< Luke 5 >

1 Ó sì ṣe, nígbà tí ìjọ ènìyàn súnmọ́ ọn láti gbọ́ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, tí ó sì dúró létí adágún Genesareti.
ⲁ̅ⲀⲤϢⲰⲠⲒ ⲆⲈ ⲈⲦⲀⲨⲐⲰⲞⲨϮ ⲈϪⲰϤ ⲚϪⲈⲚⲒⲘⲎϢ ⲞⲨⲞϨ ⲈⲤⲰⲦⲈⲘ ⲈⲠⲒⲤⲀϪⲒ ⲚⲦⲈⲪⲚⲞⲨϮ ⲚⲐⲞϤ ⲆⲈ ⲚⲀϤⲞϨⲒ ⲈⲢⲀⲦϤ ⲠⲈ ϦⲀⲦⲈⲚ ϮⲖⲨⲘⲚⲎ ⲚⲦⲈⲄⲈⲚⲚⲎⲌⲀⲢⲈⲐ.
2 Ó rí ọkọ̀ méjì ti o wá létí adágún: èyí tí àwọn apẹja ti sọ̀kalẹ̀ kúrò nínú wọn, nítorí tí wọ́n ń fọ àwọ̀n wọn.
ⲃ̅ⲞⲨⲞϨ ⲀϤⲚⲀⲨ ⲈϪⲞⲒ ⲂⲈⲨⲘⲞⲚⲒ ϦⲀⲦⲈⲚ ϮⲖⲨⲘⲚⲎ ⲚⲒⲞⲨⲞϨⲒ ⲆⲈ ⲈⲦⲀⲨⲒ ⲈϨⲢⲎⲒ ϨⲒⲰⲦⲞⲨ ⲚⲀⲨⲢⲰϦⲒ ⲚⲚⲞⲨϢⲚⲎⲞⲨ ⲠⲈ.
3 Ó sì wọ ọ̀kan nínú àwọn ọkọ̀ náà, tí í ṣe ti Simoni, ó sì bẹ̀ ẹ́ kí ó tì í sí ẹ̀yìn díẹ̀ kúrò ní ilẹ̀. Ó sì jókòó, ó sì ń kọ́ ìjọ ènìyàn láti inú ọkọ̀ náà.
ⲅ̅ⲀϤⲞⲖϤ ⲚⲞⲨⲀⲒ ⲚⲚⲒϪⲞⲒ ⲈⲪⲀ ⲤⲒⲘⲰⲚ ⲠⲈ ⲀϤϪⲞⲤ ⲚⲀϤ ⲈⲐⲢⲈϤϨⲈⲚϤ ⲤⲀⲂⲞⲖ ⲘⲠⲒⲬⲢⲞ ⲚⲞⲨⲔⲞⲨϪⲒ ⲈⲦⲀϤϨⲈⲘⲤⲒ ⲆⲈ ⲚⲀϤϮⲤⲂⲰ ⲚⲚⲒⲘⲎ ϢⲈⲂⲞⲖ ϨⲒ ⲠⲒϪⲞⲒ.
4 Bí ó sì ti dákẹ́ ọ̀rọ̀ sísọ, ó wí fún Simoni pé, “Tì í sí ibú, kí o sì ju àwọ̀n yín sí ìsàlẹ̀ fún àkópọ̀.”
ⲇ̅ⲈⲦⲀϤⲞⲨⲰ ⲆⲈ ⲈϤⲤⲀϪⲒ ⲠⲈϪⲀϤ ⲚⲤⲒⲘⲰⲚ ϪⲈ ⲀⲘⲞⲨ ⲈⲂⲞⲖ ⲈⲠⲈⲦϢⲎⲔ ⲞⲨⲞϨ ⲬⲀ ⲚⲈⲦⲈⲚϢⲚⲎ ⲞⲨ ⲈϦⲢⲎⲒ ⲈⲞⲨϪⲞⲢϪⲤ.
5 Simoni sì dáhùn ó sì wí fún un pé, “Olùkọ́ni, gbogbo òru ni àwa fi ṣiṣẹ́, àwa kò sì mú nǹkan kan: ṣùgbọ́n nítorí ọ̀rọ̀ rẹ èmi ó ju àwọ̀n náà sí ìsàlẹ̀.”
ⲉ̅ⲞⲨⲞϨ ⲀϤⲈⲢⲞⲨⲰ ⲚϪⲈⲤⲒⲘⲰⲚ ⲠⲈϪⲀϤ ϪⲈ ⲠⲒⲢⲈϤϮⲤⲂⲰ ⲠⲒⲈϪⲰⲢϨ ⲦⲎⲢϤ ⲀⲚⲀⲒϤ ⲚϦⲞⲤⲒ ⲘⲠⲈⲚⲦⲀϨⲞ ϦⲈⲚⲠⲈⲔⲤⲀϪⲒ ⲆⲈ ⲦⲈⲚⲚⲀⲬ ⲰⲚⲚⲒϢⲚⲎⲞⲨ ⲈϦⲢⲎⲒ.
