< Judges 9 >

1 Ní ọjọ́ kan Abimeleki ọmọ Jerubbaali lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn arákùnrin ìyá rẹ̀ ní Ṣekemu ó sì bá wọn sọ̀rọ̀ àti gbogbo àwọn ìbátan ìyá rẹ̀ wí pé,
Gideon’s son Abimelech went to [talk with] his mother’s brothers in Shechem [city]. He said to them and to all his mother’s relatives,
2 “Ẹ bi gbogbo àwọn ará Ṣekemu léèrè, ‘Èwo ló sàn fún un yín, ṣé kí gbogbo àwọn àádọ́rin ọmọ Jerubbaali jẹ ọba lórí yín ni tàbí kí ẹnìkan ṣoṣo ṣe àkóso yín?’ Ṣùgbọ́n ẹ rántí pé ẹran-ara yín àti ẹ̀jẹ̀ yín ni èmi ń ṣe.”
“Ask all the leaders of your city: ‘Do you [think it would be] good for all 70 of Gideon’s sons to rule over you? Or would it be better to have only one of his sons, [me], to rule over you?’ And do not forget that I am your relative! [MTY]”
3 Nígbà tí àwọn arákùnrin rẹ̀ sọ èyí ní etí àwọn ará Ṣekemu, ọkàn wọn fà sí àti tẹ̀lé Abimeleki torí, wọ́n sọ wí pé, “Arákùnrin wa ní í ṣe.”
So Abimelech’s mother’s brothers spoke to all the leaders of Shechem about what Abimelech had said. They said to each other, “We should allow Abimelech to rule over us, because he is our relative.”
4 Wọ́n fún un ní àádọ́rin ṣékélì fàdákà láti ilé òrìṣà Baali-Beriti, Abimeleki fi owó náà gba àwọn jàǹdùkú àti aláìníláárí ènìyàn tí wọ́n sì di olùtẹ̀lé rẹ̀.
So the leaders of Shechem took from the temple of [their god] Baal-Berith (almost 2 pounds/0.8 kg.) of silver and gave it to Abimelech. With that silver he paid some worthless troublemakers to help him, and they went with Abimelech wherever he went.
5 Ó kó wọn lọ sí ilé baba rẹ̀ ní Ofira, níbẹ̀ ní orí òkúta kan ṣoṣo ni ó ti pa àádọ́rin nínú àwọn arákùnrin rẹ̀, àwọn Jerubbaali, ṣùgbọ́n Jotamu, àbíkẹ́yìn nínú àwọn ọmọ Jerubbaali, bọ́ yọ nítorí pé ó sá pamọ́.
They went to Ophrah, his father’s town, and murdered 69 of his 70 brothers, the sons of his father Gideon. They killed all those men on one huge rock. But Gideon’s youngest son Jotham hid [from Abimelech and his men], and he escaped.
6 Gbogbo àwọn ará Ṣekemu àti àwọn ará Beti-Milo pàdé pọ̀ ní ẹ̀bá igi óákù ní ibi òpó ní Ṣekemu láti fi Abimeleki jẹ ọba.
Then all the leaders of Shechem and Beth-Millo gathered under the big sacred tree in Shechem. There they appointed Abimelech to be their leader.
7 Nígbà tí wọ́n sọ ohun tí ó ń ṣẹlẹ̀ yìí fún Jotamu, ó gun orí ṣóńṣó òkè Gerisimu lọ, ó sì ké lóhùn rara pé, “Ẹ tẹ́tí sí mi, ẹ̀yin àgbàgbà Ṣekemu, kí Ọlọ́run le tẹ́tí sí yín.
When Jotham heard about that, he climbed up Gerizim Mountain. He stood at the top of the mountain and shouted to the people [down below], “You leaders of Shechem, listen to me, in order that God will listen to you!
8 Ní ọjọ́ kan àwọn igi jáde lọ láti fi òróró yan ọba fún ara wọn. Wọ́n pe igi Olifi pé, ‘Wá ṣe ọba wa.’
One day the trees decided to appoint a king to rule over all of them. So they said to the olive tree, ‘You be our king!’
9 “Ṣùgbọ́n igi Olifi dá wọn lóhùn pé, ‘Èmi yóò ha fi òróró mi sílẹ̀ èyí tí a ń lò láti fi ọ̀wọ̀ fún àwọn ọlọ́run àti ènìyàn kí èmi sì wá ṣe olórí àwọn igi?’
