< Leviticus 20 >

1 Olúwa sọ fún Mose pé,
Yahweh spoke to Moses, saying,
2 “Sọ fún àwọn ará Israẹli pé, ‘Ẹnikẹ́ni nínú àwọn ará Israẹli tàbí àwọn àlejò tí ń gbé láàrín Israẹli, tí ó bá fi èyíkéyìí nínú àwọn ọmọ rẹ̀ fún Moleki, kí wọ́n pa á, kí àwọn olùgbé ilẹ̀ náà sọ ọ́ ní òkúta pa.
“Say to the people of Israel, 'Anyone among the people of Israel, or any foreigner who lives in Israel who gives any of his children to Molech, must certainly be put to death. The people in the land must stone him with stones.
3 Èmi tìkára mi yóò bínú sí irú ẹni bẹ́ẹ̀, ń ó sì gé e kúrò láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀ fún òrìṣà Moleki ó ti ba ibi mímọ́ mi jẹ́ pẹ̀lú.
I also will set my face against that man and will cut him off from among his people because he has given his child to Molech, so as to defile my holy place and profane my holy name.
4 Bí àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà bá mójú kúrò lára irú ẹni bẹ́ẹ̀ tí ó fi ọ̀kan nínú àwọn ọmọ rẹ̀ fún òrìṣà Moleki tí wọn kò sì pa irú ẹni bẹ́ẹ̀.
If the people of the land close their eyes to that man when he gives any of his children to Molech, if they do not put him to death,
5 Èmi yóò bínú sí irú ẹni bẹ́ẹ̀ àti gbogbo ìdílé rẹ̀, èmi yóò sì ké wọn kúrò láàrín àwọn ènìyàn wọn, òun àti gbogbo àwọn tí ó jọ ṣe àgbèrè tọ òrìṣà Moleki lẹ́yìn.
then I myself will set my face against that man and his clan, and I will cut him off and everyone else who prostitutes himself in order to play the harlot with Molech.
6 “‘Bí ẹnikẹ́ni bá tọ àwọn abókùúsọ̀rọ̀ àti àwọn ẹlẹ́mìí òkùnkùn lọ, tí ó sì ṣe àgbèrè tọ̀ wọ́n lẹ́yìn, Èmi yóò bínú sí irú ẹni bẹ́ẹ̀, Èmi yóò sì gé e kúrò láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.
The person who turns to those who talk with the dead, or to those who talk with spirits so as to prostitute themselves with them, I will set my face against that person; I will cut him off from among his people.
7 “‘Torí náà ẹ ya ara yín sí mímọ́ kí ẹ sì jẹ́ mímọ́, torí pé, Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.
Therefore consecrate yourselves and be holy, because I am Yahweh your God.
8 Ẹ máa kíyèsi àṣẹ mi, kí ẹ sì máa pa wọ́n mọ́. Èmi ni Olúwa tí ó sọ yín di mímọ́.
You must keep my commands and carry them out. I am Yahweh who sets you apart as holy.
9 “‘Ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣépè lé baba tàbí ìyá rẹ̀ ni kí ẹ pa, ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ wà lórí ara rẹ̀ torí pé ó ti ṣépè lé baba àti ìyá rẹ̀.
Everyone who curses his father or his mother must surely be put to death. He has cursed his father or his mother, so he is guilty and deserves to die.
10 “‘Bí ẹnikẹ́ni bá bá aya aládùúgbò rẹ̀ lòpọ̀: ọkùnrin àti obìnrin náà ni kí ẹ sọ ní òkúta pa.
The man who commits adultery with another man's wife, that is, anyone who commits adultery with his neighbor's wife—the adulterer and the adulteress must both certainly be put to death.
11 “‘Ẹnikẹ́ni tí ó bá bá aya baba rẹ̀ lòpọ̀ ti tàbùkù baba rẹ̀. Àwọn méjèèjì ni kí ẹ pa. Ẹ̀jẹ̀ wọn yóò wà lórí wọn.
If a man lies with his father's wife, he uncovers his father's nakedness. Both the son and his father's wife must certainly be put to death. Their blood is upon them.
12 “‘Bí ọkùnrin kan bá bá arábìnrin ìyàwó rẹ̀ lòpọ̀, àwọn méjèèjì ni kí ẹ pa, wọ́n ti ṣe ohun tí ó lòdì, ẹ̀jẹ̀ wọn yóò wà lórí wọn.
If a man sleeps with his daughter-in-law, both of them must certainly be put to death. They have committed perversion. They are guilty and deserve to die.
13 “‘Bí ọkùnrin kan bá bá ọkùnrin mìíràn lòpọ̀ bí wọ́n ti í bá obìnrin lòpọ̀: àwọn méjèèjì ti ṣe ohun ìríra, pípa ni kí ẹ pa wọ́n, ẹ̀jẹ̀ wọn yóò wà lórí wọn.
If a man sleeps with another man, as with a woman, both of them have done something detestable. They must surely be put to death. They are guilty and deserve to die.
14 “‘Bí ọkùnrin kan bá fẹ́ tìyátọmọ papọ̀, ìwà búburú ni èyí: iná ni kí ẹ fi sun wọ́n, òun àti àwọn méjèèjì, kí ìwà búburú má ba à gbilẹ̀ láàrín yín.
If a man marries a woman and also marries her mother, this is wickedness. They must be burned, both he and the women, so that there will be no wickedness among you.
15 “‘Bí ọkùnrin kan bá bá ẹranko lòpọ̀, ẹ gbọdọ̀ pa ọkùnrin náà àti ẹranko náà.
If a man sleeps with an animal, he must surely be put to death, and you must kill the animal.
