< Luke 7 >

1 Nígbà tí ó sì parí gbogbo ọ̀rọ̀ rẹ̀ fun àwọn ènìyàn, ó wọ Kapernaumu lọ.
A ol te pilnam kah a hna ah boeih a baetawt sak phoeiah tah Kapernaum la kun.
2 Ọmọ ọ̀dọ̀ balógun ọ̀rún kan, tí ó ṣọ̀wọ́n fún un, ṣàìsàn, ó sì ń kú lọ.
Te vaengah rhalboei kah sal pakhat te tloh a khueh tih dalh duek. Anih tah a taengah a khoelh la om.
3 Nígbà tí ó sì gbúròó Jesu, ó rán àwọn àgbàgbà Júù sí i, ó ń bẹ̀ ẹ́ pé kí ó wá mú ọmọ ọ̀dọ̀ òun láradá.
A kawng a yaak coeng dongah Judah patong rhoek te Jesuh taengla a tueih tih a sal hoeih sak ham halo dae saeh tila a cael.
4 Nígbà tí wọ́n sì dé ọ̀dọ̀ Jesu, wọ́n fi ìtara bẹ̀ ẹ́, pé, “Ó yẹ ní ẹni tí òun ìbá ṣe èyí fún.
Te rhoek loh Jesuh te a paan uh phoeiah ngahngah a cael uh tih, “Anih te doedan tueng la om he,
5 Nítorí tí ó fẹ́ràn orílẹ̀-èdè wa, ó sì ti kọ́ Sinagọgu kan fún wa.”
mah namtu a lungnah dongah tunim te khaw anih long ni mamih ham a sak,” a ti nah.
6 Jesu sì ń bá wọn lọ. Nígbà tí kò sì jìn sí etí ilé mọ́, balógun ọ̀rún náà rán àwọn ọ̀rẹ́ sí i, pé, “Olúwa, má ṣe yọ ara rẹ lẹ́nu, nítorí tí èmi kò yẹ tí ìwọ ìbá fi wọ abẹ́ òrùlé mi.
Te dongah amih te Jesuh loh a caeh puei tih im pha ham pataeng hla voel pawh. Te vaengah rhalboei loh a puei rhoek te a tueih tih, “Boeipa, na tawnba mai pawt nim? Ka imphu ah na kun ham khaw a koihvaih la ka om moenih.
7 Nítorí náà èmi kò sì rò pé èmi náà yẹ láti tọ̀ ọ́ wá, ṣùgbọ́n sọ ní gbólóhùn kan, a ó sì mú ọmọ ọ̀dọ̀ mi láradá.
Namah te kam paan ham khaw ka tueng moenih. Tedae ol kamat mah thui lamtah ka sal he hoeih bitni.
8 Nítorí èmi náà pẹ̀lú jẹ́ ẹni tí a fi sí abẹ́ àṣẹ, tí ó ní ọmọ-ogun lẹ́yìn mi, mo sì wí fún ọ̀kan pé, ‘Lọ,’ a sì lọ; àti fún òmíràn pé, ‘Wá,’ a sì wá; àti fún ọmọ ọ̀dọ̀ mi pé, ‘Ṣe èyí,’ a sì ṣe é.”
Kai khaw saithainah aka khueh hmuikah aka om hlang pakhat van ni. Kamah hmuiah rhalkap rhoek khaw om van. Te dongah pakhat te “Cet” ka ti nah tih cet, pakhat te, “Ha lo lah,” ka ti nah tih ha lo mai. Te dongah tahae kah bangla na saii pah vetih ka sal te a saii mako,” a ti nah.
9 Nígbà tí Jesu gbọ́ nǹkan wọ̀nyí, ẹnu sì yà, ó sì yípadà sí ìjọ ènìyàn tí ń tọ̀ ọ́ lẹ́yìn, ó wí pé, “Mo wí fún yín pé èmi kò rí irú ìgbàgbọ́ ńlá bí èyí nínú àwọn ènìyàn Israẹli.”
Te te Jesuh loh a yaak vaengah a ngaihmang. Te dongah anih aka vai hlangping te a mael thil tih, “Nangmih taengah ka thui, Israel khuiah pataeng tangnah heyet ka hmuh moenih,” a ti nah.