6 Nígbà tí wọ́n sì ti ṣe èyí, wọ́n kó ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹja: àwọ̀n wọn sì ya.
ⲋ̅ⲈⲦⲀⲨⲒⲢⲒ ⲆⲈ ⲘⲪⲀⲒ ⲀⲨⲐⲰⲞⲨϮ ⲚⲞⲨⲘⲎ ϢⲚⲦⲈⲂⲦ ⲈⲚⲀϢⲰϤ ⲚⲀⲨⲚⲀⲪⲰϦ ⲆⲈ ⲠⲈ ⲚϪⲈⲚⲒϢⲚⲎⲞⲨ.
7 Wọ́n sì pe àwọn ẹgbẹ́ wọn, tí ó wà nínú ọkọ̀ kejì, kí wọn kí ó wá ràn wọ́n lọ́wọ́. Wọ́n sì wá, wọ́n kó ẹja ọkọ̀ méjèèjì sì kún, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí í rì.
ⲍ̅ⲞⲨⲞϨ ⲀⲨϬⲰⲢⲈⲘ ⲈⲚⲞⲨϢⲪⲎⲢ ⲚⲎ ⲈⲦϨⲒ ⲠⲒⲔⲈϪⲞⲒ ϨⲒⲚⲀ ⲚⲦⲞⲨⲒ ⲚⲦⲞⲨϮⲦⲞⲦⲞⲨ ⲚⲈⲘⲰⲞⲨ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲨⲒ ⲀⲨⲘⲀϨ ⲠⲒϪⲞⲒ ⲂϨⲰⲤⲦⲈ ⲚⲦⲞⲨⲈⲢϨⲎⲦⲤ ⲚⲰⲘⲤ.
8 Nígbà tí Simoni Peteru sì rí i, ó wólẹ̀ lẹ́bàá eékún Jesu, ó wí pé, “Lọ kúrò lọ́dọ̀ mi Olúwa; nítorí ẹlẹ́ṣẹ̀ ni mí.”
ⲏ̅ⲈⲦⲀϤⲚⲀⲨ ⲆⲈ ⲚϪⲈⲤⲒⲘⲰⲚ ⲠⲈⲦⲢⲞⲤ ⲀϤϨⲒⲦϤ ϦⲀⲦⲈⲚ ⲚⲈⲚϬⲀⲖⲀⲨϪ ⲚⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲈϤϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ϪⲈ ⲘⲀϢⲈ ⲚⲀⲔ ⲈⲂⲞⲖ ϨⲀⲢⲞⲒ ⲠⲀϬⲞⲒⲤ ϪⲈ ⲀⲚⲞⲔ ⲞⲨⲢⲰⲘⲒ ⲚⲢⲈϤⲈⲢⲚⲞⲂⲒ.
9 Ẹnu sì yà wọ́n, àti gbogbo àwọn tí ń bẹ pẹ̀lú rẹ̀, fún àkópọ̀ ẹja tí wọ́n kó,
ⲑ̅ⲞⲨϨⲞϮ ⲄⲀⲢ ⲀⲤⲦⲀϨⲞϤ ⲚⲈⲘ ⲞⲨⲞⲚ ⲚⲒⲂⲈⲚ ⲈⲐⲚⲈⲘⲀϤ ⲈϪⲈⲚ ϮϪⲞⲢϪⲤ ⲚⲦⲈⲚⲒⲦⲈⲂⲦ ⲈⲦⲀⲨⲦⲀϨⲰⲞⲨ.
10 bẹ́ẹ̀ ni Jakọbu àti Johanu àwọn ọmọ Sebede, tí ń ṣe alábákẹ́gbẹ́ Simoni. Jesu sì wí fún Simoni pé, “Má bẹ̀rù; láti ìsinsin yìí lọ ìwọ ó máa mú ènìyàn.”
ⲓ̅ⲠⲀⲒⲢⲎϮ ⲆⲈ ⲞⲚ ⲠⲒⲔⲈⲒⲀⲔⲰⲂⲞⲤ ⲚⲈⲘ ⲒⲰⲀⲚⲚⲎⲤ ⲚⲒϢⲎⲢⲒ ⲚⲦⲈⲌⲈⲂⲈⲆⲈⲞⲤ ⲚⲎ ⲈⲚⲀⲨⲞⲒ ⲚϢⲪⲎⲢ ⲈⲤⲒⲘⲰⲚ ⲠⲈϪⲈ ⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲚⲤⲒⲘⲰⲚ ϪⲈ ⲘⲠⲈⲢⲈⲢϨⲞϮ ⲒⲤϪⲈⲚ ϮⲚⲞⲨ ⲄⲀⲢ ⲈⲔⲈϢⲰⲠⲒ ⲚⲞⲨⲞϨⲒ ⲚⲢⲈϤⲦⲀϨⲈ ⲢⲰⲘⲒ.
