< Luke 21 >

1 Nígbà tí ó sì gbé ojú sókè, ó rí àwọn ọlọ́rọ̀ ń fi ẹ̀bùn wọn sínú àpótí ìṣúra.
[Jesus] looked up [from where he was sitting] and saw rich people putting their gifts into the [offering] boxes [in the Temple courtyard].
2 Ó sì rí tálákà opó kan pẹ̀lú, ó ń sọ owó idẹ wẹ́wẹ́ méjì síbẹ̀.
He also saw a poor widow putting in two [small] copper coins.
3 Ó sì wí pé, “Lóòótọ́ ni mo wí fún yín, tálákà opó yìí fi sí i ju gbogbo wọn lọ,
He said [to his disciples], “The truth is that these rich people have a lot of money, [but] they gave [only a small part of it]. But this woman, who is very poor, has put in all the money that she had to pay for the things she needs! So [God considers that] [HYP] this poor widow has put more money into the box than all the others.”
4 nítorí gbogbo àwọn wọ̀nyí fi sínú ẹ̀bùn Ọlọ́run láti ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìní wọn; ṣùgbọ́n òun nínú àìní rẹ̀ ó sọ gbogbo ohun ìní rẹ̀ tí ó ní sínú rẹ̀.”
5 Bí àwọn kan sì ti ń sọ̀rọ̀ nípa tẹmpili, bí a ti fi òkúta dáradára àti ẹ̀bùn ṣe é ní ọ̀ṣọ́, fun Ọlọ́run, Jesu wí pé
Some [of Jesus’ disciples] talked about the Temple. [They commented about] the beautiful stones [used in building the Temple] and the other decorations that [people] had given, decorations [that were on the walls]. But he said,
6 “Ohun tí ẹ̀yin ń wò wọ̀nyí, ọjọ́ ń bọ̀, nígbà tí a kì yóò fi òkúta kan sílẹ̀ lórí èkejì tí a kì yóò wó lulẹ̀.”
“[I want to tell you something about] these things that you are looking at. [They will be destroyed] {[Foreign invaders will] destroy [these buildings]} [completely]. Every stone [in these buildings] will be thrown down {They will throw down every stone in these buildings}. Not one stone will be left {They will not leave one stone} on top of another.”
7 Wọ́n sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀, pé, “Olùkọ́, nígbà wo ni nǹkan wọ̀nyí yóò rí bẹ́ẹ̀? Àti àmì kín ni yóò wà, nígbà tí nǹkan wọ̀nyí yóò fi ṣẹ?”
[Later] his disciples asked him, “Teacher, when will that happen? What will happen [to the temple] to indicate that the things [you(sg) just told us] are about to happen?”
8 Ó sì wí pé, “Ẹ máa kíyèsára, kí a má bá à mú yín ṣìnà: nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ yóò wá ní orúkọ mi, tí yóò máa wí pé, ‘Èmi ní Kristi náà àkókò náà sì kù sí dẹ̀dẹ̀.’ Ẹ má ṣe tọ̀ wọ́n lẹ́yìn.
He said, “[All that I will say is], be sure that you are not deceived {that they do not deceive [you]} [about these things]! Many [people] will come and say (that I [sent them]/that they have my authority) [MTY]. They will say, ‘I am [the Messiah]!’ They will also [say] ‘It is now the time [when God will begin to rule]!’ Do not follow them [to become their disciples]
9 Ṣùgbọ́n nígbà tí ẹ̀yin bá gbúròó ogun àti ìdágìrì, ẹ má ṣe fòyà; nítorí nǹkan wọ̀nyí ní láti kọ́kọ́ ṣẹlẹ̀, ṣùgbọ́n òpin náà kì í ṣe lójúkan náà.”
Also, whenever you hear about wars and riots, do not be terrified. Keep in mind that [God has said that] those things must happen. But [when they happen], it will not mean that [the world] will end right away!”
10 Nígbà náà ni ó wí fún wọn pé, “Orílẹ̀-èdè yóò dìde sí orílẹ̀-èdè, àti ìjọba sí ìjọba.
Then he said to them, “[Groups in various] countries will fight each other, and [various] governments [will also fight] against each other.
11 Ilẹ̀-rírì ńlá yóò sì wà káàkiri, àti ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn; ohun ẹ̀rù, àti àmì ńlá yóò sì ti ọ̀run wá.
There will be [big] earthquakes, and in various places there will be famines and plagues. [People will see] things that will terrify them. There will also be unusual things happening in the sky.
12 “Ṣùgbọ́n ṣáájú gbogbo nǹkan wọ̀nyí, wọn ó nawọ́ mú yín, wọn ó sì ṣe inúnibíni sí yín, wọn ó mú yín lọ sí Sinagọgu, àti sínú túbú, wọn ó mú yín lọ sọ́dọ̀ àwọn ọba àti àwọn ìjòyè nítorí orúkọ mi.
