< Leviticus 22 >

1 Olúwa sọ fún Mose pé,
Perwerdigar Musagha söz qilip mundaq dédi: —
2 “Sọ fún Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ kí wọ́n fi ọ̀wọ̀ fún ọrẹ mímọ́ tí àwọn ọmọ Israẹli yà sọ́tọ̀ fún mi, kí wọ́n má ba à ba orúkọ mímọ́ mi jẹ́. Èmi ni Olúwa.
Sen Harun bilen uning oghullirigha mundaq dégin: — «Siler Israillarning Manga atighan muqeddes hediyelerni éhtiyatchanliq bilen bir terep qilinglar, bolmisa ular namimni bulghishi mumkin. Men Perwerdigardurmen».
3 “Sọ fún wọn pé, ‘Fún àwọn ìran tí ń bọ̀. Bí ẹnikẹ́ni nínú àwọn ọmọ yín tí kò mọ́ bá wá sí ibi ọrẹ mímọ́ tí àwọn ara Israẹli ti yà sọ́tọ̀ fún Olúwa, kí ẹ yọ ẹni náà kúrò nínú iṣẹ́ àlùfáà ní iwájú mi. Èmi ni Olúwa.
Ulargha mundaq dégin: — «Siler herbir dewrlerde, barliq nesillinglardin herqaysisi Israillar Perwerdigargha atighan pak nersilerge napak halette yéqinlashsa, undaq kishi Méning aldimdin üzüp tashlinidu. Men Perwerdigardurmen.
4 “‘Bí ọ̀kan nínú àwọn ọmọ Aaroni bá ní ààrùn ara tí ń ran ni, tàbí ìtújáde nínú ara. Ó lè má jẹ ọrẹ mímọ́ náà títí di ìgbà tí a ó fi wẹ̀ ẹ́ mọ́. Òun tún lè di aláìmọ́ bí ó bá fọwọ́ kan ohunkóhun tí òkú nǹkan bá sọ di àìmọ́ tàbí bí ó bá farakan ẹnikẹ́ni tí ó ní ìtújáde.
Harunning neslidin biri pése-maxaw yaki aqma késili bolghan bolsa, pak bolmighuche muqeddes nersilerdin yémisun. Birkim ölükning sewebidin napak bolghan birkimge we yaki meniysi éqip ketken kishige tégip ketse,
5 Tàbí bí ó bá fọwọ́ kan èyíkéyìí nínú ohun tí ń rákò, tí ó sọ ọ́ di aláìmọ́, tàbí ẹnikẹ́ni tí ó sọ ọ́ di àìmọ́, ohunkóhun yówù kí àìmọ́ náà jẹ́.
yaki ademni napak qilidighan ömiligüchi janiwargha tegse yaki herqandaq yuqup qalidighan napakliqi bar bir ademge tégip ketse, (napakliqi némidin bolushidin qet’iynezer)
6 Ẹni náà tí ó fọwọ́ kan irú nǹkan bẹ́ẹ̀ yóò di aláìmọ́ títí ìrọ̀lẹ́. Kò gbọdọ̀ jẹ èyíkéyìí nínú ọrẹ mímọ́ àyàfi bí ó bá wẹ ara rẹ̀.
mundaq nersilerge tegken kishi kech kirgüche napak bolup, muqeddes nersilerdin yémisun. U bedinini suda yusun
7 Bí oòrùn bá wọ̀, ẹni náà di mímọ́, lẹ́yìn náà ni ó tó le jẹ ọrẹ mímọ́, torí pé wọ́n jẹ́ oúnjẹ rẹ̀.
andin kün olturghanda pak sanilip, muqeddes nersilerdin yéyishke bolidu; chünki bular uning ozuqidur.
8 Kò gbọdọ̀ jẹ ohunkóhun tí ó bá ti kú sílẹ̀, tàbí tí ẹranko fàya, kí ó sì tipa bẹ́ẹ̀ di aláìmọ́. Èmi ni Olúwa.
U [özlükidin] ölgen we yaki yirtquchlar boghup qoyghan haywanni yéyish bilen özini napak qilmisun. Men Perwerdigardurmen.
