< Luke 20 >

1 Ní ọjọ́ kan, bí ó ti ń kọ́ àwọn ènìyàn ní tẹmpili tí ó sì ń wàásù ìyìnrere, àwọn olórí àlùfáà, àti àwọn akọ̀wé, pẹ̀lú àwọn àgbàgbà dìde sí i.
In pripetilo se je, da so na enega izmed tistih dni, ko je v templju učil ljudi in oznanjal evangelij, prišli nad njega visoki duhovniki in pisarji s starešinami
2 Wọ́n sì wí fún un pé, “Sọ fún wa, àṣẹ wo ni ìwọ fi ń ṣe nǹkan wọ̀nyí? Tàbí ta ni ó fún ọ ní àṣẹ yìí?”
in mu spregovorili, rekoč: »Povej nam, s kakšno oblastjo delaš te stvari? Ali kdo je tisti, ki ti je dal to oblast?«
3 Ó sì dáhùn ó sì wí fún wọn pé, “Èmi pẹ̀lú yóò sì bi yín léèrè ọ̀rọ̀ kan; ẹ sì fi ìdáhùn fún mi.
In odgovoril je ter jim rekel: »Tudi jaz vas bom vprašal eno besedo in odgovorite mi:
4 Ìtẹ̀bọmi Johanu, láti ọ̀run wá ni tàbí láti ọ̀dọ̀ ènìyàn?”
›Ali je bil Janezov krst iz nebes ali od ljudi?‹«
5 Wọ́n sì bá ara wọn gbèrò pé, “Bí àwa bá wí pé, ‘Láti ọ̀run wá ni,’ òun yóò wí pé, ‘Èéṣe tí ẹ̀yin kò fi gbà á gbọ́?’
Oni pa so razpravljali med seboj, rekoč: »Če bomo rekli: ›Iz nebes, ‹ bo rekel: ›Zakaj mu potem niste verjeli?‹
6 Ṣùgbọ́n bí àwa bá sì wí pé, ‘Láti ọ̀dọ̀ ènìyàn,’ gbogbo ènìyàn ni yóò sọ wá ní òkúta, nítorí wọ́n gbàgbọ́ pé, wòlíì ni Johanu.”
Toda če rečemo: ›Od ljudi, ‹ nas bodo vsi ljudje kamnali, kajti pregovorjeni so, da je bil Janez prerok.«
7 Wọ́n sì dáhùn wí pé, “Àwa kò mọ̀ ibi tí ó ti wá.”
In odgovorili so, da ne morejo povedati, od kod je bil.
8 Jesu sì wí fún wọn pé, “Ǹjẹ́ èmi kì yóò wí fún yín àṣẹ tí èmi fi ń ṣe nǹkan wọ̀nyí.”
In Jezus jim je rekel: »Niti vam jaz ne povem, s kakšno oblastjo delam te stvari.«
9 Nígbà náà ni ó bẹ̀rẹ̀ sí í pa òwe yìí fún àwọn ènìyàn pé, “Ọkùnrin kan gbin ọgbà àjàrà kan, ó sì fi ṣe àgbàtọ́jú fún àwọn olùṣọ́gbà, ó sì lọ sí àjò fún ìgbà pípẹ́.
Potem je začel ljudem govoriti to prispodobo: »Neki človek je zasadil vinograd in ga prepustil poljedelcem ter za dolgo časa odšel v daljno deželo.
10 Nígbà tí ó sì tó àkókò, ó rán ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ kan sí àwọn olùṣọ́gbà náà, kí wọn lè fún un nínú èso ọgbà àjàrà náà, ṣùgbọ́n àwọn alágbàtọ́jú lù ú, wọ́n sì rán an padà lọ́wọ́ òfo.
Ob primernem obdobju pa je poslal k poljedelcem služabnika, da bi mu lahko dali od sadu vinograda, toda poljedelci so ga pretepli in ga odposlali praznega.
11 Ó sì tún rán ọmọ ọ̀dọ̀ mìíràn, wọ́n sì lù ú pẹ̀lú, wọ́n sì jẹ ẹ́ ní yà, wọ́n sì rán an padà lọ́wọ́ òfo.
On pa je ponovno poslal drugega služabnika in tudi njega so pretepli in sramotno ravnali z njim ter ga odposlali praznega.