“But the olive tree said, ‘No! [I will not be your king] Men and gods enjoy the oil from my fruit. I will not [RHQ] stop producing [olives from which we make] that oil, in order to rule over you other trees!’
10 “Àwọn igi sọ fún igi ọ̀pọ̀tọ́ pé, ‘Wá jẹ ọba ní orí wa.’
“Then the trees said to the fig tree, ‘You come and be our king!’
11 “Ṣùgbọ́n ọ̀pọ̀tọ́ dá wọn lóhùn pé, ‘Kí èmi fi èso mi tí ó dára tí ó sì dùn sílẹ̀ láti wá ṣe olórí àwọn igi?’
“But the fig tree replied, ‘No! I do not want to [RHQ] stop producing my good sweet fruit, and rule over you other trees!’
12 “Àwọn igi sì tún sọ fún àjàrà pé, ‘Wá, kí o ṣe ọba wa.’
“Then the trees said to the grapevine, ‘Come and be our king!’
13 “Ṣùgbọ́n àjàrà dáhùn pé, ‘Ṣé kí èmi dẹ́kun àti máa so èso wáìnì mi èyí tí ó ń mú inú Ọlọ́run àti àwọn ènìyàn dùn láti máa ṣe olórí àwọn igi?’
“But the grapevine replied, ‘No! [I will not be your king] The new wine [that is made from my grapes] causes people and gods [who drink it] to become very happy. I do not want to stop producing grapes and rule over you other trees!’ [RHQ]
14 “Ní ìparí gbogbo àwọn igi lọ bá igi ẹ̀gún wọ́n sì sọ fún un pé, ‘Wá kí ó ṣe ọba wa.’
“Then all the trees said to the thornbush, ‘Come and be our king!’
15 “Igi ẹ̀gún dá àwọn igi lóhùn pé, ‘Bí olóòtítọ́ ni ẹ bá fẹ́ yàn mí ní ọba yín. Ẹ sá àsálà sí abẹ́ ibòòji mi; ṣùgbọ́n tí kì í bá ṣe bẹ́ẹ̀ jẹ́ kí iná jáde láti inú igi ẹ̀gún kí ó sì jó àwọn igi kedari àti ti Lebanoni run!’
“The thornbush replied, ‘If you truly want to appoint me to be your king, come into the shade of my [tiny branches]. But if you do not want to do that, I hope/desire that fire will come out from me and burn up all the huge cedar trees in Lebanon [country]!’”
16 “Báyìí tí ó bá jẹ́ pé ẹ̀yin ṣe ohun tí ó ní ọlá àti pẹ̀lú ẹ̀mí òtítọ́ ní fífi Abimeleki jẹ ọba, tí ó bá ṣe pé ohun tí ó tọ́ ni ẹ ṣe sí Jerubbaali àti ìdílé rẹ̀, bí ẹ bá san ẹ̀san tó yẹ fún un.
“[After] Jotham [finished telling them this parable, he] said, “So now [I ask you], were you being completely honest and sincere when you appointed Abimelech to be your king [RHQ]? And have you treated Gideon and his family [RHQ] fairly? Have you rewarded Gideon by honoring him as he deserved [because of all the good things he did for you]? No!
17 Nítorí pé baba mi jà nítorí yín, ó fi ẹ̀mí rẹ̀ wéwu láti gbà yín sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn ará Midiani;
“[Do not forget that] my father fought a battle for you, and he was willing to die for you [if that had been necessary], to save you from the Midian people-group.
18 ṣùgbọ́n lónìí ẹ̀yin ṣọ̀tẹ̀ sí ilé baba mi, ní orí òkúta kan ṣoṣo ni ẹ ti pa àwọn àádọ́rin ọmọ rẹ̀, ẹ̀yin sì ti fi Abimeleki ọmọ ẹrúbìnrin rẹ̀ jẹ ọba lórí àwọn ènìyàn Ṣekemu nítorí tí ó jẹ́ arákùnrin yín.
But now you have rebelled against my father’s family, and you have killed 69 of his sons on one huge rock. And you have appointed Abimelech—who is the son of my father’s slave girl, [not the son of his wife]—to be the king who will rule you people of Shechem. You have done that only because he is one of your relatives!