9 “‘Kí àwọn àlùfáà pa ìlànà mi mọ́, kí wọn má ba à jẹ̀bi, kí wọn sì kú nítorí pé wọ́n ṣe ọrẹ wọ̀nyí pẹ̀lú fífojútẹ́ńbẹ́lú wọn. Èmi ni Olúwa tí ó sọ wọ́n di mímọ́.
Ular Méning bu tapilighanlirimni tutushi kérek; bolmisa, buninggha ixlassizliq qilsa, [shu ölük] tüpeylidin gunahkar bolup ölidu; ularni muqeddes qilghuchi Perwerdigar Özümdurmen.
10 “‘Kò sí ẹnikẹ́ni lẹ́yìn ìdílé àlùfáà tí ó le jẹ ọrẹ mímọ́ náà, bẹ́ẹ̀ ni, àlejò àlùfáà tàbí alágbàṣe rẹ̀ kò le jẹ ẹ́.
Kahinlargha yat bolghan héchqandaq kishi muqeddes nersilerdin yémisun. Kahinning yénidiki musapir-méhman we yaki medikari bolsun ularmu muqeddes nersilerdin yémisun.
11 Ṣùgbọ́n bí àlùfáà bá ra ẹrú, pẹ̀lú owó, tàbí tí a bí ẹrú kan nínú ìdílé rẹ̀, ẹrú náà lè jẹ oúnjẹ rẹ̀.
Halbuki, kahin özi pul chiqirip sétiwalghan qul uningdin yéyishke bolidu; shuningdek uning öyide tughulghan kishimu uningdin yése bolidu.
12 Bí ọmọbìnrin àlùfáà bá fẹ́ ẹni tí kì í ṣe àlùfáà, kò gbọdọ̀ jẹ nínú èyíkéyìí nínú ohun ọrẹ mímọ́.
Kahinning qizi yat kishige tegken bolsa umu «kötürme hediye» süpitide atalghan muqeddes nersilerdin yémisun.
13 Ṣùgbọ́n bí ọmọbìnrin àlùfáà bá jẹ́ opó tàbí tí a ti kọ ọ́ sílẹ̀, ṣùgbọ́n tí kò lọ́mọ tí ó sì padà sínú ilé baba rẹ̀ láti máa gbé bẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ìgbà èwe rẹ̀, ó le jẹ oúnjẹ baba rẹ̀. Bí ó ti wù kí ó rí, àlejò tí kò lẹ́tọ̀ọ́ kò gbọdọ̀ jẹ èyíkéyìí nínú oúnjẹ náà.
Lékin eger kahinning qizi tul bolup qélip, yaki qoyup bérilip perzentsiz halette atisining öyige yénip kélip, yash waqtidikidek olturghan bolsa, undaqta atisining taamidin yéyeleydu; lékin héchbir yat kishi uningdin yémesliki kérek.
14 “‘Bí ẹnikẹ́ni bá ṣèèṣì jẹ ọrẹ mímọ́ kan, ó gbọdọ̀ ṣe àtúnṣe lórí ẹbọ náà fún àlùfáà, kí ó sì fi ìdámárùn-ún ohun tí ọrẹ náà jẹ́ kún un.
Eger birkim bilmey, muqeddes nersilerdin yep salsa, undaqta u uninggha shuning beshtin birini qoshup, muqeddes nersining özi bilen kahin’gha qayturup bersun.
15 Àwọn àlùfáà kò gbọdọ̀ sọ ọrẹ mímọ́ tí àwọn ọmọ Israẹli mú wá síwájú Olúwa di àìmọ́.
