< Luke 16 >

1 Ó sì wí fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ pẹ̀lú pé, “Ọkùnrin ọlọ́rọ̀ kan wà, tí ó ní ìríjú kan; òun náà ni wọ́n fi sùn ún pé, ó ti ń fi ohun ìní rẹ̀ ṣòfò.
Asta usporedbă isto Isus u spus alu učenici: “Are om găzdak kari u dat lukru alu unu upravitelj, šă ju fost spus aluj kă upravitelju čăltešći šă răsăpă găzdăšije alu gazda aluj.
2 Nígbà tí ó sì pè é, ó wí fún un pé, ‘Èéṣe tí èmi fi ń gbọ́ èyí sí ọ? Ṣírò iṣẹ́ ìríjú rẹ; nítorí ìwọ kò lè ṣe ìríjú mi mọ́.’
Aša lu čimat pă jăl šă ju zăs: ‘Šje ăj asta šje audă dă činji? Dăm računu dă kutotu šje aj făkut, kă tu maj mult nu poc fi upravitelj!’
3 “Ìríjú náà sì wí nínú ara rẹ̀ pé, ‘Èwo ni èmi ó ṣe? Nítorí tí olúwa mi gba iṣẹ́ ìríjú lọ́wọ́ mi: èmi kò le ṣiṣẹ́ oko, bẹ́ẹ̀ ni ojú ń tì mí láti ṣagbe.
Upravitelju u zăs atunšje aluj săngur: ‘Šje să fak, aku kănd gazda je ăndărăt lukru dă la minji? Nu am pučeri să kapalesk? U fi rušănji să mă duk să kuldujesk.
4 Mo mọ èyí tí èmi yóò ṣe, nígbà tí a bá mú mi kúrò níbi iṣẹ́ ìríjú, kí àwọn ènìyàn le gbà mí sínú ilé wọn.’
Šćuv šje uj fašji! Ju uj đirežji aša dă kănd mur măna dăm lukrusta tot uj fi apukat ăm benji la kăšălje ominjistora.’
5 “Ó sì pe àwọn ajigbèsè olúwa rẹ̀ sọ́dọ̀ rẹ̀, ó sì wí fún èkínní pé, ‘Èló ni ìwọ jẹ olúwa mi?’
Aša jăl u mănat dă pă ominji šje as re dator alu gazda aluj, unu pă kići unu. Jăl u ăntribat pă elši om: ‘Kit ješć dător alu gazda amnjov?’
6 “Ó sì wí pé, ‘Ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rún òsùwọ̀n òróró.’ “Ó sì wí fún un pé, ‘Mú ìwé rẹ, sì jókòó nísinsin yìí, kí o sì kọ àádọ́ta lé ní irinwó.’
Jăl u ăntors vorba: ‘Sto bačvur dă uloj dăm maslinur.’ Upravitelju u zăs: ‘Šăz žjos, jec računu šă pă friš skrijă pedeset.’
7 “Nígbà náà ni ó sì bi ẹnìkejì pé, ‘Èló ni ìwọ jẹ?’ “Òun sì wí pé, ‘Ẹgbẹ̀rún òsùwọ̀n alikama.’ “Ó sì wí fún un pé, ‘Mú ìwé rẹ, kí o sì kọ ẹgbẹ̀rin.’
Šă jăl u ăntribat pă altu om: ‘Kit ješć tu dător?’ ‘Sto merur dă pšenică.’ Šă jăl ju zăs aluj: ‘Jec računu šă skrijă osamdeset.’
8 “Olúwa rẹ̀ sì yin aláìṣòótọ́ ìríjú náà, nítorí tí ó fi ọgbọ́n ṣe é, àwọn ọmọ ayé yìí sá à gbọ́n ní ìran wọn ju àwọn ọmọ ìmọ́lẹ̀ lọ. (aiōn g165)
Atunšje gospodaru u ămărit pă nu đirept upravitelj kari ăm oči aluj nu are bun upravitelj, kă u arătat dăstafelă mărđuljijă kari nuj bună. Asta arată, kă ominji dă asta svet ăs maj mudri ăm stvarurlje alor dă kit dă ominji dă lumină. (aiōn g165)
9 Èmi sì wí fún yín, ẹ fi ọrọ̀ ayé yìí yan ọ̀rẹ́ fún ara yín pé, nígbà tí o ba lọ, kí wọn kí ó le gbà yín sí ibùjókòó wọn títí ayé. (aiōnios g166)
Šă ju vă zăk: ‘Koristilec găzdăšije šje fužji daje kă ăj nepravednă ku aje vă făšjec urtašj pă lăngă voj, aša kănd nu maj u fi găzdăšijă, atunšje voj vic fi apukac ăm nor dă erikeš. (aiōnios g166)
10 “Ẹni tí ó bá ṣe olóòtítọ́ nínú ohun kínkínní, ó ṣe olóòtítọ́ ní púpọ̀ pẹ̀lú: ẹni tí ó bá sì ṣe aláìṣòótọ́ ní ohun kínkínní, ó ṣe aláìṣòótọ́ ní ohun púpọ̀ pẹ̀lú.
