< Lamentations 3 >

1 Èmi ni ọkùnrin tí ó rí ìpọ́njú pẹ̀lú ọ̀pá ìbínú rẹ.
אני הגבר ראה עני בשבט עברתו
2 Ó ti lé mi jáde ó sì mú mi rìn nínú òkùnkùn ju ti ìmọ́lẹ̀.
אותי נהג וילך חשך ולא אור
3 Nítòótọ́, ó ti yí ọwọ́ rẹ̀ padà sí mi síwájú àti síwájú sí i ní gbogbo ọjọ́.
אך בי ישב יהפך ידו כל היום
4 Ó jẹ́ kí àwọ̀ mi àti ẹran-ara mi gbó ó sì tún ṣẹ́ egungun mi.
בלה בשרי ועורי שבר עצמותי
5 Ó ti fi mí sí ìgbèkùn, ó sì ti yí mi ká pẹ̀lú ìkorò àti làálàá.
בנה עלי ויקף ראש ותלאה
6 Ó mú mi gbé nínú òkùnkùn, bí ti àwọn tó ti kú fún ìgbà pípẹ́.
במחשכים הושיבני כמתי עולם
7 Ó ti tì mí mọ́ ilé, nítorí náà n kò le è sálọ; ó ti fi ẹ̀wọ̀n mú mi mọ́lẹ̀.
גדר בעדי ולא אצא הכביד נחשתי
8 Pàápàá nígbà tí mo ké fún ìrànlọ́wọ́, ó kọ àdúrà mi.
גם כי אזעק ואשוע שתם תפלתי
9 Ó fi ògiri òkúta dí ọ̀nà mi; ó sì mú ọ̀nà mi wọ́.
גדר דרכי בגזית נתיבתי עוה
10 Bí i beari tí ó dùbúlẹ̀, bí i kìnnìún tí ó sá pamọ́.
דב ארב הוא לי אריה (ארי) במסתרים
11 Ó wọ́ mi kúrò ní ọ̀nà, ó tẹ̀ mí mọ́lẹ̀ ó fi mi sílẹ̀ láìsí ìrànlọ́wọ́.
דרכי סורר ויפשחני שמני שמם
12 Ó fa ọfà rẹ̀ yọ ó sì fi mí ṣe ohun ìtafàsí.
דרך קשתו ויציבני כמטרא לחץ
13 Ó fa ọkàn mí ya pẹ̀lú ọfà nínú àkọ̀ rẹ̀.
הביא בכליתי בני אשפתו
14 Mo di ẹni yẹ̀yẹ́ láàrín àwọn ènìyàn mi; wọn yẹ̀yẹ́ mi pẹ̀lú orin ní gbogbo ọjọ́.
הייתי שחק לכל עמי נגינתם כל היום
15 Ó ti kún mi pẹ̀lú ewé kíkorò àti ìdààmú bí omi.
השביעני במרורים הרוני לענה
16 Ó ti fi òkúta kán eyín mi; ó ti tẹ̀ mí mọ́lẹ̀ nínú eruku.