[Kahinlar] Israillarning Perwerdigargha atighan nersilirini bulghimasliqi kérek;
16 Nípa fífi ààyè fún wọn láti jẹ ọrẹ mímọ́ náà, kí wọ́n sì tipa bẹ́ẹ̀ mú ẹ̀bi tí wọn yóò san nǹkan fún wá sórí wọn. Èmi ni Olúwa, tí ó sọ wọ́n di mímọ́.’”
bolmisa, xelq muqeddes hediyilerdin yéyishi bilen, kahinlar xelqning gedinige itaetsizlik gunahini yüklep qoyghan bolidu; chünki ularni muqeddes qilghuchi Perwerdigar Özümdurmen».
17 Olúwa sọ fún Mose pé,
Perwerdigar Musagha söz qilip mundaq dédi: —
18 “Sọ fún Aaroni, àwọn ọmọ rẹ̀ àti fún gbogbo Israẹli kí o sì wí fún wọn pé, ‘Bí ẹnikẹ́ni nínú yín yálà ọmọ Israẹli ni tàbí àlejò tí ń gbé ní Israẹli bá mú ẹ̀bùn wá fún ọrẹ ẹbọ sísun sí Olúwa, yálà láti san ẹ̀jẹ́ tàbí ọrẹ àtinúwá.
Sen Harun bilen uning oghulliri we Israillarning hemmisige mundaq dégin: — Eger Israil jemetidin biri we yaki Israil zéminida turuwatqan musapirlarning biri öz qesemlirige baghliq qurbanliq yaki ixtiyariy qurbanliqni sunup, Perwerdigargha atap köydürme qurbanliq qilmaqchi bolsa,
19 Ẹ gbọdọ̀ mú akọ láìní àbùkù láti ara màlúù, àgùntàn tàbí ewúrẹ́, kí ó ba à lè jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà fún yín.
undaqta u qobul qilinishi üchün béjirim erkek kala, qoy yaki öchkilerdin keltürünglar.
20 Ẹ má ṣe mú ohunkóhun tí ó ní àbùkù wá, torí pé kò ní jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà fún yín.
Eyibi bolmighan bir janiwarni sunushunglar kérek; chünki shundaq bolghini siler üchün qobul qilinmas.
21 Bí ẹnikẹ́ni bá mú ọrẹ àlàáfíà wá láti inú agbo màlúù tàbí ti àgùntàn, fún Olúwa láti san ẹ̀jẹ́ pàtàkì tàbí fún ọrẹ àtinúwá. Ó gbọdọ̀ jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà láìní àbùkù.
Birsi kalilardin yaki ushshaq maldin öz qesemlirige baghliq qurbanliq yaki ixtiyariy qurbanliqni sunup, Perwerdigargha atap inaqliq qurbanliqi qilmaqchi bolsa, sunulghan haywan qobul qilinishi üchün béjirim bolushi kérek; uning héchqandaq eyibi bolmisun.
22 Ẹ má ṣe fi ẹranko tí ó fọ́jú, tí ó fi ara pa, tí ó yarọ, tí ó ní kókó, tí ó ní èkúkú, èépá àti egbò kíkẹ̀ rú ẹbọ sí Olúwa. Ẹ kò gbọdọ̀ gbé èyíkéyìí nínú wọn sórí pẹpẹ gẹ́gẹ́ bi ọrẹ tí a fi iná ṣe sí Olúwa.
Kor yaki aqsaq-cholaq, chonaq yaki yarisi yiringdap ketken, temretke basqan yaki qotur-chaqa bésip qalghan haywanlar bolsa — bularni Perwerdigargha atap sunsanglar yaki bularni Perwerdigargha atap qurbanliq süpitide qurban’gahta otta köydürsenglar bolmaydu.
23 Ẹ le mú màlúù tàbí àgùntàn tí ó ní àbùkù tàbí tí ó yọ iké wá fún ọrẹ àtinúwá, ṣùgbọ́n kò jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà fún ọrẹ ẹ̀jẹ́.
Torpaq yaki qoyning melum jüp ezasidin biri uzunraq ya qisqa bolsa, mundaqlarni ixtiyariy qurbanliq süpitide ötküzseng bolidu, lékin qesemge baghliq bolsa qurbanliq üchün qobul qilinmas.
