< Luke 16 >

1 Ó sì wí fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ pẹ̀lú pé, “Ọkùnrin ọlọ́rọ̀ kan wà, tí ó ní ìríjú kan; òun náà ni wọ́n fi sùn ún pé, ó ti ń fi ohun ìní rẹ̀ ṣòfò.
Yesu nabhabhwila lindi abheigisibhwa bhaye ati, “Aliga alio omunu umwi mutagiri ali nomunu emelegululiye emilimu jaye, nibhamubhwila ati omukosi wao unu kalasa-lasa imali yao.
2 Nígbà tí ó sì pè é, ó wí fún un pé, ‘Èéṣe tí èmi fi ń gbọ́ èyí sí ọ? Ṣírò iṣẹ́ ìríjú rẹ; nítorí ìwọ kò lè ṣe ìríjú mi mọ́.’
Kulwejo tagiri namubhilikila, namubhwila ati, “Nimisangoki jinu enungwa ingulu yao? Nuumbalile obhukumi bhwe emilimu jao, kulwokubha utachasubha kwimelegululila emilimu lindi.”
3 “Ìríjú náà sì wí nínú ara rẹ̀ pé, ‘Èwo ni èmi ó ṣe? Nítorí tí olúwa mi gba iṣẹ́ ìríjú lọ́wọ́ mi: èmi kò le ṣiṣẹ́ oko, bẹ́ẹ̀ ni ojú ń tì mí láti ṣagbe.
Omukosi we emilimu neyaikila mumwoyo gwaye, 'lata bhugenyi wani kansoshako kumilimu jokwimelegulila emilimu, nikole kutiki? Nitali namanaga gokulima, nokusabhilisha eniswala.
4 Mo mọ èyí tí èmi yóò ṣe, nígbà tí a bá mú mi kúrò níbi iṣẹ́ ìríjú, kí àwọn ènìyàn le gbà mí sínú ilé wọn.’
Mbe enimenya gunu nilakola koleleki labha nikasosibhwako kumilimu abhanu bhankumililega mumisi jebhwe.'
5 “Ó sì pe àwọn ajigbèsè olúwa rẹ̀ sọ́dọ̀ rẹ̀, ó sì wí fún èkínní pé, ‘Èló ni ìwọ jẹ olúwa mi?’
Kulwejo omukosi wemilimu nabhilikila bhanu bhaliga nibhatongwa na lata bhugenyi waye. Nabhwila owokwamba ati, 'omukulu wani kakutonga bhilinga?
6 “Ó sì wí pé, ‘Ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rún òsùwọ̀n òróró.’ “Ó sì wí fún un pé, ‘Mú ìwé rẹ, sì jókòó nísinsin yìí, kí o sì kọ àádọ́ta lé ní irinwó.’
Nasubhya ati, 'ndengo egana eja amafuta' namubhwila ati, 'nugege olwandiko lwao wiyanje bhwangu wandike makumi gatanu.'
7 “Nígbà náà ni ó sì bi ẹnìkejì pé, ‘Èló ni ìwọ jẹ?’ “Òun sì wí pé, ‘Ẹgbẹ̀rún òsùwọ̀n alikama.’ “Ó sì wí fún un pé, ‘Mú ìwé rẹ, kí o sì kọ ẹgbẹ̀rin.’
Neya nabhwila oundi, 'kawe outongwa elinga?' naika ati, 'bhilengo egana ebhya jishano ja ingano.' Namubhwila ati, 'gega olwandiko lwao wandike makumi munana.'
8 “Olúwa rẹ̀ sì yin aláìṣòótọ́ ìríjú náà, nítorí tí ó fi ọgbọ́n ṣe é, àwọn ọmọ ayé yìí sá à gbọ́n ní ìran wọn ju àwọn ọmọ ìmọ́lẹ̀ lọ. (aiōn g165)
Omumula uliya omunibhi namukuya omukosi wobhuyaga lwakutyo akolele kwo obhwenge. Kulwokubha abhana bhe echalo bhana obhwenge bhwafu na abhakola emilimu kwo bhwenge na abhanu bhanu bhali kulubhala lwebhwe kukila kutyo bhali abhana bho obhwelu. (aiōn g165)
9 Èmi sì wí fún yín, ẹ fi ọrọ̀ ayé yìí yan ọ̀rẹ́ fún ara yín pé, nígbà tí o ba lọ, kí wọn kí ó le gbà yín sí ibùjókòó wọn títí ayé. (aiōnios g166)
Mbe enibhabhwila mwikolele abhasani okusoka mubhinu bhyo obhunyamuke koleleki ebhinu bhikawao bhabhakumilile mubhwikalo bhunu bhutakuwao. (aiōnios g166)
10 “Ẹni tí ó bá ṣe olóòtítọ́ nínú ohun kínkínní, ó ṣe olóòtítọ́ ní púpọ̀ pẹ̀lú: ẹni tí ó bá sì ṣe aláìṣòótọ́ ní ohun kínkínní, ó ṣe aláìṣòótọ́ ní ohun púpọ̀ pẹ̀lú.
