< Luke 21 >

1 Nígbà tí ó sì gbé ojú sókè, ó rí àwọn ọlọ́rọ̀ ń fi ẹ̀bùn wọn sínú àpótí ìṣúra.
Och när han såg upp, fick han se huru de rika lade ned sina gåvor i offerkistorna.
2 Ó sì rí tálákà opó kan pẹ̀lú, ó ń sọ owó idẹ wẹ́wẹ́ méjì síbẹ̀.
Därvid fick han ock se huru en fattig änka lade ned två skärvar.
3 Ó sì wí pé, “Lóòótọ́ ni mo wí fún yín, tálákà opó yìí fi sí i ju gbogbo wọn lọ,
Då sade han: "Sannerligen säger jag eder: Denna fattiga änka lade dit mer än alla de andra.
4 nítorí gbogbo àwọn wọ̀nyí fi sínú ẹ̀bùn Ọlọ́run láti ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìní wọn; ṣùgbọ́n òun nínú àìní rẹ̀ ó sọ gbogbo ohun ìní rẹ̀ tí ó ní sínú rẹ̀.”
Ty det var av sitt överflöd som alla dessa lade ned något bland gåvorna, men hon lade dit av sitt armod allt vad hon hade i sin ägo."
5 Bí àwọn kan sì ti ń sọ̀rọ̀ nípa tẹmpili, bí a ti fi òkúta dáradára àti ẹ̀bùn ṣe é ní ọ̀ṣọ́, fun Ọlọ́run, Jesu wí pé
Och då några talade om helgedomen, huru den var uppförd av härliga stenar och prydd med helgedomsskänker, sade han:
6 “Ohun tí ẹ̀yin ń wò wọ̀nyí, ọjọ́ ń bọ̀, nígbà tí a kì yóò fi òkúta kan sílẹ̀ lórí èkejì tí a kì yóò wó lulẹ̀.”
"Dagar skola komma, då av allt detta som I nu sen icke skall lämnas sten på sten, utan allt skall bliva nedbrutet."
7 Wọ́n sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀, pé, “Olùkọ́, nígbà wo ni nǹkan wọ̀nyí yóò rí bẹ́ẹ̀? Àti àmì kín ni yóò wà, nígbà tí nǹkan wọ̀nyí yóò fi ṣẹ?”
Då frågade de honom och sade: "Mästare, när skall detta ske? Och vad bliver tecknet till att tiden är inne, då detta kommer att ske?"
8 Ó sì wí pé, “Ẹ máa kíyèsára, kí a má bá à mú yín ṣìnà: nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ yóò wá ní orúkọ mi, tí yóò máa wí pé, ‘Èmi ní Kristi náà àkókò náà sì kù sí dẹ̀dẹ̀.’ Ẹ má ṣe tọ̀ wọ́n lẹ́yìn.
Han svarade: "Sen till, att I icke bliven förvillade. Ty många skola komma under mitt namn och säga: 'Det är jag' och: 'Tiden är nära'. Men följen dem icke.
9 Ṣùgbọ́n nígbà tí ẹ̀yin bá gbúròó ogun àti ìdágìrì, ẹ má ṣe fòyà; nítorí nǹkan wọ̀nyí ní láti kọ́kọ́ ṣẹlẹ̀, ṣùgbọ́n òpin náà kì í ṣe lójúkan náà.”
Och när I fån höra krigslarm och upprorslarm, så bliven icke förfärade; ty sådant måste först komma, men därmed är icke strax änden inne."
10 Nígbà náà ni ó wí fún wọn pé, “Orílẹ̀-èdè yóò dìde sí orílẹ̀-èdè, àti ìjọba sí ìjọba.
Därefter sade han till dem: "Folk skall resa sig upp mot folk och rike mot rike;
11 Ilẹ̀-rírì ńlá yóò sì wà káàkiri, àti ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn; ohun ẹ̀rù, àti àmì ńlá yóò sì ti ọ̀run wá.
och det skall bliva stora jordbävningar, så ock hungersnöd och farsoter på den ena orten efter den andra, och skräcksyner skola visa sig och stora tecken på himmelen.
12 “Ṣùgbọ́n ṣáájú gbogbo nǹkan wọ̀nyí, wọn ó nawọ́ mú yín, wọn ó sì ṣe inúnibíni sí yín, wọn ó mú yín lọ sí Sinagọgu, àti sínú túbú, wọn ó mú yín lọ sọ́dọ̀ àwọn ọba àti àwọn ìjòyè nítorí orúkọ mi.
