< Luke 15 >

1 Gbogbo àwọn agbowó òde àti àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ sì súnmọ́ ọn láti gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀.
Emdi bajgirlar we bashqa gunahkarlarning hemmisi uning sözini anglashqa uning etrapigha olashmaqta idi.
2 Àti àwọn Farisi àti àwọn akọ̀wé ń kùn pé, “Ọkùnrin yìí ń gba ẹlẹ́ṣẹ̀, ó sì ń bá wọn jẹun.”
Lékin Perisiyler bilen Tewrat ustazliri ghudungshup: — Bu adem gunahkarlarni qarshi alidu we ular bilen hemdastixan olturidu! — déyishti.
3 Ó sì pa òwe yìí fún wọn, pé,
Shunga u ulargha munu temsilni sözlep berdi:
4 “Ọkùnrin wo ni nínú yín, tí ó ní ọgọ́rùn-ún àgùntàn, bí ó bá sọ ọ̀kan nù nínú wọn, tí kì yóò fi mọ́kàndínlọ́gọ́rùn-ún yokù sílẹ̀ ni ijù tí kì yóò sì tọ ipasẹ̀ èyí tí ó nù lọ, títí yóò fi rí i?
— Eger aranglarda bireylenning yüz tuyaq qoyi bolup, ulardin biri yitip ketse, toqsan toqquzini chölde qoyup qoyup yitip ketkinini tapquche izdimesmu?
5 Nígbà tí ó bá sì rí i tán, yóò gbé e lé èjìká rẹ̀ pẹ̀lú ayọ̀.
Uni tépiwalghanda, shadlan’ghan halda mürisige artidu;
6 Nígbà tí ó bá sì dé ilé yóò pe àwọn ọ̀rẹ́ àti aládùúgbò rẹ̀ jọ, yóò sì wí fún wọn pé, ‘Ẹ bá mí yọ̀; nítorí tí mo ti rí àgùntàn mi tí ó nù.’
andin öyige élip kélip, yar-buraderliri bilen qolum-qoshnilirini chaqirip, ulargha: «Men yitken qoyumni tépiwaldim, méning bilen teng shadlininglar!» deydu.
7 Mo wí fún yín, gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni ayọ̀ yóò wà ní ọ̀run lórí ẹlẹ́ṣẹ̀ kan tí ó ronúpìwàdà, ju lórí olóòtítọ́ mọ́kàndínlọ́gọ́rùn-ún lọ, tí kò nílò ìrònúpìwàdà.
Men silerge shuni éytayki, shuninggha oxshash, towa qiliwatqan bir gunahkar üchün ershte zor xursenlik bolidu; bu xursenlik towigha mohtaj bolmighan toqsan toqquz heqqaniy kishidin bolghan xursenliktin köp artuqtur.
8 “Tàbí obìnrin wo ni ó ní owó fàdákà mẹ́wàá bí ó bá sọ ọ̀kan nù, tí kì yóò tan fìtílà, kí ó fi gbá ilé, kí ó sì wá a gidigidi títí yóò fi rí i?
— Yaki bir ayalning on kümüsh dinari bolup, bir dinarni yoqitip qoysa, chiraghni yéqip, taki uni tapquche öyni süpürüp, zen qoyup izdimesmu?
9 Nígbà tí ó sì rí i, ó pe àwọn ọ̀rẹ́ àti àwọn aládùúgbò rẹ̀ jọ, ó wí pé, ‘Ẹ bá mi yọ̀; nítorí mo rí owó fàdákà tí mo ti sọnù.’
Uni tapqanda yar-burader, qolum-qoshnlirini chaqirip, ulargha: «Méning bilen teng shadlininglar, chünki men yoqitip qoyghan dinarimni tépiwaldim» — deydu.
10 Mo wí fún yín, gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni ayọ̀ ń bẹ níwájú àwọn angẹli Ọlọ́run lórí ẹlẹ́ṣẹ̀ kan tí ó ronúpìwàdà.”
Men silerge shuni éytayki, shuninggha oxshash towa qiliwatqan bir gunahkar üchün Xudaning perishtilirining arisida xursenlik bolidu.
11 Ó sì wí pé ọkùnrin kan ní ọmọ méjì:
U sözini dawam qilip mundaq dédi: — Melum bir ademning ikki oghli bar iken.