Owakisi mwibhika kuchinu chitoto muno kabhaga wekisi okubhika nolwo chinu chinene. Na unu kasakula echitoto nolwo echinene ona kasakula.
11 Ǹjẹ́ bí ẹ̀yin kò bá ti jẹ́ olóòtítọ́ nínú ọrọ̀ ayé yìí, ta ni yóò fi ọ̀rọ̀ tòótọ́ fún yín?
Labha emwe mutabheye bhakisi kubhinu bhyo obhunyamuke niga unu alibhayana okubhika ebhinu bhye echimali?
12 Bí ẹ̀yin kò bá sì ti jẹ́ olóòtítọ́ nínú ohun tí í ṣe ti ẹlòmíràn, ta ni yóò fún yín ní ohun tí í ṣe ti ẹ̀yin tìkára yín?
Ka labha mutabheye bhakisi kubhinu bhyo undi niga unu alibhayana imali yemwe abhene?
13 “Kò sì í ẹnìkan tí ó lè sin ọ̀gá méjì. Òun yóò yà kórìíra ọ̀kan tí yóò fẹ́ràn èkejì, tàbí kí ó fi ara mọ́ ọ̀kan kí ó sì yan èkejì ní ìpọ̀sí. Ẹ̀yin kò lè sin Ọlọ́run àti owó papọ̀.”
Atalio omunu unu katula okukolela bhese Bhugenyi bhabhili, kulwokubha kafururukwa no oumwi na nenda oundi, lugendo kagwatana na unu nokugaya oundi. Mutakutula okukolela Nyamuanga ne ebhinu.
14 Àwọn Farisi, tí wọ́n ní ojúkòkòrò sì gbọ́ gbogbo nǹkan wọ̀nyí, wọ́n sì yọ ṣùtì sí i.
Mbe Abhafarisayo bhanu bhaliga nibhenda jimpilya, nibhongwa ejo jona na nibhamujimya.
15 Ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin ni àwọn tí ń dá àre fún ara yín níwájú ènìyàn; ṣùgbọ́n Ọlọ́run mọ ọkàn yín, nítorí ohun ti a gbéga lójú ènìyàn, ìríra ni níwájú Ọlọ́run.
Yesu nabhabhwila ati, “Emwe nemwe omwigegela obhulengelesi imbele ya abhanu, nawe Nyamuanga kamenya emyoyo jemwe. Kulwokubha linu limenyekene kubhanu elibhaga efururusho ku Nyamuanga.
16 “Òfin àti àwọn wòlíì ń bẹ títí di ìgbà Johanu, Láti ìgbà náà wá ni a ti ń wàásù ìròyìn ayọ̀ ìjọba Ọlọ́run, olúkúlùkù sì ń fi ipá wọ inú rẹ̀.
Mbe ebhilagilo na abhalagi bhyaliga bhilio okukingila Yoana naja. Okwambila akatungu ako, Omusango ogwo bhwana ogwo obhukama bhwa Nyamuanga ogulasibhwa, na bhuli munu kalegeja okwiingisha kwa amanaga.
17 Ṣùgbọ́n ó rọrùn fún ọ̀run òun ayé láti kọjá lọ, ju kí èyí tí ó kéré jù nínú òfin kí ó yẹ.
Jolobhele olwire na insi okuwao nawe inyuguta imwi eye echilagilo okubhulao.
18 “Ẹnikẹ́ni tí ó bá kọ aya rẹ̀ sílẹ̀, tí ó sì gbé ẹlòmíràn ní ìyàwó, ó ṣe panṣágà: ẹnikẹ́ni tí ó bá sì gbé, ẹni tí ọkọ rẹ̀ kọ̀sílẹ̀ ní ìyàwó náà, ó ṣe panṣágà.
Bhuli munu unu kasigana no mugasi waye natwala oundi kalomela, naunu katwala omugasi unu asigilwe no mulume waye kalomela.
19 “Ǹjẹ́ ọkùnrin ọlọ́rọ̀ kan wà, tí ó ń wọ aṣọ elése àlùkò àti aṣọ àlà dáradára, a sì máa jẹ dídùndídùn lójoojúmọ́.
Mbe aliga alio omunu umwi alimunibhi nafwalaga jingubho ja irangi ya amajambarau ejobhugusi bhunene, bhuli siku nakondelesibhwa no obhwafu bhwo ubhutagiri bhwaye.
20 Alágbe kan sì wà tí à ń pè ní Lasaru, tí wọ́n máa ń gbé wá kalẹ̀ lẹ́bàá ọ̀nà ilé rẹ̀, ó kún fún ooju,
Alio no omunu umwi lisinanlyaye Lazaro, alimutaka ne ebhilondo, neyanjaga kumulyango gwo omunibhi oyo.
