< Luke 8 >

1 Ó sì ṣe lẹ́yìn náà, tí ó ń lá gbogbo ìlú àti ìletò kọjá lọ, ó ń wàásù, ó ń ròyìn ayọ̀ ìjọba Ọlọ́run. Àwọn méjìlá sì ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ̀,
ⲁ̅ⲁⲥϣⲱⲡⲉ ⲇⲉ ⲙⲛ̅ⲛ̅ⲥⲱⲥ ⲛ̅ⲧⲟϥ ⲇⲉ ⲛⲉϥⲙⲟⲟϣⲉ ⲕⲁⲧⲁⲡⲟⲗⲉⲓⲥ ⲁⲩⲱ ⲕⲁⲧⲁϯⲙⲉ ⲉϥⲕⲏⲣⲩⲥⲥⲉ ⲉϥⲉⲩⲁⲅⲅⲉⲗⲓⲍⲉ ⲛ̅ⲧⲙⲛ̅ⲧⲉⲣⲟ ⲙ̅ⲡⲛⲟⲩⲧⲉ ⲉⲣⲉⲡⲙⲛ̅ⲧⲥ̅ⲛⲟⲟⲩⲥ ⲛⲙ̅ⲙⲁϥ
2 àti àwọn obìnrin kan, tí a ti mú láradá kúrò lọ́wọ́ àwọn ẹ̀mí búburú àti nínú àìlera wọn, Maria tí a ń pè ní Magdalene, lára ẹni tí ẹ̀mí èṣù méje ti jáde kúrò.
ⲃ̅ⲛⲙ̅ϩⲉⲛⲕⲉϩⲓⲟⲙⲉ ⲛⲁⲓ̈ ⲉⲛⲧⲁϥⲧⲁⲗϭⲟⲟⲩ ϩⲛ̅ⲛⲉⲩⲡⲛ̅ⲁ ⲙⲡⲟⲛⲏⲣⲟⲛ ⲛⲙ̅ⲛⲉⲩϣⲱⲛⲉ. ⲙⲁⲣⲓⲁ ⲧⲉϣⲁⲩⲙⲟⲩⲧⲉ ⲉⲣⲟⲥ ϫⲉ ⲙⲁⲅⲇⲁⲗⲏⲛⲏ ⲧⲁⲓ̈ ⲉⲛⲧⲁⲥⲁϣϥ̅ ⲛ̅ⲇⲁⲓⲙⲟⲛⲓⲟⲛ ⲉ͡ⲓ ⲉⲃⲟⲗ ⲛ̅ϩⲏⲧⲥ̅
3 Àti Joanna aya Kusa tí í ṣe ìríjú Herodu, àti Susana, àti àwọn púpọ̀ mìíràn, tí wọ́n ń ṣe ìránṣẹ́ fún un nínú ohun ìní wọn.
ⲅ̅ⲛⲙ̅ⲓ̈ⲱϩⲁⲛⲛⲁ ⲑⲓⲙⲉ ⲛ̅ⲭⲟⲩⲍⲁ ⲡⲉⲡⲓⲧⲣⲟⲡⲟⲥ ⲛϩⲏⲣⲱⲇⲏⲥ ⲛⲙ̅ⲥⲟⲩⲥⲁⲛⲛⲁ ⲁⲩⲱ ϩⲉⲛⲕⲟⲟⲩⲉ ⲉⲛⲁϣⲱⲟⲩ ⲛⲁⲓ̈ ⲉⲛⲉⲩⲇⲓⲁⲕⲟⲛⲉⲓ ⲛⲁϥ ⲉⲃⲟⲗ ϩⲛⲛⲉⲩϩⲩⲡⲁⲣⲭⲟⲛⲧⲁ.
4 Nígbà tí ọ̀pọ̀ ìjọ ènìyàn péjọpọ̀, àwọn ènìyàn láti ìlú gbogbo sì tọ̀ ọ́ wá, ó fi òwe bá wọn sọ̀rọ̀ pé,
ⲇ̅ⲉⲣⲉⲟⲩⲙⲏⲏϣⲉ ⲇⲉ ⲥⲱⲟⲩϩ ⲉⲛⲁϣⲱϥ. ⲛⲙ̅ⲛⲉⲧⲛⲏⲟⲩ ϣⲁⲣⲟϥ ⲕⲁⲧⲁⲡⲟⲗⲉⲓⲥ ⲡⲉϫⲁϥ ⲛⲁⲩ ϩⲓⲧⲛⲟⲩⲡⲁⲣⲁⲃⲟⲗⲏ
5 “Afúnrúgbìn kan jáde lọ láti fún irúgbìn rẹ̀: bí ó sì ti ń fúnrúgbìn, díẹ̀ bọ́ sí ẹ̀bá ọ̀nà, a sì tẹ̀ ẹ́ mọ́lẹ̀, àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run sì ṣà á jẹ.
ⲉ̅ϫⲉ ⲁϥⲉ͡ⲓ ⲉⲃⲟⲗ ⲛ̅ϭⲓⲡⲉⲧϫⲟ ⲉⲧϫⲉⲡⲉϥϭⲣⲟϭ. ⲁⲩⲱ ϩⲙ̅ⲡⲧⲣⲉϥϫⲟ. ⲁϩⲟⲓ̈ⲛⲉ ϩⲉ ϩⲁⲧⲛⲧⲉϩⲓⲏ ⲁⲩϩⲟⲙⲟⲩ ⲁⲛϩⲁⲗⲁⲧⲉ ⲛ̅ⲧⲡⲉ ⲟⲩⲟⲙⲟⲩ.
6 Òmíràn sì bọ́ sórí àpáta; bí ó sì ti hù jáde, ó gbẹ nítorí tí kò ní omi.
ⲋ̅ⲁϩⲉⲛⲕⲟⲟⲩⲉ ⲇⲉ ϩⲉ ⲉϫⲛⲙ̅ⲡⲉⲧⲣⲁ ⲁⲩⲱ ⲛ̅ⲧⲉⲣⲟⲩⲣⲱⲧʾ ⲁⲩϣⲟⲟⲩⲉ ϫⲉ ⲙ̅ⲙⲛ̅ⲁϭⲃⲉⲥ ϩⲁⲣⲟⲟⲩ.
7 Òmíràn sì bọ́ sínú ẹ̀gún; ẹ̀gún sì dàgbà pẹ̀lú rẹ̀ sókè, ó sì fún un pa.
ⲍ̅ϩⲉⲛⲕⲟⲟⲩⲉ ⲇⲉ ⲁⲩϩⲉ ⲉⲧⲙⲏⲧⲉ ⲛⲛ̅ϣⲟⲛⲧⲉ ⲁⲩⲱ ⲛ̅ⲧⲉⲣⲉⲛ̅ϣⲟⲛⲧⲉ ⲣⲱⲧʾ ⲁⲩⲟϭⲧⲟⲩ.
8 Òmíràn sì bọ́ sí ilẹ̀ rere, ó sì hù sókè, ó sì so èso ọ̀rọ̀ọ̀rún ju èyí ti a gbin lọ.” Nígbà tí ó sì wí nǹkan wọ̀nyí tán, ó pariwo sókè pé, “Ẹni tí ó bá ní etí láti fi gbọ́, kí ó gbọ́!”