10 Nígbà tí àwọn oníṣẹ́ sì padà sí ilé, wọ́n bá ọmọ ọ̀dọ̀ náà tí ń ṣàìsàn, ara rẹ̀ ti dá.
A tueih rhoek te im la a bal uh vaengah rhalboei kah a sal te sading la a hmuh uh.
11 Ní ọjọ́ kejì, ó lọ sí ìlú kan tí a ń pè ní Naini, àwọn púpọ̀ nínú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ sì ń bá a lọ àti ọ̀pọ̀ ìjọ ènìyàn.
A vuen a pha neh Nain la a khue kho pakhat la cet. Te vaengah anih te a hnukbang rhoek neh hlangping loh muep a puei uh.
12 Bí ó sì ti súnmọ́ ẹnu ibodè ìlú náà, sì kíyèsi i, wọ́n ń gbé òkú ọkùnrin kan jáde, ọmọ kan ṣoṣo náà tí ìyá rẹ̀ bí, ó sì jẹ́ opó: ọ̀pọ̀ ìjọ ènìyàn ìlú náà sì wà pẹ̀lú rẹ̀.
Khopuei vongka neh a yoei vaengah manu pakhat tah capa khueh duen te a duek pah tih tarha hang khuen. Anih te nuhmai la om dae, khopuei kah hlangping loh anih taengah muep omuh.
13 Nígbà tí Olúwa sì rí i, àánú rẹ̀ ṣe é, ó sì wí fún un pé, “Má sọkún mọ́.”
Anih te a hmuh vaengah Boeipa loh anih soah a thinphat tih, “Rhap boeh,” a ti nah.
14 Ó sì wá, ó sì fi ọwọ́ tọ́ pósí náà: àwọn tí ń rù ú dúró jẹ́. Ó sì wí pé, “Ọ̀dọ́mọkùnrin, mo wí fún ọ, dìde!”
A paan tih rhoep te a taek vaengah aka kawt rhoek loh cawt a pai puei uh. Te phoeiah, “Cadong namah, thoo laeh ka ti,” a ti nah.
15 Ẹni tí ó kú náà sì dìde jókòó, ó bẹ̀rẹ̀ sí i fọhùn. Ó sì fà á lé ìyá rẹ̀ lọ́wọ́.
Te dongah aka duek te ngol tih pahoi cal. Te phoeiah anih te a manu taengla a paek.
16 Ẹ̀rù sì ba gbogbo wọn: wọ́n sì yin Ọlọ́run lógo, pé, “Wòlíì ńlá dìde nínú wa,” àti pé, “Ọlọ́run sì wá bẹ àwọn ènìyàn rẹ̀ wò!”
Te vaengah rhihnah loh boeih a thing uh. Te dongah, “Mamih taengah tonghma puei ha thoeng coeng, Pathen loh a pilnam a hip,” a ti uh tih Pathen a thangpom uh.
17 Òkìkí rẹ̀ sì kàn ní gbogbo Judea, àti gbogbo agbègbè tí ó yí i ká.
Te dongah Jesuh kah ol loh Judah pum neh te rhoek pingpang boeih a pha.
18 Àwọn ọmọ-ẹ̀yìn Johanu sì sọ gbogbo nǹkan wọ̀nyí fún un.
Te rhoek boeih te a hnukbang rhoek loh Johan taengla a puen pauh. Te dongah Johan loh a hnukbang rhoek khuikah panit te a khue.
19 Nígbà tí Johanu sì pe àwọn méjì nínú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, ó rán wọn sọ́dọ̀ Olúwa, wí pé, “Ìwọ ni ẹni tí ń bọ̀, tàbí kí a máa retí ẹlòmíràn?”
Boeipa taengla a tueih tih, “Aka pawk la na om coeng atah a tloe ka lamso pueng aya?” a ti nah.
20 Nígbà tí àwọn ọkùnrin náà sì dé ọ̀dọ̀ rẹ̀, wọ́n wí pé, “Johanu onítẹ̀bọmi rán wa sọ́dọ̀ rẹ, pé, ‘Ìwọ ni ẹni tí ń bọ̀, tàbí kí a máa retí ẹlòmíràn?’”
Tekah hlang rhoi loh Jesuh te a paan rhoi tih, “Tuinuem Johan loh nang taengla kaimih rhoi n'tueih tih, 'Aka pawk la na om atah a tloe ka lamso aya? ' a ti,” a ti nah.