11 Nígbà tí wọ́n sì ti mú ọkọ̀ wọn dé ilẹ̀, wọ́n fi gbogbo rẹ̀ sílẹ̀, wọ́n sì tọ̀ ọ́ lẹ́yìn lọ.
ⲓ̅ⲁ̅ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀⲨⲤⲈⲔ ⲚⲒϢⲚⲎⲞⲨ ⲈⲠⲒⲬⲢⲞ ⲀⲨⲬⲀ ϨⲰⲂ ⲚⲒⲂⲈⲚ ⲚⲤⲰⲞⲨ ⲀⲨⲞⲨⲀϨⲞⲨ ⲚⲤⲰϤ.
12 Ó sì ṣe, nígbà tí Jesu wọ ọ̀kan nínú àwọn ìlú náà, kíyèsi i, ọkùnrin kan tí ẹ̀tẹ̀ bò wa síbẹ̀: nígbà tí ó rí Jesu, ó wólẹ̀, ó sì ń bẹ̀ ẹ́, wí pé, “Olúwa, bí ìwọ bá fẹ́, ìwọ lè sọ mí di mímọ́.”
ⲓ̅ⲃ̅ⲀⲤϢⲰⲠⲒ ⲆⲈ ⲈⲦⲀⲨⲒ ⲈϦⲞⲨⲚ ⲈⲞⲨⲒ ⲚⲚⲒⲂⲀⲔⲒ ⲞⲨⲞϨ ⲒⲤ ⲞⲨⲢⲰⲘⲒ ⲈϤⲘⲈϨ ⲚⲤⲈϨⲦ ⲈⲦⲀϤⲚⲀⲨ ⲆⲈ ⲈⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲀϤϨⲒⲦϤ ⲈϪⲈⲚ ⲠⲈϤϨⲞ ⲈϤϮϨⲞ ⲈⲢⲞϤ ⲈϤϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ϪⲈ ⲠⲀϬⲞⲒⲤ ⲀⲔϢⲀⲚⲞⲨⲰϢ ⲞⲨⲞⲚ ϢϪⲞⲘ ⲘⲘⲞⲔ ⲈⲦⲞⲨⲂⲞⲒ.
13 Jesu sì na ọwọ́ rẹ̀, ó fi kàn án, ó ní, “Mo fẹ́, ìwọ di mímọ́!” Lójúkan náà ẹ̀tẹ̀ sì fi í sílẹ̀ lọ.
ⲓ̅ⲅ̅ⲞⲨⲞϨ ⲀϤⲤⲞⲨⲦⲈⲚ ⲦⲈϤϪⲒϪ ⲈⲂⲞⲖ ⲀϤϬⲒ ⲚⲈⲘⲀϤ ⲈϤϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ϪⲈ ϮⲞⲨⲰϢ ⲘⲀⲦⲞⲨⲂⲞ ⲞⲨⲞϨ ⲤⲀⲦⲞⲦϤ ⲀϤϢⲈ ⲚⲀϤ ⲈⲂⲞⲖ ϨⲀⲢⲞϤ ⲚϪⲈⲠⲒⲤⲈϨⲦ.
14 Ó sì kìlọ̀ fún u pé, “Kí ó má ṣe sọ fún ẹnìkan: ṣùgbọ́n kí ó lọ, kí ó sì fi ara rẹ̀ hàn fún àlùfáà, kí ó sì ta ọrẹ fún ìwẹ̀nùmọ́ rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí Mose ti pàṣẹ gẹ́gẹ́ bi ẹ̀rí fun wọn.”
ⲓ̅ⲇ̅ⲚⲐⲞϤ ⲆⲈ ⲀϤϨⲞⲚϨⲈⲚ ⲚⲀϤ ⲈϤϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ϪⲈ ⲘⲠⲈⲢϪⲞⲤ ⲚϨⲖⲒ ⲀⲖⲖⲀ ⲘⲀϢⲈ ⲚⲀⲔ ⲘⲀⲦⲀⲘⲈ ⲠⲒⲞⲨⲎⲂ ⲈⲢⲞⲔ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲚⲒⲞⲨⲒ ⲈϪⲈⲚ ⲠⲈⲔⲦⲞⲨⲂⲞ ⲔⲀⲦⲀ ⲪⲢⲎϮ ⲈⲦⲀϤⲞⲨⲀϨⲤⲀϨⲚⲒ ⲚϪⲈⲘⲰⲨⲤⲎⲤ ⲈⲨⲘⲈⲦⲘⲈⲐⲢⲈ ⲚⲰⲞⲨ.