12 Ó sì tún rán ẹ̀kẹta: wọ́n sì sá a lọ́gbẹ́ pẹ̀lú, wọ́n sì tì í jáde.
Pa je ponovno poslal tretjega in tudi njega so ranili ter ga vrgli ven.
13 “Nígbà náà ni Olúwa ọgbà àjàrà wí pé, ‘Èwo ni èmi ó ṣe? Èmi ó rán ọmọ mi àyànfẹ́ lọ: bóyá nígbà tí wọ́n bá rí i, wọn yóò bu ọlá fún un.’
Potem je gospodar vinograda rekel: ›Kaj naj storim? Poslal bom svojega ljubljenega sina. Ko ga bodo videli, ga bodo mogoče spoštovali.‹
14 “Ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn alágbàtọ́jú náà rí i, wọ́n bá ara wọn gbèrò pé, ‘Èyí ni àrólé; ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a pa á, kí ogún rẹ̀ lè jẹ́ ti wa.’
Toda ko so ga poljedelci zagledali, so med seboj razpravljali, rekoč: ›Ta je dedič. Pridite, ubijmo ga, da bo dediščina lahko naša.‹
15 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì tì í jáde sẹ́yìn ọgbà àjàrà, wọ́n sì pa á. “Ǹjẹ́ kín ni olúwa ọgbà àjàrà náà yóò ṣe sí wọn?
Tako so ga vrgli iz vinograda in ga ubili. Kaj jim bo torej storil gospodar vinograda?
16 Yóò wá, yóò sì pa àwọn alágbàtọ́jú náà run, yóò sì fi ọgbà àjàrà náà fún àwọn ẹlòmíràn.” Nígbà tí wọ́n sì gbọ́, wọ́n ní, “Kí a má ri i!”
Prišel bo in uničil te poljedelce, vinograd pa bo dal drugim.« Ko pa so to slišali, so rekli: »Bog ne daj.«
17 Nígbà tí ó sì wò wọ́n, ó ní, “Èwo ha ni èyí tí a ti kọ̀wé rẹ̀ pé: “‘Òkúta tí àwọn ọ̀mọ̀lé kọ̀sílẹ̀, òun náà ni ó di pàtàkì igun ilé’?
On pa jih je pogledal in rekel: »Kaj je torej to, kar je pisano: ›Kamen, ki so ga graditelji zavrgli, ta isti je postal glava vogalu?‹
18 Ẹnikẹ́ni tí ó ṣubú lu òkúta náà yóò fọ́; ṣùgbọ́n ẹnikẹ́ni tí òun bá ṣubú lù, yóò lọ̀ ọ́ lúúlúú.”
Kdorkoli bo padel na ta kamen, bo razbit, toda na kogarkoli bo ta padel, ga bo zmlel v prah.‹«
19 Àwọn olórí àlùfáà àti àwọn akọ̀wé ń wá ọ̀nà láti mú un ní wákàtí náà; ṣùgbọ́n wọ́n bẹ̀rù àwọn ènìyàn, nítorí tí wọ́n mọ̀ pé, ó pa òwe yìí mọ́ wọn.
In visoki duhovniki ter pisarji so skušali to isto uro položiti roke nanj; bali pa so se ljudi, kajti zaznali so, da je to prispodobo govoril proti njim.
20 Wọ́n sì ń ṣọ́ ọ, wọ́n sì rán àwọn ayọ́lẹ̀wò tí wọ́n ṣe ara wọn bí ẹni pé olóòtítọ́ ènìyàn, kí wọn ba à lè gbá ọ̀rọ̀ rẹ̀ mú, kí wọn ba à lè fi í lé agbára àti àṣẹ Baálẹ̀ lọ́wọ́.
In opazovali so ga ter poslali oglednike, ki naj bi se hlinili [za] pravične može, da bi ga lahko prijeli za njegove besede, da bi ga tako lahko izročili voditeljevi moči in oblasti.
21 Wọ́n sì bí i, pé, “Olùkọ́ àwa mọ̀ pé, ìwọ a máa sọ̀rọ̀ fún ni, ìwọ a sì máa kọ́ni bí ó ti tọ́, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kì í ṣe ojúsàájú ẹnìkan ṣùgbọ́n ìwọ ń kọ́ni ní ọ̀nà Ọlọ́run lóòtítọ́.