19 Bí ohun tí ẹ ṣe sí Jerubbaali àti ìdílé rẹ̀ bá jẹ́ ohun tí ó yẹ, tí ẹ sì ṣe òtítọ́ inú sí i, kí ẹ ní ayọ̀ nínú Abimeleki kí òun náà sì ní ayọ̀ nínú yín.
So, if today you have truly acted fairly and sincerely toward Gideon and his family, I hope/desire that he will cause you to be happy and that you will cause him to be happy.
20 Ṣùgbọ́n tí kò bá ṣe bẹ́ẹ̀ jẹ́ kí iná jó jáde wá láti ọ̀dọ̀ Abimeleki kí ó sì jó yín run. Ẹ̀yin ará Ṣekemu àti ará Beti-Milo, kí iná pẹ̀lú jáde láti ọ̀dọ̀ yín wá ẹ̀yin ará Ṣekemu àti ará Beti-Milo kí ó sì jó Abimeleki run.”
But if what you did was not right, I wish/desire that Abimelech will burn up all of you leaders of Shechem and Beth-Millo with fire! And I also hope/desire that the leaders of Shechem and Beth-Millo will cause fire to burn up Abimelech!”
21 Lẹ́yìn tí Jotamu ti sọ èyí tan, ó sá àsálà lọ sí Beeri, ó sì gbé níbẹ̀ nítorí ó bẹ̀rù arákùnrin rẹ̀ Abimeleki.
[After] Jotham [finished saying that, he] escaped from them and ran away to Beer [town]. He stayed there because he was afraid that his brother Abimelech [would try to kill him].
22 Lẹ́yìn tí Abimeleki ti ṣe àkóso Israẹli fún ọdún mẹ́ta,
Abimelech [became the leader of all the people of Israel. He] ruled them for three years.
23 Ọlọ́run rán ẹ̀mí búburú sáàárín Abimeleki àti àwọn ará Ṣekemu, àwọn ẹni tí ó hu ìwà ọ̀tẹ̀.
Then God sent an evil spirit [to cause trouble] between Abimelech and the leaders of Shechem, with the result that the leaders of Shechem rebelled against Abimelech.
24 Ọlọ́run ṣe èyí láti gbẹ̀san àwọn ìwà búburú, àti ìtàjẹ̀ sílẹ̀ àwọn àádọ́rin ọmọ Jerubbaali lára Abimeleki arákùnrin wọn àti lára àwọn ènìyàn Ṣekemu, ẹni tí ó ràn án lọ́wọ́ láti pa àwọn arákùnrin rẹ̀.
The leaders of Shechem had previously helped Abimelech to kill 69 of Gideon’s sons, who were his brothers. So now God sent the evil spirit to punish all of them.
25 Nítorí ìkórìíra tí wọ́n ni sí àwọn olórí, ni Ṣekemu dẹ àwọn ènìyàn sí àwọn orí òkè láti máa dá àwọn ènìyàn tó ń kọjá lọ́nà, kí wọn sì máa jà wọ́n lólè, àwọn kan ló sọ èyí fún Abimeleki.
The leaders of Shechem (set an ambush/sent men to hide) on the hilltops to ambush Abimelech. Those men robbed everyone who passed by. But someone told Abimelech about it, [so he did not go near them].
26 Gaali ọmọ Ebedi àti àwọn arákùnrin rẹ̀ wá sí Ṣekemu, àwọn ará Ṣekemu sì gbẹ́kẹ̀lé wọn, wọ́n sì fi inú tán wọn.
There was a man named Gaal, the son of Ebed, who moved into Shechem [city], along with his brothers. Soon the leaders of Shechem started to trust him.
27 Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n jáde lọ sí oko, wọ́n sì ṣa èso àjàrà wọn jọ, wọ́n fún èso àjàrà náà, wọ́n sì ṣe àjọ̀dún nínú ilé òrìṣà wọn. Nígbà tí wọ́n ń jẹ tí wọ́n ń mu wọ́n fi Abimeleki ré.
They went out [of the city] to their vineyards and picked some grapes. They pressed the grapes [to make juice, and then they made wine]. Then they had a feast in the temple of their god, and they ate [a lot of food] and drank [a lot of wine]. Then they cursed Abimelech.