15 Ṣùgbọ́n òkìkí rẹ̀ ń kàn kálẹ̀: tó bẹ́ẹ̀ tí ọ̀pọ̀ ìjọ ènìyàn sì jùmọ̀ pàdé láti gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀, àti láti gba ìwòsàn lọ́dọ̀ rẹ̀ kúrò lọ́wọ́ àìlera wọn.
ⲓ̅ⲉ̅ⲀϤⲤⲰⲢ ⲆⲈ ⲈⲂⲞⲖ ⲚϨⲞⲨⲞ ⲚϪⲈⲠⲒⲤⲀϪⲒ ⲈⲐⲂⲎⲦϤ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲨⲐⲰⲞⲨϮ ⲚϪⲈϨⲀⲚⲚⲒϢϮ ⲘⲘⲎϢ ⲈⲤⲰⲦⲈⲘ ⲈⲢⲞϤ ⲞⲨⲞϨ ⲈⲈⲢⲪⲀϦⲢⲒ ⲈⲢⲰⲞⲨ ϦⲈⲚⲚⲞⲨϢⲰⲚⲒ.
16 Ṣùgbọ́n lọ́pọ̀ ìgbà ni Jesu a máa yẹra kúrò si ibi ìdákẹ́rọ́rọ́, òun á sì máa dá wà láti gbàdúrà.
ⲓ̅ⲋ̅ⲚⲐⲞϤ ⲆⲈ ⲚⲈϢⲀϤϢⲈ ⲚⲀϤ ⲈⲚⲒⲘⲀⲚϢⲀϤⲈ ⲚⲦⲈϤⲈⲢⲠⲢⲞⲤⲈⲨⲬⲈⲤⲐⲈ.
17 Ní ọjọ́ kan, bí ó sì ti ń kọ́ni, àwọn Farisi àti àwọn amòfin jókòó pẹ̀lú rẹ̀, àwọn tí ó ti àwọn ìletò Galili gbogbo, àti Judea, àti Jerusalẹmu wá: agbára Olúwa sì ń bẹ pẹ̀lú rẹ̀ láti mú wọn láradá.
ⲓ̅ⲍ̅ⲞⲨⲞϨ ⲀⲤϢⲰⲠⲒ ϦⲈⲚⲞⲨⲀⲒ ⲚⲚⲒⲈϨⲞⲞⲨ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲐⲞϤ ⲚⲀϤϮⲤⲂⲰ ⲠⲈ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲀⲨϨⲈⲘⲤⲒ ⲚϪⲈϨⲀⲚⲪⲀⲢⲒⲤⲈⲞⲤ ⲚⲈⲘ ϨⲀⲚⲢⲈϤϮⲤⲂⲰ ⲚⲦⲈⲠⲒⲚⲞⲘⲞⲤ ⲈⲀⲨⲒ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚϮⲄⲀⲖⲒⲖⲈⲀ ⲦⲎⲢⲤ ⲚⲈⲘ ϮⲒⲞⲨⲆⲈⲀ ⲚⲈⲘ ⲒⲈⲢⲞⲤⲀⲖⲎⲘ ⲞⲨⲞϨ ⲞⲨϪⲞⲘ ⲚⲦⲈⲠϬⲞⲒⲤ ⲚⲀⲤϢⲞⲠ ⲈⲠϪⲒⲚⲦⲀⲖϬⲰⲞⲨ.
18 Sá à sì kíyèsi i, àwọn ọkùnrin kan gbé ẹnìkan tí ó ní ààrùn ẹ̀gbà wà lórí àkéte: wọ́n ń wá ọ̀nà àti gbé e wọlé, àti láti tẹ́ ẹ síwájú Jesu.
ⲓ̅ⲏ̅ⲞⲨⲞϨ ⲒⲤ ϨⲎⲠⲠⲈ ⲀⲨⲒⲚⲒ ⲚϪⲈϨⲀⲚⲢⲰⲘⲒ ⲚⲞⲨⲀⲒ ⲈϤϢⲎⲖ ⲈⲂⲞⲖ ϨⲒϪⲈⲚ ⲞⲨϬⲖⲞϪ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲀⲨⲔⲰϮ ⲠⲈ ⲚⲤⲀⲈⲚϤ ⲈϦⲞⲨⲚ ⲞⲨⲞϨ ⲈⲬⲀϤ ⲘⲠⲈϤⲘⲐⲞ
19 Nígbà tí wọn kò sì rí ọ̀nà tí wọn ìbá fi gbé e wọlé nítorí ìjọ ènìyàn, wọ́n gbé e gun òkè àjà ilé lọ, wọ́n sọ̀ ọ́ kalẹ̀ sí àárín èrò ti òun ti àkéte rẹ̀ níwájú Jesu.