ויגרס בחצץ שני הכפישני באפר
17 Mo ti jìnnà sí àlàáfíà; mo ti gbàgbé ohun tí àṣeyege ń ṣe.
ותזנח משלום נפשי נשיתי טובה
18 Nítorí náà mo wí pé, “Ògo mi ti lọ àti ìrètí mi nínú Olúwa.”
ואמר אבד נצחי ותוחלתי מיהוה
19 Mo ṣe ìrántí ìpọ́njú àti ìdààmú mi, ìkorò àti ìbànújẹ́.
זכר עניי ומרודי לענה וראש
20 Mo ṣèrántí wọn, ọkàn mi sì gbọgbẹ́ nínú mi.
זכור תזכור ותשיח (ותשוח) עלי נפשי
21 Síbẹ̀, èyí ni mo ní ní ọkàn àti nítorí náà ní mo nírètí.
זאת אשיב אל לבי על כן אוחיל
22 Nítorí ìfẹ́ Olúwa tí ó lágbára ni àwa kò fi ṣègbé, nítorí ti àánú rẹ kì í kùnà.
חסדי יהוה כי לא תמנו כי לא כלו רחמיו
23 Wọ́n jẹ́ ọ̀tún ní àárọ̀; títóbi ni òdodo rẹ̀.
חדשים לבקרים רבה אמונתך
24 Mo wí fún ara mi, ìpín mi ni Olúwa; nítorí náà èmi yóò dúró dè ọ́.
חלקי יהוה אמרה נפשי על כן אוחיל לו
25 Dídára ni Olúwa fún àwọn tí ó ní ìrètí nínú rẹ̀, sí àwọn tí ó ń wá a.
טוב יהוה לקוו לנפש תדרשנו
26 Ó dára kí a ní sùúrù fún ìgbàlà Olúwa.
טוב ויחיל ודומם לתשועת יהוה
27 Ó dára fún ènìyàn láti gbé àjàgà nígbà tí ó wà ní èwe.
טוב לגבר כי ישא על בנעוריו
28 Jẹ́ kí ó jókòó ní ìdákẹ́ jẹ́ẹ́, nítorí Olúwa ti fi fún un.
ישב בדד וידם כי נטל עליו
29 Jẹ́ kí ó bo ojú rẹ̀ sínú eruku— ìrètí sì lè wà.
יתן בעפר פיהו אולי יש תקוה
30 Jẹ́ kí ó fi ẹ̀rẹ̀kẹ́ fún àwọn tí yóò gbá a, sì jẹ́ kí ó wà ní ìdójútì.
יתן למכהו לחי ישבע בחרפה
31 Ènìyàn kò di ìtanù lọ́dọ̀ Olúwa títí láé.
כי לא יזנח לעולם אדני
32 Lóòtítọ́ ó mú ìbànújẹ́ wá, yóò fi àánú hàn, nítorí títóbi ni ìfẹ́ rẹ̀.
כי אם הוגה ורחם כרב חסדיו
33 Nítorí kò mọ̀ ọ́n mọ̀ mú ìpọ́njú wá tàbí ìrora wá fún ọmọ ènìyàn.
כי לא ענה מלבו ויגה בני איש
34 Láti tẹ mọ́lẹ̀ lábẹ́ ẹsẹ̀ gbogbo àwọn ẹlẹ́wọ̀n ní ilẹ̀ náà.
לדכא תחת רגליו כל אסירי ארץ
35 Láti ṣẹ́ ọmọ ènìyàn fún ẹ̀tọ́ rẹ̀ níwájú Ọ̀gá-ògo jùlọ,
להטות משפט גבר נגד פני עליון
36 láti yí ìdájọ́ ènìyàn padà, ǹjẹ́ Olúwa kò rí ohun bẹ́ẹ̀.
לעות אדם בריבו אדני לא ראה
37 Ta ni yóò sọ̀rọ̀ tí yóò rí bẹ́ẹ̀ tí Olúwa kò bá fi àṣẹ sí i.
מי זה אמר ותהי אדני לא צוה
38 Ǹjẹ́ kì í ṣe láti ẹnu Ọ̀gá-ògo jùlọ ni rere àti búburú tí ń wá?
מפי עליון לא תצא הרעות והטוב
39 Kí ló dé tí ẹ̀dá alààyè ṣe ń kùn nígbà tí ó bá ń jìyà ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀?
מה יתאונן אדם חי גבר על חטאו
40 Ẹ jẹ́ kí a yẹ ọ̀nà wa, kí a sì dán an wò, kí a sì tọ Olúwa lọ.
נחפשה דרכינו ונחקרה ונשובה עד יהוה
41 Ẹ jẹ́ kí a gbé ọkàn àti ọwọ́ wa sókè sí Ọlọ́run ní ọ̀run, kí a wí pé,
נשא לבבנו אל כפים אל אל בשמים
42 “Àwa ti ṣẹ̀ a sì ti ṣọ̀tẹ̀ ìwọ kò sì fi ẹ̀ṣẹ̀ wa jì wá.
נחנו פשענו ומרינו אתה לא סלחת
43 “Ìwọ fi ìbínú bo ara rẹ ìwọ sì ń lépa wa; ìwọ ń parun láìsí àánú.
