< Luke 22 >

1 Àjọ ọdún àìwúkàrà tí à ń pè ní Ìrékọjá sì kù fẹ́ẹ́rẹ́.
Přiblížily se Velikonoce.
2 Àti àwọn olórí àlùfáà, àti àwọn akọ̀wé ń wá ọ̀nà tí wọn ìbá gbà pa á; nítorí tí wọn ń bẹ̀rù àwọn ènìyàn.
Velekněží a učitelé zákona hledali vhodný způsob, jak Ježíše zprovodit ze světa. Báli se však lidí, kteří se v Jeruzalémě shromažďovali k velikonočním svátkům.
3 Satani sì wọ inú Judasi, tí à ń pè ní Iskariotu, ọ̀kan nínú àwọn méjìlá.
Jidáš Iškariotský – jeden z dvanácti Ježíšových učedníků – podlehl satanskému pokušení,
4 Ó sì mú ọ̀nà rẹ̀ pọ̀n, ó lọ láti bá àwọn olórí àlùfáà àti àwọn olórí ẹ̀ṣọ́ gbèrò pọ̀, bí òun yóò tí fi í lé wọn lọ́wọ́.
odešel za veleknězi a veliteli chrámové stráže a nabídl jim pomoc při Ježíšově zatčení.
5 Wọ́n sì yọ̀, wọ́n sì bá a dá májẹ̀mú láti fún un ní owó.
Ti se samozřejmě zaradovali a slíbili mu odměnu.
6 Ó sì gbà; ó sì ń wá àkókò tí ó wọ̀, láti fi í lé wọn lọ́wọ́ láìsí ariwo.
Jidáš souhlasil a od té chvíle čekal na vhodnou příležitost, kdy by Ježíš mohl být nenápadně, bez mnoha svědků, zatčen.
7 Ọjọ́ àìwúkàrà pé, nígbà tí wọ́n ní láti pa ọ̀dọ́-àgùntàn ìrékọjá fún ìrúbọ.
Židé se o Velikonocích scházeli k večeři, při níž jedli nekvašený chléb a předepsaným způsobem připraveného beránka.
8 Ó sì rán Peteru àti Johanu, wí pé, “Ẹ lọ pèsè ìrékọjá fún wa, kí àwa ó jẹ.”
Proto Ježíš uložil Petrovi a Janovi, aby tuto večeři uchystali pro něj a ostatní učedníky.
9 Wọ́n sì wí fún un pé, “Níbo ni ìwọ ń fẹ́ kí á pèsè sílẹ̀?”
Zeptali se: „Kde chceš, abychom ji udělali?“
10 Ó sì wí fún wọn pé, “Kíyèsi i, nígbà tí ẹ̀yin bá ń wọ ìlú lọ, ọkùnrin kan tí ó ru ìkòkò omi yóò pàdé yín, ẹ bá a lọ sí ilé tí ó bá wọ̀,
Odpověděl: „Když přijdete do města, potkáte muže, který ponese džbán vody. Jděte za ním do domu, kam vejde. Majiteli domu řekněte:
11 kí ẹ sì wí fún baálé ilé náà pé, ‘Olùkọ́ wí fún ọ pé, níbo ni gbàngàn àpèjẹ náà gbé wà, níbi tí èmi ó gbé jẹ ìrékọjá pẹ̀lú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn mi?’
‚Mistr tě žádá abys nám ukázal místnost, ve které by se mohl se svými učedníky sejít k velikonoční večeři.‘
12 Òun ó sì fi gbàngàn ńlá kan lókè ilé hàn yín, tí a ṣe lọ́ṣọ̀ọ́, níbẹ̀ ni kí ẹ̀yin pèsè sílẹ̀.”
Zavede vás do velké jídelny v horním patře. Tam všechno nachystejte.“
13 Wọ́n sì lọ wọ́n sì bá a gẹ́gẹ́ bí ó tí sọ fún wọn, wọ́n sì pèsè ìrékọjá sílẹ̀.
Odešli a našli všechno přesně tak, jak jim Ježíš řekl, a připravili velikonočního beránka.