But before all these things happen, [some of] you will be persecuted and arrested {people will persecute some of you and arrest you} [MTY]. [Some of] you will be put {They will put [some of] you} [on trial] in the places where you gather to worship, and [you will be thrown] into prison. You will be put on trial {[They] will put you on trial} in front of high government authorities because you are my [MTY] [disciples].
13 Ẹ o si jẹ́rìí nípa mi.
That will be a time for you to tell [them about me].
14 Nítorí náà ẹ pinnu rẹ̀ ní ọkàn yín pé ẹ ko ronú ṣáájú, bí ẹ ó ti dáhùn.
So determine within yourselves not to be worrying before that happens what you will say to defend yourselves,
15 Nítorí tí èmi ó fún yín ní ẹnu àti ọgbọ́n, tí gbogbo àwọn ọ̀tá yín kì yóò lè sọ̀rọ̀-òdì sí, tí wọn kì yóò sì lè kò lójú.
because I will make you wise [HEN] so that you will [know] what to say. As a result, none of your enemies will be able to oppose what you say or (refute you/show that you are wrong).
16 A ó sì fi yín hàn láti ọwọ́ àwọn òbí yín wá, àti àwọn arákùnrin, àti àwọn ìbátan, àti àwọn ọ̀rẹ́; òun ó sì mú kì a pa nínú yín.
[And there will also be other evil things that will happen]: Even your parents and brothers and [other] relatives and friends [who do not believe in me] will (betray you/help your enemies to seize you). They will kill some of you.
17 A ó sì kórìíra yín lọ́dọ̀ gbogbo ènìyàn nítorí orúkọ mi.
[In general], most people will [HYP] hate you because [you believe in] me [MTY].
18 Ṣùgbọ́n irun orí yín kan kì yóò ṣègbé.
But your souls will be absolutely safe [IDM].
19 Nínú ìdúró ṣinṣin yín ni ẹ̀yin ó jèrè ọkàn yín.
By enduring [all these things people will do to you], you will preserve your [eternal] life [SYN].”
20 “Nígbà tí ẹ̀yin bá sì rí ti a fi ogun yí Jerusalẹmu ká, ẹ mọ̀ nígbà náà pé, ìsọdahoro rẹ̀ kù sí dẹ̀dẹ̀.
“But when you see that Jerusalem has been surrounded by the armies of [your enemies], you will know that it is time for [this city] to be completely destroyed {[them] to completely destroy [this city]}.
21 Nígbà náà ni kí àwọn tí ń bẹ ní Judea sálọ sórí òkè; àti àwọn tí ń bẹ láàrín rẹ̀ kí wọn jáde kúrò; kí àwọn tí ó sì ń bọ̀ ní ìgbèríko má ṣe wọ inú rẹ̀ wá.
At that time those [of you] who are in Judea [district] must flee to the [higher] hills. Those who are in this city must leave [quickly]. Those who are in the nearby countryside must not go back into the city [to get any of their possessions before they flee].
22 Nítorí ọjọ́ ẹ̀san ni ọjọ́ wọ̀nyí, kì a lè mú ohun gbogbo tí a ti kọ̀wé rẹ̀ ṣẹ.
[You must obey what I tell you] because, in order that all the things that are written [in the Scriptures] will be fulfilled, [God] will very severely punish [the people who stay in this city].
23 Ṣùgbọ́n ègbé ni fún àwọn tí ó lóyún, àti àwọn tí ó fi ọyàn fún ọmọ mu ní ọjọ́ wọ̀nyí! Nítorí tí ìpọ́njú púpọ̀ yóò wà lórí ilẹ̀ àti ìbínú sí àwọn ènìyàn wọ̀nyí.
[I feel] very sorry for women [in this city] who will be pregnant, and women who will be nursing [their babies] in those days, [because it will be very difficult for them to run away! I] feel sorry [because] the people in this [land] will suffer greatly [MTY] [when God punishes them].
24 Wọn ó sì ti ojú idà ṣubú, a ó sì dìwọ́n ní ìgbèkùn lọ sí orílẹ̀-èdè gbogbo; Jerusalẹmu yóò sì di ìtẹ̀mọ́lẹ̀ lẹ́sẹ̀ àwọn aláìkọlà, títí àkókò àwọn aláìkọlà yóò fi kún.
Many of them will be killed {Their enemies will kill many of them} with swords. [Others will be captured] and taken {They will capture [others] and take them} to [HYP] [other] countries. Non-Jewish people will trample over Jerusalem until the time [that God has determined for them to rule the city] is ended.”
25 “Àmì yóò sì wà ní oorun, àti ní òṣùpá, àti ní ìràwọ̀; àti lórí ilẹ̀ ayé ìdààmú fún àwọn orílẹ̀-èdè nínú ìpayà híhó Òkun àti ìgbì omi.
