu nie służy.

< Malachi 3 >