14 Nígbà tí àkókò sì tó, ó jókòó àti àwọn aposteli pẹ̀lú rẹ̀.
Ve stanovenou hodinu zaujal Ježíš se svými dvanácti apoštoly místo u stolu.
15 Ó sì wí fún wọn pé, “Tinútinú ni èmi fẹ́ fi bá yín jẹ ìrékọjá yìí, kí èmi tó jìyà.
Řekl jim: „Velice jsem si přál ještě jíst s vámi beránka, dříve než budu trpět.
16 Nítorí mo wí fún yín, Èmi kì yóò jẹ nínú rẹ̀ mọ́, títí a ó fi mú un ṣẹ ní ìjọba Ọlọ́run.”
Je to naposledy, co ho takto jíme. Záhy se totiž stane to, co vám Bůh oběťmi velikonočního beránka naznačoval.“
17 Ó sì gba ago, nígbà tí ó sì ti dúpẹ́, ó wí pé, “Gba èyí, kí ẹ sì pín in láàrín ara yín.
Když jim po modlitbě podával kalich s vínem,
18 Nítorí mo wí fún yín, Èmi kì yóò mu nínú èso àjàrà mọ́, títí ìjọba Ọlọ́run yóò fi dé.”
řekl, že už ho s nimi nebude pít, dokud se nesejdou k hostině v nebi.
19 Ó sì mú àkàrà, nígbà tí ó sì ti dúpẹ́ ó bù ú, ó sì fi fún wọn, ó wí pé, “Èyí ni ara mí tí a fi fún yín, ẹ máa ṣe èyí ní ìrántí mi.”
Pak vzal chléb, poděkoval Bohu, rozlámal ho a podával svým učedníkům se slovy: „To je moje tělo, které se za vás obětuje. Tímto způsobem si mne vždycky znovu připomínejte.“
20 Bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ lẹ́yìn oúnjẹ alẹ́, ó sì mú ago wáìnì, ó wí pé, “Ago yìí ni májẹ̀mú tuntun nínú ẹ̀jẹ̀ mi, tí a ta sílẹ̀ fún yín.
Po večeři jim podal opět víno a řekl: „Tento kalich je znamením nové smlouvy Boha s člověkem, zpečetěné krví, kterou za vás proliji.
21 Ṣùgbọ́n ẹ kíyèsi i, ọwọ́ ẹni tí yóò fi mí hàn wà pẹ̀lú mi lórí tábìlì.
Zde u stolu sedí člověk, který se tváří jako přítel, ale je odhodlán mne zradit.
22 Ọmọ Ènìyàn ń lọ nítòótọ́ bí a tí pinnu rẹ̀, ṣùgbọ́n ègbé ni fún ọkùnrin náà nípasẹ̀ ẹni tí a gbé ti fi í hàn.”
Vím, že musím zemřít, ale běda zrádci.“
23 Wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí béèrè láàrín ara wọn, ta ni nínú wọn tí yóò ṣe nǹkan yìí.
Po těchto slovech se začali mezi sebou dohadovat, kdo z nich by byl schopen něčeho takového.
24 Ìjà kan sì ń bẹ láàrín wọn, ní ti ẹni tí a kà sí olórí nínú wọn.
Nakonec mezi nimi vznikl spor, kdo z nich je přednější.
25 Ó sì wí fún wọn pé, “Àwọn ọba aláìkọlà a máa fẹlá lórí wọn, a sì máa pe àwọn aláṣẹ wọn ní olóore.
Ježíš jim řekl: „Vládci panují nad svými poddanými a dávají si říkat dobrodinci.
26 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kì yóò rí bẹ́ẹ̀; ṣùgbọ́n ẹni tí ó ba pọ̀jù nínú yín kí ó jẹ́ bí ẹni tí o kéré ju àbúrò; ẹni tí ó sì ṣe olórí, bí ẹni tí ń ṣe ìránṣẹ́.