ⲏ̅ϩⲉⲛⲕⲟⲟⲩⲉ ⲇⲉ ⲁⲩϩⲉ ⲉϫⲙ̅ⲡⲕⲁϩ ⲉⲧⲛⲁⲛⲟⲩϥ ⲁⲩⲱ ⲛ̅ⲧⲉⲣⲟⲩⲣⲱⲧ ⲁⲩⲧⲁⲩⲉⲕⲁⲣⲡⲟⲥ ⲉⲃⲟⲗ ⲛ̅ϣⲉ ⲛ̅ⲕⲱⲃ. ⲛⲁⲉⲓ ⲇⲉ ⲉϥϫⲱ ⲙ̅ⲙⲟⲟⲩ ⲛⲉϥⲙⲟⲩⲧⲉ ⲡⲉ ϫⲉ ⲡⲉⲧⲉⲩⲛ̅ⲧϥ̅ⲙⲁⲁϫⲉ ⲙ̅ⲙⲁⲩ ⲉⲥⲱⲧⲙ̅ ⲙⲁⲣⲉϥⲥⲱⲧⲙ̅.
9 Àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ sì bi í léèrè, pé, “Kí ni a lè mọ òwe yìí sí?”
ⲑ̅ⲁⲛⲉϥⲙⲁⲑⲏⲧⲏⲥ ⲇⲉ ϫⲛⲟⲩϥ ϫⲉ ⲟⲩ ⲧⲉ ⲧⲉⲓ̈ⲡⲁⲣⲁⲃⲟⲗⲏ.
10 Ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin ni a fi fún láti mọ ohun ìjìnlẹ̀ ìjọba Ọlọ́run; ṣùgbọ́n fún àwọn ẹlòmíràn wọn yóò jẹ́ òwe, pé ní rí rí, “‘kí wọn má ba à rí, àti ní gbígbọ́ kí ó má lè yé wọn.’
ⲓ̅ⲛ̅ⲧⲟϥ ⲇⲉ ⲡⲉϫⲁϥ ⲛⲁⲩ ϫⲉ ⲛ̅ⲧⲁⲩⲧⲁⲁⲥ ⲛⲏⲧⲛ̅ ⲉⲉ͡ⲓⲙⲉ ⲉⲡⲙⲩⲥⲧⲏⲣⲓⲟⲛ ⲛ̅ⲧⲙⲛ̅ⲧⲉⲣⲟ ⲙ̅ⲡⲛⲟⲩⲧⲉ. ⲉⲓ̈ϣⲁϫⲉ ⲇⲉ ⲛⲙ̅ⲡⲕⲉⲥⲉⲉⲡⲉ ϩⲛ̅ϩⲉⲛⲡⲁⲣⲁⲃⲟⲗⲏ ϫⲉⲕⲁⲥ ⲉⲩⲉⲛⲁⲩ ⲛ̅ⲛⲉⲩⲓ̈ⲱⲣϩ̅ ⲁⲩⲱ ⲉⲩⲥⲱⲧⲙ̅ ⲛ̅ⲛⲉⲩⲓ̈ⲙⲉ.
11 “Ǹjẹ́ òwe náà ni èyí: irúgbìn ni ọ̀rọ̀ Ọlọ́run.
ⲓ̅ⲁ̅ⲧⲁⲓ̈ ⲇⲉ ⲧⲉ ⲧⲡⲁⲣⲁⲃⲟⲗⲏ. ⲡⲉϭⲣⲟϭ ⲡⲉ ⲡϣⲁϫⲉ ⲙ̅ⲡⲛⲟⲩⲧⲉ.
12 Àwọn ti ẹ̀bá ọ̀nà ni àwọn tí ó gbọ́ nígbà náà ni èṣù wá ó sì mú ọ̀rọ̀ náà kúrò ní ọkàn wọn, kí wọn má ba à gbàgbọ́, kí a sì gbà wọ́n là.
ⲓ̅ⲃ̅ⲛⲉⲧϩⲁⲧⲛ̅ⲧⲉϩⲓⲏ ⲇⲉ ⲛⲉ ⲛⲉⲛⲧⲁⲩⲥⲱⲧⲙ̅ ⲙⲛ̅ⲛ̅ⲥⲱⲥ ⲉϣⲁⲣⲉⲡ̅ⲡⲟⲛⲏⲣⲟⲥ ⲉ͡ⲓ ⲛϥ̅ϥⲓ ⲙ̅ⲡϣⲁϫⲉ ⲉⲃⲟⲗ ϩⲙ̅ⲡⲉⲩϩⲏⲧʾ ϫⲉ ⲛ̅ⲛⲉⲩⲡⲓⲥⲧⲉⲩⲉ ⲛ̅ⲥⲉⲟⲩϫⲁⲓ̈.
13 Àwọn ti orí àpáta ni àwọn, tí wọ́n gbọ́, wọ́n fi ayọ̀ gba ọ̀rọ̀ náà, àwọn wọ̀nyí kò sì ní gbòǹgbò, wọ́n á gbàgbọ́ fún sá à díẹ̀; nígbà ìdánwò, wọn á padà sẹ́yìn.
ⲓ̅ⲅ̅ⲛⲉⲧϩⲓϫⲛ̅ⲧⲡⲉⲧⲣⲁ ⲇⲉ (ⲛⲉ) ⲛⲁⲉⲓ ⲉϣⲁⲩⲥⲱⲧⲙ̅ ⲛⲥⲉϣⲉⲡⲡϣⲁϫⲉ ⲉⲣⲟⲟⲩ ϩⲛ̅ⲟⲩⲣⲁϣⲉ. ⲛⲁⲉⲓ ⲇⲉ ⲙ̅ⲙⲛ̅ⲧⲟⲩⲛⲟⲩⲛⲉ ⲙ̅ⲙⲁⲩ ⲉϣⲁⲩⲡⲓⲥⲧⲉⲩⲉ ⲡⲣⲟⲥⲟⲩⲟⲉⲓϣ. ϩⲛ̅ⲟⲩⲟⲉⲓϣ ⲇⲉ ⲙ̅ⲡⲓⲣⲁⲥⲙⲟⲥ ϣⲁⲩⲕⲟⲧⲟⲩ ⲉⲃⲟⲗ.
14 Àwọn tí ó bọ́ sínú ẹ̀gún ni àwọn, tí wọ́n gbọ́ tán, wọ́n ti n lọ, wọn a sì fi ìtọ́jú àti ọrọ̀ àti ìrora ayé fún un pa, wọn kò sì lè so èso àsogbó.
ⲓ̅ⲇ̅ⲛⲉⲛⲧⲁⲩϩⲉ ⲇⲉ ⲉϫⲛ̅ⲛ̅ϣⲟⲛⲧⲉ ⲛⲉ ⲛⲁⲓ̈ ⲉⲧⲥⲱⲧⲙ̅ ⲉⲡϣⲁϫⲉ ⲉⲧⲙⲟⲟϣⲉ ϩⲛ̅ⲛⲣⲟⲟⲩϣ ⲛⲙ̅ⲧⲙⲛ̅ⲧⲣⲙ̅ⲙⲁⲟ ⲛⲙ̅ⲛ̅ϩⲏⲇⲟⲛⲏ ⲛ̅ⲧⲉⲡⲃⲓⲟⲥ ⲉⲩⲱϭⲧ̅ʾ ⲙ̅ⲙⲟⲟⲩ ⲁⲩⲱ ⲉⲛⲥⲉϫⲱⲕ ⲉⲃⲟⲗ ⲁⲛ.
