< Luke 17 >

1 Ó sì wí fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ pé, “Kò le ṣe kí ohun ìkọ̀sẹ̀ máa wa, ṣùgbọ́n ègbé ni fún ẹni tí ó ti ipasẹ̀ rẹ̀ dé.
He said then to the disciples (of Him; *no) Impossible it is that the stumbling blocks not to come, (but *N+kO) woe [to him] through whom they come!
2 Ìbá sàn fún un kí a so ọlọ mọ́ ọn ní ọrùn, kí a sì gbé e jù sínú Òkun, ju kí ó mú ọ̀kan nínú àwọn kékeré wọ̀nyí kọsẹ̀.
It is better for him if (a stone of a mill *N+kO) is hung around the neck of him and he has been thrown into the sea than that he may cause to stumble little [ones] of these one.
3 Ẹ máa kíyèsára yín. “Bí arákùnrin rẹ bá ṣẹ̀, bá a wí; bí ó bá sì ronúpìwàdà, dáríjì ín.
do take heed to yourselves. If (now *k) shall sin (against *k) (you *K) the brother of you, do rebuke him; and if he shall repent, do forgive him.
4 Bí ó bá sì ṣẹ̀ ọ́ ní igba méje ní òòjọ́, tí ó padà tọ̀ ọ́ wá ní ìgbà méje ní òòjọ́ pé, ‘Mo ronúpìwàdà,’ dáríjì ín.”
And if seven times in the day (he shall sin *N+kO) against you and seven times (day *k) shall return (to *N+kO) you saying: I repent, you will forgive him.
5 Àwọn aposteli sì wí fún Olúwa pé, “Bù sí ìgbàgbọ́ wa.”
And said the apostles to the Lord; do add to us faith!
6 Olúwa sì wí pé, “Bí ẹ̀yin bá ní ìgbàgbọ́ bí hóró irúgbìn musitadi, ẹ̀yin yóò lè wí fún igi sikamine yìí pé, ‘Di fi fà á tu, kí a sì gbìn ọ́ sínú Òkun,’ yóò sì gbọ́ tiyín.
Said then the Lord; If (you have *N+kO) faith like a grain of mustard, you have spoken then would to the mulberry tree this; do be uprooted and do be planted in the sea, and it have obeyed would you.
7 “Ṣùgbọ́n ta ni nínú yín, tí ó ní ọmọ ọ̀dọ̀, tí ó ń tulẹ̀, tàbí tí ó ń bọ́ ẹran, tí yóò wí fún un lójúkan náà tí ó bá ti oko dé pé, ‘Lọ í jókòó láti jẹun’?
Which now of you a servant having plowing or shepherding, the [one] having come in out of the field will say to him; Immediately having come (do recline? *N+kO)
8 Tí kì yóò kúkú wí fún un pé, ‘Pèsè ohun tí èmi yóò jẹ, sì di àmùrè, kí ìwọ kí ó máa ṣe ìránṣẹ́ fún mi, títí èmi ó fi jẹ kí èmi ó sì mu tán; lẹ́yìn náà ni ìwọ ó sì jẹ, tí ìwọ ó sì mu’?
But surely he will say to him; do prepare what I may eat, and having girded yourself about do serve me while I may eat and I may drink, and after these things you will eat and will drink you yourself?’
9 Òun ó ha máa dá ọpẹ́ lọ́wọ́ ọmọ ọ̀dọ̀ náà, nítorí ó ṣe ohun tí a pàṣẹ fún un bí? Èmi kò rò bẹ́ẹ̀.
Not is he thankful to the servant (that [one] *k) because he did the [things] having been commanded (to him not I think? *K)
10 Gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin pẹ̀lú, nígbà tí ẹ bá ti ṣe ohun gbogbo tí a pàṣẹ fún yín tán, ẹ wí pé, ‘Aláìlérè ọmọ ọ̀dọ̀ ni wá: èyí tí í ṣe iṣẹ́ wa láti ṣe, ní àwa ti ṣe.’”
Thus also you yourselves, when you may have done all the [things] having been commanded you, do say that Servants unworthy are we; (for *k) that which (we were obliged *NK+o) to do we have done.