U vás ať je tomu naopak. Nechtějte panovat, ale sloužit. Kdo je mezi vámi nejvyšší, ať jedná, jako by byl nejnižší, kdo je vůdčí osobností, ať slouží druhým.
27 Nítorí ta ni ó pọ̀jù, ẹni tí ó jókòó tí oúnjẹ, tàbí ẹni tí ó ń ṣe ìránṣẹ́. Ẹni tí ó jókòó ti oúnjẹ kọ́ bí? Ṣùgbọ́n èmi ń bẹ láàrín yín bí ẹni tí ń ṣe ìránṣẹ́.
Kdo je přednější? Ten, kdo sedí za stolem a dá se obsluhovat, nebo ten, kdo obsluhuje? Obecně platí, že ten, kdo se dá obsluhovat. Vidíte, a já jsem mezi vámi jako ten, kdo slouží.
28 Ẹ̀yin ni àwọn tí ó ti dúró tì mí nínú ìdánwò mi.
Až dosud jste mi v mých zkouškách stáli věrně po boku.
29 Mo sì yan ìjọba fún yín, gẹ́gẹ́ bí Baba mi ti yàn fún mi.
Můj Otec mi dal království a já vám uděluji právo,
30 Kí ẹ̀yin lè máa jẹ, kí ẹ̀yin sì lè máa mu lórí tábìlì mi ní ìjọba mi, kí ẹ̀yin lè jókòó lórí ìtẹ́, àti kí ẹ̀yin lè máa ṣe ìdájọ́ fún àwọn ẹ̀yà Israẹli méjìlá.”
abyste v tom království jedli a pili u mého stolu. Však také usednete na soudné stolice a budete soudit dvanáct izraelských rodů.“
31 Olúwa sì wí pé, “Simoni, Simoni, wò ó, Satani fẹ́ láti gbà ọ́, kí ó lè kù ọ́ bí alikama.
Pak oslovil Šimona Petra: „Satan si vyžádal, aby vás mohl prosívat jako obilí,
32 Ṣùgbọ́n mo ti gbàdúrà fún ọ, kí ìgbàgbọ́ rẹ má ṣe yẹ̀; àti ìwọ nígbà tí ìwọ bá sì padà bọ̀ sípò, mú àwọn arákùnrin rẹ lọ́kàn le.”
ale já jsem se za tebe přimlouval, aby tvoje víra vydržela. A až se pak obrátíš, utvrzuj ve víře své bratry.“
33 Ó sì wí fún un pé, “Olúwa, mo múra tán láti bá ọ lọ sínú túbú, àti sí ikú.”
Šimon odpověděl: „Pane, s tebou jsem odhodlán jít do vězení i na smrt.“
34 Ó sì wí pé, “Mo wí fún ọ, Peteru, àkùkọ kì yóò kọ lónìí tí ìwọ ó fi sẹ́ mi lẹ́ẹ̀mẹ́ta pé, ìwọ kò mọ̀ mí.”
Ježíš mu řekl: „Říkám ti, Petře, že dříve než dnes zakokrhá první kohout, třikrát popřeš, žes mne znal.“
35 Ó sì wí fún wọn pé, “Nígbà tí mo rán yín lọ láìní àpò-owó, àti àpò, àti bàtà, ọ̀dá ohun kan dá yín bí?” Wọ́n sì wí pé, “Rárá!”
Pak jim ještě řekl: „Posílal jsem vás za lidmi bez peněz, bez zásob a bosé. Můžete říci, že jste měli v něčem nedostatek?“Oni odpověděli: „Ne, ani v nejmenším.“
36 Nígbà náà ni ó wí fún wọn pé, “Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, ẹni tí ó bá ní àpò-owó kí ó mú un, àti àpò pẹ̀lú; ẹni tí kò bá sì ní idà, kí ó ta aṣọ rẹ̀, kí ó sì fi ra ọ̀kan.