15 Ṣùgbọ́n ti ilẹ̀ rere ni àwọn tí wọ́n fi ọkàn òtítọ́ àti rere gbọ́ ọ̀rọ̀ náà, wọ́n dìímú ṣinṣin, wọ́n sì fi sùúrù so èso.
ⲓ̅ⲉ̅ⲛⲉⲧʾϩⲓϫⲙ̅ⲡⲕⲁϩ ⲇⲉ ⲉⲧⲛⲁⲛⲟⲩϥ ⲛⲉ ⲛⲁⲓ̈ ⲉⲛⲧⲁⲩⲥⲱⲧⲙ̅ ⲉⲡϣⲁϫⲉ ϩⲛ̅ⲟⲩϩⲏⲧ ⲉⲛⲁⲛⲟⲩϥ ⲛ̅ⲁⲅⲁⲑⲟⲥ ⲁⲩⲁⲙⲁϩⲧⲉ ⲙ̅ⲙⲟϥ ⲁⲩϯⲕⲁⲣⲡⲟⲥ ϩⲛ̅ⲟⲩϩⲩⲡⲟⲙⲟⲛⲏ.
16 “Kò sí ẹnikẹ́ni, nígbà tí ó bá tán fìtílà tan, tí yóò fi ohun èlò bò ó mọ́lẹ̀, tàbí tí yóò gbé e sábẹ́ àkéte; bí kò ṣe kí ó gbé e ka orí ọ̀pá fìtílà, kí àwọn tí ń wọ ilé lè rí ìmọ́lẹ̀.
ⲓ̅ⲋ̅ⲙⲉⲣⲉⲗⲁⲁⲩ ϫⲉⲣⲉⲟⲩϩⲏⲃⲥ̅ ⲛϥ̅ϩⲟⲃⲥϥ̅ ⲛ̅ⲟⲩϩⲛⲁⲁⲩ ⲏ ⲛϥ̅ⲕⲁⲁϥ ϩⲁⲟⲩϭⲗⲟϭ. ⲁⲗⲗⲁ ⲉϣⲁϥⲕⲁⲁϥ ⲉϫⲛ̅ⲧⲗⲩⲭⲛⲓⲁ. ϫⲉ ⲉⲣⲉⲛⲉⲧⲃⲏⲕ ⲉϩⲟⲩⲛ ⲛⲁⲩ ⲉⲡⲟⲩⲟⲉⲓⲛ.
17 Nítorí kò sí ohun tí ó fi ara sin, tí a kì yóò fihàn, tàbí ohun tí a fi pamọ́, ti a kì yóò sì mọ̀ kí ó sì yọ sí gbangba.
ⲓ̅ⲍ̅ⲙ̅ⲙⲛ̅ⲗⲁⲁⲩ ⲅⲁⲣ ⲉϥϩⲏⲡ ⲉⲛϥ̅ⲛⲁⲟⲩⲱⲛϩ̅ ⲉⲃⲟⲗ ⲁⲛ. ⲁⲩⲱ ⲙ̅ⲙⲛ̅ⲗⲁⲁⲩ ⲉϥϩⲟⲃⲥ̅ ⲉⲛⲥⲉⲛⲁⲉ͡ⲓⲙⲉ ⲉⲣⲟϥ ⲁⲛ ⲛϥⲉ͡ⲓ ⲉⲡⲟⲩⲟⲓ̈ⲛ.
18 Ǹjẹ́ kí ẹ̀yin máa kíyèsára bí ẹ̀yin ti ń gbọ́: nítorí ẹnikẹ́ni tí ó bá ní, lọ́wọ́ rẹ̀ ni a ó sì gba èyí tí ó ṣe bí òun ní.”
ⲓ̅ⲏ̅ϯϩⲧⲏⲧⲛ̅ ϭⲉ ϫⲉ ⲉⲧⲉⲧⲛ̅ⲥⲱⲧⲙ̅ ⲛ̅ⲁϣ ⲛ̅ϩⲉ. ⲡⲉⲧⲉⲟⲩⲛⲧⲁϥ ⲅⲁⲣ ⲥⲉⲛⲁϯ ⲛⲁϥ ⲁⲩⲱ ⲡⲉⲧⲉⲙⲛ̅ⲧⲁϥ. ⲡⲉⲧϥ̅ϫⲱ ⲙ̅ⲙⲟⲥ ϫⲉ ⲟⲩⲛⲧⲁⲓ̈ⲥϥ̅ ⲥⲉⲛⲁϥⲓⲧϥ̅ ⲛ̅ⲧⲟⲟⲧϥ̅·
19 Nígbà náà ní ìyá rẹ̀ àti àwọn arákùnrin rẹ̀ tọ̀ ọ́ wá, wọn kò sì lè súnmọ́ ọn nítorí ọ̀pọ̀ ènìyàn.
ⲓ̅ⲑ̅ⲁⲧⲉϥⲙⲁⲁⲩ ⲇⲉ ⲉ͡ⲓ ϣⲁⲣⲟϥ ⲛⲙ̅ⲛⲉϥⲥⲛⲏⲩ ⲙ̅ⲡⲟⲩⲉϣϭⲙ̅ϭⲟⲙ ⲉⲧⲱⲙⲛⲧ̅ ⲉⲣⲟϥ ⲉⲧⲃⲉⲡⲙⲏⲏϣⲉ.
20 Wọ́n sì wí fún un pé, “Ìyá rẹ àti àwọn arákùnrin rẹ dúró lóde, wọn fẹ́ rí ọ.”
ⲕ̅ⲁⲩϫⲓⲡⲟⲩⲱ ⲇⲉ ⲛⲁϥ ϫⲉ ⲧⲉⲕⲙⲁⲁⲩ ⲛⲙ̅ⲛⲉⲕⲥⲛⲏⲟⲩ ⲁϩⲉⲣⲁⲧⲟⲩ ϩⲓⲡⲥⲁ ⲃ̅ⲃⲟⲗ ⲉⲩⲟⲩⲉϣ ⲛⲁⲩ ⲉⲣⲟⲕ.
21 Ó sì dáhùn wí fún wọn pé, “Ìyá mi àti àwọn arákùnrin mi ni àwọn wọ̀nyí tí wọ́n ń gbọ́ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, tí wọ́n sì ń ṣe é.”
ⲕ̅ⲁ̅ⲛ̅ⲧⲟϥ ⲇⲉ ⲁϥⲟⲩⲱϣⲃ̅ ⲡⲉϫⲁϥ ⲛⲁⲩ ϫⲉ. ⲧⲁⲙⲁⲁⲩ ⲛⲙⲛⲁⲥⲛⲏⲩ ⲛⲉ ⲛⲁⲓ̈ ⲉⲧⲥⲱⲧⲙ̅ ⲉⲡϣⲁϫⲉ ⲙ̅ⲡⲛⲟⲩⲧⲉ. ⲉϯⲣⲉ ⲙ̅ⲙⲟϥ·
22 Ní ọjọ́ kan, ó sì wọ ọkọ̀ ojú omi kan lọ òun pẹ̀lú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀. O sì wí fún wọn pé, “Ẹ jẹ́ kí a rékọjá lọ sí ìhà kejì adágún.” Wọ́n sì ṣíkọ̀ láti lọ.
