< Luke 21 >

1 Nígbà tí ó sì gbé ojú sókè, ó rí àwọn ọlọ́rọ̀ ń fi ẹ̀bùn wọn sínú àpótí ìṣúra.
Yesu alangili abhabhuene bhagosi matajiri bhabhabhekeghe zawadi sya bhene mu hazina.
2 Ó sì rí tálákà opó kan pẹ̀lú, ó ń sọ owó idẹ wẹ́wẹ́ méjì síbẹ̀.
Akambona mjane mmonga maskini ibheka senti sya muene sibhele.
3 Ó sì wí pé, “Lóòótọ́ ni mo wí fún yín, tálákà opó yìí fi sí i ju gbogbo wọn lọ,
Hivyo akajobha, kweli nikabhajobhela, ojhu mjane maskini abhekili simehele kuliko bhangi bhoha.
4 nítorí gbogbo àwọn wọ̀nyí fi sínú ẹ̀bùn Ọlọ́run láti ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìní wọn; ṣùgbọ́n òun nínú àìní rẹ̀ ó sọ gbogbo ohun ìní rẹ̀ tí ó ní sínú rẹ̀.”
Abha bhoha bhahomisi zawadi ese kuhoma mu fingi fyabhajhe nefu. Lakini ojho mjane, mu umasikini bhwa muene ahomisi hela syoha syaajhe nasu kwa ndabha jha kuishi kwa muene.”
5 Bí àwọn kan sì ti ń sọ̀rọ̀ nípa tẹmpili, bí a ti fi òkúta dáradára àti ẹ̀bùn ṣe é ní ọ̀ṣọ́, fun Ọlọ́run, Jesu wí pé
Wakati bhamana bho bhijobha panani pa hekalu, namna kyalikepambibhu ni maganga manofu ni matoleo, ajobhili,
6 “Ohun tí ẹ̀yin ń wò wọ̀nyí, ọjọ́ ń bọ̀, nígbà tí a kì yóò fi òkúta kan sílẹ̀ lórí èkejì tí a kì yóò wó lulẹ̀.”
“Kwa habari jha mambo agha ghamkaghabhona, magono ghibetakuhida ambagho lijhelepi liganga limonga ambalyo libeta kulekibhwa panani pa lenge ambalyo libeta lepi kubomolibhwa.”
7 Wọ́n sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀, pé, “Olùkọ́, nígbà wo ni nǹkan wọ̀nyí yóò rí bẹ́ẹ̀? Àti àmì kín ni yóò wà, nígbà tí nǹkan wọ̀nyí yóò fi ṣẹ?”
Hivyo bhakan'kota, bhakajobha, “Mwalimu, mambo agha ghibeta kutokela ndali? Ni kiki kibeta kujha ishara kwamba agha mambo gha jhobhi karibu kutokela?”
8 Ó sì wí pé, “Ẹ máa kíyèsára, kí a má bá à mú yín ṣìnà: nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ yóò wá ní orúkọ mi, tí yóò máa wí pé, ‘Èmi ní Kristi náà àkókò náà sì kù sí dẹ̀dẹ̀.’ Ẹ má ṣe tọ̀ wọ́n lẹ́yìn.
Yesu ajibili, “Mujhelayi bhaangalifu kwamba musikofibhu. Kwandabha bhingi bhibeta kuhida kwa lihina lya nene, ni kujobha, 'Nene ndo muene, ni muda ukaribili'. Musibhabesi.
9 Ṣùgbọ́n nígbà tí ẹ̀yin bá gbúròó ogun àti ìdágìrì, ẹ má ṣe fòyà; nítorí nǹkan wọ̀nyí ní láti kọ́kọ́ ṣẹlẹ̀, ṣùgbọ́n òpin náà kì í ṣe lójúkan náà.”
Mukapelekayi vita ni fuju musitili, kwandabha mambo agha lazima ghatokelayi hoti, lakini mwisho wibetalepi kuhomela manyata.”
10 Nígbà náà ni ó wí fún wọn pé, “Orílẹ̀-èdè yóò dìde sí orílẹ̀-èdè, àti ìjọba sí ìjọba.
Kisha akabhajobhela, “Taifa libeta kujhinuka kukomana ni taifa lenge, ni ufalme juu jha ufalme bhongi.
11 Ilẹ̀-rírì ńlá yóò sì wà káàkiri, àti ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn; ohun ẹ̀rù, àti àmì ńlá yóò sì ti ọ̀run wá.
Kubetakujha ni matetemeku mabhaha ni njala ni tauni mu maeneo mbalimbali. Kubetakujha ni matukio gha kutisya ni ishara sya kutisya kuhoma kumbinguni.
12 “Ṣùgbọ́n ṣáájú gbogbo nǹkan wọ̀nyí, wọn ó nawọ́ mú yín, wọn ó sì ṣe inúnibíni sí yín, wọn ó mú yín lọ sí Sinagọgu, àti sínú túbú, wọn ó mú yín lọ sọ́dọ̀ àwọn ọba àti àwọn ìjòyè nítorí orúkọ mi.