24 Ẹ má ṣe fi ẹranko tí kóró ẹpọ̀n rẹ̀ fọ́ tàbí tí a tẹ̀, tàbí tí a yà tàbí tí a là rú ẹbọ sí Olúwa. Ẹ kò gbọdọ̀ ṣe èyí ní ilẹ̀ yín.
Uruqdini zeximlen’gen, ézilip ketken, yérilghan yaki pichilghan haywanni Perwerdigargha atap qurbanliq qilmanglar. Mundaq ishni öz zémininglardimu hergiz qilmanglar.
25 Ẹ kò gbọdọ̀ gba irú ẹranko bẹ́ẹ̀ lọ́wọ́ àlejò kankan láti fi rú ẹbọ gẹ́gẹ́ bí oúnjẹ sí Ọlọ́run yín. A kò nígbà wọ́n fún yín nítorí pé wọ́n ní àbùkù, wọ́n sì díbàjẹ́.’”
Xudayinglarning néni süpitide yaqa yurtluq kishining qolidin shundaq haywanlardin héchqaysisini élip sunmanglar; chünki ular méyip bolghachqa, siler üchün qobul qilinmaydu.
26 Olúwa sọ fún Mose pé,
Perwerdigar Musagha söz qilip mundaq dédi: —
27 “Nígbà tí màlúù bá bímọ, tí àgùntàn bímọ, tí ewúrẹ́ sì bímọ, ọmọ náà gbọdọ̀ wà pẹ̀lú ìyá rẹ̀ fún ọjọ́ méje. Láti ọjọ́ kẹjọ ni ó ti di ìtẹ́wọ́gbà fún ọrẹ àfinásun sí Olúwa.
Bir mozay, qoza yaki oghlaq tughulsa yette kün’giche anisini emsun; sekkizinchi künidin bashlap Perwerdigargha atap otta sunidighan qurbanliq süpitide qobul bolushqa yaraydu.
28 Ẹ má ṣe pa màlúù àti ọmọ rẹ̀ tàbí àgùntàn àti ọmọ rẹ̀ ní ọjọ́ kan náà.
Meyli kala bolsun, qoy bolsun, siler anisi bilen balisini bir künde boghuzlimanglar.
29 “Nígbà tí ẹ bá rú ẹbọ ọpẹ́ sí Olúwa, ẹ rú u ní ọ̀nà tí yóò fi jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà fún yín.
Siler Perwerdigargha atap bir teshekkür qurbanliqi sunmaqchi bolsanglar, qobul qilinishqa layiq bolghan yol bilen sununglar.
30 Ẹ gbọdọ̀ jẹ ẹ́ ní ọjọ́ náà gan an, ẹ má ṣe ṣẹ́ ọ̀kankan kù di àárọ̀. Èmi ni Olúwa.
U sunulghan künide yéyilishi kérek; uningdin héchnémini etisige qaldurmasliqinglar kérek. Men Perwerdigardurmen.
31 “Ẹ pa òfin mi mọ́, kí ẹ sì máa ṣe wọ́n. Èmi ni Olúwa.
Siler Méning emrlirimni ching tutup, ulargha emel qilinglar. Men Perwerdigardurmen.
32 Ẹ má ṣe ba orúkọ mímọ́ mi jẹ́. Àwọn ọmọ Israẹli gbọdọ̀ mọ̀ mí ní mímọ́. Èmi ni Olúwa tí ó sọ yín di mímọ́.
Méning muqeddes namimni bulghimanglar, Men emdi Israillarning arisida muqeddes dep bilinimen. Men silerni muqeddes qilghuchi Perwerdigar bolup,
33 Tí ó sì mú yín jáde láti Ejibiti wá láti jẹ́ Ọlọ́run yín. Èmi ni Olúwa.”
Xudayinglar bolushqa silerni Misir zéminidin chiqirip keldim. Men Perwerdigardurmen.

< Leviticus 22 >