11 Ó sì ṣe, bí ó ti ń lọ sí Jerusalẹmu, ó kọjá láàrín Samaria Galili.
And it came to pass in the going up (him *ko) to Jerusalem that He himself was passing through ([the] midst *N+kO) of Samaria and Galilee.
12 Bí ó sì ti ń wọ inú ìletò kan lọ, àwọn ọkùnrin adẹ́tẹ̀ mẹ́wàá pàdé rẹ̀, wọ́n dúró ní òkèrè,
And when is entering He into a certain village met with Him ten leprous men, who (stood *NK+O) afar off.
13 wọ́n sì kígbe sókè wí pé, “Jesu, Olùkọ́, ṣàánú fún wa.”
And they themselves lifted up [their] voice saying; Jesus Master, do have compassion on us.
14 Nígbà tí ó rí wọn, ó wí fún wọn pé, “Ẹ lọ í fi ara yín hàn fún àwọn àlùfáà.” Ó sì ṣe, bí wọ́n ti ń lọ, wọ́n sì di mímọ́.
And having seen [them] He said to them; Having gone do show yourselves to the priests. And it came to pass in the going them, they were cleansed.
15 Nígbà tí ọ̀kan nínú wọn rí i pé a mú òun láradá ó padà, ó sì fi ohùn rara yin Ọlọ́run lógo.
one then of them having seen that he was healed, turned back with a voice loud glorifying God.
16 Ó sì wólẹ̀ lẹ́bàá ẹsẹ̀ rẹ̀, ó ń dúpẹ́ ní ọwọ́ rẹ̀: ará Samaria ni òun í ṣe.
and he fell on [his] face at the feet of Him giving thanks to Him; and he himself was a Samaritan.
17 Jesu sì dáhùn wí pé, “Àwọn mẹ́wàá kí a sọ di mímọ́? Àwọn mẹ́sàn-án ìyókù ha dà?
Having answered then Jesus said; (surely *NK+o) the ten were cleansed? But the nine are where?
18 A kò rí ẹnìkan tí ó padà wá fi ògo fún Ọlọ́run, bí kò ṣe àlejò yìí?”
None was there found having returned to give glory to God only except foreigner this?
19 Ó sì wí fún un pé, “Dìde, kí o sì máa lọ, ìgbàgbọ́ rẹ mú ọ láradá.”
And He said to him; Having risen up do go forth; the faith of you has cured you!
20 Nígbà tí àwọn Farisi bi í pé, nígbà wo ni ìjọba Ọlọ́run yóò dé, ó dá wọn lóhùn pé, “Ìjọba Ọlọ́run kì í wá pẹ̀lú àmì.
Having been asked now by the Pharisees when is coming the kingdom of God, He answered to them and said; Not comes the kingdom of God with careful observation,
21 Bẹ́ẹ̀ ni wọn kì yóò wí pé, ‘Kíyèsi i níhìn-ín!’ tàbí ‘Kíyèsi i lọ́hùn ún ni!’ sá à wò ó, ìjọba Ọlọ́run ń bẹ nínú yín.”
nor will they say; Behold here or (behold *ko) There. Behold for the kingdom of God in the midst of you is.
22 Ó sì wí fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ pé, “Ọjọ́ ń bọ̀, nígbà tí ẹ̀yin yóò fẹ́ láti rí ọ̀kan nínú ọjọ́ Ọmọ Ènìyàn, ẹ̀yin kì yóò sì rí i.
He said then to the disciples; Will come days when you will desire one of the days of the Son of Man to see and not you will behold [it].
23 Wọ́n sì wí fún yín pé, ‘Wò ó níhìn-ín!’ tàbí ‘Wò ó lọ́hùn ún!’ Ẹ máa lọ, ẹ má ṣe tẹ̀lé wọn.
And they will say to you; Behold there or Behold here. Not may go forth nor may follow.
24 Nítorí gẹ́gẹ́ bí mọ̀nàmọ́ná ti í kọ ní apá kan lábẹ́ ọ̀run, tí sì í mọ́lẹ̀ ní apá kejì lábẹ́ ọ̀run, bẹ́ẹ̀ ni Ọmọ Ènìyàn yóò sì rí ní ọjọ́ rẹ̀.