In vprašali so ga, rekoč: »Učitelj, vemo, da prav govoriš in učiš niti ne sprejemaš zunanjega videza kogarkoli, temveč resnično učiš Božjo pot:
22 Ǹjẹ́ ó tọ́ fún wa láti máa san owó òde fún Kesari, tàbí kò tọ́?”
›Ali je za nas zakonito, da dajemo cesarju davek ali ne?‹«
23 Ṣùgbọ́n ó kíyèsi àrékérekè wọn, ó sì wí fún wọn pé,
Vendar je zaznal njihovo prebrisanost in jim rekel: »Zakaj me skušate?
24 “Ẹ fi owó idẹ kan hàn mí. Àwòrán àti àkọlé ti ta ni ó wà níbẹ̀?” Wọ́n sì dá a lóhùn pé, “Ti Kesari ni.”
Pokažite mi kovanec. Čigavo podobo in napis ima?« Odgovorili so in rekli: »Cesarjevo.«
25 Ó sì wí fún wọn pé, “Ǹjẹ́ ẹ fi ohun tí i ṣe ti Kesari fún Kesari, àti ohun tí í ṣe ti Ọlọ́run fún Ọlọ́run.”
In rekel jim je: »Povrnite torej cesarju stvari, ki so cesarjeve, Bogu pa stvari, ki so Božje.«
26 Wọn kò sì lè gbá ọ̀rọ̀ rẹ̀ mú níwájú àwọn ènìyàn: ẹnu sì yà wọ́n sí ìdáhùn rẹ̀, wọ́n sì pa ẹnu wọn mọ́.
In pred ljudmi ga niso mogli prijeti zaradi njegovih besed in čudili so se ob njegovem odgovoru in molčali.
27 Àwọn Sadusi kan sì tọ̀ ọ́ wá, àwọn tí wọ́n ń wí pé àjíǹde òkú kò sí wọ́n sì bi í,
Potem so prišli k njemu nekateri izmed saducejev, ki zanikajo, da obstaja kakršnokoli vstajenje in vprašali so ga,
28 wí pé, “Olùkọ́, Mose kọ̀wé fún wa pé, Bí arákùnrin ẹnìkan bá kú, ní àìlọ́mọ, tí ó sì ní aya, kí arákùnrin rẹ̀ ṣú aya rẹ̀ lópó, kí ó lè gbé irú-ọmọ dìde fún arákùnrin rẹ̀.
rekoč: »Učitelj, Mojzes nam je napisal: ›Če komu umre brat, ki ima ženo in umre brez otrok, da naj njegov brat vzame njegovo ženo in svojemu bratu obudi seme.
29 Ǹjẹ́ àwọn arákùnrin méje kan ti wà; èkínní gbé ìyàwó, ó sì kú ní àìlọ́mọ.
Bilo je torej sedem bratov in prvi je vzel ženo ter umrl brez otrok.
30 Èkejì sì ṣú u lópó: òun sì kú ní àìlọ́mọ.
In drugi jo je vzel za ženo ter umrl brez otrok.
31 Ẹ̀kẹta sì ṣú u lópó: gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ sì ni àwọn méjèèje pẹ̀lú: wọn kò sì fi ọmọ sílẹ̀, wọ́n sì kú.
In vzel jo je tretji in na podoben način tudi sedmi, pa niso zapustili otrok in so umrli.
32 Nígbẹ̀yìn pátápátá obìnrin náà kú pẹ̀lú.
Zadnja izmed vseh je umrla tudi ženska.
33 Ǹjẹ́ ní àjíǹde òkú, aya ti ta ni yóò ha ṣe nínú wọn? Nítorí àwọn méjèèje ni ó sá à ni í ní aya.”