ⲕ̅ⲃ̅ⲁⲥϣⲱⲡⲉ ⲇⲉ ⲛ̅ⲟⲩϩⲟⲟⲩ ⲉⲁϥⲧⲁⲗⲉ ⲉⲩϫⲟⲓ̈ ⲛⲙ̅ⲛⲉϥⲙⲁⲑⲏⲧⲏⲥ. ⲡⲉϫⲁϥ ⲛⲁⲩ ϫⲉ ⲙⲁⲣⲟⲛ ⲉⲡⲉⲕⲣⲟ ⲛ̅ⲧⲗⲓⲙⲛⲏ. ⲁⲩⲱ ⲁⲩⲣ̅ϩⲱⲧʾ
23 Bí wọ́n sì ti ń lọ, ó sùn; ìjì ńlá sì dé, ó ń fẹ́ lójú adágún; omi si wọ inú ọkọ, wọ́n sì wà nínú ewu.
ⲕ̅ⲅ̅ⲉⲩⲣϩⲱⲧʾ ⲇⲉ ⲁϥⲱⲃϣ̅. ⲁⲩⲧⲣⲱⲙ ⲛ̅ⲧⲏⲩ ⲉ͡ⲓ ⲉⲡⲉⲥⲏⲧʾ ⲉⲧⲗⲓⲙⲛⲏ ⲁⲩϣⲧⲟⲣⲧⲣ̅ ⲇⲉ ⲁⲩⲱ ⲁⲩϭⲓⲛⲇⲩⲛⲉⲩⲉ.
24 Wọ́n sì tọ̀ ọ́ wá wọ́n sì jí i, wí pé, “Olùkọ́, Olùkọ́, àwa yóò ṣègbé!” Nígbà náà ni ó dìde, ó sì bá ìjì líle àti ríru omi wí; wọ́n sì dúró, ìdákẹ́rọ́rọ́ sì dé.
ⲕ̅ⲇ̅ⲁⲩϯⲡⲉⲩⲟⲩⲟⲓ̈ ⲇⲉ ⲉⲣⲟϥ ⲁⲩⲧⲟⲩⲛⲟⲥϥ̅ ⲉⲩϫⲱ ⲙ̅ⲙⲟⲥ ϫⲉ ⲡⲥⲁϩ ⲡⲥⲁϩ ⲧⲛ̅ⲛⲁⲧⲁⲕⲟ. ⲛ̅ⲧⲟϥ ⲇⲉ ⲁϥⲧⲱⲟⲩⲛ ⲁϥⲉⲡⲓⲧⲓⲙⲁ ⲙ̅ⲡⲧⲏⲟⲩ ⲛⲙ̅ⲫⲟⲉⲓⲙ ⲙ̅ⲡⲙⲟⲟⲩ ⲁϥⲗⲟ ⲁⲩϫⲁⲙⲏ ϣⲱⲡⲉ.
25 Ó sì wí fún wọn pé, “Ìgbàgbọ́ yín dà?” Bí ẹ̀rù ti ń ba gbogbo wọn, tí hà sì ń ṣe wọ́n, wọ́n ń bi ara wọn pé, “Irú ọkùnrin wo ni èyí, nítorí ó bá ìjì líle àti ríru omi wí, wọ́n sì gbọ́ tirẹ̀?”
ⲕ̅ⲉ̅ⲡⲉϫⲁϥ ⲇⲉ ⲛⲁⲩ ϫⲉ ⲉⲥⲧⲱⲛ ⲧⲉⲧⲛ̅ⲡⲓⲥⲧⲓⲥ. ⲉⲩⲣ̅ϩⲟⲧⲉ ⲇⲉ ⲁⲩⲱ ⲉⲩⲣ̅ϣⲡⲏⲣⲉ ⲉⲩϫⲱ ⲙ̅ⲙⲟⲥ ⲛ̅ⲛⲉⲩⲉⲣⲏⲩ ϫⲉ ⲛⲓⲙ ϭⲉ ⲛ̅ⲧⲟϥ ⲡⲉ ⲡⲁⲓ̈ ϫⲉ ϥⲟⲩⲉϩⲥⲁϩⲛⲉ ⲛⲛ̅ⲧⲏⲩ ⲛⲙ̅ⲡⲙⲟⲟⲩ ⲥⲉⲥⲱⲧⲙ̅ ⲛ̅ⲥⲱϥ.
26 Wọ́n sì gúnlẹ̀ ní ilẹ̀ àwọn ará Gadara, tí ó kọjú sí Galili.
ⲕ̅ⲋ̅ⲁⲩⲥϭⲏⲣ ⲇⲉ ⲉϩⲣⲁⲓ̈ ⲉⲧⲉⲭⲱⲣⲁ ⲛⲛ̅ⲅⲉⲣⲁⲍⲏⲛⲟⲥ ⲉⲧⲉⲧⲁⲓ̈ ⲧⲉ (ⲉ)ⲧⲙ̅ⲡⲉⲙⲧⲟ ⲉⲃⲟⲗ ⲛ̅ⲧⲅⲁⲗⲓⲗⲁⲓⲁ.
27 Nígbà tí ó sì sọ̀kalẹ̀, ọkùnrin kan pàdé rẹ̀ lẹ́yìn ìlú náà, tí ó ti ní àwọn ẹ̀mí èṣù fún ìgbà pípẹ́, tí kì í wọ aṣọ, bẹ́ẹ̀ ni kì í jókòó ní ilé kan, bí kò ṣe ní ibojì.
ⲕ̅ⲍ̅ⲛ̅ⲧⲉⲣⲉϥⲉ͡ⲓ ⲇⲉ ⲉⲡⲉⲕⲣⲟ ⲁⲩⲣⲱⲙⲉ ⲧⲱⲙⲛⲧ̅ ⲉⲣⲟϥ ⲉϥⲛⲏⲟⲩ ⲉⲃⲟⲗ ϩⲛ̅ⲧⲡⲟⲗⲉⲓⲥ ⲉⲩⲛϩⲉⲛⲇⲁⲓⲙⲟⲛⲓⲟⲛ ϩⲓⲱⲱϥ. ⲉⲁϥⲣⲟⲩⲛⲟϭ ⲛⲟⲩⲟⲉⲓϣ ⲉⲙⲡϥ̅ϯϩⲟⲓ̈ⲧⲉ ϩⲓⲱⲱϥ ⲁⲩⲱ ⲉⲙⲡϥ̅ⲟⲩⲱϩ ϩⲛ̅ⲏⲉⲓ ⲁⲗⲗⲁ ⲉϥϩⲛⲛⲉⲙϩⲁⲟⲩ.
28 Nígbà tí ó rí Jesu, ó ké, ó wólẹ̀ níwájú rẹ̀, ó wí lóhùn rara, pé, “Kí ni mo ní í ṣe pẹ̀lú rẹ, Jesu, ìwọ Ọmọ Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo? Èmi bẹ̀ ọ́ má ṣe dá mi lóró.”