28 Gaali ọmọ Ebedi dáhùn pé, “Ta ni Abimeleki tàbí ta ni Ṣekemu tí àwa ó fi sìn ín? Ọmọ Jerubbaali kọ́ ní ṣe tàbí Sebulu kọ́ ní igbákejì rẹ̀? Ẹ má sin àwọn ará Hamori baba àwọn ará Ṣekemu, èéṣe tí a ó fi sin Abimeleki?
Gaal said, “(Why should [we allow] Abimelech to rule over us?/We should not allow Abimelech to rule over us!) [RHQ] He is only one of Gideon’s sons [so he really does not belong to us] [RHQ]! And he appointed Zebul, the governor of our city, to be his deputy! We should (serve/be loyal to) [one of the descendants of] Hamor, [the founder of our city], and let him be our leader, not Abimelech [RHQ]!
29 Ìbá se pé àwọn ènìyàn yìí wà ní abẹ́ ìṣàkóso mi ni! Èmi ìbá bọ́ àjàgà rẹ̀ kúrò ní ọrùn yín. Èmi yóò wí fún Abimeleki pé, ‘Kó gbogbo àwọn ogun rẹ jáde láti jà.’”
If you would appoint me to be your leader, I would get rid of Abimelech. I would say to him, ‘Get your army ready, [and then come to fight us]!’”
30 Nígbà tí Sebulu, alákòóso ìlú náà gbọ́ ohun tí Gaali ọmọ Ebedi sọ, inú bí i gidigidi.
When someone told Zebul what Gaal said, he was very angry.
31 Ó ránṣẹ́ sí Abimeleki pé, “Gaali ọmọ Ebedi àti àwọn arákùnrin rẹ̀ wá láti máa gbé ní Ṣekemu ṣùgbọ́n, wọ́n ń rú àwọn ènìyàn sókè láti ṣọ̀tẹ̀ sí ọ.
He secretly sent some messengers to Abimelech. They told him, “Gaal and his brothers have come here to Shechem, and they are causing [the people of] the city to rebel against you.
32 Wá ní òru kí ìwọ àti àwọn ogun rẹ sá pamọ́ dè wọ́n nínú igbó.
You and your men should get up during the night and go and hide in the fields outside the city.
33 Ní òwúrọ̀ kùtùkùtù bí oòrùn ti ń yọ ìwọ yóò wọ inú ìlú náà lọ láti bá a jà. Yóò sì ṣe nígbà tí Gaali àti àwọn ogun rẹ̀ tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ bá jáde sí ọ láti bá ọ jà, ìwọ yóò ṣe ohunkóhun tí o bá fẹ́ sí wọn.”
As soon as the sun rises in the morning, get up and attack the city. When Gaal and his men come out to fight against you, you can do to them whatever you want to.”
34 Abimeleki àti gbogbo àwọn ogun rẹ̀ sì jáde ní òru, wọ́n sì sá pamọ́ sí ọ̀nà mẹ́rin yí Ṣekemu ká.
So Abimelech and all the men who were with him got up during the night. They [divided into] four groups, [and] hid [in the fields] near Shechem.
35 Gaali ọmọ Ebedi jáde síta, ó sì dúró ní ẹnu-ọ̀nà ibodè ìlú náà ní àkókò tí Abimeleki àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ jáde kúrò níbi tí wọn sá pamọ́ sí.
[The next morning], Gaal went out and stood at the entrance to the city gate. While he was standing there, Abimelech and his soldiers came out of their hiding places [and started walking toward the city].
36 Nígbà tí Gaali rí àwọn ènìyàn náà, ó sọ fún Sebulu pé, “Wò ó, àwọn ènìyàn ń ti orí òkè sọ̀kalẹ̀ wá!” Sebulu sì wí fún un pé, “Òjìji òkè wọ̀n-ọn-nì ni ìwọ rí bi ẹni pé ènìyàn.”
When Gaal saw the soldiers, he said to Zebul, “Look! There are people coming down from the hills!” But Zebul said, “You are seeing only the shadows [of trees] on the hills. They [are not people; they] only resemble people.”
37 Gaali ké ó ní, “Wòkè, àwọn ènìyàn ń tọ̀ wá bọ̀ láti agbede-méjì ilẹ̀ wá àti ẹ̀gbẹ́ kan sì ń ti ọ̀nà igi óákù Meonenimu wá.”