Čigava žena od teh bo torej ob vstajenju? Kajti sedem jo je imelo za ženo.‹«
34 Jesu sì dáhùn ó wí fún wọn pé, “Àwọn ọmọ ayé yìí a máa gbéyàwó, wọn a sì máa fa ìyàwó fún ni. (aiōn g165)
Jezus jim odgovori in reče: »Otroci tega sveta se poročajo in so dane v zakon, (aiōn g165)
35 Ṣùgbọ́n àwọn tí a kà yẹ láti jogún ìyè ayérayé náà, àti àjíǹde kúrò nínú òkú, wọn kì í gbéyàwó, wọn kì í sì í fa ìyàwó fún ni. (aiōn g165)
toda tisti, ki bodo šteti za vredne, da dosežejo oni svet in vstajenje od mrtvih, se ne bodo niti poročali, niti ne bodo dane v zakon, (aiōn g165)
36 Nítorí wọn kò lè kú mọ́; nítorí tí wọn bá àwọn angẹli dọ́gba; àwọn ọmọ Ọlọ́run sì ni wọ́n, nítorí wọ́n di àwọn ọmọ àjíǹde.
niti ne morejo več umreti, kajti enaki so angelom in so Božji otroci, saj so otroci vstajenja.
37 Ní ti pé a ń jí àwọn òkú dìde, Mose tìkára rẹ̀ sì ti fihàn nínú igbó, nígbà tí ó pe ‘Olúwa ni Ọlọ́run Abrahamu, àti Ọlọ́run Isaaki, àti Ọlọ́run Jakọbu.’
Torej, da so mrtvi obujeni, je pokazal celó Mojzes pri grmu, ko je imenoval Gospoda ›Bog Abrahamov in Bog Izakov in Bog Jakobov.‹
38 Bẹ́ẹ̀ ni òun kì í ṣe Ọlọ́run àwọn òkú, bí kò ṣe ti àwọn alààyè, nítorí gbogbo wọn wà láààyè fún un.”
Kajti on ni Bog mrtvih, temveč živih, kajti njemu vsi živijo.«
39 Nígbà náà ni àwọn kan nínú àwọn akọ̀wé dá a lóhùn, pé, “Olùkọ́ ìwọ wí rere!”
Tedaj so nekateri izmed pisarjev odgovorili in rekli: »Učitelj, dobro si povedal.«
40 Wọn kò sì jẹ́ bi í léèrè ọ̀rọ̀ kan mọ́.
Nató pa se ga niso drznili vprašati nobenega vprašanja več.
41 Ó sì wí fún wọn pé, “Èéṣe tí wọ́n fi ń wí pé, ọmọ Dafidi ni Kristi?
In rekel jim je: »Kako pravijo, da je Kristus Davidov sin?
42 Dafidi tìkára rẹ̀ sì wí nínú ìwé Saamu pé: “‘Olúwa sọ fún Olúwa mi pé: “Ìwọ jókòó ní ọwọ́ ọ̀tún mi
In sam David pravi v knjigi Psalmov: › Gospod je rekel mojemu Gospodu: ›Sedi na mojo desnico,
43 títí èmi ó fi sọ àwọn ọ̀tá rẹ di àpótí ìtìsẹ̀ rẹ.”’
dokler ne naredim tvojih sovražnikov [za] tvojo pručko.‹‹
44 Ǹjẹ́ bí Dafidi bá pè é ní ‘Olúwa.’ Òun ha sì ti ṣe jẹ́ ọmọ rẹ̀?”
David mu torej reče Gospod, kako je potem on njegov sin?«
45 Ó sì wí fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ ní etí gbogbo ènìyàn pé,
Potem je pred občinstvom vseh ljudi svojim učencem rekel:
46 “Ẹ máa kíyèsára lọ́dọ̀ àwọn akọ̀wé, tí wọ́n fẹ́ láti máa rìn nínú aṣọ gígùn, tí wọ́n sì fẹ́ ìkíni ní ọjà, àti ibùjókòó ọlá nínú Sinagọgu, àti ipò ọlá ní ibi àsè;
»Pazite se pisarjev, ki želijo hoditi v dolgih svečanih oblačilih in imajo radi pozdrave na trgih in najvišje sedeže v sinagogah ter vodilna mesta na praznovanjih,
47 Àwọn tí ó jẹ ilé àwọn opó run, tí wọ́n sì ń gbàdúrà gígùn fún àṣehàn, àwọn wọ̀nyí náà ni yóò jẹ̀bi pọ̀jù.”
ki vdovam požirajo hiše in zaradi lepšega delajo dolge molitve; isti bodo prejeli večje prekletstvo.«

< Luke 20 >