< Luke 11 >

1 Bí ó ti ń gbàdúrà ní ibi kan, bí ó ti dákẹ́, ọ̀kan nínú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ wí fún un pé, “Olúwa, kọ́ wa bí a ti ń gbàdúrà, bí Johanu ti kọ́ àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀.”
A gdy przebywał w jakimś miejscu na modlitwie i skończył [ją], jeden z jego uczniów powiedział do niego: Panie, naucz nas się modlić, tak jak i Jan nauczył swoich uczniów.
2 Ó sì wí fún wọn pé, “Nígbà tí ẹ̀yin bá ń gbàdúrà, ẹ máa wí pé: “‘Baba wa tí ń bẹ ní ọ̀run, kí á bọ̀wọ̀ fún orúkọ yín. Kí ìjọba yín dé, ìfẹ́ tiyín ni kí a ṣe, bí i ti ọrun, bẹ́ẹ̀ ni ní ayé.
I powiedział do nich: Gdy się modlicie, mówcie: Ojcze nasz, który jesteś w niebie, niech będzie uświęcone twoje imię. Niech przyjdzie twoje królestwo. Niech się dzieje twoja wola na ziemi, tak jak w niebie.
3 Fún wa ní oúnjẹ òòjọ́ wa lójoojúmọ́.
Dawaj nam każdego dnia naszego powszedniego chleba.
4 Kí o sì dárí ẹ̀ṣẹ̀ wa jì wá; nítorí àwa tìkára wa pẹ̀lú a máa dáríjì olúkúlùkù ẹni tí ó jẹ wá ní gbèsè, Má sì fà wá sínú ìdánwò, ṣùgbọ́n gbà wá lọ́wọ́ ẹni búburú ni.’”
Przebacz nam nasze grzechy, bo i my przebaczamy każdemu, kto przeciwko nam zawinił. I nie wystawiaj nas na pokusę, ale wybaw nas od złego.
5 Ó sì wí fún wọn pé, “Ta ni nínú yín tí yóò ní ọ̀rẹ́ kan, tí yóò sì tọ̀ ọ́ lọ láàrín ọ̀gànjọ́, tí yóò sì wí fún un pé, ‘Ọ̀rẹ́, yá mi ní ìṣù àkàrà mẹ́ta.
I powiedział do nich: Któż z was, mając przyjaciela, pójdzie do niego o północy i powie mu: Przyjacielu, pożycz mi trzy chleby;
6 Nítorí ọ̀rẹ́ mi kan ti àjò dé sọ́dọ̀ mi, èmi kò sì ní nǹkan tí èmi ó gbé kalẹ̀ níwájú rẹ̀.’
Mój przyjaciel bowiem przyszedł do mnie z drogi, a nie mam mu co podać?
7 Tí òun ó sì gbé inú ilé dáhùn wí fún un pé, ‘Má yọ mí lẹ́nu, a ti sé ìlẹ̀kùn, àwọn ọmọ mi si ń bẹ lórí ẹní pẹ̀lú mi: èmi kò lè dìde fi fún ọ!’
A on z wewnątrz odpowie: Nie naprzykrzaj mi się. Drzwi są już zamknięte i moje dzieci są ze mną w łóżku. Nie mogę wstać i dać ci.
8 Mo wí fún yín, bí òun kò tilẹ̀ ti fẹ́ dìde kí ó fi fún un nítorí tí í ṣe ọ̀rẹ́ rẹ̀, ṣùgbọ́n nítorí àwíìyánnu rẹ̀, yóò dìde, yóò sì fún un tó bí ó ti ń fẹ́.
Mówię wam: Chociażby nie wstał i nie dał mu dlatego, że jest jego przyjacielem, jednak z powodu jego natarczywości wstanie i da mu, ile potrzebuje.