ⲓ̅ⲑ̅ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲈⲘⲠⲞⲨϪⲈⲘ ⲠⲒⲢⲎϮ ⲚⲈⲚϤ ⲈϦⲞⲨⲚ ⲈⲐⲂⲈ ⲠⲒⲘⲎϢ ⲀⲨϢⲈ ⲚⲰⲞⲨ ⲈϨⲢⲎⲒ ⲈϪⲈⲚ ⲠⲒϪⲈⲚⲈⲪⲰⲢ ⲀⲨⲬⲀϤ ⲈϦⲢⲎⲒ ⲚⲈⲘ ⲠⲒϬⲖⲞϪ ⲈⲂⲞⲖ ϨⲒϪⲈⲚ ⲠⲒⲖⲰⲂϢ ϦⲈⲚⲐⲘⲎϮ ⲘⲠⲈⲘⲐⲞ ⲚⲒⲎⲤⲞⲨⲤ.
20 Nígbà tí ó sì rí ìgbàgbọ́ wọn, ó wí pé, “Ọkùnrin yìí, a darí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ jì ọ́.”
ⲕ̅ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀϤⲚⲀⲨ ⲈⲠⲞⲨⲚⲀϨϮ ⲠⲈϪⲀϤ ⲘⲪⲎ ⲈⲦϢⲎⲖ ⲈⲂⲞⲖ ϪⲈ ⲪⲢⲰⲘⲒ ⲤⲈⲬⲎ ⲚⲀⲔ ⲈⲂⲞⲖ ⲚϪⲈⲚⲈⲔⲚⲞⲂⲒ.
21 Àwọn akọ̀wé àti àwọn Farisi bẹ̀rẹ̀ sí í gbèrò wí pé, “Ta ni eléyìí tí ń sọ ọ̀rọ̀-òdì? Ta ni ó lè dárí ẹ̀ṣẹ̀ ji ni bí kò ṣe Ọlọ́run nìkan ṣoṣo.”
ⲕ̅ⲁ̅ⲞⲨⲞϨ ⲀⲨⲈⲢϨⲎⲦⲤ ⲘⲘⲞⲔⲘⲈⲔ ⲚϪⲈⲚⲒⲤⲀϦ ⲚⲈⲘ ⲚⲒⲪⲀⲢⲒⲤⲈⲞⲤ ⲈⲨϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ϪⲈ ⲚⲒⲘ ⲠⲈ ⲪⲀⲒ ⲈⲦⲤⲀϪⲒ ⲘⲠⲀⲒϪⲈⲞⲨⲀ ⲚⲒⲘ ⲈⲦⲈ ⲞⲨⲞⲚ ϢϪⲞⲘ ⲘⲘⲞϤ ⲈⲬⲀ ⲚⲞⲂⲒ ⲈⲂⲞⲖ ⲈⲂⲎⲖ ⲈⲠⲒⲞⲨⲀⲒ ⲘⲘⲀⲨⲀⲦϤ ⲪⲚⲞⲨϮ.
22 Jesu sì mọ èrò inú wọn, ó dáhùn ó sì wí fún wọn pé, “Èéṣe tí ẹ fi ń ro nǹkan wọ̀nyí nínú ọkàn yín?
ⲕ̅ⲃ̅ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀϤⲈⲘⲒ ⲚϪⲈⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲈⲚⲞⲨⲘⲞⲔⲘⲈⲔ ⲀϤⲈⲢⲞⲨⲰ ⲠⲈϪⲀϤ ⲚⲰⲞⲨ ϪⲈ ⲈⲐⲂⲈⲞⲨ ⲦⲈⲦⲈⲚⲘⲞⲔⲘⲈⲔ ϦⲈⲚⲚⲈⲦⲈⲚϨⲎⲦ
23 Èwo ni ó yá jù: láti wí pé, ‘A dárí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ jì ọ́,’ tàbí láti wí pé, ‘Dìde kí ìwọ sì máa rìn’?
ⲕ̅ⲅ̅ⲞⲨ ⲈⲐⲘⲞⲦⲈⲚ ⲈϪⲞⲤ ϪⲈ ⲚⲈⲔⲚⲞⲂⲒ ⲤⲈⲬⲎ ⲚⲀⲔ ⲈⲂⲞⲖ ⲒⲈ ⲈϪⲞⲤ ϪⲈ ⲦⲰⲚⲔ ⲞⲨⲞϨ ⲘⲞϢⲒ.
24 Ṣùgbọ́n kí ẹ̀yin lè mọ̀ pé Ọmọ Ènìyàn ní agbára ní ayé láti dárí ẹ̀ṣẹ̀ ji ni.” Ó wí fún ẹlẹ́gbà náà pé, “Mo wí fún ọ, dìde, sì gbé àkéte rẹ, kí o sì máa lọ sí ilé!”