Ježíš pokračoval. „Teď se situace mění, přijde pro vás těžká doba. Dobře se na ni vybavte a vyzbrojte.
37 Nítorí mo wí fún yín pé, ‘Èyí tí a ti kọ̀wé rẹ̀ kò lè ṣe kí ó má ṣẹ lára mi, a sì kà á mọ́ àwọn arúfin.’ Nítorí àwọn ohun wọ̀nyí nípa ti èmi yóò ní ìmúṣẹ.” tí a sì kà á mọ́ àwọn alárékọjá.
Brzy budu souzen jako zločinec, jak to bylo předpověděno. Prorocká slova o mně se plní.“
38 Wọ́n sì wí pé, “Olúwa, sá wò ó, idà méjì ń bẹ níhìn-ín yìí!” Ó sì wí fún wọn pé, “Ó tó.”
Řekli: „Pane, máme tu dva meče.“Ježíš odpověděl: „To stačí.“
39 Ó sì jáde, ó sì lọ bí ìṣe rẹ̀ sí òkè olifi, àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ sì tọ̀ ọ́ lẹ́yìn.
Pak se jako obvykle vydal na Olivovu horu a jeho učedníci ho provázeli.
40 Nígbà tí ó wà níbẹ̀, ó wí fún wọn pé, “Ẹ máa gbàdúrà, kí ẹ̀yin má ṣe bọ́ sínú ìdẹwò.”
Když došli na místo, řekl jim: „Modlete se, abyste obstáli v těžkých zkouškách, které vás čekají.“
41 Ó sì fi wọ́n sílẹ̀ níwọ̀n ìsọ-òkò kan, ó sì kúnlẹ̀ ó sì ń gbàdúrà.
Sám se pak vzdálil, co by kamenem dohodil, poklekl a modlil se:
42 Wí pé, “Baba, bí ìwọ bá fẹ́, mu ago yìí kúrò lọ́dọ́ mi: ṣùgbọ́n ìfẹ́ ti èmi kọ́, bí kò ṣe tìrẹ ni kí à ṣe.”
„Otče, kdybys mne mohl ušetřit tohoto kalicha utrpení, ale ať se vyplní tvoje vůle, ne moje.“
43 Angẹli kan sì yọ sí i láti ọ̀run wá, ó ń gbà á ní ìyànjú.
Tu při něm stál anděl a dodával mu sílu.
44 Bí ó sì ti wà nínú gbígbóná ara ó ń gbàdúrà sí i kíkankíkan; òógùn rẹ̀ sì dàbí ìró ẹ̀jẹ̀ ńlá, ó ń kán sílẹ̀.
Ježíš se modlil v smrtelné úzkosti. Pot jako krvavé kapky mu stékal na zem.
45 Nígbà tí ó sì dìde kúrò ní ibi àdúrà, tí ó sì tọ àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ wá, ó bá wọn, wọ́n ń sùn nítorí ìbànújẹ́ ti mu kí ó rẹ̀ wọ́n.
Když skončil modlitbu, šel ke svým učedníkům a shledal, že pod tíhou událostí usnuli.
46 Ó sì wí fún wọn pé, “Kí ni ẹ̀ yin ń sùn sí? Ẹ dìde, ẹ máa gbàdúrà, kí ẹ̀yin má ṣe bọ́ sínú ìdẹwò.”
Probudil je: „Jak můžete spát? Vstaňte a modlete se, abyste obstáli ve zkouškách, které jsou před vámi.“
47 Bí ó sì ti ń sọ lọ́wọ́, kíyèsi i, ọ̀pọ̀ ènìyàn, àti ẹni tí a ń pè ní Judasi, ọ̀kan nínú àwọn méjìlá, ó ṣáájú wọn, ó súnmọ́ Jesu láti fi ẹnu kò ó ní ẹnu.
Ještě to ani nedořekl a objevil se houf lidí s Jidášem v čele. Ten přistoupil k Ježíšovi, aby ho políbil.