ⲕ̅ⲏ̅ⲛ̅ⲧⲉⲣⲉϥⲛⲁⲩ ⲇⲉ ⲉⲓ̅ⲥ̅ ⲁϥϫⲓϣⲕⲁⲕ ⲉⲃⲟⲗ ⲁϥⲡⲁϩⲧϥ̅ ϩⲁⲣⲁⲧϥ̅. ⲡⲉϫⲁϥ ϩⲛⲟⲩⲛⲟϭ ⲛ̅ⲥⲙⲏ ϫⲉ. ⲉⲕⲟⲩⲉϣⲟⲩ ⲛⲙ̅ⲙⲁⲛ ⲓ̅ⲥ̅ ⲡϣⲏⲣⲉ ⲙ̅ⲡⲛⲟⲩⲧⲉ ⲉⲧϫⲟⲥⲉ. ϯⲥⲟⲡⲥ̅ ⲙ̅ⲙⲟⲕ ⲙ̅ⲡⲣ̅ⲃⲁⲥⲁⲛⲓⲍⲉ ⲙ̅ⲙⲟⲓ̈.
29 (Nítorí tí ó ti wí fún ẹ̀mí àìmọ́ náà pé, kí ó jáde kúrò lára ọkùnrin náà. Nígbàkígbà ni ó ń mú un: wọn a sì fi ẹ̀wọ̀n àti ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ dè é; a sì ja gbogbo ìdè náà, ẹ̀mí èṣù náà a sì darí rẹ̀ sí ijù).
ⲕ̅ⲑ̅ⲁϥⲡⲁⲣⲁⲅⲅⲉⲓⲗⲉ ⲅⲁⲣ ⲛ̅ⲛⲉⲡⲛ̅ⲁ ⲛ̅ⲁⲕⲁⲑⲁⲣⲧⲟⲛ ⲉⲉ͡ⲓ ⲉⲃⲟⲗ ϩⲙ̅ⲡⲣⲱⲙⲉ. ⲛⲉⲁϥⲣ̅ϩⲉⲛⲛⲟϭ ⲅⲁⲣ ⲛ̅ⲟⲩⲟⲉⲓϣ ⲉϣⲁϥⲧⲟⲣⲡϥ̅ ⲛⲉϣⲁⲩⲙⲟⲣϥ̅ ⲇⲉ ⲡⲉ ϩⲛ̅ϩⲉⲛϩⲁⲗⲩⲥⲓⲥ ⲛⲙ̅ϩⲉⲛⲓⲛⲉ ⲛ̅ϩⲟⲙⲛ̅ⲧ ⲉⲩϩⲁⲣⲉϩ ⲉⲣⲟϥ. ⲁⲩⲱ ϣⲁϥⲡⲱϩ ⲛⲙ̅ⲙⲣ̅ⲣⲉ ⲛ̅ⲥⲉϫⲓⲧϥ̅ ⲉⲃⲟⲗ ϩⲓⲧⲛ̅ⲡⲇⲁⲓⲙⲟⲛⲓⲟⲛ ⲉϩⲉⲛⲙⲁ ⲛ̅ϫⲁⲓ̈ⲉ.
30 Jesu sì bi í pé, “Kí ni orúkọ rẹ?” Ó sì dáhùn pé, “Ligioni,” nítorí ẹ̀mí èṣù púpọ̀ ni ó wa nínú rẹ.
ⲗ̅ⲁⲓ̅ⲥ̅ ⲇⲉ ϫⲛⲟⲩϥ ϫⲉ ⲛⲓⲙ ⲡⲉ ⲡⲉⲕⲣⲁⲛ ⲛ̅ⲧⲟϥ ⲇⲉ ⲡⲉϫⲁϥ ϫⲉ ⲗⲉⲅⲉⲱⲛ ϫⲉ ⲁϩⲁϩ ⲛ̅ⲇⲁⲓⲙⲟⲛⲓⲟⲛ ⲃⲱⲕ ⲉϩⲟⲩⲛ ⲉⲣⲟϥ
31 Wọ́n sì bẹ̀ ẹ́ pé, kí ó má ṣe rán wọn lọ sínú ọ̀gbun. (Abyssos g12)
ⲗ̅ⲁ̅ⲁⲩⲱ ⲁⲩⲥⲉⲡⲥⲱⲡϥ̅ ϫⲉ ⲛ̅ⲛⲉϥⲟⲩⲉϩⲥⲁϩⲛⲉ ⲛⲁⲩ ⲉⲃⲱⲕ ⲉⲡⲛⲟⲩⲛ (Abyssos g12)
32 Agbo ẹlẹ́dẹ̀ púpọ̀ sì ń bẹ níbẹ̀ tí ń jẹ lórí òkè: wọ́n sì bẹ̀ ẹ́ kí ó jẹ́ kí àwọn wọ inú wọn lọ. Ó sì gba fún wọn.
ⲗ̅ⲃ̅ⲛⲉⲟⲩⲛⲟⲩⲁⲅⲉⲗⲏ ⲇⲉ ⲣ̅ⲣⲓⲣ ⲙ̅ⲙⲁⲩ ⲡⲉ ⲉⲛⲁϣⲱⲥ ⲉⲩⲙⲟⲟⲛⲉ ⲙ̅ⲙⲟⲥ ϩⲓⲡⲧⲟⲟⲩ ⲁⲩⲥⲉⲡⲥⲱⲡϥ̅ ⲇⲉ ϫⲉ ⲉϥⲉⲟⲩⲉϩⲥⲁϩⲛⲉ ⲛⲁⲩ ⲉⲃⲱⲕ ⲉϩⲟⲩⲛ ⲉⲛⲉⲧⲙ̅ⲙⲁⲩ. ⲁⲩⲱ ⲁϥⲕⲁⲁⲩ.
33 Nígbà tí àwọn ẹ̀mí èṣù sì jáde kúrò lára ọkùnrin náà, wọ́n sì wọ inú àwọn ẹlẹ́dẹ̀ lọ. Agbo ẹlẹ́dẹ̀ sì tú ka, wọ́n sí súré rọ́ gììrì sọ̀kalẹ̀ sì bèbè odò bọ́ sínú adágún náà, wọ́n sì rì sínú rẹ̀.
ⲗ̅ⲅ̅ⲁⲛⲇⲁⲓⲙⲟⲛⲓⲟⲛ ⲇⲉ ⲉ͡ⲓ ⲉⲃⲟⲗ ϩⲙ̅ⲡⲣⲱⲙⲉ ⲁⲩⲃⲱⲕ ⲉϩⲟⲩⲛ ⲉⲛⲣⲓⲣ. ⲁⲥϯⲡⲉⲥⲟⲩⲟⲓ̈ ⲇⲉ ⲛ̅ϭⲓⲧⲁⲅⲉⲗⲏ ⲉϫⲛ̅ⲧϣⲱⲙⲉ ⲉⲡⲉⲥⲏⲧʾ ⲉⲧⲗⲓⲙⲛⲏ ⲁⲩⲙⲟⲩ.
