< Luke 24 >

1 Ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ ọ̀sẹ̀, àwọn obìnrin wá sí ibojì, wọ́n sì mú ìkunra olóòórùn dídùn ti wọ́n tí pèsè sílẹ̀ wá.
Wauhā nanedauwaudaa hesee hauchauvadede, hajesejevesesanith haejeedadauwu hadausaesenanith, haenauuchaudenauau hathāeneevaudenee heesaanuthaunenau, nau jasae hauthauau nauguu.
2 Òkúta ti yí kúrò ní ẹnu ibojì.
Nau haenauhauvanauau hauunaugane haeausānene hehethee hadausaesee.
3 Nígbà tí wọ́n sì wọ inú rẹ̀, wọn kò rí òkú Jesu Olúwa.
Nau haejedānauau, nau haejeveedenauau hedanayaunene Vahadāhenith Hejavaneauthusaun.
4 Bí wọ́n ti dààmú kiri níhà ibẹ̀, kíyèsi i, àwọn ọkùnrin méjì aláṣọ dídán dúró tì wọ́n.
Nau hethauwuu daugaudauwuthajauthee heee, naune, hanesenethe henanenau haetheaugudaunā haenauasāaunenau hedāchaunene:
5 Nígbà tí ẹ̀rù ń bà wọ́n, tí wọ́n sì dojúbolẹ̀, àwọn angẹli náà bi wọ́n pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin fi ń wá alààyè láàrín àwọn òkú?
Nau daunāthajauthee, nau haenaunauagunauau vedauauwuu, haeāedauwunā, Naudu nananena haenaudehauna hanenaededaunaude nethee gaujauaudahehehau?
6 Kò sí níhìn-ín yìí, ṣùgbọ́n ó jíǹde; ẹ rántí bí ó ti wí fún yín nígbà tí ó wà ní Galili.
Hehauwanedau hede, hau jaegauhāde: dauyewuwuu neethāedauwunāna denausunanedaude Gananee,
7 Pé, ‘A ó fi Ọmọ Ènìyàn lé àwọn ènìyàn ẹlẹ́ṣẹ̀ lọ́wọ́, a ó sì kàn án mọ́ àgbélébùú, ní ọjọ́ kẹta yóò sì jíǹde.’”
Neesenehede, Heau henane hadvenavathe hejadenene wauwauchudaunanenau, nau hadsaethechauhude, nau nasese hadjaegauhāde.
8 Wọ́n sì rántí ọ̀rọ̀ rẹ̀.
Nau haedauyewuwunauau hedanadedaunene,
9 Wọ́n sì padà ti ibojì wá, wọ́n sì ròyìn gbogbo nǹkan wọ̀nyí fún àwọn mọ́kànlá, àti fún gbogbo àwọn ìyókù.
Nau haenaudauwu hehethee needausaesenanith, nau haeauthedaunanauau vahee nuu hayauhuhau jasānee, nau vahee hauthauau.
10 Maria Magdalene, àti Joanna, àti Maria ìyá Jakọbu, àti àwọn mìíràn pẹ̀lú wọn sì ni àwọn tí ó ròyìn nǹkan wọ̀nyí fún àwọn aposteli.
Haenane Mare Magdalene, nau Joanna, nau Mare henaune James, nau hauthauauau hesānauau henee henethaunādaunenau, neauthedaunauthee nuu hayauhuhau vadauhanau.
11 Ọ̀rọ̀ wọ̀nyí sì dàbí ìsọkúsọ lójú wọn, wọn kò sì gbà wọ́n gbọ́.
Nau hedanadedaunenau hathanadauwuyaugaune gaugauyaune, nau haejethauwaudaunaunauau.
12 Nígbà náà ni Peteru dìde, ó súré lọ sí ibojì; nígbà tí ó sì bẹ̀rẹ̀, ó rí aṣọ àlà lọ́tọ̀ fúnra wọn, ó sì padà lọ sí ilé rẹ̀, ẹnu yà á sí ohun tí ó ṣe.
Hanaāegauhāde Peda, nau haeyeseneegau hadausaesenanith, nau haeewauguau, haenauhaude naunaujānaunee haeānaudanenau jessaa, nau haenaude, haegaugauanade hasaunee.
13 Sì kíyèsi i, àwọn méjì nínú wọn ń lọ ní ọjọ́ náà sí ìletò kan tí a ń pè ní Emmausi, tí ó jìnnà sí Jerusalẹmu níwọ̀n ọgọ́ta ibùsọ̀.
Nau, naune, hanesenethe haeyehaunenau henee hajesesenee hajasee hauauwudan Emmaus haseagu, hehethee Dādaunedan wauau nesaudauchu nau gauuu daugauha.