9 “Èmí sì wí fún yín, ẹ béèrè, a ó sì fi fún un yín; ẹ wá kiri, ẹ̀yin ó sì rí; ẹ kànkùn, a ó sì ṣí i sílẹ̀ fún yín.
I ja wam mówię: Proście, a będzie wam dane, szukajcie, a znajdziecie, pukajcie, a będzie wam otworzone.
10 Nítorí ẹnikẹ́ni tí ó bá béèrè, ó rí gbà; ẹni tí ó sì ń wá kiri, ó rí; àti ẹni tí ó kànkùn ni a ó ṣí i sílẹ̀ fún.
Każdy bowiem, kto prosi, otrzymuje, a kto szuka, znajduje, a temu, kto puka, będzie otworzone.
11 “Ta ni baba nínú yín tí ọmọ rẹ̀ yóò béèrè àkàrà lọ́dọ̀ rẹ̀, tí yóò fún un ní òkúta? Tàbí bí ó béèrè ẹja, tí yóò fún un ní ejò?
I czy jest wśród was ojciec, który, gdy syn prosi go o chleb, da mu kamień? Albo [gdy prosi] o rybę, czy zamiast ryby da mu węża?
12 Tàbí bí ó sì béèrè ẹ̀yin, tí yóò fún un ní àkéekèe?
Albo gdy prosi o jajko, czy da mu skorpiona?
13 Ǹjẹ́ bí ẹ̀yin tí ó jẹ́ ènìyàn búburú bá mọ bí a ti í fi ẹ̀bùn dáradára fún àwọn ọmọ yín, mélòó mélòó ha ni Baba yín tí ń bẹ ní ọ̀run yóò fi Ẹ̀mí Mímọ́ rẹ̀ fún àwọn tí ó béèrè lọ́dọ̀ rẹ̀!”
Jeśli więc wy, będąc złymi, umiecie dawać dobre dary waszym dzieciom, o ileż bardziej wasz Ojciec niebieski da Ducha Świętego tym, którzy go proszą?
14 Ó sì ń lé ẹ̀mí èṣù kan jáde, tí ó sì yadi. Nígbà tí ẹ̀mí èṣù náà jáde, odi sọ̀rọ̀; ẹnu sì ya ìjọ ènìyàn.
I wypędzał demona, który był niemy. A gdy demon wyszedł, niemy przemówił, a ludzie się dziwili.
15 Ṣùgbọ́n àwọn ẹlòmíràn nínú wọn wí pé, “Nípa Beelsebulu olórí àwọn ẹ̀mí èṣù ni ó fi ń lé àwọn ẹ̀mí èṣù jáde.”
Lecz niektórzy z nich mówili: Przez Belzebuba, władcę demonów, wypędza demony.
16 Àwọn ẹlòmíràn sì ń dán an wò, wọ́n ń fẹ́ àmì lọ́dọ̀ rẹ̀ láti ọ̀run wá.
Inni zaś, wystawiając [go] na próbę, żądali od niego znaku z nieba.
17 Ṣùgbọ́n òun mọ èrò inú wọn, ó wí fún wọn pé, “Gbogbo ìjọba tí ó ya ara rẹ̀ ní ipá, ni a ń sọ di ahoro; ilé tí ó sì ya ara rẹ̀ nípá yóò wó.
Ale on, znając ich myśli, powiedział do nich: Każde królestwo podzielone wewnętrznie pustoszeje, a dom [skłócony] sam ze sobą upada.
18 Bí Satani ba yapa sí ara rẹ̀, ìjọba rẹ̀ yóò ha ṣe dúró? Nítorí ẹ̀yin wí pé, nípa Beelsebulu ni èmi fi ń lé àwọn ẹ̀mí èṣù jáde.
Jeśli i szatan jest wewnętrznie podzielony, jakże przetrwa jego królestwo? Mówicie bowiem, że ja przez Belzebuba wypędzam demony.