ⲕ̅ⲇ̅ϨⲒⲚⲀ ⲚⲦⲈⲦⲈⲚⲈⲘⲒ ϪⲈ ⲞⲨⲞⲚ ⲈⲢϢⲒϢⲒ ⲚⲦⲈⲠϢⲎⲢⲒ ⲘⲪⲢⲰⲘⲒ ϨⲒϪⲈⲚ ⲠⲒⲔⲀϨⲒ ⲈⲬⲀ ⲚⲞⲂⲒ ⲈⲂⲞⲖ ⲞⲨⲞϨ ⲠⲈϪⲀϤ ⲘⲪⲎ ⲈⲦϢⲎⲖ ⲈⲂⲞⲖ ϪⲈ ⲚⲐⲞⲔ ⲠⲈϮϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ⲚⲀⲔ ⲦⲰⲚⲔ ⲰⲖⲒ ⲘⲠⲈⲔϬⲖⲞϪ ⲞⲨⲞϨ ⲘⲀϢⲈ ⲚⲀⲔ ⲈⲠⲈⲔⲎⲒ.
25 Ó sì dìde lọ́gán níwájú wọn, ó gbé ohun tí ó dùbúlẹ̀ lé, ó sì lọ sí ilé rẹ̀, ó yin Ọlọ́run lógo.
ⲕ̅ⲉ̅ⲞⲨⲞϨ ⲤⲀⲦⲞⲦϤ ⲀϤⲦⲰⲚϤ ⲘⲠⲞⲨⲘⲐⲞ ⲈⲂⲞⲖ ⲀϤⲰⲖⲒ ⲘⲪⲎ ⲈⲚⲀϤⲚⲔⲞⲦ ϨⲒϪⲰϤ ⲀϤϢⲈ ⲚⲀϤ ⲈⲠⲈϤⲎⲒ ⲈϤϮⲰⲞⲨ ⲘⲪⲚⲞⲨϮ.
26 Ẹnu sì ya gbogbo wọn, wọ́n sì yin Ọlọ́run lógo, ẹ̀rù sì bà wọ́n, wọ́n ń wí pé, “Àwa rí ohun ìyanu lónìí.”
ⲕ̅ⲋ̅ⲞⲨⲞϨ ⲞⲨⲦⲰⲘⲦ ⲀϤϬⲒ ⲚⲞⲨⲞⲚ ⲚⲒⲂⲈⲚ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲀⲨϮⲰⲞⲨ ⲘⲪⲚⲞⲨϮ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲨⲘⲞϨ ⲚϨⲞϮ ⲈⲨϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ϪⲈ ⲀⲚⲚⲀⲨ ⲈϨⲀⲚϢⲪⲎⲢⲒ ⲘⲪⲞⲞⲨ.
27 Lẹ́hìn èyí, Jesu jáde lọ, ó sì rí agbowó òde kan tí à ń pè ní Lefi, ó jókòó sí ibi tí ó ti ń gba owó òde, Jesu sì wí fún un pé, “Tẹ̀lé mi,”
ⲕ̅ⲍ̅ⲘⲈⲚⲈⲚⲤⲀ ⲚⲀⲒ ⲆⲈ ⲀϤⲒ ⲈⲂⲞⲖ ⲞⲨⲞϨ ⲀϤⲚⲀⲨ ⲈⲞⲨⲦⲈⲖⲰⲚⲎⲤ ⲈⲠⲈϤⲢⲀⲚ ⲠⲈ ⲖⲈⲨⲒ ⲈϤϨⲈⲘⲤⲒ ϨⲒ ⲞⲨⲦⲈⲖⲰⲚⲒⲞⲚ ⲞⲨⲞϨ ⲠⲈϪⲀϤ ⲚⲀϤ ϪⲈ ⲘⲞϢⲒ ⲚⲤⲰⲒ.
28 Lefi sì fi ohun gbogbo sílẹ̀ ó sì ń tẹ̀lé e.
ⲕ̅ⲏ̅ⲞⲨⲞϨ ⲀϤⲬⲀ ϨⲰⲂ ⲚⲒⲂⲈⲚ ⲀϤⲦⲰⲚϤ ⲀϤⲘⲞϢⲒ ⲚⲤⲰϤ
29 Lefi sì ṣe àsè ńlá kan fún Jesu ní ilé rẹ̀, ọ̀pọ̀ àwọn agbowó òde àti àwọn mìíràn sì ń jẹun pẹ̀lú wọn.
ⲕ̅ⲑ̅ⲞⲨⲞϨ ⲖⲈⲨⲒ ⲀϤⲈⲢ ⲞⲨⲚⲒϢϮ ⲚϢⲞⲠⲤ ⲈⲢⲞϤ ⲚϦⲞⲨⲚ ϦⲈⲚⲠⲈϤⲎⲒ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲈⲞⲨⲞⲚ ⲞⲨⲚⲒϢϮ ⲘⲘⲎϢ ⲚⲦⲈⲚⲒⲦⲈⲖⲰⲚⲎⲤ ⲚⲈⲘ ϨⲀⲚⲔⲈⲬ ⲰⲞⲨⲚⲒ ⲈⲨⲢⲞⲦⲈⲂ ⲚⲈⲘⲰⲞⲨ.