16 “‘Bí obìnrin kan bá súnmọ́ ẹranko tí ó sì bá a lòpọ̀ obìnrin náà àti ẹranko náà ni kí ẹ pa, ẹ̀jẹ̀ wọn yóò sì wà lórí ara wọn.
If a woman approaches any animal to sleep with it, you must kill the woman and the animal. They must certainly be put to death. They are guilty and deserve to die.
17 “‘Bí ọkùnrin kan bá fẹ́ arábìnrin rẹ̀ yálà ọmọbìnrin baba rẹ̀ tàbí ọmọbìnrin ìyá rẹ̀ tí ó sì bá a lòpọ̀, ohun ìtìjú ni èyí, ẹ ó gé wọn kúrò lójú àwọn ènìyàn wọn, ó ti tàbùkù arábìnrin rẹ̀. Ẹ̀bi rẹ̀ yóò wá sórí rẹ̀.
If a man sleeps with his sister, a daughter of his father or a daughter of his mother, and he uncovers her nakedness, and she sees his nakedness, it is a shameful thing. They must be cut off from the presence of their people, because he has slept with his sister. He must carry his guilt.
18 “‘Bí ọkùnrin kan bá súnmọ́ obìnrin, ní àkókò nǹkan oṣù rẹ̀ tí ó sì bá a lòpọ̀. Ó ti tú orísun ẹ̀jẹ̀ rẹ̀. Òun náà sì gbà á láààyè. Àwọn méjèèjì ni a ó gé kúrò láàrín àwọn ènìyàn wọn.
If a man sleeps with a woman during her menstrual period and has slept with her, he has uncovered the flow of her blood, the source of her blood. Both the man and woman must be cut off from among their people.
19 “‘Má ṣe bá arábìnrin baba tàbí ti ìyá rẹ lòpọ̀, nítorí o ti tú ìhòhò ìbátan rẹ, ẹ̀yin méjèèjì ni yóò ru ẹ̀bi yín.
You must not sleep with your mother's sister, or with your father's sister, because you would disgrace your close relative. You must carry your own guilt.
20 “‘Bí ọkùnrin kan bá bá aya arákùnrin baba rẹ̀ lòpọ̀ ó ti tàbùkù arákùnrin baba rẹ̀. A ó jẹ wọ́n ní ìyà; wọn yóò sì kú láìlọ́mọ.
If a man sleeps with his aunt, he has dishonored his uncle. They will bear responsibility for their sin, and they will die without children.
21 “‘Bí ọkùnrin kan bá gba aya arákùnrin rẹ̀, ohun àìmọ́ ni èyí, ó ti tàbùkù arákùnrin rẹ̀, wọn ó wà láìlọ́mọ.
If a man marries his brother's wife while his brother is still living, that is disgraceful. He has dishonored his brother, and I will take away from their children any property they may have inherited from their parents.
22 “‘Kí ẹ pa gbogbo àṣẹ àti òfin mi mọ́, kí ẹ sì máa ṣe wọ́n. Kí ilẹ̀ náà tí èmi ó fi fún yín láti máa gbé má ba à pọ̀ yín jáde.
You must therefore keep all my statutes and all my decrees; you must obey them so that the land into which I am bringing you to live will not vomit you up.
23 Ẹ má ṣe tẹ̀lé àṣà àwọn orílẹ̀-èdè tí mo lé jáde níwájú yín torí pé gbogbo nǹkan wọ̀nyí ni wọ́n ń ṣe, tí mo kórìíra wọn.
You must not walk in the customs of the nations that I will drive out before you, for they have done all these things, and I detest them.
24 Ṣùgbọ́n mo ti sọ fún yín pé, “Ẹ̀yin ni yóò jogún ilẹ̀ wọn, Èmi yóò sì fi fún yín láti jogún ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin.” Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín tí ó ti yà yín sọ́tọ̀ kúrò láàrín àwọn ènìyàn yòókù.
I said to you, “You will inherit their land; I will give it to you to possess, a land flowing with milk and honey. I am Yahweh your God, who has separated you from the other peoples.
25 “‘Ẹ gbọdọ̀ pààlà sáàrín ẹran tí ó mọ́ àti àwọn tí kò mọ́. Láàrín ẹyẹ tí ó mọ́ àti àwọn tí kò mọ́. Ẹ má ṣe sọ ara yín di àìmọ́ nípasẹ̀ àwọn ẹranko tàbí ẹyẹ tàbí ohunkóhun tí ń rìn lórí ilẹ̀: èyí tí mo yà sọ́tọ̀ fún yín gẹ́gẹ́ bí ohun àìmọ́.
You must therefore distinguish between the clean animals and the unclean, and between the unclean birds and the clean. You must not defile yourselves with unclean animals or birds or with any creature that crawls along the ground, which I have separated as unclean from you.
26 Ẹ gbọdọ̀ jẹ́ mímọ́ fún mi torí pé, Èmi Olúwa fẹ́ mímọ́. Mó sì ti yà yín kúrò nínú àwọn orílẹ̀-èdè yòókù kí ẹ le jẹ́ tèmi.
You must be holy, for I, Yahweh, am holy, and I have separated you from the other peoples, for you belong to me.
27 “‘Ọkùnrin tàbí obìnrin tí ó jẹ́ abókùúsọ̀rọ̀ tàbí oṣó láàrín yín ni kí ẹ pa. Ẹ sọ wọ́n ní òkúta, ẹ̀jẹ̀ wọn yóò wà lórí wọn.’”
A man or a woman who talks with the dead or who talks with spirits must certainly be put to death. The people must stone them with stones. They are guilty and deserve to die.'”

< Leviticus 20 >