19 Bí ó ba ṣe pé nípa Beelsebulu ni èmi fi ń lé àwọn ẹ̀mí èṣù jáde, nípa ta ni àwọn ọmọ yín fi ń lé wọn jáde, nítorí náà àwọn ni yóò ṣe onídàájọ́ yín.
A jeśli ja przez Belzebuba wypędzam demony, to przez kogo wypędzają wasi synowie? Dlatego oni będą waszymi sędziami.
20 Ṣùgbọ́n bí ó bá ṣe pé nípa ìka ọwọ́ Ọlọ́run ni èmi fi ń lé àwọn ẹ̀mí èṣù jáde, ǹjẹ́ ìjọba Ọlọ́run dé bá yín tán.
Ale jeśli ja palcem Bożym wypędzam demony, to istotnie przyszło do was królestwo Boże.
21 “Nígbà tí alágbára ọkùnrin tí ó ni ìhámọ́ra bá ń ṣọ́ ààfin rẹ̀, ẹrù rẹ̀ yóò wà ní àlàáfíà.
Gdy uzbrojony mocarz strzeże swego pałacu, bezpieczne jest jego mienie.
22 Ṣùgbọ́n nígbà tí ẹni tí ó ní agbára jù ú bá kọlù ú, tí ó sì ṣẹ́gun rẹ̀ a gba gbogbo ìhámọ́ra rẹ̀ tí ó gbẹ́kẹ̀lé lọ́wọ́ rẹ̀, a sì pín ìkógun rẹ̀.
Lecz gdy mocniejszy od niego nadejdzie i zwycięży go, zabiera całą jego broń, na której polegał, i rozdaje jego łupy.
23 “Ẹni tí kò bá wà pẹ̀lú mi, ó lòdì sí mi, ẹni tí kò bá sì bá mi kójọpọ̀, ó fọ́nká.
Kto nie jest ze mną, jest przeciwko mnie, a kto nie zbiera ze mną, rozprasza.
24 “Nígbà tí ẹ̀mí àìmọ́ bá jáde kúrò lára ènìyàn, a máa rìn kiri ní ibi gbígbẹ, a máa wá ibi ìsinmi; nígbà tí kò bá sì rí, a wí pé, ‘Èmi yóò padà lọ sí ilé mi ní ibi tí mo gbé ti jáde wá.’
Gdy duch nieczysty wychodzi z człowieka, przechadza się po miejscach bezwodnych, szukając odpoczynku, a gdy nie znajduje, mówi: Wrócę do mego domu, skąd wyszedłem.
25 Nígbà tí ó bá sì dé, tí ó sì rí tí a gbá a, tí a sì ṣe é ní ọ̀ṣọ́.
A przyszedłszy, zastaje [go] zamiecionym i przyozdobionym.
26 Nígbà náà ni yóò lọ, yóò sì mú ẹ̀mí méje mìíràn tí ó burú ju òun tìkára rẹ̀ lọ wá, wọn yóò wọlé, wọn yóò sì máa gbé níbẹ̀, ìgbẹ̀yìn ọkùnrin náà yóò sì burú ju ìṣáájú rẹ̀ lọ.”
Wtedy idzie i bierze ze sobą siedem innych duchów, gorszych niż on sam, i wszedłszy, mieszkają tam. I końcowy [stan] tego człowieka staje się gorszy niż pierwszy.
27 Bí ó ti ń sọ nǹkan wọ̀nyí, obìnrin kan gbóhùn rẹ̀ sókè nínú ìjọ, ó sì wí fún un pé, “Ìbùkún ni fún inú tí ó bí ọ, àti ọmú tí ìwọ mu!”
A gdy on to mówił, pewna kobieta spośród zgromadzonych powiedziała do niego donośnym głosem: Błogosławione łono, które cię nosiło, i piersi, które ssałeś!