34 Nígbà tí àwọn tí n bọ́ wọn rí ohun tí ó ṣẹlẹ̀, wọ́n sá, wọ́n sì lọ, wọ́n sì ròyìn ní ìlú àti ní ilẹ̀ náà.
ⲗ̅ⲇ̅ⲁⲛⲉⲧⲙⲟⲟⲛⲉ ⲇⲉ ⲛⲁⲩ ⲉⲡⲉⲛⲧⲁϥϣⲱⲡⲉ ⲁⲩⲡⲱⲧʾ ⲁⲩϫⲓⲡⲟⲩⲱ ⲉⲧⲡⲟⲗⲉⲓⲥ ⲁⲩⲱ ⲉⲛⲥⲱϣⲉ.
35 Nígbà náà ni wọ́n jáde lọ wo ohun náà tí ó ṣẹlẹ̀, wọ́n sì tọ Jesu wá, wọ́n sì rí ọkùnrin náà, lára ẹni tí àwọn ẹ̀mí èṣù ti jáde lọ, ó jókòó lẹ́bàá ẹsẹ̀ Jesu, ó wọ aṣọ, iyè rẹ̀ sì bọ́ sí ipò: ẹ̀rù sì bà wọ́n.
ⲗ̅ⲉ̅ⲁⲩⲉ͡ⲓ ⲇⲉ ⲉⲃⲟⲗ ⲉⲛⲁⲩ ⲉⲡⲉⲛⲧⲁϥϣⲱⲡⲉ. ⲁⲩⲉ͡ⲓ ϣⲁⲓ̅ⲥ̅ ⲁⲩϩⲉ ⲉⲡⲣⲱⲙⲉ ⲉϥϩⲙⲟⲟⲥ ⲡⲁⲓ̈ ⲉⲛⲧⲁⲛ̅ⲇⲁⲓⲙⲟⲛⲓⲟⲛ (ⲉⲓ) ⲉⲃⲟⲗ ⲛ̅ϩⲏⲧϥ̅ ⲉⲣⲉⲛⲉϥϩⲟⲓ̈ⲧⲉ ϩⲓⲱⲱϥ ⲉⲣⲉⲡⲉϥϩⲏⲧʾ ⲥⲙⲟⲛⲧ̅ʾ ⲉϥϩⲙⲟⲟⲥ ϩⲁⲧⲛ̅ⲟⲩⲉⲣⲏⲧⲉ ⲛ̅ⲓ̅ⲥ̅ ⲁⲩⲱ ⲁⲩⲣ̅ϩⲟⲧⲉ
36 Àwọn tí ó rí i ròyìn fún wọn bí ó ti ṣe mú ẹni tí ó ní ẹ̀mí èṣù náà láradá.
ⲗ̅ⲋ̅ⲁⲛⲉⲛⲧⲁⲩⲛⲁⲩ ⲇⲉ ⲧⲁⲙⲟⲟⲩ ⲉⲑⲉ ⲉⲛⲧⲁⲡⲉⲧⲟ ⲛⲇⲁⲓⲙⲟⲛⲓⲟⲛ ⲟⲩϫⲁⲓ̈ ⲙ̅ⲙⲟⲥ.
37 Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn láti ilẹ̀ Gadara yíká bẹ̀ ẹ́ pé, kí ó lọ kúrò lọ́dọ̀ wọn; nítorí ẹ̀rù bà wọ́n gidigidi. Ó sì bọ́ sínú ọkọ̀ ojú omi, ó si kúrò.
ⲗ̅ⲍ̅ⲁⲩⲥⲉⲡⲥⲱⲡϥ̅ ⲇⲉ ⲛ̅ϭⲓⲡⲙⲏⲏϣⲉ ⲧⲏⲣϥ̅ ⲛ̅ⲧⲡⲉⲣⲓⲭⲱⲣⲟⲥ ⲛⲛ̅ⲅⲉⲣⲁⲍⲏⲛⲟⲥ ⲉⲃⲱⲕ ⲉⲃⲟⲗ ϩⲓⲧⲟⲟⲧⲟⲩ ϫⲉ ⲁⲩⲛⲟϭ ⲛ̅ϩⲟⲧⲉ ⲧⲁϩⲟⲟⲩ. ⲛ̅ⲧⲟϥ ⲇⲉ ⲁϥⲁⲗⲉ ⲉⲩϫⲟⲓ̈ ⲁϥⲕⲧⲟϥ.
38 Ǹjẹ́ ọkùnrin náà tí ẹ̀mí èṣù jáde kúrò lára rẹ̀, bẹ̀ ẹ́ kí òun lè máa bá a gbé: ṣùgbọ́n Jesu rán an lọ, wí pé,
ⲗ̅ⲏ̅ⲛⲉⲣⲉⲡⲣⲱⲙⲉ ⲇⲉ ⲉⲛⲧⲁⲛ̅ⲇⲁⲓⲙⲟⲛⲓⲟⲛ ⲉ͡ⲓ ⲉⲃⲟⲗ ⲛ̅ϩⲏⲧϥ̅ ⲧⲱⲃϩ̅ ⲙ̅ⲙⲟϥ ⲉⲧⲣⲉϥⲙⲟⲟϣⲉ ⲛⲙ̅ⲙⲁϥ. ⲁϥⲕⲁⲁϥ ⲇⲉ ⲉⲃⲟⲗ ⲉϥϫⲱ ⲙ̅ⲙⲟⲥ
39 “Padà lọ sí ilé rẹ, kí o sì sọ ohun tí Ọlọ́run ṣe fún ọ bí ó ti pọ̀ tó.” Ó sì lọ, o sì ń ròyìn ka gbogbo ìlú náà bí Jesu ti ṣe ohun ńlá fún òun tó.
ⲗ̅ⲑ̅ϫⲉ. ⲕⲟⲧⲕ ⲉϩⲣⲁⲓ̈ ⲉⲡⲉⲕⲏⲉⲓ ⲛⲅ̅ϫⲱ ⲛ̅ⲛⲉⲛⲧⲁⲡⲛⲟⲩⲧⲉ ⲁⲁⲩ ⲛⲁⲕ. ⲁⲩⲱ ⲁϥⲃⲱⲕ ⲉⲃⲟⲗ ϩⲛ̅ⲧⲡⲟⲗⲉⲓⲥ ⲧⲏⲣⲥ̅ ⲉϥⲧⲁϣⲉⲟⲓ̈ϣ ⲛ̅ⲛⲉⲛⲧⲁⲡⲛⲟⲩⲧⲉ ⲁⲁⲩ ⲛⲁϥ·
40 Ó sì ṣe, nígbà tí Jesu padà lọ, àwọn ènìyàn tẹ́wọ́gbà á; nítorí tí gbogbo wọn ti ń retí rẹ̀.
ⲙ̅ϩⲙ̅ⲡⲧⲣⲉⲓ̅ⲥ̅ ⲇⲉ ⲕⲟⲧϥ̅ ⲁⲡⲙⲏⲏϣⲉ ϣⲟⲡϥ̅ ⲉⲣⲟⲟⲩ ⲛⲉⲩϭⲱϣⲧ̅ʾ ⲅⲁⲣ ⲧⲏⲣⲟⲩ ⲡⲉ ⲉⲃⲟⲗ ϩⲏⲧϥ̅.