48 Jesu sì wí fún un pé, “Judasi, ìwọ yóò ha fi ìfẹnukonu fi Ọmọ Ènìyàn hàn?”
Ježíš mu řekl: „Jidáši, polibkem mne zrazuješ?“
49 Nígbà tí àwọn tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀ ń wo bí nǹkan yóò ti jásí, wọ́n bi í pé, “Olúwa kí àwa fi idà sá wọn?”
Když ostatní učedníci pochopili, co se děje, volali: „Pane, máme tě bránit?“
50 Ọ̀kan nínú wọn sì fi idà ṣá ọmọ ọ̀dọ̀ olórí àlùfáà, ó sì gé etí ọ̀tún rẹ̀ sọnù.
A jeden z nich skutečně vytasil meč a uťal pravé ucho jednomu muži z chrámové stráže.
51 Ṣùgbọ́n Jesu dáhùn ó wí pé, “Ko gbọdọ̀ ṣe èyí mọ.” Ó sì fi ọwọ́ tọ́ ọ ní etí, ó sì wò ó sàn.
Ježíš však řekl: „Dost! Nechte toho!“Dotkl se ucha zraněného a uzdravil ho.
52 Jesu wí fún àwọn olórí àlùfáà, àti àwọn olórí ẹ̀ṣọ́ tẹmpili, àti àwọn alàgbà, tí wọ́n jáde tọ̀ ọ́ wá pé, “Ẹ̀yin ha jáde wá pẹ̀lú idà àti ọ̀kọ̀ bí ẹni tọ ọlọ́ṣà wá?
Pak Ježíš oslovil stráž, jejich velitele a kněze, kteří je vedli: „Přišli jste si pro mne s meči a klacky jako pro lotra.
53 Nígbà tí èmi wà pẹ̀lú yín lójoojúmọ́ ní tẹmpili, ẹ̀yin kò na ọwọ́ mú mi, ṣùgbọ́n àkókò tiyín ni èyí, àti agbára òkùnkùn n jẹ ọba.”
A přitom jsem s vámi denně býval v chrámu a ruku jste na mne nevztáhli. Ale já vím, přišla vaše chvíle a tma teď nabývá vrchu.“
54 Wọ́n sì gbá a mú, wọ́n sì fà á lọ, wọ́n sì mú un wá sí ilé olórí àlùfáà. Ṣùgbọ́n Peteru tọ̀ ọ́ lẹ́yìn ní òkèrè.
Tu se ho zmocnili a odvedli do veleknězova paláce. Petr je zpovzdálí sledoval.
55 Nígbà tí wọ́n sì ti dáná láàrín àgbàlá, tí wọ́n sì jókòó pọ̀, Peteru jókòó láàrín wọn.
Vojáci rozdělali uprostřed nádvoří oheň a sesedli se okolo. Petr se přišel mezi ně také ohřát.
56 Ọmọbìnrin kan sì rí i bí ó ti jókòó níbi ìmọ́lẹ̀ iná náà, ó sì tẹjúmọ́ ọn, ó ní, “Eléyìí náà wà pẹ̀lú rẹ̀.”
Jak mu plamen osvěcoval tvář, všimla si ho jedna služka, prohlédla si ho a řekla: „Podívejte se, ten s ním také chodil.“
57 Ṣùgbọ́n, ó wí pé, “Obìnrin yìí, èmi kò mọ̀ ọ́n.”
Petr se bránil: „Ženo, vždyť já ho vůbec neznám.“
58 Kò pẹ́ lẹ́yìn náà ẹlòmíràn sì rí i, ó ní, “Ìwọ pẹ̀lú wà nínú wọn.” Ṣùgbọ́n Peteru wí pé, “Ọkùnrin yìí, èmi kọ́.”
Za chvíli si ho všiml někdo jiný: „Ty k nim taky patříš.“Petr řekl: „To se mýlíte.“
59 Ó sì tó bí i wákàtí kan síbẹ̀ ẹlòmíràn tẹnumọ́ ọn, wí pé, “Nítòótọ́ eléyìí náà wà pẹ̀lú rẹ̀: nítorí ará Galili ní í ṣe.”