30 Ṣùgbọ́n àwọn Farisi, àwọn olùkọ́ òfin tí ó jẹ́ ara wọn fi ẹ̀sùn kan àwọn ọmọ-ẹ̀yìn pe, “Èéṣe tí ẹ̀yin fi ń jẹun tí ẹ sì ń mú pẹ̀lú àwọn agbowó òde àti àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀.”
ⲗ̅ⲞⲨⲞϨ ⲚⲀⲨⲬⲢⲈⲘⲢⲈⲘ ⲚϪⲈⲚⲒⲪⲀⲢⲒⲤⲈⲞⲤ ⲚⲈⲘ ⲚⲒⲤⲀϦ ⲞⲨⲂⲈ ⲚⲈϤⲘⲀⲐⲎⲦⲎⲤ ⲈⲨϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ϪⲈ ⲈⲐⲂⲈⲞⲨ ⲦⲈⲦⲈⲚⲞⲨⲰⲘ ⲞⲨⲞϨ ⲦⲈⲦⲈⲚⲤⲰ ⲚⲈⲘ ⲚⲒⲦⲈⲖⲰⲚⲎⲤ ⲚⲈⲘ ⲚⲒⲢⲈϤⲈⲢⲚⲞⲂⲒ.
31 Jesu dáhùn ó wí fún wọn pé, “Ẹni tí ara rẹ̀ le kò nílò oníṣègùn, bí kò ṣe ẹni tí ara rẹ̀ kò dá.
ⲗ̅ⲁ̅ⲞⲨⲞϨ ⲀϤⲈⲢⲞⲨⲰ ⲚϪⲈⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲠⲈϪⲀϤ ⲚⲰⲞⲨ ϪⲈ ⲚⲎ ⲈⲦϪⲞⲢ ⲤⲈⲈⲢⲬⲢⲒⲀ ⲘⲠⲒⲤⲎⲒⲚⲒ ⲀⲚ ⲀⲖⲖⲀ ⲚⲎ ⲈⲐⲘⲞⲔϨ.
32 Èmí kò wá láti pe àwọn olódodo bí kò ṣe àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ sí ìrònúpìwàdà.”
ⲗ̅ⲃ̅ⲚⲈⲦⲀⲒⲒ ⲄⲀⲢ ⲀⲚ ⲈⲐⲀϨⲈⲘ ⲚⲒⲐⲘⲎⲒ ⲀⲖⲖⲀ ⲚⲒⲢⲈϤⲈⲢⲚⲞⲂⲒ ⲈⲨⲘⲈⲦⲀⲚⲞⲒⲀ.
33 Wọ́n wí fún pé, “Àwọn ọmọ-ẹ̀yìn Johanu a máa gbààwẹ̀, wọn a sì máa gbàdúrà, bẹ́ẹ̀ pẹ̀lú sì ni àwọn ọmọ-ẹ̀yìn àwọn Farisi ṣùgbọ́n àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ a máa jẹ, wọn a sì máa mu pẹ̀lú.”
ⲗ̅ⲅ̅ⲚⲐⲰⲞⲨ ⲆⲈ ⲠⲈϪⲰⲞⲨ ⲚⲀϤ ϪⲈ ⲚⲒⲘⲀⲐⲎ ⲦⲎⲤ ⲚⲦⲈⲒⲰⲀⲚⲚⲎⲤ ⲤⲈⲒⲢⲒ ⲚϨⲀⲚⲘⲎϢ ⲚⲚⲎⲤⲦⲒⲀ ⲚⲈⲘ ϨⲀⲚⲦⲰⲂϨ ⲠⲀⲒⲢⲎϮ ⲞⲚ ⲚⲀ ⲚⲒⲪⲀⲢⲒⲤⲈⲞⲤ ⲚⲈⲔⲘⲀⲐⲎⲦⲎⲤ ⲆⲈ ⲚⲐⲰⲞⲨ ⲤⲈⲞⲨⲰⲘ ⲤⲈⲤⲰ.
34 Jesu sì dáhùn ó wí fún wọn pé, “Ǹjẹ́ ó ṣe é ṣe kí àwọn àlejò ọkọ ìyàwó máa gbààwẹ̀ nígbà tí ọkọ ìyàwó wà pẹ̀lú wọn bí?
ⲗ̅ⲇ̅ⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲆⲈ ⲠⲈϪⲀϤ ⲚⲰⲞⲨ ϪⲈ ⲘⲎ ⲞⲨⲞⲚ ϢϪⲞⲘ ⲘⲘⲰⲦⲈⲚ ⲈⲐⲢⲈ ⲚⲈⲚϢⲎⲢⲒ ⲘⲠⲒⲠⲀⲦϢⲈⲖⲎ ⲦⲈⲢⲚⲎⲤⲦⲈⲨⲒⲚ ϨⲰⲤ ⲈⲠⲒⲠⲀⲦϢⲈⲖⲈⲦ ⲚⲈⲘⲰⲞⲨ.