14 Wọ́n ń bá ara wọn sọ̀rọ̀ gbogbo nǹkan wọ̀nyí tí ó ṣẹlẹ̀.
Nau haeanadenauau wauhaunee vahee nuu hayauhuhau hasaunee.
15 Ó sì ṣe, bí wọ́n ti ń bá ara wọn sọ̀rọ̀, tí wọ́n sì ń bá ara wọn jíròrò, Jesu tìkára rẹ̀ súnmọ́ wọn, ó sì ń bá wọn rìn lọ.
Nau hethauwuu, henee, dauanadethee wauhaunee nau haenaunaudedaunadenauau, Hejavaneauthusau Nehayau haeeauchauna, nau haenethauna.
16 Ṣùgbọ́n a rú wọn lójú, kí wọn má le mọ̀ ọ́n.
Hau hesesānenau haedunenenau henee hadjaenaunauthee.
17 Ó sì bi wọ́n pé, “Ọ̀rọ̀ kín ni ẹ̀yin ń bá ara yín sọ, bí ẹ̀yin ti ń rìn?” Wọ́n sì dúró jẹ́, wọ́n fajúro.
Nau haeāedauwuna, Hayewnau hadanadedaunenau nuu henee nananena hānegudaudenenau, daujajāwauaunadena, nau daudaneāauna?
18 Ọ̀kan nínú wọn, tí a ń pè ní Kileopa, sì dáhùn wí fún un pé, “Àlejò sá à ni ìwọ ní Jerusalẹmu, tí ìwọ kò sì mọ ohun tí ó ṣẹ̀ níbẹ̀ ní ọjọ́ wọ̀nyí?”
Nau jasaa hanaaseede Cleopas, haeauchuhananadethaa, Gauhanane vavade dauhadavesane nuu Dādaunedan, nau gauhajaene hayauhuhau hasedaudenee hena nuu hesee?
19 Ó sì bi wọ́n pé, “Kín ni?” Wọ́n sì wí fún un pé, “Ní ti Jesu ti Nasareti, ẹni tí ó jẹ́ wòlíì, tí ó pọ̀ ní ìṣe àti ní ọrọ̀ níwájú Ọlọ́run àti gbogbo ènìyàn,
Nau haeāedauwuna, Hayewnau? Nau haeāedauwunaa, Heee Hejavaneauthusau Nazareth, nananede Haeyāhe naunaudāde hanasedaude nau hedanadede hathaāhenith Hejavaneauthu nau vahee henanedanede:
20 àti bí àwọn olórí àlùfáà àti àwọn alàgbà wa ti fi òun lé wọn lọ́wọ́ láti dá a lẹ́bi ikú, àti bí wọ́n ti kàn án mọ́ àgbélébùú.
Nau najanauau vevethahevahehauau nau hadauchuwunanevene neesevānethe gaujauaudahede hadneauchuwuhade, nau nesaethechauhude.
21 Bẹ́ẹ̀ ni òun ni àwa ti ní ìrètí pé, òun ni ìbá dá Israẹli ní ìdè. Àti pẹ̀lú gbogbo nǹkan wọ̀nyí, òní ni ó di ọjọ́ kẹta tí nǹkan wọ̀nyí ti ṣẹlẹ̀.
Hau nejauwuwuhaunauau Nananede hadnenayaudede Israel: nau nauguu vahee nuu, desenee nanasāe hesee hāesenesedaudenee.
22 Àwọn obìnrin kan pẹ̀lú nínú ẹgbẹ́ wa, tí wọ́n lọ si ibojì ní kùtùkùtù, sì wá yà wá lẹ́nu,
Haa, nau jasae hesānauau jea hadahenauau nenāvānauau, naugusāge neanedauthee hadausaesenanith;
23 nígbà tí wọn kò sì rí òkú rẹ̀, wọ́n wá wí pé, àwọn rí ìran àwọn angẹli tí wọ́n wí pé, ó wà láààyè.
Nau dejeveedethee hedanayaunene, nejenuusathee, neauthedathee, henee jea haenauhauvanauau hautheaunau neethāhaugaunee henee daujaenaedeyaugaune.
24 Àti àwọn kan tí wọ́n wà pẹ̀lú wa lọ sí ibojì, wọ́n sì rí i gẹ́gẹ́ bí àwọn obìnrin náà ti wí, ṣùgbọ́n òun tìkára rẹ̀ ni wọn kò rí.”
Nau hauthauauau hānethaunādaunene deyehaunauau hadausaesee, nau haeveedenauau vavade hesānauau neesenehenethe: hau haejenauhauvanauau.
25 Ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin tí òye kò yé, tí ẹ sì yigbì ní àyà láti gba gbogbo èyí tí àwọn wòlíì ti wí gbọ́,
Hanaāāedauwunaude, Hau hāhauwaenava nau gaunauanuu hadahenau hethauwaudanee vahee henee haeyāhehauau nethauthedathee:
26 kò ha yẹ kí Kristi ó jìyà nǹkan wọ̀nyí kí ó sì wọ inú ògo rẹ̀ lọ.”