12 “Èyí àbúrò nínú wọn wí fún baba rẹ̀ pé, ‘Baba, fún mi ní ìní tí ó kàn mí.’ Ó sì pín ohun ìní rẹ̀ fún wọn.
Kichik oghli atisigha: «Ey ata, mal-mülüktin tégishlik ülüshümni hazirla manga bergin» dep éytiptu. We u öz mal-mülüklirini ikkisige teqsim qilip bériptu.
13 “Kò sì tó ọjọ́ mélòó kan lẹ́yìn náà, èyí àbúrò kó ohun gbogbo tí ó ní jọ, ó sì mú ọ̀nà àjò rẹ̀ pọ̀n lọ sí ilẹ̀ òkèrè, níbẹ̀ ni ó sì gbé fi ìwà wọ̀bìà ná ohun ìní rẹ̀ ní ìnákúnàá.
Uzun ötmeyla, kichik oghli bar-yoqini yighishturup, yiraq bir yurtqa seper qiliptu. U u yerde eysh-ishretlik ichide turmush kechürüp mal-dunyasini buzup-chéchiptu.
14 Nígbà tí ó sì ba gbogbo rẹ̀ jẹ́ tan, ìyàn ńlá wá mú ní ilẹ̀ náà; ó sì bẹ̀rẹ̀ sí di aláìní.
Del u bar-yoqini serp qilip tügetken waqtida, u yurtta qattiq acharchiliq bolup, u xélila qisilchiliqta qaptu.
15 Ó sì fi ara rẹ sọfà fun ọ̀kan lára àwọn ọmọ ìlú náà; òun sì rán an lọ sí oko rẹ̀ láti tọ́jú ẹlẹ́dẹ̀.
Shuning bilen u bérip, shu yurtning bir puqrasigha medikar bolup yalliniptu; u uni étizliqigha choshqa béqishqa ewetiptu.
16 Ayọ̀ ni ìbá fi jẹ oúnjẹ tí àwọn ẹlẹ́dẹ̀ ń jẹ ní àjẹyó, ṣùgbọ́n ẹnikẹ́ni kò sì fi fún un.
U hetta qorsiqini choshqilarning yémi bolghan purchaq posti bilen toyghuzushqa teqezza boptu; lékin héchkim uninggha héchnerse bermeptu.
17 “Ṣùgbọ́n nígbà tí ojú rẹ̀ wálẹ̀, ó ní ‘Mélòó mélòó àwọn alágbàṣe baba mí ni ó ní oúnjẹ àjẹyó, àti àjẹtì, èmi sì ń kú fún ebi níhìn-ín.
Axir bérip u hoshini tépip: «Atamning shunche köp medikarlirining aldidin yémek-ichmek éship-téship turidu; lékin men bolsam bu yerde achliqtin öley dep qaldim!
18 Èmi ó dìde, èmi ó sì tọ baba mi lọ, èmi ó sì wí fún un pé, Baba, èmí ti dẹ́ṣẹ̀ sí ọ̀run, àti níwájú rẹ,
Ornumdin turup, atamning aldigha bérip uninggha: Ey ata, men ershning aldidimu we séning aldingdimu gunah qildim.
19 èmi kò sì yẹ, ní ẹni tí à bá pè ní ọmọ rẹ mọ́; fi mí ṣe ọ̀kan nínú àwọn alágbàṣe rẹ.’
Emdi séning oghlung atilishqa layiq emesmen. Méni medikarliring süpitide qobul qilghaysen! — deymen» dep oylaptu.
20 Ó sì dìde, ó sì tọ baba rẹ̀ lọ. “Ṣùgbọ́n nígbà tí ó sì wà ní òkèrè, baba rẹ̀ rí i, àánú ṣe é, ó sì súré, ó rọ̀ mọ́ ọn ní ọrùn, ó sì fi ẹnu kò ó ní ẹnu.
Shuning bilen ornidin turup atisining aldigha qaytip méngiptu. Lékin atisi yiraqtinla uni körüp uninggha ichi aghritip, aldigha yügürüp chiqip, uning boynigha ésilip uni söyüp kétiptu.
21 “Ọmọ náà sì wí fún un pé, Baba, èmi ti dẹ́ṣẹ̀ sí ọ̀run, àti níwájú rẹ, èmi kò yẹ ní ẹni tí à bá pè ní ọmọ rẹ mọ́!
Oghli: «Ata, men ershning aldidimu, séning aldingdimu gunah qildim. Emdi séning oghlung atilishqa layiq emesmen» — deptu.
