< Luke 10 >

1 Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí, Olúwa sì yan méjìléláàádọ́rin ọmọ-ẹ̀yìn mìíràn pẹ̀lú, ó sì rán wọn ní méjì méjì lọ ṣáájú rẹ̀, sí gbogbo ìlú àti ibi tí òun tìkára rẹ̀ yóò sì dé.
Njalo emva kwalezizinto iNkosi yamisa njalo abanye abangamatshumi ayisikhombisa, yabathuma ngababili phambi kobuso bayo emizini yonke lezindaweni zonke ebizakuya kuzo yona.
2 Ó sì wí fún wọn pé, “Ìkórè pọ̀, ṣùgbọ́n àwọn alágbàṣe kò tó nǹkan, nítorí náà ẹ bẹ Olúwa ìkórè, kí ó lè rán àwọn alágbàṣe sínú ìkórè rẹ̀.
Ngakho yathi kubo: Isibili isivuno sikhulu, kodwa izisebenzi zinlutshwana. Ngakho ncengani eNkosini yesivuno, ukuze ithume izisebenzi esivunweni sayo.
3 Ẹ mú ọ̀nà yín pọ̀n: sá wò ó, èmi rán yín lọ bí ọ̀dọ́-àgùntàn sáàrín ìkookò.
Hambani; khangelani, mina ngiyalithuma linjengezimvana phakathi kwezimpisi.
4 Ẹ má ṣe mú àpò, ẹ má ṣe mú àpamọ́wọ́, tàbí bàtà: ẹ má sì ṣe kí ẹnikẹ́ni lọ́nà.
Lingaphathi umxhaka, lesikhwama, lamanyathela; njalo lingabingeleli muntu endleleni.
5 “Ní ilékílé tí ẹ̀yin bá wọ̀, kí ẹ kọ́ wí pé, ‘Àlàáfíà fún ilé yìí!’
Njalo lakuyiphi indlu elingena kuyo, qalani lithi: Ukuthula kakube kulindlu.
6 Bí ọmọ àlàáfíà bá sì wà níbẹ̀, àlàáfíà yín yóò bà lé e: ṣùgbọ́n bí kò bá sí, yóò tún padà sọ́dọ̀ yín.
Njalo uba kukhona lapho indodana yokuthula, ukuthula kwenu kuzahlala phezu kwayo; kodwa uba kungenjalo, kuzabuyela kini.
7 Ẹ dúró sínú ilé náà, kí ẹ máa jẹ, kí ẹ sì máa mu ohunkóhun tí wọ́n bá fi fún yín, nítorí ọ̀yà alágbàṣe tọ́ sí i. Ẹ má ṣe lọ láti ilé dé ilé.
Hlalani-ke kuleyondlu, lidle linathe izinto ezivela kubo; ngoba isisebenzi sifanele umvuzo waso. Lingayi endlini lendlini.
8 “Ìlúkílùú tí ẹ̀yin bá wọ̀, tí wọ́n bá sì gbà yín, ẹ jẹ ohunkóhun tí a bá gbé ka iwájú yín.
Lakuwuphi umuzi elingena kuwo, besebelemukela, dlanini okubekwa phambi kwenu,
9 Ẹ sì mú àwọn aláìsàn tí ń bẹ nínú rẹ̀ láradá, kí ẹ sì wí fún wọn pé, ‘Ìjọba Ọlọ́run kù sí dẹ̀dẹ̀ sí yín!’
lisilise abagulayo abakuwo, njalo lithi kubo: Umbuso kaNkulunkulu usondele kini.
10 Ṣùgbọ́n ní ìlúkílùú tí ẹ̀yin bá sì wọ̀, tí wọn kò bá sì gbà yín, nígbà tí ẹ̀yin bá sì jáde ní ìgboro ìlú náà, kí ẹ̀yin sì wí pé,
Kodwa lakuwuphi umuzi elingena kuwo, futhi bengalemukeli, phumelani endleleni zawo, lithi:
11 ‘Eruku ìlú yín tí ó kù sí wa lẹ́sẹ̀, a gbọ̀n ọ́n sílẹ̀ fún yín! Ṣùgbọ́n ẹ mọ èyí pé, ìjọba Ọlọ́run kù sí dẹ̀dẹ̀.’
Lothuli lomuzi wenu olusinamatheleyo siyaluthintithela kini; kodwa-ke yazini lokhu, ukuthi umbuso kaNkulunkulu usondele kini.