But Gaal [looked] again [and] said, “Look! There are people coming down from the top of the sacred mountain! There is a group of them coming down from where the tree is where people talk with the spirits of dead people!”
38 Nígbà náà ni Sebulu dá a lóhùn pé, “Níbo ni ẹnu tí ó ń ṣe ni wà báyìí. Ṣe bí o wí pé, ‘Ta ni Abimeleki tí àwa ó fi máa sìn ín?’ Àwọn ẹni tí ó gàn án kọ́ nìyí? Jáde lọ kí o sì bá wọn jà!”
Zebul said to Gaal, “Now (what good is your bragging?/your bragging is worthless!) [MTY, RHQ] You said, ‘(Why should we serve Abimelech/We should not allow Abimelech to rule over us)?’ You made fun of these men. So now go out and fight them!”
39 Gaali sì síwájú àwọn ogun ará Ṣekemu lọ kọjú Abimeleki láti bá wọn jagun.
So Gaal led the men of Shechem outside [the city] to fight Abimelech [and his men].
40 Abimeleki sì lé e, ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ọmọ-ogun ṣubú wọ́n sì gbọgbẹ́ bí wọ́n ṣe ń sálọ, títí dé ẹnu-ọ̀nà ibùdó ìlú náà.
Abimelech and his men pursued them, and they killed many of Gaal’s men before they could return [safely] inside the city gate.
41 Abimeleki dúró sí Aruma, nígbà tí Sebulu lé Gaali àti àwọn arákùnrin rẹ̀ kúrò ni Ṣekemu, kò sì jẹ́ kí wọ́n gbé Ṣekemu mọ́.
Abimelech then stayed at Arumah, [about five miles away from Shechem], and Zebul’s men forced Gaal and his brothers to leave Shechem.
42 Ní ọjọ́ kejì àwọn ará Ṣekemu sì jà lọ́ sí oko, ẹnìkan ló ṣe òfófó rẹ̀ fún Abimeleki.
The next day, the people of Shechem [got ready to leave the city and work] in their fields. When someone told Abimelech about that,
43 Ó kó àwọn ènìyàn rẹ̀, ó pín wọn sí ẹgbẹ́ mẹ́ta ó sì sá pamọ́ sí inú oko. Nígbà tí ó sì rí tí àwọn ènìyàn náà ń jáde kúrò nínú ìlú, ó dìde ó gbóguntì wọ́n.
he divided his men into three groups, and told them to hide in the fields. So they did that. And when they saw the people coming out of the city, they jumped up and attacked them.
44 Abimeleki àti àwọn ọmọ-ogun tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ sáré síwájú, wọ́n gba ẹnu ibodè ìlú náà, wọ́n sì dúró níbẹ̀. Àwọn ẹgbẹ́ méjì tókù sì sáré sí àwọn tó wà ní oko wọ́n sì gbóguntì wọ́n.
Abimelech and the men who were with him ran to the city gate. The other two groups ran out to the people in the fields and attacked them.
45 Ní gbogbo ọjọ́ náà ni Abimeleki fi bá àwọn ará ìlú náà jà, ó sì ṣẹ́gun wọn, ó sì pa àwọn ènìyàn ìlú náà ó wó ìlú náà palẹ̀ pátápátá ó sì fọ́n iyọ̀ sí i.
Abimelech and his men fought all day. They captured the city and killed all the people. They tore down all the buildings, and then they threw salt over the ruins [in order that nothing would grow there again].
46 Àwọn ènìyàn ilé ìṣọ́ Ṣekemu gbọ́ ohun tí ó ṣẹlẹ̀, wọ́n sálọ fún ààbò sí inú ilé ìṣọ́ òrìṣà El-Beriti.
When the leaders who lived in the tower/fortress outside of Shechem heard what had happened, they ran and hid inside the [fortress, which was also a] temple of [their god] El-Berith.
47 Nígbà tí wọ́n sọ fún Abimeleki pé gbogbo àwọn ènìyàn ilé ìṣọ́ Ṣekemu kó ara wọn jọ pọ̀.
But someone told Abimelech that all the leaders had gathered there.
48 Abimeleki àti gbogbo àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ gun òkè Salmoni lọ. Ó gé àwọn ẹ̀ka díẹ̀ pẹ̀lú àáké, ó gbé àwọn ẹ̀ka wọ̀nyí sí èjìká rẹ̀. Ó sọ fún àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ pé, “Ẹ ṣe ohun tí ẹ rí tí mo ń ṣe yìí ní kíákíá.”