Ala kari ăj vjeran ăm maj mišj stvarur, ăj isto aša vjeran ăm stvarurlje mar; šă ala kari nuj vjeran ăm stvarurlje mišj ăj isto nu vjeran ăm stvarurlje mar.
11 Ǹjẹ́ bí ẹ̀yin kò bá ti jẹ́ olóòtítọ́ nínú ọrọ̀ ayé yìí, ta ni yóò fi ọ̀rọ̀ tòótọ́ fún yín?
Šă aša dakă nac fost vjerni ăm svetovno găzdăšijă šjinji vu ănkređi ku pravă găzdăšijă să upravljalec?
12 Bí ẹ̀yin kò bá sì ti jẹ́ olóòtítọ́ nínú ohun tí í ṣe ti ẹlòmíràn, ta ni yóò fún yín ní ohun tí í ṣe ti ẹ̀yin tìkára yín?
Šă dakă nu šćijec upravljali ku altora benjilje, šjinji vu da aje šje pripadalešći avovă?
13 “Kò sì í ẹnìkan tí ó lè sin ọ̀gá méjì. Òun yóò yà kórìíra ọ̀kan tí yóò fẹ́ràn èkejì, tàbí kí ó fi ara mọ́ ọ̀kan kí ó sì yan èkejì ní ìpọ̀sí. Ẹ̀yin kò lè sin Ọlọ́run àti owó papọ̀.”
Njiš una sluga nu poći să služulaskă pă doj gazdur dăm turdată, kă pă unu u zamrzăli a pă altu u plašji, ili u fi vjeran alu unu a pă halalănt nu u puće viđe ăm oč. Nu pučec služuli šă alu găzdăšijă šă alu Dimizov istovremeno.”
14 Àwọn Farisi, tí wọ́n ní ojúkòkòrò sì gbọ́ gbogbo nǹkan wọ̀nyí, wọ́n sì yọ ṣùtì sí i.
Kutotu aje auze farizeji, kari asre lukumic dă banj, šă jej su apukat să ăš fakă šjuf.
15 Ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin ni àwọn tí ń dá àre fún ara yín níwájú ènìyàn; ṣùgbọ́n Ọlọ́run mọ ọkàn yín, nítorí ohun ti a gbéga lójú ènìyàn, ìríra ni níwájú Ọlọ́run.
Atunšje Isus u zăs: “Voj vă fišjec pravedni ăm oči alu lume, ali Dimizov šćijă sufljičilje avoštri. Šje lume tari cenilešći, skărbă ăj ăm nenće alu Dimizov.”
16 “Òfin àti àwọn wòlíì ń bẹ títí di ìgbà Johanu, Láti ìgbà náà wá ni a ti ń wàásù ìròyìn ayọ̀ ìjọba Ọlọ́run, olúkúlùkù sì ń fi ipá wọ inú rẹ̀.
Isus zăšji: “Zakonu alu Mojsije šă kenvijurlje alu proroci kari jej ur skris vridile păn šje no vinjit Ivan kari bučuza šă dă atunšje spunje Hir fălos dă kraljevstva alu Dimizov a noj trăbujenj să nagovurelenj să mergă ăm kraljevstva alu Dimizov.
17 Ṣùgbọ́n ó rọrùn fún ọ̀run òun ayé láti kọjá lọ, ju kí èyí tí ó kéré jù nínú òfin kí ó yẹ.
Nu značalešči kă zakonu alu Mojsije nuj bun. Majnti u trešji noru šă pămăntu, kită să propadalaskă zakonu ili să kadă una slovă dăm zakon.
18 “Ẹnikẹ́ni tí ó bá kọ aya rẹ̀ sílẹ̀, tí ó sì gbé ẹlòmíràn ní ìyàwó, ó ṣe panṣágà: ẹnikẹ́ni tí ó bá sì gbé, ẹni tí ọkọ rẹ̀ kọ̀sílẹ̀ ní ìyàwó náà, ó ṣe panṣágà.
Kari să lasă dă la băšăcaš să să ănsori ku alta băšăca fašji preljub. Šă tot omu kari u ănsura pă mujeri kari ăj lăsată dă la bărbat isto fašji preljub.”
19 “Ǹjẹ́ ọkùnrin ọlọ́rọ̀ kan wà, tí ó ń wọ aṣọ elése àlùkò àti aṣọ àlà dáradára, a sì máa jẹ dídùndídùn lójoojúmọ́.
Isus zăšji: “Are om găzdak kari să ămbrăka ăm colji skumpi šă ăm totă ză mănka skumpă mănkari.
20 Alágbe kan sì wà tí à ń pè ní Lasaru, tí wọ́n máa ń gbé wá kalẹ̀ lẹ́bàá ọ̀nà ilé rẹ̀, ó kún fún ooju,
Akulo are isto aša om sărak kari să čima Lazar kari are astupat ku čirevur pă jăl šă are pă košći la uša la ala găzdak.