28 Ṣùgbọ́n òun wí pé, nítòótọ́, kí ó kúkú wí pé, “Ìbùkún ni fún àwọn tí ń gbọ́ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, tí wọ́n sì pa á mọ́!”
On zaś odpowiedział: Błogosławieni [są] raczej ci, którzy słuchają słowa Bożego i strzegą go.
29 Nígbà tí ìjọ ènìyàn sì ṣùjọ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀, ó bẹ̀rẹ̀ sí wí pé, “Ìran búburú ni èyí, wọ́n ń wá àmì; a kì yóò sì fi àmì kan fún un bí kò ṣe àmì Jona wòlíì!
A gdy ludzie się gromadzili, zaczął mówić: Pokolenie to jest złe. Żąda znaku, ale [żaden] znak nie będzie mu dany, oprócz znaku proroka Jonasza.
30 Nítorí bí Jona ti jẹ́ àmì fún àwọn ará Ninefe, gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni Ọmọ Ènìyàn yóò ṣe jẹ́ àmì fún ìran yìí.
Jak bowiem Jonasz [był] znakiem dla mieszkańców Niniwy, tak będzie i Syn Człowieczy dla tego pokolenia.
31 Ọbabìnrin gúúsù yóò dìde ní ọjọ́ ìdájọ́ pẹ̀lú àwọn ènìyàn ìran yìí, yóò sì dá wọn lẹ́bi: nítorí tí ó ti ìhà ìpẹ̀kun ayé wá láti gbọ́ ọgbọ́n Solomoni: sì kíyèsi i, ẹni tí ó pọ̀jù Solomoni lọ ń bẹ níhìn-ín yìí.
Królowa z południa stanie na sądzie z ludźmi tego pokolenia i potępi ich, bo przybyła z krańców ziemi, aby słuchać mądrości Salomona, a oto tu [ktoś] więcej niż Salomon.
32 Àwọn ará Ninefe yóò dìde ní ọjọ́ ìdájọ́ pẹ̀lú ìran yìí, wọn ó sì dá a lẹ́bi: nítorí tí wọn ronúpìwàdà nípa ìwàásù Jona; sì kíyèsi i, ẹni tí ó pọ̀jù Jona lọ ń bẹ níhìn-ín yìí.
Ludzie z Niniwy staną na sądzie z tym pokoleniem i potępią je, ponieważ pokutowali na skutek głoszenia Jonasza, a oto tu [ktoś] więcej niż Jonasz.
33 “Kò sí ẹnìkan, nígbà tí ó bá tan fìtílà tan, tí gbé e sí ìkọ̀kọ̀, tàbí sábẹ́ òsùwọ̀n, bí kò ṣe sórí ọ̀pá fìtílà, kí àwọn tí ń wọlé ba à lè máa rí ìmọ́lẹ̀.
Nikt nie zapala świecy i nie stawia jej w ukryciu ani pod naczyniem, ale na świeczniku, aby ci, którzy wchodzą, widzieli światło.
34 Ojú ni fìtílà ara: bí ojú rẹ bá mọ́lẹ̀ kedere, gbogbo ara rẹ a mọ́lẹ̀; ṣùgbọ́n bí ojú rẹ bá ṣókùnkùn, ara rẹ pẹ̀lú a kún fún òkùnkùn.
Światłem ciała jest oko. Jeśli więc twoje oko jest szczere, to i całe twoje ciało będzie pełne światła, a jeśli jest złe, to i twoje ciało będzie pełne ciemności.
35 Nítorí náà kíyèsi i, kí ìmọ́lẹ̀ tí ń bẹ nínú rẹ má ṣe di òkùnkùn.
Uważaj więc, aby światło, które jest w tobie, nie było ciemnością.
36 Ǹjẹ́ bí gbogbo ara rẹ bá kún fún ìmọ́lẹ̀, tí kò ní apá kan tí ó ṣókùnkùn, gbogbo rẹ̀ ni yóò ní ìmọ́lẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ìgbà tí fìtílà bá fi ìtànṣán rẹ̀ fún ọ ní ìmọ́lẹ̀.”