So he and all the men who were with him went up Zalmon Mountain [which is near Shechem]. Abimelech cut some branches of trees with an axe, and put them on his shoulders. Then he said to all the men who were with him, “Quickly, do what I have just done!”
49 Báyìí gbogbo àwọn ọkùnrin tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀ gé àwọn ẹ̀ka igi wọn tẹ̀lé Abimeleki. Wọ́n kó wọn ti ilé ìṣọ́ agbára níbi tí àwọn ènìyàn sá pamọ́ sí wọ́n sì fi iná sí i, tóbẹ́ẹ̀ tí gbogbo àwọn ọkùnrin ilé ìṣọ́ Ṣekemu fi kú pẹ̀lú. Gbogbo àwọn ènìyàn náà tí ó tó ẹgbẹ̀rún ènìyàn lọ́kùnrin àti lóbìnrin sì kú.
So his men all cut branches [then carried them down the mountain], following Abimelech. They went to the fortress and piled the branches against its walls. Then they kindled a fire, and the fire burned down the fortress and killed all the people who were inside. So all the people who were inside the fortress—about 1,000 men and women—died.
50 Abimeleki tún lọ sí Tebesi, ó yí ìlú náà ká pẹ̀lú àwọn ọmọ-ogun, ó sì ṣẹ́gun rẹ̀.
Then Abimelech and his men went to Thebes [city]. They surrounded it and captured it.
51 Ilé ìṣọ́ kan tí ó ní agbára sì wà nínú ìlú náà. Gbogbo àwọn ènìyàn ìlú náà ọkùnrin àti obìnrin sá sínú ilé ìṣọ́ náà. Wọ́n ti ara wọn mọ́ ibẹ̀ wọ́n sì sálọ sí inú àjà ilé ìṣọ́ náà.
But there was a strong tower inside the city. So all the men, women, and leaders of the city ran to the tower. When they were all inside, they locked the door. Then they climbed up to the roof of the tower.
52 Abimeleki lọ sí ìsàlẹ̀ ilé ìṣọ́ náà, ó sì ń bá a jà. Ṣùgbọ́n bí ó ti súnmọ́ ẹnu-ọ̀nà ilé ìṣọ́ náà láti dáná sun ún,
Abimelech and his men came to the tower and tried to get in the door, [but they could not]. Then Abimelech prepared to light a fire to burn down the door.
53 obìnrin kan sọ ọmọ ọlọ lu Abimeleki lórí, ó sì fọ́ ọ ní agbárí.
But when Abimelech came near the doorway, a woman [who was on the roof] dropped a big grinding stone on his head, and crushed his skull.
54 Ní ojú kan náà ni ó pe ẹni tí ó ru àpáta rẹ̀ pé, “Yára yọ idà rẹ kí o sì pa mí, kí wọn má ba à sọ pé, ‘Obìnrin ni ó pa á.’” Ọ̀dọ́mọkùnrin náà sì fi ọ̀kọ̀ gún un, ó sì kú.
Abimelech quickly called to the young man who carried Abimelech’s weapons, and said, “Pull out your sword and kill me with it! I do not want people to say ‘It was a woman who killed Abimelech.’” So the young man thrust his sword into Abimelech, and Abimelech died.
55 Nígbà tí àwọn ará Israẹli rí i pé Abimeleki kú, olúkúlùkù wọn padà sí ilé rẹ̀.
When the Israeli soldiers saw that Abimelech was dead, they all returned to their homes.
56 Báyìí ni Ọlọ́run san ẹ̀san ìwà búburú ti Abimeleki hù sí baba rẹ̀ ní ti pípa tí ó pa, àwọn àádọ́rin arákùnrin rẹ̀.
In that way God punished Abimelech for the evil things that he had done to his father and especially for killing all 69 of his brothers.
57 Ọlọ́run jẹ́ kí ìwà búburú àwọn ará Ṣekemu pẹ̀lú padà sí orí wọn. Ègún Jotamu ọmọ Jerubbaali pàápàá wá sí orí wọn.
God also punished the men of Shechem for the evil things that they had done. And when those things happened, it fulfilled what Gideon’s son Jotham said when he cursed [Abimelech and the leaders of Shechem].

< Judges 9 >