As for the lightning (which *ko) is flashing from the [one end] under (the *no) sky to the [other end] under [the] sky shines, thus will be (also *k) the Son of Man in the day of Him.
25 Ṣùgbọ́n kò lè ṣàìmá kọ́ jìyà ohun púpọ̀, kí a sì kọ̀ ọ́ lọ́dọ̀ ìran yìí.
First however it behooves Him many things to suffer and to be rejected by generation this.
26 “Bí ó ti rí ní ọjọ́ Noa, bẹ́ẹ̀ ni yóò rí ní ọjọ́ Ọmọ Ènìyàn.
And even as it came to pass in the days of Noah, thus will it be also in the days of the Son of man:
27 Wọ́n ń jẹ, wọ́n ń mu, wọ́n ń gbéyàwó, wọ́n sì ń fa ìyàwó fún ni, títí ó fi di ọjọ́ ti Noa wọ inú ọkọ̀ lọ, kíkún omi sì dé, ó sì run gbogbo wọn.
They were eating, were drinking, were marrying, (were being given in marriage, *N+kO) until that day entered Noah into the ark, and came the flood and destroyed (all. *N+kO)
28 “Bí ó sì ti rí ní ọjọ́ Lọti; wọ́n ń jẹ, wọ́n ń mu, wọ́n ń rà, wọ́n ń tà, wọ́n ń gbìn, wọ́n ń kọ́lé,
Likewise (even as *N+kO) it came to pass in the days of Lot; they were eating, they were drinking, they were buying, they were selling, they were planting, they were building.
29 ṣùgbọ́n ní ọjọ́ náà tí Lọti jáde kúrò ní Sodomu, òjò iná àti sulfuru rọ̀ láti ọ̀run wá, ó sì run gbogbo wọn.
in that then day went out Lot from Sodom, it rained fire and brimstone from heaven and destroyed (all; *N+kO)
30 “Gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni yóò rí ní ọjọ́ náà tí Ọmọ Ènìyàn yóò farahàn.
According (to these *N+kO) will it be in that day the Son of Man is revealed.
31 Ní ọjọ́ náà, ẹni tí ó bá wà lórí ilé, tí ẹrù rẹ̀ sì ń bẹ ní ilẹ̀, kí ó má ṣe sọ̀kalẹ̀ láti wá kó o; ẹni tí ó bá sì wà ní oko, kí ó má ṣe padà sẹ́yìn.
In that [very] day the [one who] will be on the housetop and the goods of him in the house, not he should come down to take away them; and the [one] in (the *k) field likewise not he should return to the [things] back.
32 Ẹ rántí aya Lọti.
do remember the wife of Lot!
33 Ẹnikẹ́ni tí ó bá ń wá àti gba ẹ̀mí rẹ̀ là yóò sọ ọ́ nù; ẹnikẹ́ni tí ó bá sì sọ ọ́ nù yóò gbà á là.
Who[ever] if shall seek the life of him (to gain *N+KO) will lose it, (and *k) who[ever] (but *no) (maybe *N+kO) (shall lose *NK+o) (it *k) will preserve it.
34 Mo wí fún yín, ní òru ọjọ́ náà, ènìyàn méjì yóò wà lórí àkéte kan; a ó mú ọ̀kan, a ó sì fi èkejì sílẹ̀.
I say to you; in that night there will be two upon bed one: The one will be taken, and the other will be left.
35 Ènìyàn méjì yóò sì máa lọ ọlọ pọ̀; a ó mú ọ̀kan, a ó sì fi èkejì sílẹ̀.”
There will be two [women] grinding at the same [place]; (The *no) one will be taken, (and *k) (and *no) the other will be left.
(two in field; one will be taken and another it will be left *K)
37 Wọ́n sì dá a lóhùn, wọ́n bi í pé, “Níbo, Olúwa?” Ó sì wí fún wọn pé, “Níbi tí òkú bá gbé wà, níbẹ̀ pẹ̀lú ni igún ìkójọpọ̀ sí.”
And answering they say to Him; Where, Lord? And He said to them; Where the body [is], there (also *no) the vultures (will be gathered. *N+kO)

< Luke 17 >