41 Sì kíyèsi i, ọkùnrin kan tí a ń pè ní Jairu, ọ̀kan nínú àwọn olórí Sinagọgu wá; ó sì wólẹ̀ lẹ́bàá ẹsẹ̀ Jesu, ó bẹ̀ ẹ́ pé, kí ó wá sí ilé òun,
ⲙ̅ⲁ̅ⲉⲓⲥϩⲏⲏⲧⲉ ⲇⲉ ⲁⲩⲣⲱⲙⲉ ⲉ͡ⲓ ⲉⲡⲉϥⲣⲁⲛ ⲡⲉ ⲉⲓⲁⲉⲓⲣⲟⲥ ⲉⲡⲁⲣⲭⲱⲛ ⲡⲉ ⲛ̅ⲧⲥⲩⲛⲁⲅⲱⲅⲏ. ⲁϥⲡⲁϩⲧϥ̅ ϩⲁⲛⲟⲩⲉⲣⲏⲧⲉ ⲛ̅ⲓ̅ⲥ̅ ⲁϥⲥⲉⲡⲥⲱⲡϥ̅ ⲉⲧⲣⲉϥⲃⲱⲕ ⲉϩⲟⲩⲛ ⲉⲡⲉϥⲏⲓ̈
42 nítorí ó ní ọmọbìnrin kan ṣoṣo, ọmọ ìwọ̀n ọdún méjìlá, ti ó ń kú lọ. Bí ó sì ti ń lọ àwọn ènìyàn ko fun ni ààyè.
ⲙ̅ⲃ̅ϫⲉ ⲉⲛⲉⲟⲩⲛ̅ⲧϥ̅ⲟⲩϣⲉⲉⲣⲉ ⲟⲩⲱⲧʾ ⲉⲥⲛⲁⲣⲙⲛⲧ̅ⲥ̅ⲛⲟⲟⲩⲥ ⲣ̅ⲣⲟⲙⲡⲉ. ⲧⲁⲓ̈ ⲇⲉ ⲛⲉⲥⲛⲉⲥⲛⲁⲙⲟⲩ. ⲉϥⲃⲏⲕ ⲇⲉ ⲁⲡⲙⲏⲏϣⲉ ϩⲉϫϩⲱϫϥ̅.
43 Obìnrin kan tí ó sì ní ìsun ẹ̀jẹ̀ láti ìgbà ọdún méjìlá, tí ó ná ohun gbogbo tí ó ní fún àwọn oníṣègùn, tí kò sì sí ẹnìkan tí ó lè mú un láradá,
ⲙ̅ⲅ̅ⲉⲓⲥⲟⲩⲥϩⲓⲙⲉ ⲇⲉ ⲉⲣⲉⲡⲉⲥⲛⲟϥ ϩⲁⲣⲟⲥ ⲙ̅ⲙⲛⲧ̅ⲥⲛⲟⲟⲩⲥⲉ ⲣ̅ⲣⲟⲙⲡⲉ ⲧⲁⲓ̈ ⲉⲙⲡⲉⲗⲁⲁⲩ ⲉϣϭⲙ̅ϭⲟⲙ ⲉⲧⲁⲗϭⲟⲥ.
44 Ó wá sí ẹ̀yìn rẹ̀, ó fi ọwọ́ tọ́ ìṣẹ́tí aṣọ rẹ̀; lọ́gán ni ìsun ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ sì ti gbẹ.
ⲙ̅ⲇ̅ⲁⲥϯⲡⲉⲥⲟⲩⲟⲓ̈ ⲉⲡⲁϩⲟⲩ ⲙ̅ⲙⲟϥ ⲁⲥϫⲱϩ ⲉⲛⲧⲱⲧⲉ ⲛ̅ⲧⲉϥϣⲧⲏⲛ ⲁⲩⲱ ϩⲛ̅ⲧⲉⲩⲛⲟⲩ ⲁⲡⲉⲥⲛⲟϥ ϭⲱ ⲉϥϣⲟⲩⲟ̅.
45 Jesu sì wí pé, “Ta ni ó fi ọwọ́ kàn mí?” Nígbà tí gbogbo wọn sẹ́ Peteru àti àwọn tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ sọ pé, “Olùkọ́, àwọn ènìyàn ko ní ààyè, wọ́n sì ń kọlù ọ́, ìwọ sì wí pé, Ta ni ó fi ọwọ́ kàn mi?”
ⲙ̅ⲉ̅ⲡⲉϫⲉⲓ̅ⲥ̅ ϫⲉ ⲛⲓⲙ ⲡⲉ ⲛ̅ⲧⲁϥϫⲱϩ ⲉⲣⲟⲓ̈. ⲛ̅ⲧⲉⲣⲟⲩϫⲟⲟⲥ ⲇⲉ ⲧⲏⲣⲟⲩ ϫⲉ ⲛ̅ⲁⲛⲟⲛ ⲁⲛ ⲛⲉ. ⲡⲉϫⲉⲡⲉⲧⲣⲟⲥ ⲛⲁϥ ϫⲉ. ⲡⲥⲁϩ. ⲙ̅ⲙⲏⲏϣⲉ ⲛⲉⲧʾϩⲟϫϩⲉϫ ⲙ̅ⲙⲟⲕ ⲉⲧʾⲑⲗⲓⲃⲉ ⲙ̅ⲙⲟⲕ.
46 Jesu sì wí pé, “Ẹnìkan fi ọwọ́ kàn mí: nítorí tí èmí mọ̀ pé, àṣẹ jáde lára mi.”
ⲙ̅ⲋ̅ⲓ̅ⲥ̅ ⲇⲉ ⲡⲉϫⲁϥ ϫⲉ ⲁⲩϫⲱϩ ⲉⲣⲟⲓ̈ ⲁⲛⲟⲕ ⲅⲁⲣ ⲁⲓ̈ⲉ͡ⲓⲙⲉ ⲉⲩϭⲟⲙ ⲉⲁⲥⲉ͡ⲓ ⲉⲃⲟⲗ ⲛ̅ϩⲏⲧʾ.
47 Nígbà tí obìnrin náà sì mọ̀ pé òun kò fi ara sin, ó wárìrì, ó wá, ó sì wólẹ̀ níwájú rẹ̀, ó sì sọ fún un lójú àwọn ènìyàn gbogbo nítorí ohun tí ó ṣe, tí òun fi fi ọwọ́ kàn án, àti bí a ti mú òun láradá lójúkan náà.
ⲙ̅ⲍ̅ⲁⲥⲛⲁⲩ ⲇⲉ ⲛ̅ϭⲓⲧⲉⲥϩⲓⲙⲉ ϫⲉ ⲙ̅ⲡⲉⲡϩⲱⲃ ϩⲱⲡ ⲁⲥⲉ͡ⲓ ⲉⲥⲥⲧⲱⲧʾ ⲁⲥⲡⲁϩⲧⲥ̅ ⲛⲁϥ ⲁⲥⲧⲁⲙⲟϥ ϫⲉ ⲛ̅ⲧⲁⲥϫⲱϩ ⲉⲣⲟϥ ⲉⲧⲃⲉⲟⲩ ⲛ̅ϩⲱⲃ ⲙ̅ⲡⲉⲙⲧⲟ ⲉⲃⲟⲗ ⲙⲡⲙⲏⲏϣⲉ ⲧⲏⲣϥ̅. ⲁⲩⲱ ⲉⲑⲉ ⲉⲛⲧⲁⲥⲗⲟ ⲛ̅ⲧⲉⲩⲛⲟⲩ
48 Ó sì wí fún un pé, “Ọmọbìnrin, ìgbàgbọ́ rẹ mú ọ láradá, máa lọ ní Àlàáfíà.”