22 “Ṣùgbọ́n baba náà wí fún àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ pé, Ẹ mú ààyò aṣọ wá kánkán, kí ẹ sì fi wọ̀ ọ́; ẹ sì fi òrùka bọ̀ ọ́ lọ́wọ́, àti bàtà sí ẹsẹ̀ rẹ̀:
Biraq atisi chakarlirigha: «Derhal eng ésil tonni ekélip uninggha kiydürünglar, qoligha üzük sélinglar, putlirigha ayagh kiydürüngler;
23 Ẹ sì mú ẹgbọrọ màlúù àbọ́pa wá, kí ẹ sì pa á, kí a máa ṣe àríyá.
we bordaq torpaqni ekélip soyunglar; andin obdan yep, rawurus tebrikleyli!
24 Nítorí ọmọ mi yìí ti kú, ó sì tún yè, ó ti nù, a sì rí i. Wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí í ṣe àríyá.
Chünki méning bu oghlum ölgenidi, tirildi, yitip ketkenidi, tépildi!» — deptu. Andin ular tebrikleshkili bashlaptu.
25 “Ṣùgbọ́n ọmọ rẹ̀ èyí ẹ̀gbọ́n ti wà ní oko: bí ó sì ti ń bọ̀, tí ó súnmọ́ etí ilé, ó gbọ́ orin àti ijó.
Emdi chong oghli étizgha ketkeniken. U qaytip kéliwétip öyge yéqin kelgende neghme-nawa bilen ussulning awazini anglaptu.
26 Ó sì pe ọ̀kan nínú àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ wọn, ó béèrè, kín ni a mọ nǹkan wọ̀nyí sí?
U chakarlardin birini chaqirip, uningdin néme ish boluwatqinini soraptu.
27 Ó sì wí fún un pé, ‘Arákùnrin rẹ dé, baba rẹ sì pa ẹgbọrọ màlúù àbọ́pa, nítorí tí ó rí i padà ní àlàáfíà àti ní ìlera.’
Chakar uninggha: Ukang keldi we atang uni saq-salamet tépiwalghanliqi üchün bordaq torpaqni soydi» deptu.
28 “Ó sì bínú, ó sì kọ̀ láti wọlé; baba rẹ̀ sì jáde, ó sì wá í ṣìpẹ̀ fún un.
Lékin [chong oghli] xapa bolup, öyge kirgili unimaptu. We atisi chiqip uning öyge kirishini ötünüptu.
29 Ó sì dáhùn ó wí fún baba rẹ̀ pé, ‘Wò ó, láti ọdún mélòó wọ̀nyí ni èmi ti ń sìn ọ́, èmi kò sì rú òfin rẹ rí, ìwọ kò sì tí ì fi ọmọ ewúrẹ́ kan fún mi, láti fi bá àwọn ọ̀rẹ́ mi ṣe àríyá.
Emma u atisigha jawab bérip: «Qara! Men shunche yildin béri quldek xizmitingde boldum, esla héchbir emringdin chiqip baqmidim. Biraq sen manga el-aghinilirim bilen xush qilghili héchqachan birer oghlaqmu bermiding!
30 Ṣùgbọ́n nígbà tí ọmọ rẹ yìí dé, ẹni tí ó fi panṣágà fi ọrọ̀ rẹ̀ ṣòfò, ìwọ sì ti pa ẹgbọrọ màlúù àbọ́pa fún un.’
Lékin séning mal-mülükliringni pahishilerge xejlep tügetken bu oghlung qaytip kelgende, sen uning üchün bordaq torpaqni soyupsen» — deptu.
31 “Ó sì wí fún un pé, ‘Ọmọ, nígbà gbogbo ni ìwọ ń bẹ lọ́dọ̀ mi, ohun gbogbo tí mo sì ní, tìrẹ ni.
Biraq atisi yene uninggha: «Ey oghlum, sen herdaim méning yénimdisen we méning barliqim séningkidur.
32 Ó yẹ kí a ṣe àríyá kí a sì yọ̀: nítorí arákùnrin rẹ yìí ti kú, ó sì tún yè; ó ti nù, a sì rí i.’”
Emdi tebriklep shadlinishqa layiqtur; chünki bu séning ukang ölgenidi, tirildi, yoqilip ketkenidi, tépildi» — deptu.

< Luke 15 >