35 Ṣùgbọ́n àkókò ń bọ̀ nígbà tí a ó gba ọkọ ìyàwó kúrò lọ́dọ̀ wọn, ní àwọn ọjọ́ wọ̀nyí ni wọn yóò gbààwẹ̀.”
ⲗ̅ⲉ̅ⲤⲈⲚⲎⲞⲨ ⲆⲈ ⲚϪⲈϨⲀⲚⲈϨⲞⲞⲨ ϨⲞⲦⲀⲚ ⲀⲨϢⲀⲚⲰⲖⲒ ⲘⲠⲒⲠⲀⲦϢⲈⲖⲈⲦ ⲈⲂⲞⲖ ϨⲀⲢⲰⲞⲨ ⲦⲞⲦⲈ ⲈⲨⲈⲈⲢⲚⲎⲤⲦⲈⲨⲒⲚ ϦⲈⲚⲚⲒⲈϨⲞⲞⲨ ⲈⲦⲈⲘⲘⲀⲨ.
36 Ó sì pa òwe yìí fún wọn wí pé, “Kò sí ẹni tó lè ya aṣọ tuntun kí ó sì rán mọ́, èyí tó ti gbó. Tí ó ba ṣe èyí, yóò ba aṣọ tuntun jẹ́, èyí tí ó tuntun náà kì yóò sì dọ́gba pẹ̀lú èyí tí ó ti gbó.
ⲗ̅ⲋ̅ⲚⲀⲨϪⲰ ⲆⲈ ⲚⲞⲨⲠⲀⲢⲀⲂⲞⲖⲎ ⲚⲰⲞⲨ ϪⲈ ⲘⲠⲀⲢⲈ ϨⲖⲒ ⲪⲈϦ ⲞⲨⲦⲰⲒⲤ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲞⲨϨⲂⲞⲤ ⲘⲂⲈⲢⲒ ⲚⲦⲈϤϨⲒⲦⲤ ⲈⲞⲨϨⲂⲞⲤ ⲚⲀⲠⲀⲤ ⲘⲘⲞⲚ ϢⲀⲤⲪⲈϦ ⲠⲒⲔⲈⲂⲈⲢⲒ ⲞⲨⲞϨ ⲘⲠⲀⲤϮⲘⲀϮ ⲚⲈⲘ ⲠⲒⲀⲠⲀⲤ ⲚϪⲈϮⲦⲰⲒⲤ ⲈⲦⲀⲨⲞⲖⲤ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲠⲒⲂⲈⲢⲒ.
37 Àti wí pé, kò sí ẹni tí ó lè dá ọtí wáìnì tuntun sínú ògbólógbòó ìgò-awọ, tí ó bá ṣe èyí, wáìnì tuntun yóò fa awọ náà ya, wáìnì náà yóò dànù, awọ náà a sì bàjẹ́.
ⲗ̅ⲍ̅ⲞⲨⲆⲈ ⲘⲠⲀⲢⲈ ϨⲖⲒ ϨⲒ ⲎⲢⲠ ⲘⲂⲈⲢⲒ ⲈⲀⲤⲔⲞⲤ ⲚⲀⲠⲀⲤ ⲘⲘⲞⲚ ϢⲀⲢⲈ ⲠⲒⲎⲢⲠ ⲘⲂⲈⲢⲒ ⲪⲈϦ ⲚⲒⲀⲤⲔⲞⲤ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲐⲞϤ ϢⲀϤⲪⲰⲚ ⲈⲂⲞⲖ ⲞⲨⲞϨ ϢⲀⲢⲈ ⲚⲒⲀⲤⲔⲞⲤ ⲦⲀⲔⲞ.
38 Nítorí náà, ó tọ́ kí á da wáìnì tuntun sínú awọ tuntun.
ⲗ̅ⲏ̅ⲀⲖⲖⲀ ⲈϢⲀⲨϨⲒ ⲎⲢⲠ ⲘⲂⲈⲢⲒ ⲈⲀⲤⲔⲞⲤ ⲘⲂⲈⲢⲒ.
39 Kò sì ẹni tí yóò fẹ́ láti mu wáìnì tuntun lẹ́yìn tí ó bá ti mu ògbólógbòó tán, nítorí yóò wí pé, ‘Èyí tí ó jẹ́ ògbólógbòó dára jù.’”
ⲗ̅ⲑ̅ⲞⲨⲞϨ ⲘⲘⲞⲚ ϨⲖⲒ ⲈϤⲤⲰ ⲀⲠⲀⲤ ⲚⲀⲞⲨⲰϢ ⲂⲈⲢⲒ ϤϪⲰ ⲄⲀⲢ ⲘⲘⲞⲤ ϪⲈ ϤϨⲞⲖϪ ⲚϪⲈⲠⲒⲀⲠⲀⲤ.

< Luke 5 >