Jeśli zatem całe twoje ciało będzie pełne światła, nie mając [w sobie] żadnej ciemnej cząstki, całe będzie [tak] pełne światła, jak gdy świeca oświetla cię swoim blaskiem.
37 Bí ó sì ti ń wí, Farisi kan bẹ̀ ẹ́ kí ó bá òun jẹun: ó sì wọlé, ó jókòó láti jẹun.
Kiedy to mówił, pewien faryzeusz poprosił go, aby zjadł u niego obiad. Wszedł więc i usiadł [za stołem].
38 Nígbà tí Farisi náà sì rí i, ẹnu yà á nítorí tí kò kọ́kọ́ wẹ ọwọ́ kí ó tó jẹun.
A faryzeusz, widząc to, dziwił się, że nie umył się przed obiadem.
39 Olúwa sì wí fún un pé, “Ẹ̀yin Farisi a máa ń fọ òde ago àti àwopọ̀kọ́: ṣùgbọ́n, inú yín kún fún ìwà búburú àti ìrẹ́jẹ.
Wtedy Pan powiedział do niego: Teraz wy, faryzeusze, oczyszczacie to, co jest na zewnątrz kubka i misy, ale to, co jest wewnątrz was, pełne jest zdzierstwa i nieprawości.
40 Ẹ̀yin aṣiwèrè, ẹni tí ó ṣe èyí tí ń bẹ lóde, òun kò ha ṣe èyí tí ń bẹ nínú pẹ̀lú?
Głupcy, czyż ten, który uczynił to, co jest na zewnątrz, nie uczynił też tego, co jest wewnątrz?
41 Nípa ohun ti inú yin, ki ẹ̀yin kúkú máa ṣe ìtọrẹ àánú nínú ohun tí ẹ̀yin ní, sì kíyèsi i, ohun gbogbo ni ó di mímọ́ fún yín.
Raczej z tego, co jest wewnątrz, dawajcie jałmużnę, a wszystko będzie dla was czyste.
42 “Ṣùgbọ́n ègbé ni fún yín, ẹ̀yin Farisi, nítorí tí ẹ̀yin a máa san ìdámẹ́wàá minti àti irúgbìn, àti gbogbo ewébẹ̀, ṣùgbọ́n ẹ̀yin kọ ìdájọ́ àti ìfẹ́ Ọlọ́run: wọ̀nyí jẹ́ ohun tí ẹ gbọdọ̀ ṣe, láìsí fi àwọn ìyókù sílẹ̀ láìṣe.
Ale biada wam, faryzeusze, bo dajecie dziesięcinę z mięty, ruty i z każdego ziela, lecz opuszczacie sąd i miłość Boga. To należało czynić i tamtego nie opuszczać.
43 “Ègbé ni fún yín, ẹ̀yin Farisi, àgàbàgebè! Nítorí tí ẹ̀yin fẹ́ ipò ọlá nínú Sinagọgu, àti ìkíni ní ọjà.
Biada wam, faryzeusze, bo kochacie pierwsze miejsca w synagogach i pozdrowienia na rynkach.
44 “Ègbé ni fún un yín, nítorí ẹ̀yin dàbí ibojì tí kò farahàn, tí àwọn ènìyàn sì ń rìn lórí rẹ̀ láìmọ̀.”
Biada wam, uczeni w Piśmie i faryzeusze, obłudnicy, bo jesteście jak groby, których nie widać, a ludzie, którzy chodzą po nich, nie wiedzą [o tym].
45 Nígbà náà ni ọ̀kan nínú àwọn amòfin dáhùn, ó sì wí fún un pé, “Olùkọ́, nínú èyí tí ìwọ ń wí yìí ìwọ ń gan àwa pẹ̀lú.”
I odezwał się jeden ze znawców prawa: Nauczycielu, mówiąc to, i nas znieważasz.