12 Ṣùgbọ́n mo wí fún yín, yóò sàn fún Sodomu ní ọjọ́ náà, ju fún ìlú náà lọ.
Njalo ngithi kini: Kuzakuba lula eSodoma ngalolosuku, kulakulowomuzi.
13 “Ègbé ni fún ìwọ, Korasini! Ègbé ni fún ìwọ Betisaida! Nítorí ìbá ṣe pé a ti ṣe iṣẹ́ agbára tí a ṣe nínú yín, ní Tire àti Sidoni, wọn ìbá ti ronúpìwàdà lọ́jọ́ pípẹ́ sẹ́yìn, wọn ìbá sì jókòó nínú aṣọ ọ̀fọ̀ àti nínú eérú.
Maye kuwe, Korazini! Maye kuwe, Bhethisayida! Ngoba uba kwakwenziwe eTire leSidoni imisebenzi yamandla eyenziwe kini, ngabe kade baphenduka bahlala emasakeni lemlotheni.
14 Ṣùgbọ́n yóò sàn fún Tire àti Sidoni nígbà ìdájọ́ jù fún yín lọ.
Kodwa kuzakuba lula eTire leSidoni ekugwetshweni, kulakini.
15 Àti ìwọ, Kapernaumu, a ó ha gbé ọ ga dé òkè ọ̀run? A ó rẹ̀ ọ́ sílẹ̀ dé isà òkú. (Hadēs g86)
Lawe, Kapenawume, ophakanyiselwe ezulwini, uzaphoselwa phansi esihogweni. (Hadēs g86)
16 “Ẹni tí ó bá gbọ́ tiyín, ó gbọ́ tèmi. Ẹni tí ó bá sì kọ̀ yín, ó kọ̀ mi. Ẹni tí ó bá sì kọ̀ mi, ó kọ ẹni tí ó rán mi.”
Olizwayo lina uyangizwa mina; lolalayo lina uyangala mina; longalayo mina uyamala ongithumileyo.
17 Àwọn àádọ́rin náà sì fi ayọ̀ padà, wí pé, “Olúwa, àwọn ẹ̀mí èṣù tilẹ̀ foríbalẹ̀ fún wa ní orúkọ rẹ.”
Babuya-ke abangamatshumi ayisikhombisa ngentokozo, besithi: Nkosi, lamadimoni ayazehlisela ngaphansi kwethu ebizweni lakho.
18 Ó sì wí fún wọn pé, “Èmí rí Satani ṣubú bí mọ̀nàmọ́ná láti ọ̀run wá.
Wasesithi kubo: Ngabona uSathane njengombane esiwa evela ezulwini.
19 Kíyèsi i, èmí fún yín ní àṣẹ láti tẹ ejò àti àkéekèe mọ́lẹ̀, àti lórí gbogbo agbára ọ̀tá, kò sì ṣí ohun kan bí ó ti wù tí ó ṣe, tí yóò pa yín lára.
Khangelani, ngilinika amandla okunyathela phezu kwezinyoka labofezela, laphezu kwamandla wonke esitha; njalo akusoze kube lalutho olungalilimaza.
20 Ṣùgbọ́n kí ẹ má ṣe yọ̀ nítorí èyí pé, àwọn ẹ̀mí ń foríbalẹ̀ fún yín; ṣùgbọ́n ẹ kúkú yọ̀, pé; a kọ̀wé orúkọ yín ní ọ̀run!”
Kodwa lingathokozi ngalokho ukuthi omoya bayazehlisela ngaphansi kwenu; kodwa ikakhulu thokozani ukuthi amabizo enu alotshiwe emazulwini.
21 Ní wákàtí kan náà Jesu yọ̀ nínú Ẹ̀mí mímọ́ ó sì wí pé, “Mo dúpẹ́ lọ́wọ́ rẹ, Baba, Olúwa ọ̀run àti ayé, pé, ìwọ pa nǹkan wọ̀nyí mọ́ kúrò lọ́dọ̀ àwọn ọlọ́gbọ́n àti amòye, ìwọ sì fi wọ́n hàn fún àwọn ọmọ ọwọ́. Bẹ́ẹ̀ ni, Baba, bẹ́ẹ̀ ni ó sá à yẹ ní ojú rẹ.
Ngalelohola uJesu wathokoza emoyeni, wathi: Ngiyakubonga, Baba, Nkosi yezulu lomhlaba, ngoba uzifihlile lezizinto kwabahlakaniphileyo labaqedisisayo, kodwa wazembulela izingane; yebo, Baba, ngoba ngokunjalo kwaba kuhle phambi kwakho.