21 Ní wákàtí náà, ó sì ṣe ìmúláradá ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn nínú àìsàn, àti ààrùn, àti ẹ̀mí búburú; ó sì fi ìríran fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn afọ́jú.
Te vaeng tue ah tlohtat khaw, nganboh khaw, mueihla thae muep a hoeih sak. Mikdael rhoek khaw muep a hmuh sak.
22 Jesu sì dáhùn ó wí fún wọn pé, “Ẹ padà lọ, ẹ ròyìn nǹkan tí ẹ̀yin rí, tí ẹ̀yin sì gbọ́ fún Johanu: àwọn afọ́jú ń ríran, àwọn amúnkùn ún rìn, a sọ àwọn adẹ́tẹ̀ di mímọ́, àwọn adití ń gbọ́rọ̀, a ń jí àwọn òkú dìde, àti fún àwọn òtòṣì ni à ń wàásù ìyìnrere.
Te phoeiah amih te a doo tih, “Cet uh lamtah na hmuh neh na yaak te Johan taengla puen pah. Mikdael loh a hmuh coeng, aka khawn loh pongpa coeng, hmaibae khaw cing tih hnapang loh a yaak, aka duek rhoek khaw thoo uh coeng, khodaeng loh olthangthen a yaak coeng.
23 Alábùkún fún sì ni ẹnikẹ́ni tí kò kọsẹ̀ lára mi.”
Tedae kai kongah a khah pawt te tah yoethen la om,” a ti nah.
24 Nígbà tí àwọn oníṣẹ́ Johanu padà lọ, ó bẹ̀rẹ̀ sí í sọ fún ìjọ ènìyàn ní ti Johanu pé, “Kí ni ẹ̀yin jáde lọ sí ijù lọ wò? Ewéko tí afẹ́fẹ́ ń mì?
Johan kah puencawn rhoi te a caeh phoeiah Johan kawng neh hlangping te, “Khosoek la na caeh uh vaengah balae na hmuh uh? Khohli kah a hinghuen capu a?
25 Ṣùgbọ́n kín ni ẹ̀yin jáde lọ wò? Ọkùnrin tí a wọ̀ ní aṣọ fẹ́lẹ́fẹ́lẹ́? Wò ó, àwọn tí á wọ̀ ní aṣọ ògo, tí wọ́n sì ń jayé, ń bẹ ní ààfin ọba!
Tedae himbai hnal neh aka phuekhlak uh hlang te hmuh ham nim na caeh uh? Rhuepom pueinak neh pumdomnah dongah kho aka sa rhoek tah manghai-im ah om uh lah ko ke.
26 Ṣùgbọ́n kí ni ẹ̀yin jáde lọ wò? Wòlíì? Lóòótọ́ ni mo wí fún yín, ó sì ju wòlíì lọ!
Tedae na caeh uh te balae na hmuh uh? Tonghma a? Ue ta, nangmih taengah tonghma lakah khaw olpuei ka ti rhoe ta.
27 Èyí yìí ni ẹni tí a ti kọ̀wé nítorí rẹ̀ pé: “‘Wò ó, èmi yóò rán oníṣẹ́ mi síwájú rẹ; ẹni tí yóò tún ọ̀nà rẹ ṣe níwájú rẹ.’
A kawng la a daek pah te anih ni. Ka puencawn te Nang hmai ah kan tueih. Anih long ni nang hmaikah na longpuei te a rhoekbah eh.
28 Mo wí fún yín nínú àwọn tí a bí nínú obìnrin, kò sí wòlíì tí ó pọ̀ ju Johanu Onítẹ̀bọmi lọ, ṣùgbọ́n ẹni tí ó kéré jùlọ ní ìjọba Ọlọ́run, ó pọ̀jù ú lọ.”
Nangmih taengah kan thui, huta kah a cun rhoek khuiah Johan lakah aka tanglue a om moenih. Tedae Pathen ram khuiah a yit koek long pataeng anih lakah tanglue la om,” pahoi a ti nah.
29 (Gbogbo àwọn ènìyàn tí ó gbọ́ àti àwọn agbowó òde, wọ́n dá Ọlọ́run láre, nítorí tí a fi ìtẹ̀bọmi Johanu tẹ̀ wọn bọ mi.
Aka ya pilnam boeih neh mangmucoi rhoek long tah Pathen te a tang sak uh tih Johan kah baptisma neh nuem uh.