Lakini kabla jha mambo agha ghoha, bhibeta kubheka mabhoko ghe bhene panani pa muenga ni kubhatisya, kubhapeleka mu masinagogi ni magereza, kubhaleta mbele jha bhafalme ni bhenye mamlaka kwandabha jha lihina lya nene.
13 Ẹ o si jẹ́rìí nípa mi.
Ijhe jhibeta kufungulibhwa fursa kwa ushuhuda bhwa jhomu.
14 Nítorí náà ẹ pinnu rẹ̀ ní ọkàn yín pé ẹ ko ronú ṣáájú, bí ẹ ó ti dáhùn.
Henu muamulayi mu mioyo ghya jhomu kubela kuandala utetezi bhwinu manyata,
15 Nítorí tí èmi ó fún yín ní ẹnu àti ọgbọ́n, tí gbogbo àwọn ọ̀tá yín kì yóò lè sọ̀rọ̀-òdì sí, tí wọn kì yóò sì lè kò lójú.
Kwandabha nibeta kubhapela malobhi gha hekima, ambagho bhaadui bhinu bhoha bhibeta bhwesya lepi kujhipinga ni kujhibela.
16 A ó sì fi yín hàn láti ọwọ́ àwọn òbí yín wá, àti àwọn arákùnrin, àti àwọn ìbátan, àti àwọn ọ̀rẹ́; òun ó sì mú kì a pa nínú yín.
Lakini mwibeta kubelibhwa kabhele ni bhazazi bha jhomu, bhalongo bhinu, jamaa bhinu ni marafiki bhinu, ni kubhakoma baadhi jha muenga.
17 A ó sì kórìíra yín lọ́dọ̀ gbogbo ènìyàn nítorí orúkọ mi.
Mwibeta kudadibhwa ni khila mmonga kwandabha jha lihina lya nene.
18 Ṣùgbọ́n irun orí yín kan kì yóò ṣègbé.
Lakini lwibeta lepi kujha unywele wa vichwa vyenu utakaopotea.
19 Nínú ìdúró ṣinṣin yín ni ẹ̀yin ó jèrè ọkàn yín.
katika kuvumilia mtaziponya nafsi zenu.
20 “Nígbà tí ẹ̀yin bá sì rí ti a fi ogun yí Jerusalẹmu ká, ẹ mọ̀ nígbà náà pé, ìsọdahoro rẹ̀ kù sí dẹ̀dẹ̀.
Pamwibeta kubhona Yerusalemu jhisyonguiki ni majeshi, basi mumanyayi kujha uharibifu bhuake bhukaribili.
21 Nígbà náà ni kí àwọn tí ń bẹ ní Judea sálọ sórí òkè; àti àwọn tí ń bẹ láàrín rẹ̀ kí wọn jáde kúrò; kí àwọn tí ó sì ń bọ̀ ní ìgbèríko má ṣe wọ inú rẹ̀ wá.
Apu bhala bhabhajhele Yudea bhajumbililayi kukidonda, ni bhala bhabhajhele pagati pa jiji bhabhokayi, na musibhaleki bhabhajhele mu fijijini kujhingila.
22 Nítorí ọjọ́ ẹ̀san ni ọjọ́ wọ̀nyí, kì a lè mú ohun gbogbo tí a ti kọ̀wé rẹ̀ ṣẹ.
Mana agha ndo magono gha kisasi, ili kwamba mambo ghoha ghaghabembibhu ghatimilalayi.
23 Ṣùgbọ́n ègbé ni fún àwọn tí ó lóyún, àti àwọn tí ó fi ọyàn fún ọmọ mu ní ọjọ́ wọ̀nyí! Nítorí tí ìpọ́njú púpọ̀ yóò wà lórí ilẹ̀ àti ìbínú sí àwọn ènìyàn wọ̀nyí.
Ole ni kwa bhala bha bhajhele ni luleme ni kwa bhala bhafiele mu magono aghu! Kwa mana kubetakujha ni adha mbaha panani pa nchi, ni gadhabu kwa bhanu abha.
24 Wọn ó sì ti ojú idà ṣubú, a ó sì dìwọ́n ní ìgbèkùn lọ sí orílẹ̀-èdè gbogbo; Jerusalẹmu yóò sì di ìtẹ̀mọ́lẹ̀ lẹ́sẹ̀ àwọn aláìkọlà, títí àkókò àwọn aláìkọlà yóò fi kún.
Na bhibeta kubina kwa ncha jha upanga na bhibeta kitolibhwa mateka kwa mataifa ghoha, ni Yerusalemu jhibetakukanyibhwa ni bhanu bha mataifa, mpaka wakati bhwa bhanu bha mataifa pamwibeta kutimilika.
25 “Àmì yóò sì wà ní oorun, àti ní òṣùpá, àti ní ìràwọ̀; àti lórí ilẹ̀ ayé ìdààmú fún àwọn orílẹ̀-èdè nínú ìpayà híhó Òkun àti ìgbì omi.
Kubetakujha ni ishara mu lijobha, muesi ni mat'ondo. Ni mu nchi kubetakujha ni dhiki jha mataifa, mu kakata tamaa kutokana ni mwamujhele bha bahari ni manyegha.