21 Òun a sì máa fẹ́ kí a fi èérún tí ó ti orí tábìlì ọlọ́rọ̀ bọ́ sílẹ̀ bọ́ òun, àwọn ajá sì wá, wọ́n sì fá a ní ooju lá.
Lazaro esigomberaga okwiguta ganu galagalaga okusoka kumeja yo omunibhi jimbwa nijija okumulamba ebhilonda bhaye.
22 “Ó sì ṣe, alágbe kú, a sì ti ọwọ́ àwọn angẹli gbé e lọ sí oókan àyà Abrahamu: ọlọ́rọ̀ náà sì kú pẹ̀lú, a sì sin ín;
Mbe ejile omutaka afwa nagegwa na bhamalaika nibhamukingya muchifubha cha Ibraimu. Omunibhi uliya ona nafwa nasikwa.
23 Ní ipò òkú ni ó gbé ojú rẹ̀ sókè, ó ń bẹ nínú ìjìyà oró, ó sì rí Abrahamu ní òkèrè, àti Lasaru ní oókan àyà rẹ̀. (Hadēs g86)
Munyombe ao aliga alimunyako, nalalamila nalola Ibraimu alikula na Lazaro alimuchifubha chaye. (Hadēs g86)
24 Ó sì ké, ó wí pé, ‘Baba Abrahamu, ṣàánú fún mi, kí o sì rán Lasaru, kí ó tẹ orí ìka rẹ̀ bọ omi, kí ó sì fi tù mí ní ahọ́n; nítorí èmi ń joró nínú ọ̀wọ́n iná yìí.’
Nalola naika ati, 'Lata Ibraimu, nuumfwile chigongo utume Lazaro enike insonde yechala chaye mumanji anyilishe olulimi lwwni; kulwokubha eninyasibhwa mumulilo gunu.
25 “Ṣùgbọ́n Abrahamu wí pé, ‘Ọmọ, rántí pé, nígbà ayé rẹ, ìwọ ti gba ohun rere tìrẹ, àti Lasaru ohun búburú, ṣùgbọ́n nísinsin yìí ara rọ̀ ọ́, ìwọ sì ń joró.
Nawe Ibraimu naika ati, 'Mwana wani ichuka lwa kutyo mubhulame bhwao walamiye agekisi, ka Lazaro nabhona amabhibhi. Nawe olyanu alyanu kafung'amibhwa kawe ounyasibhwa.
26 Àti pẹ̀lú gbogbo èyí, a gbé ọ̀gbun ńlá kan sí agbede-méjì àwa àti ẹ̀yin, kí àwọn tí ń fẹ́ má ba á le rékọjá láti ìhín lọ sọ́dọ̀ yín, kí ẹnikẹ́ni má sì le ti ọ̀hún rékọjá tọ̀ wá wá.’
Ingulu ya jona, liteweo elyobho enene na elela agati yeswe, koleleki bhanu abhenda okusoka enu okuja kwimwe bhasige okutula, nolwo abhanu bhe ewemwe bhatajokwambuka okuja kwiswe.'
27 “Ó sì wí pé, ‘Ǹjẹ́ mo bẹ̀ ọ́, baba, kí ìwọ kí ó rán Lasaru lọ sí ilé baba mi,
Omunibhi oyo naika ati, 'Enikusabhwa lata Ibraimu, utume Lazaro ika owasu kulata.
28 nítorí mo ní arákùnrin márùn-ún; kí ó lè rò fún wọn kí àwọn kí ó má ba á wá sí ibi oró yìí pẹ̀lú.’
Kulwokubha nina bhamula bhasu bhatanu koleleki abhakishe, enubhaya abhene ona bhasiga kukinga munyako anu nili.'
29 “Abrahamu sì wí fún un pé, ‘Wọ́n ní Mose àti àwọn wòlíì; kí wọn kí ó gbọ́ tiwọn.’
Nawe Ibraimu naika ati, 'bhali na Musa na abhalagi. Bhasigela bhabhategeleshe abho.
30 “Ó sì wí pé, ‘Bẹ́ẹ̀ kọ́, Abrahamu baba; ṣùgbọ́n bí ẹnìkan bá ti inú òkú tọ̀ wọ́n lọ, wọn ó ronúpìwàdà.’
Omunibhi naika ati, 'Pai, Lata Ibraimu, omunu akasoka mubhafuye nabhakingako abhata ebhibhi.'
31 “Ó sì wí fún un pé, ‘Bí wọn kò bá gbọ́ ti Mose àti ti àwọn wòlíì, a kì yóò yí wọn ní ọkàn padà bí ẹnìkan tilẹ̀ ti inú òkú dìde.’”
Nawe Ibraimu namubhwila ati, 'bhakabhula okungwa Musa na abhalagi bhatakutula okungwa nolwo omunu akasoka mubhafuye.'”

< Luke 16 >