30 Ṣùgbọ́n àwọn Farisi àti àwọn amòfin kọ ète Ọlọ́run fún ara wọn, a kò bamitiisi wọn lọ́dọ̀ rẹ̀.)
Tedae Pharisee rhoek neh olming rhoek long tah Pathen kah mangtaengnah te amamih ham a aal uh dongah Johan lamloh nuem uh pawh.
31 Jesu sì wí pé, “Kí ni èmi ìbá fi àwọn ènìyàn ìran yìí wé? Kí ni wọ́n sì jọ?
Te dongah tahae cadil hlang rhoek ba nen nim ka thuidoek lah vetih unim phek a loh uh he?
32 Wọ́n dàbí àwọn ọmọ kékeré tí ó jókòó ní ibi ọjà, tí wọ́n sì ń kọ sí ara wọn, tí wọ́n sì ń wí pé, “‘Àwa fọn fèrè fún yín, ẹ̀yin kò jó, àwa sì ṣọ̀fọ̀ fún yín, ẹ̀yin kò sọkún!’
Hnoyoih hmuen ah ngoluh tih khat neh khat aka khue uh thae camoe rhoek phek a lohuh. Amih loh, “Nangmih ham phavi kan tum uh dae na lam uh pawh. Kan hlai uh akhaw na rhap uh pawh,” a ti uh.
33 Nítorí Johanu Onítẹ̀bọmi wá, kò jẹ àkàrà, bẹ́ẹ̀ ni kò sì mu ọtí wáìnì, ẹ̀yin sì wí pé, ‘Ó ní ẹ̀mí èṣù?’
Tuinuem Johan ha pawk tih buh ca pawh, misur khaw a ok pawt hatah, ' Rhaithae a khueh,’ na ti uh.
34 Ọmọ ènìyàn dé, ó ń jẹ, ó sì ń mu, ẹ̀yin sì wí pé, ‘Wò ó, ọ̀jẹun, àti ọ̀mùtí, ọ̀rẹ́ àwọn agbowó òde àti àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀!’
Hlang capa loh ha pawk tih a caak, a ok hatah, ' hlang khaw carhut neh yumi la he, mangmu aka coi neh hlangtholh rhoek kah a paya ni, ' na ti uh.
35 Ṣùgbọ́n ọgbọ́n ni a dá láre nípasẹ̀ ọmọ rẹ.”
Tedae cueihnah loh a ca rhoek te boeih a tang sak.
36 Farisi kan sì rọ̀ ọ́ kí ó wá bá òun jẹun, ó sì wọ ilé Farisi náà lọ ó sì jókòó láti jẹun.
Pharisee pakhat loh Jesuh te amah taengah buh ca la a cael. Te dongah Pharisee im la kun tih a vael van.
37 Sì kíyèsi i, obìnrin kan wà ní ìlú náà, ẹni tí i ṣe ẹlẹ́ṣẹ̀, nígbà tí ó mọ̀ pé Jesu jókòó, ó ń jẹun ní ilé Farisi, ó mú ṣágo kékeré alabasita òróró ìkunra wá,
Pharisee im ah buh a vael te kho ah aka om hlangtholh nu loh lawt a ming.
38 Ó sì dúró tì í lẹ́bàá ẹsẹ̀ rẹ̀ lẹ́yìn, ó ń sọkún, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí i fi omijé wẹ̀ ẹ́ ní ẹsẹ̀, ó sì ń fi irun orí rẹ nù ún nù, ó sì ń fi ẹnu kò ó ní ẹsẹ̀, ó sì ń fi òróró kùn wọ́n.
Te dongah botui te lungbok um dongah a khuen tih a rhah doela Jesuh kho tang ah pai. Te phoeiah Jesuh kho te mikphi neh koe a sul tih a lu sam neh a huih pah. A kho te a mok pah tih botui neh a hluk pah.
39 Nígbà tí Farisi tí ó pè é sì rí i, ó wí nínú ara rẹ̀ pé, “Ọkùnrin yìí ìbá ṣe wòlíì, ìbá mọ ẹni àti irú ẹni tí obìnrin yìí jẹ́ tí ń fi ọwọ́ kàn an, nítorí ẹlẹ́ṣẹ̀ ni.”