46 Ó sì wí pé, “Ègbé ni fún ẹ̀yin amòfin pẹ̀lú, nítorí tí ẹ̀yin di ẹrù tí ó wúwo láti rù lé ènìyàn lórí, bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin tìkára yín kò jẹ́ fi ìka yín kan ẹrù náà.
A on powiedział: I wam, znawcom prawa, biada, bo obciążacie ludzi brzemionami nie do uniesienia, a sami nawet jednym palcem tych brzemion nie dotykacie.
47 “Ègbé ni fún yín, nítorí tí ẹ̀yin kọ́ ibojì àwọn wòlíì, tí àwọn baba yín pa.
Biada wam, bo budujecie grobowce proroków, a wasi ojcowie ich pozabijali.
48 Ǹjẹ́ ẹ̀yin jẹ́ ẹlẹ́rìí, ẹ sì ní inú dídùn sí iṣẹ́ àwọn baba yín, nítorí tí wọn pa wọ́n, ẹ̀yin sì kọ́ ibojì wọn.
Doprawdy świadczycie, że pochwalacie uczynki waszych ojców. Oni bowiem ich pozabijali, a wy budujecie ich grobowce.
49 Nítorí èyí ni ọgbọ́n Ọlọ́run sì ṣe wí pé, ‘Èmi ni ó rán àwọn wòlíì àti àwọn aposteli sí wọn, wọn ó sì ṣe inúnibíni sí wọn.’
Dlatego też mądrość Boża powiedziała: Poślę do nich proroków i apostołów, a [niektórych] z nich będą zabijać i prześladować;
50 Kí a lè béèrè ẹ̀jẹ̀ àwọn wòlíì gbogbo, tí a ti ta sílẹ̀ láti ìgbà ìpilẹ̀ṣẹ̀ ayé wá, lọ́wọ́ ìran yìí;
Aby dopominano się od tego pokolenia krwi wszystkich proroków, która została przelana od założenia świata;
51 láti ẹ̀jẹ̀ Abeli wá, títí ó sì fi dé ẹ̀jẹ̀ Sekariah, tí ó ṣègbé láàrín pẹpẹ àti tẹmpili. Lóòótọ́ ni mo wí fún yín ìran yìí ni yóò ru gbogbo ẹ̀bi àwọn nǹkan wọ̀nyí.
Od krwi Abla aż do krwi Zachariasza, który zginął między ołtarzem a świątynią. Doprawdy, mówię wam, dopominać się jej będą od tego pokolenia.
52 “Ègbé ni fún yín, ẹ̀yin amòfin, nítorí tí ẹ̀yin ti mú kọ́kọ́rọ́ ìmọ̀ kúrò; ẹ̀yin tìkára yín kò wọlé, àwọn tí sì ń wọlé, ni ẹ̀yin ń dí lọ́wọ́.”
Biada wam, znawcom prawa, bo zabraliście klucz poznania. Sami nie weszliście i tym, którzy chcieli wejść, przeszkodziliście.
53 Bí ó ti ń lọ kúrò níbẹ̀, àwọn akọ̀wé àti àwọn Farisi bẹ̀rẹ̀ sí bi í lọ́rọ̀ gidigidi, wọ́n sì ń yọ ọ́ lẹ́nu láti wí nǹkan púpọ̀.
A gdy im to mówił, uczeni w Piśmie i faryzeusze zaczęli bardzo na niego nastawać i prowokować go do mówienia o wielu [rzeczach];
54 Wọ́n ń ṣọ́ ọ, wọ́n ń wá ọ̀nà láti rí nǹkan gbámú lẹ́nu kí wọn bá à lè fi ẹ̀sùn kàn án.
Czyhając na niego i próbując wychwycić coś z jego słów, żeby go oskarżyć.

< Luke 11 >