22 “Ohun gbogbo ni a ti fi fún mi láti ọ̀dọ̀ Baba mi; kò sì ṣí ẹni tí ó mọ ẹni tí ọmọ jẹ́, bí kò ṣe Baba, àti ẹnikẹ́ni tí ó bá sì wu ọmọ láti fi í hàn fún.”
Konke kwanikelwa kimi nguBaba; njalo kakho owaziyo ukuthi iNdodana ingubani, ngaphandle kukaBaba, lokuthi uBaba ungubani, ngaphandle kweNdodana, njalo loba ngubani iNdodana ethanda ukumembulela.
23 Ó sì yípadà sí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ ní apá kan. Ó ní, “Ìbùkún ni fún ojú tí ń rí ohun tí ẹ̀yin ń rí.
Wasephendukela kubafundi bebodwa wathi: Abusisiwe amehlo abona elikubonayo.
24 Nítorí mo wí fún yín, ọ̀pọ̀ àwọn wòlíì àti àwọn ọba ni ó ń fẹ́ láti rí ohun tí ẹ̀yin ń rí, wọn kò sì rí wọn, àti láti gbọ́ ohun tí ẹ̀yin ń gbọ́, wọn kò sì gbọ́ wọn.”
Ngoba ngithi kini: Abaprofethi abanengi lamakhosi babethanda ukubona izinto elizibonayo lina, kodwa kabazibonanga; lokuzwa izinto elizizwayo, kodwa kabazizwanga.
25 Sì kíyèsi i amòfin kan dìde, ó ń dán an wò, ó ní, “Olùkọ́, kín ni èmi ó ṣe kí èmi lè jogún ìyè àìnípẹ̀kun?” (aiōnios g166)
Njalo khangela, isazumthetho esithile sasesisukuma, simlinga, sisithi: Mfundisi, ngenzeni ukuze ngidle ilifa lempilo elaphakade? (aiōnios g166)
26 Ó sì bi í pé, “Kí ni a kọ sínú ìwé òfin? Báwo ni ìwọ sì ti kà á?”
Wasesithi kuso: Kubhalweni emlayweni? Uwubala njani?
27 Ó sì dáhùn wí pé, “‘Kí ìwọ fi gbogbo àyà rẹ, àti gbogbo ọkàn rẹ, àti gbogbo agbára rẹ, àti gbogbo inú rẹ fẹ́ Olúwa Ọlọ́run rẹ’; àti, ‘Ẹnìkejì rẹ bí ara rẹ.’”
Sasesiphendula sathi: Wothanda iNkosi uNkulunkulu wakho, ngenhliziyo yakho yonke, langomphefumulo wakho wonke, langamandla akho wonke, langengqondo yakho yonke; lomakhelwane wakho njengalokhu uzithanda wena.
28 Ó sì wí fún un pé, “Ìwọ́ dáhùn rere. Ṣe èyí, ìwọ ó sì yè.”
Wasesithi kuso: Uphendule ngokuqonda; yenza lokhu, futhi uzaphila.
29 Ṣùgbọ́n ó ń fẹ́ láti da ara rẹ̀ láre, ó wí fún Jesu wí pé, “Ta ha sì ni ẹnìkejì mi?”
Kodwa sona sithanda ukuzilungisisa sathi kuJesu: Kanti ngubani umakhelwane wami?
30 Jesu sì dáhùn ó wí pé, “Ọkùnrin kan ń ti Jerusalẹmu sọ̀kalẹ̀ lọ sí Jeriko, ó sì bọ́ sí ọwọ́ àwọn ọlọ́ṣà; wọ́n gbà á ní aṣọ, wọ́n sá a lọ́gbẹ́, wọ́n sì fi sílẹ̀ lọ ní àìpatán.
UJesu wasephendula wathi: Umuntu othile wehla evela eJerusalema esiya eJeriko, watheleka phakathi kwabaphangi, njalo bamhlubula impahla bamtshaya imivimvinya basuka bahamba, bamtshiya ephosukufa.
31 Ní kòńgẹ́ àkókò yìí ni àlùfáà kan sì ń sọ̀kalẹ̀ lọ lọ́nà náà. Nígbà tí ó sì rí i ó kọjá lọ níhà kejì.
Umpristi othile waseqabuka esehla ngaleyondlela; njalo wathi embona, wadlula eceleni.