סכותה באף ותרדפנו הרגת לא חמלת
44 Ìwọ ti fi àwọsánmọ̀ bo ara rẹ pé kí àdúrà wa má ba à dé ọ̀dọ̀ rẹ.
סכותה בענן לך מעבור תפלה
45 Ó ti sọ wá di èérí àti ààtàn láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo.
סחי ומאוס תשימנו בקרב העמים
46 “Gbogbo àwọn ọ̀tá wa ti la ẹnu wọn gbòòrò sí wa.
פצו עלינו פיהם כל איבינו
47 Àwa ti jìyà àti ìparun, nínú ìbẹ̀rù àti ewu.”
פחד ופחת היה לנו השאת והשבר
48 Omijé ń sàn ní ojú mi bí odò nítorí a pa àwọn ènìyàn mi run.
פלגי מים תרד עיני על שבר בת עמי
49 Ojú mi kò dá fún omijé, láì sinmi,
עיני נגרה ולא תדמה מאין הפגות
50 títí ìgbà tí Olúwa yóò síjú wolẹ̀ láti òkè ọ̀run tí yóò sì rí i.
עד ישקיף וירא יהוה משמים
51 Ohun tí mo rí mú ìbẹ̀rù wá ọkàn mi nítorí gbogbo àwọn obìnrin ìlú mi.
עיני עוללה לנפשי מכל בנות עירי
52 Àwọn tí ó jẹ́ ọ̀tá mi láìnídìí dẹ mí bí ẹyẹ.
צוד צדוני כצפור איבי חנם
53 Wọ́n gbìyànjú láti mú òpin dé bá ayé mi nínú ihò wọ́n sì ju òkúta lù mí.
צמתו בבור חיי וידו אבן בי
54 Orí mi kún fún omi, mo sì rò pé ìgbẹ̀yìn dé.
צפו מים על ראשי אמרתי נגזרתי
55 Mo pe orúkọ rẹ, Olúwa, láti ọ̀gbun ìsàlẹ̀ ihò.
קראתי שמך יהוה מבור תחתיות
56 Ìwọ gbọ́ ẹ̀bẹ̀ mi, “Má ṣe di etí rẹ sí igbe ẹ̀bẹ̀ mi fún ìtura.”
קולי שמעת אל תעלם אזנך לרוחתי לשועתי
57 O wá tòsí nígbà tí mo ké pè ọ́, o sì wí pé, “Má ṣe bẹ̀rù.”
קרבת ביום אקראך אמרת אל תירא
58 Olúwa, ìwọ gba ẹjọ́ mi rò, o ra ẹ̀mí mi padà.
רבת אדני ריבי נפשי גאלת חיי
59 O ti rí i, Olúwa, búburú tí a ṣe sí mi. Gba ẹjọ́ mi ró!
ראיתה יהוה עותתי שפטה משפטי
60 Ìwọ ti rí ọ̀gbun ẹ̀san wọn, gbogbo ìmọ̀ wọn sí mi.
ראיתה כל נקמתם--כל מחשבתם לי
61 Olúwa ìwọ ti gbọ́ ẹ̀gàn wọn àti ìmọ̀ búburú wọn sí mi,
שמעת חרפתם יהוה כל מחשבתם עלי
62 ohun tí àwọn ọ̀tá mi ń sọ sí mi ní gbogbo ọjọ́.
שפתי קמי והגיונם עלי כל היום
63 Wò wọ́n! Ní jíjòkòó tàbí ní dídìde, wọ́n ń ṣẹlẹ́yà mi nínú orin wọn.
שבתם וקימתם הביטה אני מנגינתם
64 Olúwa san wọ́n lẹ́san ohun tí ó tọ́ sí wọn fún ohun tí ọwọ́ wọn ti ṣe.
תשיב להם גמול יהוה כמעשה ידיהם
65 Fi ìbòjú bò wọ́n ní ọkàn, kí o sì fi wọ́n ré.
תתן להם מגנת לב תאלתך להם
66 Ni wọ́n lára kí o sì pa wọ́n run pẹ̀lú ìbínú, lábẹ́ ọ̀run Olúwa.
תרדף באף ותשמידם מתחת שמי יהוה

< Lamentations 3 >