26 Àyà àwọn ènìyàn yóò máa já fún ìbẹ̀rù, àti ìrètí nǹkan wọ̀nyí tí ń bọ̀ sórí ayé: nítorí àwọn agbára ọ̀run ni a ó mì tìtì.
Kubetakujha ni bhanu bhabhizimila kwa hofu ni katika kutalajila mambo ghaghibeta kuhomela panani pa dunia kwa maana nghofu sya mbigu sibetakutikisibhwa.
27 Nígbà náà ni wọn ó sì rí Ọmọ Ènìyàn tí yóò máa bọ̀ wá nínú àwọsánmọ̀ pẹ̀lú agbára àti ògo ńlá.
Kisha bhibeta kumbona mwana ghwa Adamu ihida mu mabhengu mu ngofu ni utukufu mbaha.
28 Ṣùgbọ́n nígbà tí nǹkan wọ̀nyí bá bẹ̀rẹ̀ sí í ṣẹ, ǹjẹ́ kí ẹ wo òkè, kí ẹ sì gbé orí yín sókè; nítorí ìdáǹdè yín kù sí dẹ̀dẹ̀.”
Lakini mambo agha paghibeta kujhanda kuhomela, mujhemayi, mujhinulayi mitu ghya jhomu, kwandabha ukombozi bhwa jhomu uhegelili karibu.
29 Ó sì pa òwe kan fún wọn pé, “Ẹ kíyèsi igi ọ̀pọ̀tọ́, àti sí gbogbo igi.
Yesu akabhajobhela kwa mfano, “Mubhulangayi mtini, ni mabhehe ghoha.
30 Nígbà tí wọ́n bá rúwé, ẹ̀yin rí i, ẹ sì mọ̀ fúnra ara yín pé, ìgbà ẹ̀ẹ̀rùn kù fẹ́ẹ́rẹ́.
Pajhihome sya machipukizi, mukilolela mwebhene ni kumanya kujha kilolelu tayari kijhe karibu.
31 Gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ náà ni ẹ̀yin, nígbà tí ẹ̀yin bá rí nǹkan wọ̀nyí tí o ṣẹ, kí ẹ̀yin mọ̀ pé, ìjọba Ọlọ́run kù sí dẹ̀dẹ̀.
Mebhu, pamwibhona mambo agha ghihomela, muenga mumanyayi jha kujha ufalme bhwa K'yara uhegelili.
32 “Lóòótọ́ ni mo wí fún yín, ìran yìí kì yóò rékọjá, títí gbogbo nǹkan wọ̀nyí yóò fi ṣẹ.
Kweli, nikabhajobhela, kizazi ekhe kibetalepi kupeta, mpaka mambo agha ghoha paghibeta kuhomela.
33 Ọ̀run àti ayé yóò rékọjá, ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ mi kì yóò rékọjá.
Mbingu ni nchi sibetakup'eta, lakini malobhi ghangu ghibeta lepi kup'eta kamwe.
34 “Ṣùgbọ́n ẹ máa kíyèsára yín, kí ọkàn yín má ṣe kún fún wọ̀bìà, àti fún ọtí àmupara, àti fún àníyàn ayé yìí, tí ọjọ́ náà yóò sì fi dé bá yín lójijì bí ìkẹ́kùn.
Lakini mulangayi mwabhene, ili kwamba mioyo ghya jhomu isihidi kudemebhwa ni ufisadi, ulevi, ni mahangaiku gha maisha agha. Kwandabha ligono lela libetakubhahidila ghafla.
35 Nítorí bẹ́ẹ̀ ni yóò dé bá gbogbo àwọn tí ń gbé orí gbogbo ilẹ̀ ayé.
Kama n'teghu. kwa ndabha ibeta kujha panani pa khila mmonga jhaitama mu uso bhwa dunia jhioha.
36 Ǹjẹ́ kì ẹ máa ṣọ́nà, kí ẹ sì máa gbàdúrà nígbà gbogbo, kí ẹ ba à lè la gbogbo nǹkan wọ̀nyí tí yóò ṣẹlẹ̀, kí ẹ sì lè dúró níwájú Ọmọ Ènìyàn.”
Lakini mujhelayi tayari muda bhuoha, mus'okayi kujha mwibeta kujha imara fya kutosha kughajhepa agha ghoha ghaghibeta kuhomela, ni kujhemela mbele sya mwana ghwa Adamu.”
37 Lọ́sàn án, Jesu a sì máa kọ́ni ní tẹmpili, lóru, a sì máa jáde lọ í wọ̀ ní òkè tí à ń pè ní Òkè Olifi.
Hivyo wakati wa pamusi ajhele ifundisya mu hekalu ni pakilu ahomili kwibhala, ni kulota kukesha pa kidonda kya kikutibhweghe kya Mzeituni.
38 Gbogbo ènìyàn sì ń tọ̀ ọ́ wá ní tẹmpili ní kùtùkùtù òwúrọ̀, láti gbọ́rọ̀ rẹ̀.
Bhanu bhoha bhan'hidili lukhela lubhuliku ili kumpelekesya mugati mu. hekalu.

< Luke 21 >