“There will also be strange things that will [happen to] the sun, the moon, and the stars. In [many] nations, [people] will be very frightened, and they will be anxious [when they hear] the ocean roaring and [see huge] waves.
26 Àyà àwọn ènìyàn yóò máa já fún ìbẹ̀rù, àti ìrètí nǹkan wọ̀nyí tí ń bọ̀ sórí ayé: nítorí àwọn agbára ọ̀run ni a ó mì tìtì.
People will faint because they will be afraid as they wait for what will happen. [They will be afraid] because the powerful [objects] in the sky will be shaken {shake}.
27 Nígbà náà ni wọn ó sì rí Ọmọ Ènìyàn tí yóò máa bọ̀ wá nínú àwọsánmọ̀ pẹ̀lú agbára àti ògo ńlá.
Then they will see [me], the one who came from heaven, coming in a cloud powerfully and very gloriously.
28 Ṣùgbọ́n nígbà tí nǹkan wọ̀nyí bá bẹ̀rẹ̀ sí í ṣẹ, ǹjẹ́ kí ẹ wo òkè, kí ẹ sì gbé orí yín sókè; nítorí ìdáǹdè yín kù sí dẹ̀dẹ̀.”
So when these things that [I have just now described] begin to happen, stand up [straight and] be brave, because it will be close to the time when [God] will free you [from all suffering].”
29 Ó sì pa òwe kan fún wọn pé, “Ẹ kíyèsi igi ọ̀pọ̀tọ́, àti sí gbogbo igi.
[Then] Jesus told his disciples this parable: “Think about the fig tree, and all the [other] trees.
30 Nígbà tí wọ́n bá rúwé, ẹ̀yin rí i, ẹ sì mọ̀ fúnra ara yín pé, ìgbà ẹ̀ẹ̀rùn kù fẹ́ẹ́rẹ́.
As soon as you see their leaves beginning to sprout, you know that summer is near.
31 Gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ náà ni ẹ̀yin, nígbà tí ẹ̀yin bá rí nǹkan wọ̀nyí tí o ṣẹ, kí ẹ̀yin mọ̀ pé, ìjọba Ọlọ́run kù sí dẹ̀dẹ̀.
Similarly, when you see these things that [I have just described] happening, you will know that it is almost time for God to [truly] rule as king.
32 “Lóòótọ́ ni mo wí fún yín, ìran yìí kì yóò rékọjá, títí gbogbo nǹkan wọ̀nyí yóò fi ṣẹ.
Keep this in mind: All the things that [I have just now described] will happen before all the people who have observed the things that I have done have died.
33 Ọ̀run àti ayé yóò rékọjá, ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ mi kì yóò rékọjá.
[You can be certain that these things] that I have told [you] about will happen. That they will happen is more [certain] than that the earth and sky will continue to exist.”
34 “Ṣùgbọ́n ẹ máa kíyèsára yín, kí ọkàn yín má ṣe kún fún wọ̀bìà, àti fún ọtí àmupara, àti fún àníyàn ayé yìí, tí ọjọ́ náà yóò sì fi dé bá yín lójijì bí ìkẹ́kùn.
“But be on guard. Do not be getting drunk with carousing or let yourselves be distracted by worries [concerning] your lives [SYN] {or let worries [concerning] your lives [SYN] distract you}. [If you do wrong things like those, you may be suddenly surprised by my return] [MTY], like a trap [suddenly catches an animal in it].
35 Nítorí bẹ́ẹ̀ ni yóò dé bá gbogbo àwọn tí ń gbé orí gbogbo ilẹ̀ ayé.
[You need to know that my return will surprise] everyone all over the earth.
36 Ǹjẹ́ kì ẹ máa ṣọ́nà, kí ẹ sì máa gbàdúrà nígbà gbogbo, kí ẹ ba à lè la gbogbo nǹkan wọ̀nyí tí yóò ṣẹlẹ̀, kí ẹ sì lè dúró níwájú Ọmọ Ènìyàn.”
So be ready at all times. Pray that you will be able to endure without being afraid of all these [difficult] things that will happen, so that you will then stand [confidently] before me, the one who came from heaven.”
37 Lọ́sàn án, Jesu a sì máa kọ́ni ní tẹmpili, lóru, a sì máa jáde lọ í wọ̀ ní òkè tí à ń pè ní Òkè Olifi.
Each day [during that week Jesus] taught the people in the Temple [courtyard in Jerusalem]. But at night he [and his disciples] left [the city] and stayed on Olive [Tree] Hill.
38 Gbogbo ènìyàn sì ń tọ̀ ọ́ wá ní tẹmpili ní kùtùkùtù òwúrọ̀, láti gbọ́rọ̀ rẹ̀.
Early [each] morning many people came to the Temple [courtyard] to listen to him.

< Luke 21 >