Asi za hodinu zase někdo jiný začal tvrdit: „Tenhle s ním určitě byl také, je to Galilejec.“
60 Ṣùgbọ́n Peteru wí pé, “Ọkùnrin yìí, èmi kò mọ ohun tí ìwọ ń wí!” Lójúkan náà, bí ó tí ń wí lẹ́nu, àkùkọ kọ!
Petr to popřel: „Člověče, vůbec nevím, o čem mluvíš.“Než to dořekl, zakokrhal kohout.
61 Olúwa sì yípadà, ó wo Peteru. Peteru sì rántí ọ̀rọ̀ Olúwa, bí ó ti wí fún un pé, “Kí àkùkọ tó kọ, ìwọ ó sẹ́ mi lẹ́ẹ̀mẹ́ta.”
A tu se Ježíš otočil a podíval se na Petra a ten si vzpomněl, že mu Pán řekl: „Dříve než kohout zakokrhá, třikrát mne zapřeš.“
62 Peteru sì bọ́ sí òde, ó sọkún kíkorò.
Vyběhl z nádvoří a venku se hořce rozplakal.
63 Ó sì ṣe, àwọn ọkùnrin tí wọ́n mú Jesu, sì fi í ṣe ẹlẹ́yà, wọ́n lù ú.
Stráž se začala Ježíšovi vysmívat.
64 Nígbà tí wọ́n sì dì í ní ojú, wọ́n lù ú níwájú, wọ́n ń bi í pé, “Sọtẹ́lẹ̀! Ta ni ó lù ọ́?”
Zavázali mu oči, bili ho do tváře a říkali: „Jsi přece prorok, tak hádej, kdo tě uhodil.“
65 Wọ́n sì sọ ọ̀pọ̀ ohun búburú mìíràn sí i, láti fi ṣe ẹlẹ́yà.
A předháněli se v tom, kdo ho víc poníží.
66 Nígbà tí ilẹ̀ sì mọ́, ìjọ àwọn alàgbà àwọn ènìyàn péjọpọ̀, àti àwọn olórí àlùfáà, àti àwọn akọ̀wé, wọ́n sì fà á lọ sí àjọ wọn, wọ́n ń wí pé,
Když se rozednilo, sešla se nejvyšší rada, kterou tvořili představitelé lidu, velekněží a učitelé zákona. Dali si Ježíše předvést a naléhali na něho: „Jsi Mesiáš? Řekni nám to!“
67 “Bí ìwọ bá jẹ́ Kristi náà? Sọ fún wa!” Ó sì wí fún wọn pé, “Bí mo bá wí fún yín, ẹ̀yin kì yóò gbàgbọ́,
On odpověděl: „I kdybych vám to řekl, stejně tomu neuvěříte.
68 bí mo bá sì bi yín léèrè pẹ̀lú, ẹ̀yin kì yóò dá mi lóhùn.
A kdybych se já vás na něco zeptal, neodpovíte mi.
69 Ṣùgbọ́n láti ìsinsin yìí lọ ni Ọmọ Ènìyàn yóò jókòó lọ́wọ́ ọ̀tún agbára Ọlọ́run.”
Řeknu vám jenom to: Již záhy usedne Syn člověka po Boží pravici.“
70 Gbogbo wọn sì wí pé, “Ìwọ ha ṣe Ọmọ Ọlọ́run bí?” Ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin wí pé, èmi ni.”
Všichni začali volat: „Ty jsi tedy Boží Syn?“Ježíš odpověděl: „Vaše vlastní slova to potvrzují.“
71 Wọ́n sì wí pé, “Ẹ̀rí wo ni àwa tún ń fẹ́ àwa tìkára wa sá à ti gbọ́ lẹ́nu rẹ̀!”
Tu křičeli jeden přes druhého: „To nám stačí, už žádné další svědectví nepotřebujeme, usvědčil se sám!“

< Luke 22 >