Anih aka khue Pharisee loh a hmuh vaengah a khuiah a toel tih, “Anih he tonghma la om koinih amah aka taek huta te, unim?, mebangnim? ti khaw a ming ni ta, hlangtholh dae ni ke,” a ti.
40 Jesu sì dáhùn, ó wí fún un pé, “Simoni, Mo ní ohun kan sọ fún ọ.” Ó sì dáhùn pé, “Olùkọ́ máa wí.”
Te dongah Jesuh loh anih te a doo tih, “Simon, nang taengah thui ham bet ka khueh,” a ti nah. Anih long khaw, “Thui lah saw saya,” a ti nah.
41 “Ayánilówó kan wà tí ó ní ajigbèsè méjì: ọ̀kan jẹ ẹ́ ní ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta owó idẹ, èkejì sì jẹ ẹ́ ní àádọ́ta.
Puhlah pakhat taengah purhong panit om tih, pakhat loh denari yanga, pakhat loh sawmnga a ba.
42 Nígbà tí wọn kò sì ní ohun tí wọn ó san, ó dáríjì àwọn méjèèjì. Wí nínú àwọn méjèèjì, ta ni yóò fẹ́ ẹ jù?”
Tedae a thuung nah a khueh rhoi pawt dongah vik a yoe sak. Te vaengah amih rhoi khuiah ulae puhlah a lungnah ngai eh?,” a ti nah.
43 Simoni dáhùn wí pé, “Mo ṣe bí ẹni tí ó dáríjì jù ni.” Jesu wí fún un pé, “Ìwọ ti dájọ́ náà dáradára.”
Simon loh a doo tih, “A yet a yoe sak te ka ti,” a ti nah. Te dongah anih te Jesuh loh, “Buelh na naai het coeng,” a ti nah.
44 Ó sì yípadà sí obìnrin náà, ó wí fún Simoni pé, “Wo obìnrin yìí? Èmi wọ ilé rẹ, ìwọ kò fi omi wẹ ẹsẹ̀ fún mi: ṣùgbọ́n, omijé rẹ̀ ni ó fi ń rọ̀jò sí mi lẹ́sẹ̀ irun orí ni ó fi ń nù wọ́n nù.
Te phoeiah huta taengla mael tih Simon te, “Huta he na hmuh a? Nang im khuila ka kun dae, kai he kho silh tui nan paek moenih. Anih long tah kai kho he mikphi neh a sul tih a sam neh a huih.
45 Ìwọ kò fi ìfẹnukonu fún mi: ṣùgbọ́n òun, nígbà tí mo ti wọ ilé, kò dẹ́kun ẹnu fífi kò mí lẹ́sẹ̀.
Kai taengah moknah khaw nang khueh pawh, anih long tah ka kun parhi te kai kho a mok he toeng voel pawh.
46 Ìwọ kò fi òróró pa mí lórí, ṣùgbọ́n òun ti fi òróró pa mí lẹ́sẹ̀.
Ka lu he situi nan hluk pawh, anih long tah ka kho he botui neh a hluk.
47 Ǹjẹ́ mo wí fún ọ, A dárí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ tí ó pọ̀ jì í: nítorí tí ó ní ìfẹ́ púpọ̀: ẹni tí a sì dárí díẹ̀ jì, òun náà ni ó ní ìfẹ́ díẹ̀.”
Te dongah ni namah taengah kan thui, anih tah tholh a yet loh a hlah coeng dongah muep a lungnah. Tedae a yool a hlah pah long te tah a yool ni a lungnah,” a ti nah.
48 Ó sì wí fún un pé, “A dárí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ jì ọ́!”
Te phoeiah huta te khaw, “Na tholhnah loh n'hlah coeng,” a ti nah.
49 Àwọn tí ó bá a jókòó jẹun sì bẹ̀rẹ̀ sí í rò nínú ara wọn pé, “Ta ni èyí tí ń dárí ẹ̀ṣẹ̀ ji ni pẹ̀lú?”
Te vaengah aka vael rhoek loh amamih khuiah, “Tholh aka hlah pah te ulae aka om he,” pahoi a ti uh.
50 Ó sì dáhùn wí fún obìnrin náà pé, “Ìgbàgbọ́ rẹ gbà ọ́ là, máa lọ ní àlàáfíà.”
Huta te khaw, “Na tangnah loh nang ng'khang coeng, ngaimong la cet laeh,” a ti nah.

< Luke 7 >