ⲙ̅ⲏ̅ⲛ̅ⲧⲟϥ ⲇⲉ ⲡⲉϫⲁϥ ⲛⲁⲥ ϫⲉ ⲧⲁϣⲉⲉⲣⲉ ⲧⲟⲩⲡⲓⲥⲧⲓⲥ ⲧⲉⲛⲧⲁⲥⲛⲁϩⲙⲉ ⲃⲱⲕ ϩⲛ̅ⲟⲩⲓ̈ⲣⲏⲛⲏ.
49 Bí ó sì ti ń sọ̀rọ̀ lẹ́nu, ẹnìkan ti ilé olórí Sinagọgu wá, ó wí fún un pé, “Ọmọbìnrin rẹ kú; má yọ olùkọ́ni lẹ́nu mọ́.”
ⲙ̅ⲑ̅ⲉⲧⲓ ⲇⲉ ⲉϥϣⲁϫⲉ ⲁϥⲉ͡ⲓ ⲛ̅ϭⲓⲟⲩⲁ ⲉⲃⲟⲗ ϩⲓⲧⲛ̅ⲛⲁⲡⲁⲣⲭⲓⲥⲩⲛⲁⲅⲱⲅⲟⲥ ⲉϥϫⲱ ⲙ̅ⲙⲟⲥ ϫⲉ ⲁⲧⲉⲕϣⲉⲉⲣⲉ ⲙⲟⲩ ⲙ̅ⲡⲣ̅ⲥⲕⲩⲗⲗⲉⲓ ϭⲉ ⲙⲡⲥⲁϩ.
50 Ṣùgbọ́n nígbà tí Jesu gbọ́, ó dá a lóhùn, pé, “Má bẹ̀rù: sá gbàgbọ́ nìkan, a ó sì mú un láradá.”
ⲛ̅ⲓ̅ⲥ̅ ⲇⲉ ⲁϥⲥⲱⲧⲙ̅ ⲡⲉϫⲁϥ ϫⲉ ⲙ̅ⲡⲣ̅ⲣ̅ϩⲟⲧⲉ. ⲙⲟⲛⲟⲛ ⲡⲓⲥⲧⲉⲩⲉ ⲁⲩⲱ ⲥⲛⲁⲱⲛϩ̅.
51 Ṣùgbọ́n nígbà tí Jesu sì wọ ilé, kò jẹ́ kí ẹnikẹ́ni wọlé, bí kò ṣe Peteru, àti Jakọbu, àti Johanu, àti baba àti ìyá ọmọbìnrin náà.
ⲛ̅ⲁ̅ⲛ̅ⲧⲉⲣⲉϥⲉ͡ⲓ ⲇⲉ ⲉⲡⲏⲓ̈ ⲙⲡ̅ϥⲕⲁⲗⲁⲁⲩ ⲉⲃⲱⲕ ⲉϩⲟⲩⲛ ⲛⲙ̅ⲙⲁϥ ⲛ̅ⲥⲁⲡⲉⲧⲣⲟⲥ ⲛⲙ̅ⲓ̈ⲱϩⲁⲛⲛⲏⲥ ⲛⲙ̅ⲓ̈ⲁⲕⲱⲃⲟⲥ ⲛⲙⲡⲓⲱⲧʾ ⲛ̅ⲧϣⲉⲉⲣⲉ ϣⲏⲙ ⲛⲙ̅ⲧⲉⲥⲙⲁⲁⲩ.
52 Gbogbo wọn sì sọkún, wọ́n pohùnréré ẹkún rẹ̀: ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ má sọkún mọ́; kò kú, sísùn ni ó sùn.”
ⲛ̅ⲃ̅ⲛⲉⲩⲣⲓⲙⲉ ⲇⲉ ⲧⲏⲣⲟⲩ ⲁⲩⲱ ⲛⲉⲩⲛⲉϩⲡⲉ ⲡⲉ ⲉⲣⲟⲥ. ⲛ̅ⲧⲟϥ ⲇⲉ ⲡⲉϫⲁϥ ϫⲉ ⲙ̅ⲡⲣ̅ⲣⲓⲙⲉ. ⲙ̅ⲡⲥ̅ⲙⲟⲩ ⲅⲁⲣ ⲁⲗⲗⲁ ⲉⲥⲛ̅ⲕⲟⲧⲕ̅.
53 Wọ́n sì fi í ṣẹ̀fẹ̀, wọ́n sá mọ̀ pé ó kú.
ⲛ̅ⲅ̅ⲁⲩⲥⲱⲃⲉ ⲇⲉ ⲛ̅ⲥⲱϥ ⲉⲩⲥⲟⲟⲩⲛ ϫⲉ ⲁⲥⲙⲟⲩ.
54 Nígbà tí ó sì sé gbogbo wọn mọ́ òde, ó mú un lọ́wọ́, ó sì wí pé, “Ọmọbìnrin, dìde!”
ⲛ̅ⲇ̅ⲛ̅ⲧⲟϥ ⲇⲉ ⲁϥⲛⲉϫⲟⲩⲟⲛ ⲛⲓⲙ ⲉⲃⲟⲗ ⲁϥⲁⲙⲁϩⲧⲉ ⲛ̅ⲧⲉⲥϭⲓϫ ⲁϥⲙⲟⲩⲧⲉ ⲉϥϫⲱ ⲙ̅ⲙⲟⲥ ϫⲉ ⲧϣⲉⲉⲣⲉ ϣⲏⲙ ⲧⲱⲟⲩⲛⲉ.
55 Ẹ̀mí rẹ̀ sì padà bọ̀, ó sì dìde lọ́gán: ó ní kí wọn fún un ní oúnjẹ.
ⲛ̅ⲉ̅ⲁⲡⲉⲥⲡⲛ̅ⲁ ⲇⲉ ⲕⲟⲧϥ̅ ⲉⲣⲟⲥ ⲁⲥⲧⲱⲟⲩⲛ ⲛ̅ⲧⲉⲩⲛⲟⲩ. ⲁϥⲟⲩⲉϩⲥⲁϩⲛⲉ ⲉⲧⲣⲉⲩϯ ⲛⲁⲥ ⲉⲩⲱⲙ.
56 Ẹnu sì ya àwọn òbí rẹ̀: ṣùgbọ́n ó kìlọ̀ fún wọn pé, kí wọn má ṣe wí fún ẹnìkan ohun tí a ṣe.
ⲛ̅ⲋ̅ⲁⲩⲣ̅ϣⲡⲏⲣⲉ ⲇⲉ ⲛ̅ϭⲓⲛⲉⲥⲓ̈ⲟⲧⲉ ⲛ̅ⲧⲟϥ ⲇⲉ ⲁϥⲡⲁⲣⲁⲅⲅⲉⲓⲗⲉ ⲛⲁⲩ ⲉⲧⲙ̅ϫⲉⲡⲉⲛⲧⲁϥϣⲱⲡⲉ ⲗ̅ⲗⲁⲁⲩ·

< Luke 8 >