Naasauau Chris hadnasenede nuu, nau hadjedāde hadnedauvasāthaa.
27 Ó sì bẹ̀rẹ̀ láti Mose àti gbogbo àwọn wòlíì wá, ó sì túmọ̀ nǹkan fún wọn nínú ìwé mímọ́ gbogbo nípa ti ara rẹ̀.
Nau jeeejasesee Mosese nau vahee haeyāhehauau, neevavesāedauwunaude heee vahee hanathauthaunauhunee hayauhuhau hadnesenaedede Nehayau.
28 Wọ́n sì súnmọ́ ìletò tí wọ́n ń lọ, ó sì ṣe bí ẹni pé yóò lọ sí iwájú.
Nau haeeauchauwu hajasee hauauwudan hasesathee: nau nehayau haenanedauneha hadjavesade.
29 Wọ́n sì rọ̀ ọ́, pé, “Bá wa dúró: nítorí ó di ọjọ́ alẹ́, ọjọ́ sì kọjá tán.” Ó sì wọlé lọ, ó bá wọn dúró.
Hau haeneenadaunanauau, hathauhaugaunee, Hanedaudaunāa: hayānaesade, nau hesee hayāenauwusanauau. Nau haejedā hadnanedaudaunaude.
30 Ó sì ṣe, bí ó ti bá wọn jókòó ti oúnjẹ, ó mú àkàrà, ó súre sí i, ó sì bù ú, ó sì fi fún wọn.
Nau hethauwuu, daujanaugude haenethevetheheva, Haeedane jauaujau, nau haevaveene, nau haejeane, nau haevena.
31 Ojú wọn sì là, wọ́n sì mọ̀ ọ́n, ó sì nù mọ́ wọn ní ojú.
Nau hesesānenau haegaunanenenau, nau hanaāaenaunauthee; nau haeeyauhaudenauau.
32 Wọ́n sì bá ara wọn sọ pé, “Ọkàn wa kò ha gbiná nínú wa, nígbà tí ó ń bá wa sọ̀rọ̀ tí ó sì ń túmọ̀ ìwé mímọ́ fún wa!”
Nau hadāhene gauhauchāe hethauvaa, hanathadagaunee jaee, deanadethānauau jāthee, nau hāegaunanauwunānauau wauthaunauhanau?
33 Wọ́n sì dìde ní wákàtí kan náà, wọ́n padà lọ sí Jerusalẹmu, wọ́n sì bá àwọn mọ́kànlá péjọ, àti àwọn tí ń bẹ lọ́dọ̀ wọn.
Nau haegauhānauau chauchaunu nau haejaeyehaunauau Dādaunedan, nau haeveehanauau jasānee haeaunauudaunāhenenau, nau hauthauau henee hanedaudaunādaunenau,
34 Wọn si wí pé, “Olúwa jíǹde nítòótọ́, ó sì ti fi ara hàn fún Simoni!”
Vahadāde gauhāde hethauwuu, nau haenauhautheha Simon, hathahaugaunee.
35 Àwọn náà sì ròyìn nǹkan tí ó ṣe ní ọ̀nà, àti bí ó ti di mí mọ̀ fún wọn ní bíbu àkàrà.
Nau haeauthedanauau hayauhuhau hanasedaunith hadesathee, nau hasaenaunāde daujeanauau jauaujau.
36 Bí wọ́n sì ti ń sọ nǹkan wọ̀nyí Jesu tìkára rẹ̀ dúró láàrín wọn, ó sì wí fún wọn pé, “Àlàáfíà fún yín.”
Nau daunausunanadethee, Hejavaneauthusau Nehayau haetheaugu nahethāe hadauthee, nau hathāhaugaunee, Danādauyauau vanenathana.
37 Ṣùgbọ́n àyà fò wọ́n, wọ́n sì wárìrì, wọ́n ṣe bí àwọn rí ẹ̀mí kan.
Hau haenānauaunauau nau haenāthajaunauau, nau hasethajauhaugaunee henee haenauhauvanauau vadathu.
38 Ó sì wí fún wọn pé, “Èéṣe tí ara yín kò lélẹ̀? Èé sì ti ṣe tí èròkerò fi ń sọ nínú ọkàn yín?
Nau hathauhuk, Naudu nananena haenāthajauna, nau naudu haegaugauuthajauna gauhānauha hadahenau?
39 Ẹ wo ọwọ́ mi àti ẹsẹ̀ mi, pé èmi tìkára mi ni! Ẹ dì mímú kí ẹ wò ó nítorí tí iwin kò ní ẹran àti egungun lára, bí ẹ̀yin ti rí tí èmi ní.”