Men före allt detta skall man gripa eder, man skall förfölja eder och draga eder inför synagogorna och sätta eder i fängelse och föra eder fram inför konungar och landshövdingar, för mitt namns skull.
13 Ẹ o si jẹ́rìí nípa mi.
Så skolen I få tillfälle att frambära vittnesbörd.
14 Nítorí náà ẹ pinnu rẹ̀ ní ọkàn yín pé ẹ ko ronú ṣáájú, bí ẹ ó ti dáhùn.
Märken därför noga att I icke förut mån göra eder bekymmer för huru I skolen försvara eder.
15 Nítorí tí èmi ó fún yín ní ẹnu àti ọgbọ́n, tí gbogbo àwọn ọ̀tá yín kì yóò lè sọ̀rọ̀-òdì sí, tí wọn kì yóò sì lè kò lójú.
Ty jag skall giva eder sådana ord och sådan vishet, att ingen av edra vedersakare skall kunna stå emot eller säga något emot.
16 A ó sì fi yín hàn láti ọwọ́ àwọn òbí yín wá, àti àwọn arákùnrin, àti àwọn ìbátan, àti àwọn ọ̀rẹ́; òun ó sì mú kì a pa nínú yín.
I skolen bliva förrådda till och med av föräldrar och bröder och fränder och vänner; och somliga av eder skall man döda.
17 A ó sì kórìíra yín lọ́dọ̀ gbogbo ènìyàn nítorí orúkọ mi.
Och I skolen bliva hatade av alla för mitt namns skull.
18 Ṣùgbọ́n irun orí yín kan kì yóò ṣègbé.
Men icke ett hår på edra huvuden skall gå förlorat.
19 Nínú ìdúró ṣinṣin yín ni ẹ̀yin ó jèrè ọkàn yín.
Genom att vara ståndaktiga skolen I vinna edra själar.
20 “Nígbà tí ẹ̀yin bá sì rí ti a fi ogun yí Jerusalẹmu ká, ẹ mọ̀ nígbà náà pé, ìsọdahoro rẹ̀ kù sí dẹ̀dẹ̀.
Men när I fån se Jerusalem omringas av krigshärar, då skolen I veta att dess ödeläggelse är nära.
21 Nígbà náà ni kí àwọn tí ń bẹ ní Judea sálọ sórí òkè; àti àwọn tí ń bẹ láàrín rẹ̀ kí wọn jáde kúrò; kí àwọn tí ó sì ń bọ̀ ní ìgbèríko má ṣe wọ inú rẹ̀ wá.
Då må de som äro i Judeen fly bort till bergen, och de som äro inne i staden må draga ut därifrån och de som äro ute på landsbygden må icke gå ditin.
22 Nítorí ọjọ́ ẹ̀san ni ọjọ́ wọ̀nyí, kì a lè mú ohun gbogbo tí a ti kọ̀wé rẹ̀ ṣẹ.
Ty detta är en hämndens tid, då allt som är skrivet skall uppfyllas.
23 Ṣùgbọ́n ègbé ni fún àwọn tí ó lóyún, àti àwọn tí ó fi ọyàn fún ọmọ mu ní ọjọ́ wọ̀nyí! Nítorí tí ìpọ́njú púpọ̀ yóò wà lórí ilẹ̀ àti ìbínú sí àwọn ènìyàn wọ̀nyí.
Ve dem som äro havande, eller som giva di på den tiden! Ty stor nöd skall då komma i landet, och en vredesdom över detta folk.
24 Wọn ó sì ti ojú idà ṣubú, a ó sì dìwọ́n ní ìgbèkùn lọ sí orílẹ̀-èdè gbogbo; Jerusalẹmu yóò sì di ìtẹ̀mọ́lẹ̀ lẹ́sẹ̀ àwọn aláìkọlà, títí àkókò àwọn aláìkọlà yóò fi kún.
Och de skola falla för svärdsegg och bliva bortförda i fångenskap till allahanda hednafolk; och Jerusalem skall bliva förtrampat av hedningarna, till dess att hedningarnas tider äro fullbordade.
25 “Àmì yóò sì wà ní oorun, àti ní òṣùpá, àti ní ìràwọ̀; àti lórí ilẹ̀ ayé ìdààmú fún àwọn orílẹ̀-èdè nínú ìpayà híhó Òkun àti ìgbì omi.