21 Òun a sì máa fẹ́ kí a fi èérún tí ó ti orí tábìlì ọlọ́rọ̀ bọ́ sílẹ̀ bọ́ òun, àwọn ajá sì wá, wọ́n sì fá a ní ooju lá.
Jăl ăš kivinje să fijă rănjit ku mrvicurlje šje kăđe dă pă masa alu omuluje găzdak. Kănji delj divljă čak vinje la jăl šă ăj ljinže čirevur.
22 “Ó sì ṣe, alágbe kú, a sì ti ọwọ́ àwọn angẹli gbé e lọ sí oókan àyà Abrahamu: ọlọ́rọ̀ náà sì kú pẹ̀lú, a sì sin ín;
U vinjit vreme kănd u murit kuldužu, šă anđeji lor dus ăm bracă la Abraham. Omu găzdak isto u murit šă u fost ăngrupat.
23 Ní ipò òkú ni ó gbé ojú rẹ̀ sókè, ó ń bẹ nínú ìjìyà oró, ó sì rí Abrahamu ní òkèrè, àti Lasaru ní oókan àyà rẹ̀. (Hadēs g86)
Ăm mari mukă ăm podzemlje, găzdaku su ujtat sus šă u văzut pă Abraham dă dăparći šă pă Lazar kari are lăngă Abraham. (Hadēs g86)
24 Ó sì ké, ó wí pé, ‘Baba Abrahamu, ṣàánú fún mi, kí o sì rán Lasaru, kí ó tẹ orí ìka rẹ̀ bọ omi, kí ó sì fi tù mí ní ahọ́n; nítorí èmi ń joró nínú ọ̀wọ́n iná yìí.’
Šă jăl u plăns ăm mužjală: ‘Tata, Abraham fijăc milă dă minji! Mănăl pă Lazar la minji lasăl să ăntupaskă žježjitu ăm apă šă săm răšjaskă ljimba, kă mari mukur ăs pă minji ăm fokusta.’
25 “Ṣùgbọ́n Abrahamu wí pé, ‘Ọmọ, rántí pé, nígbà ayé rẹ, ìwọ ti gba ohun rere tìrẹ, àti Lasaru ohun búburú, ṣùgbọ́n nísinsin yìí ara rọ̀ ọ́, ìwọ sì ń joró.
Abraham u ăntors vorba: ‘Fišjoru amnjov, tu trăbă să či ăngănđešć dă aje kănd arej pă pămănt tu avej mulći bunji stvarur, kănd Lazar ave mulći relji stvarur. Ali jăl ăj aku ăm utjehă, kănd ješć tu ăm mukă.
26 Àti pẹ̀lú gbogbo èyí, a gbé ọ̀gbun ńlá kan sí agbede-méjì àwa àti ẹ̀yin, kí àwọn tí ń fẹ́ má ba á le rékọjá láti ìhín lọ sọ́dọ̀ yín, kí ẹnikẹ́ni má sì le ti ọ̀hún rékọjá tọ̀ wá wá.’
Šă dă kutotu asta, ăntri noj šă ăntri voj ăj mari gropă făr dă kraj. Eje kari ar gănđi să mergă dă ajišje la voj nu poći, šă njiš njime nu poći dă la voj să vijă la noj.’
27 “Ó sì wí pé, ‘Ǹjẹ́ mo bẹ̀ ọ́, baba, kí ìwọ kí ó rán Lasaru lọ sí ilé baba mi,
Atunšje omu šje are găzdak u zăs: ‘Mă arog la činji să ăl măj pă Lazar la kasa alu tata amnjov.
28 nítorí mo ní arákùnrin márùn-ún; kí ó lè rò fún wọn kí àwọn kí ó má ba á wá sí ibi oró yìí pẹ̀lú.’
Ju am šinšj frac kari akulo kustă. Lasă să lji upozurulaskă să nu vijă pă ista lok pljin dă mukă!’
29 “Abrahamu sì wí fún un pé, ‘Wọ́n ní Mose àti àwọn wòlíì; kí wọn kí ó gbọ́ tiwọn.’
Abraham u ăntors vorba: ‘Jej ari kenvijur kari Mojsije šă proroci ari skris dă jej să lji opozurulaskă! Lasălji să pujă ureći la jej!’
30 “Ó sì wí pé, ‘Bẹ́ẹ̀ kọ́, Abrahamu baba; ṣùgbọ́n bí ẹnìkan bá ti inú òkú tọ̀ wọ́n lọ, wọn ó ronúpìwàdà.’
A jăl u zăs: ‘O nu, Tata amnjov Abraham. Alor lji trăbă să lji vijă šjinjiva dăm morc, šă jej sur ănkăji.’
31 “Ó sì wí fún un pé, ‘Bí wọn kò bá gbọ́ ti Mose àti ti àwọn wòlíì, a kì yóò yí wọn ní ọkàn padà bí ẹnìkan tilẹ̀ ti inú òkú dìde.’”
Abraham u ăntors vorba: ‘Dakă no punji ureče la Mojsije šă la prorokur, nur ănkređi njiš să să skolji šjinjiva dăm morc.’”

< Luke 16 >