Nauhaudauwuu Najadenau nau Nauaudau, henee Nananenau nehayau: Vasanee, nau nauhauwuu; hanau vadathau hehauwudausānune nau hehauwudechaunave, hathauhauwuna.
40 Nígbà tí ó sì wí bẹ́ẹ̀ tan, ó fi ọwọ́ àti ẹsẹ̀ rẹ̀ hàn wọ́n.
Nau dauhanadede, haenauhautheha hejadenau nau heaudau.
41 Nígbà tí wọn kò sì tí ì gbàgbọ́ fún ayọ̀, àti fún ìyanu, ó wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin ní ohunkóhun jíjẹ níhìn-ín yìí?”
Nau haejethauwuthajaunauau heee haunauwuthajaude, nau haegaugauuthajaunauau, Haeāedauwuna, Gauhajevetheneva hede?
42 Wọ́n sì fún un ní ẹja tí a fi oyin sè.
Nau haevenanauau hanesāhenith nauwu haeaujaunene, nau gauhauaugunaugauye.
43 Ó sì gbà á, ó jẹ ẹ́ lójú wọn.
Nau haeedane, nau haevethe hathaājenethe.
44 Ó sì wí fún wọn pé, “Wọ̀nyí ni ọ̀rọ̀ tí mo sọ fún yín, nígbà tí èmí ti wà pẹ̀lú yín pé, a ní láti mú ohun gbogbo ṣẹ, tí a ti kọ nínú òfin Mose, àti nínú ìwé àwọn wòlíì, àti nínú Saamu, nípasẹ̀ mi.”
Nau haeāedauwuna, Nuu nanāe hanadedaunau hāauthedaunathadenenau, denausunethenaedevathana, henee vahee hayauhuhau hadnethauwunauauchuu, hanathauthaunauhuu henanavaavede Mosese, nau haeyāhehauau, nau psalms heee Nananenau.
45 Nígbà náà ni ó ṣí wọn ní iyè, kí ìwé mímọ́ lè yé wọn.
Hanaāegaunanauwunaude hadnaenauwunethe, henee hadnaenauwunethe wauthaunauhanau,
46 Ó sì wí fún wọn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni a ti kọ̀wé rẹ̀, pé: kí Kristi jìyà, àti kí ó sì jíǹde ní ọjọ́ kẹta kúrò nínú òkú,
Nau haeāedauwuna, Hathauthaunauhuu, nau naasauau Chris hadnasenede, nau hadjaegauhāde hehethee gaujauaudahede nasese:
47 àti pé kí a wàásù ìrònúpìwàdà àti ìdáríjì ẹ̀ṣẹ̀ lórúkọ rẹ̀, ní orílẹ̀-èdè gbogbo, bẹ̀rẹ̀ láti Jerusalẹmu lọ.
Nau henee haugauthegaugauuthajaude nau hadjaegudanee wauchudaudenau hadnautheduhunee heee Heneseede nanadee jajaesenanedanede, hehethee Dādaunedan.
48 Ẹ̀yin sì ni ẹlẹ́rìí nǹkan wọ̀nyí.
Nau nananena haenauwuna nuu hayauhuhau.
49 Èmi yóò rán ohun tí Baba mi ṣe ìlérí sí yín, ṣùgbọ́n ẹ jókòó ní ìlú Jerusalẹmu, títí a ó fífi agbára wọ̀ yín, láti òkè ọ̀run wá.”
Nau, naune, Nananenau vanenathana sayānee Nāsaunau hau theauguu hedan Dādaunedan, haunaude nananena hāchauwunagu nauguu naudahede hehethee hejavaa.
50 Ó sì mú wọn jáde lọ títí wọ́n fẹ́rẹ̀ dé Betani, nígbà tí ó sì gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè, ó súre fún wọn.
Nau haejasesenedauwauna hajechaudanee Bethany, nau haeegauha, nau haevevethasa.
51 Ó sì ṣe, bí ó ti ń súre fún wọn, ó yà kúrò lọ́dọ̀ wọn, a sì gbé e lọ sí ọ̀run.
Nau hethauwuu, daunausuvevethauchaude, Haenautha, nau haeejechauhau jethee hejavaa.
52 Wọ́n sì foríbalẹ̀ fún un, wọ́n sì padà lọ sí Jerusalẹmu pẹ̀lú ayọ̀ púpọ̀.
Nau haevevethedaunanauau, nau haejaeyehaunauau Dādaunedan nauguu vaseneethajaude:
53 Wọ́n sì wà ní tẹmpili nígbà gbogbo, wọ́n ń fi ìyìn, àti ìbùkún fún Ọlọ́run.
Nau dajauaunee haeanedaunauau jedauwuu Vadannauauwuu, hauwaunede nau haevevethedaunanauau Hejavaneauthu. Hethauvaa.

< Luke 24 >