Och tecken skola ske i solen och månen och i stjärnorna, och på jorden skall ångest komma över folken, och de skola stå rådlösa vid havets och vågornas dån,
26 Àyà àwọn ènìyàn yóò máa já fún ìbẹ̀rù, àti ìrètí nǹkan wọ̀nyí tí ń bọ̀ sórí ayé: nítorí àwọn agbára ọ̀run ni a ó mì tìtì.
då nu människor uppgiva andan av förskräckelse och ängslan för det som skall övergå världen; ty himmelens makter skola bäva.
27 Nígbà náà ni wọn ó sì rí Ọmọ Ènìyàn tí yóò máa bọ̀ wá nínú àwọsánmọ̀ pẹ̀lú agbára àti ògo ńlá.
Och då skall man få se 'Människosonen komma i en sky', med stor makt och härlighet.
28 Ṣùgbọ́n nígbà tí nǹkan wọ̀nyí bá bẹ̀rẹ̀ sí í ṣẹ, ǹjẹ́ kí ẹ wo òkè, kí ẹ sì gbé orí yín sókè; nítorí ìdáǹdè yín kù sí dẹ̀dẹ̀.”
Men när detta begynner ske, då mån I resa eder upp och upplyfta edra huvuden, ty då nalkas eder förlossning."
29 Ó sì pa òwe kan fún wọn pé, “Ẹ kíyèsi igi ọ̀pọ̀tọ́, àti sí gbogbo igi.
Och han framställde för dem en liknelse: "Sen på fikonträdet och på alla andra träd.
30 Nígbà tí wọ́n bá rúwé, ẹ̀yin rí i, ẹ sì mọ̀ fúnra ara yín pé, ìgbà ẹ̀ẹ̀rùn kù fẹ́ẹ́rẹ́.
När I fån se att de skjuta knopp, då veten I av eder själva att sommaren redan är nära.
31 Gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ náà ni ẹ̀yin, nígbà tí ẹ̀yin bá rí nǹkan wọ̀nyí tí o ṣẹ, kí ẹ̀yin mọ̀ pé, ìjọba Ọlọ́run kù sí dẹ̀dẹ̀.
Likaså, när I sen detta ske, då kunnen I ock veta att Guds rike är nära.
32 “Lóòótọ́ ni mo wí fún yín, ìran yìí kì yóò rékọjá, títí gbogbo nǹkan wọ̀nyí yóò fi ṣẹ.
Sannerligen säger jag eder: Detta släkte skall icke förgås, förrän allt detta sker.
33 Ọ̀run àti ayé yóò rékọjá, ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ mi kì yóò rékọjá.
Himmel och jord skola förgås, men mina ord skola aldrig förgås.
34 “Ṣùgbọ́n ẹ máa kíyèsára yín, kí ọkàn yín má ṣe kún fún wọ̀bìà, àti fún ọtí àmupara, àti fún àníyàn ayé yìí, tí ọjọ́ náà yóò sì fi dé bá yín lójijì bí ìkẹ́kùn.
Men tagen eder till vara för att låta edra hjärtan förtyngas av omåttlighet och dryckenskap och timliga omsorger, så att den dagen kommer på eder oförtänkt;
35 Nítorí bẹ́ẹ̀ ni yóò dé bá gbogbo àwọn tí ń gbé orí gbogbo ilẹ̀ ayé.
ty såsom en snara skall den komma över hela jordens alla inbyggare.
36 Ǹjẹ́ kì ẹ máa ṣọ́nà, kí ẹ sì máa gbàdúrà nígbà gbogbo, kí ẹ ba à lè la gbogbo nǹkan wọ̀nyí tí yóò ṣẹlẹ̀, kí ẹ sì lè dúró níwájú Ọmọ Ènìyàn.”
Men vaken alltjämt, och bedjen att I mån kunna undfly allt detta som skall komma, och kunna bestå inför Människosonen."
37 Lọ́sàn án, Jesu a sì máa kọ́ni ní tẹmpili, lóru, a sì máa jáde lọ í wọ̀ ní òkè tí à ń pè ní Òkè Olifi.
Och han undervisade om dagarna i helgedomen, men om aftnarna gick han ut till det berg som kallas Oljeberget och stannade där över natten.
38 Gbogbo ènìyàn sì ń tọ̀ ọ́ wá ní tẹmpili ní kùtùkùtù òwúrọ̀, láti gbọ́rọ̀ rẹ̀.
Och allt folket kom bittida om morgonen till honom i helgedomen för att höra honom.

< Luke 21 >