32 Bẹ́ẹ̀ náà sì ni ọmọ Lefi kan pẹ̀lú, nígbà tí ó dé ibẹ̀, tí ó sì rí i, ó kọjá lọ níhà kejì.
Langokunjalo lomLevi nxa wayesekulindawo, wafika embona, wadlula eceleni.
33 Ṣùgbọ́n ará Samaria kan, bí ó ti ń re àjò, ó dé ibi tí ó gbé wà; nígbà tí ó sì rí i, àánú ṣe é.
Kodwa umSamariya othile owayehamba wafika lapho ayekhona, njalo kwathi embona waba lesihelo,
34 Ó sì tọ̀ ọ́ lọ, ó sì di ọgbẹ́ rẹ̀, ó da òróró àti ọtí wáìnì sí i, ó sì gbé e lé orí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ti òun tìkára rẹ̀, ó sì mú un wá sí ilé èrò, a sì ń ṣe ìtọ́jú rẹ̀.
waya kuye wabopha amanxeba akhe, ewathela amagcobo lewayini; wamkhweza phezu kweyakhe inyamazana, wamusa endlini yezihambi, wamlondoloza.
35 Nígbà tí ó sì lọ ní ọjọ́ kejì, ó fi owó idẹ méjì fún olórí ilé èrò ó sì wí fún un pé, ‘Máa tọ́jú rẹ̀; ohunkóhun tí ìwọ bá sì ná kún un, nígbà tí mo bá padà dé, èmi ó san án fún ọ.’
Kusisa esehamba, wakhupha odenariyo ababili wabanika umninindlu, wathi kuye: Umlondoloze; njalo loba yini ozakuchitha okwedlula lokhu, mina ngizabuyisela kuwe ekubuyeni kwami.
36 “Nínú àwọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta wọ̀nyí, ta ni ìwọ rò pé ó jẹ́ ẹnìkejì ẹni tí ó bọ́ sí ọwọ́ àwọn ọlọ́ṣà?”
Pho, nguwuphi kulaba abathathu ocabanga ukuthi wayengumakhelwane walowo owatheleka phakathi kwabaphangi?
37 Ó sì dáhùn wí pé, “Ẹni tí ó ṣàánú fún un ni.” Jesu sì wí fún un pé, “Lọ, kí o ṣe bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́!”
Wasesithi: Ngulowo owamenzela isihawu. Ngakho uJesu wathi kuye: Hamba, lawe wenze njalo.
38 Ó sì ṣe, bí wọ́n ti ń lọ, o wọ ìletò kan, obìnrin kan tí a ń pè ní Marta sì gbà á sí ilé rẹ̀.
Kwasekusithi ekuhambeni kwabo, yena wangena emzaneni othile; lowesifazana othile, uMarta ngebizo, wamemukela endlini yakhe.
39 Ó sì ní arábìnrin kan tí a ń pè ní Maria tí ó sì jókòó lẹ́bàá ẹsẹ̀ Olúwa, tí ó ń gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀.
Njalo lo wayelodadewabo othiwa nguMariya, laye owahlala enyaweni zikaJesu, walizwa ilizwi lakhe.
40 Ṣùgbọ́n Marta ń ṣe ìyọnu ohun púpọ̀, ó sì tọ̀ ọ́ wá, ó wí pé, “Olúwa, ìwọ kò sì bìkítà sí ti arábìnrin mi pé ó fi mí sílẹ̀ láti máa nìkan ṣe ìránṣẹ́? Wí fún un kí ó ràn mí lọ́wọ́.”
Kodwa uMarta wayephazanyiswa yikusebenza okunengi; weza eduze wasesithi: Nkosi, kawukhathali yini ukuthi udadewethu ungitshiye ukuthi ngisebenze ngedwa? Ngakho umtshele ukuthi angisize.
41 Ṣùgbọ́n Olúwa sì dáhùn, ó sì wí fún un pé, “Marta, Marta, ìwọ ń ṣe àníyàn àti làálàá nítorí ohun púpọ̀.
Kodwa uJesu waphendula wathi kuye: Marta, Marta, uyaphiseka ukhathazeke ngezinto ezinengi;
42 Ṣùgbọ́n ohun kan ni a kò lè ṣe aláìní, Maria sì ti yan ipa rere náà tí a kò lè gbà lọ́wọ́ rẹ̀.”
kodwa yinye into edingekayo; kodwa uMariya ukhethile isabelo esihle, angayikwemukwa sona.

< Luke 10 >