< Judges 8 >

1 Àwọn àgbàgbà ẹ̀yà Efraimu sì bínú gidigidi sí Gideoni wọ́n bi í léèrè pé, kí ló dé tí o fi ṣe irú èyí sí wa? Èéṣe tí ìwọ kò fi pè wá nígbà tí ìwọ kọ́kọ́ jáde lọ láti bá àwọn ará Midiani jagun? Ohùn ìbínú ni wọ́n fi bá a sọ̀rọ̀.
I mężczyźni z Efraima powiedzieli do niego: Dlaczego tak z nami postąpiłeś, że nie wezwałeś nas, gdy wyruszyłeś do walki z Midianitami? I mocno się z nim spierali.
2 Ṣùgbọ́n Gideoni dá wọn lóhùn pé, “Àṣeyọrí wo ni mo ti ṣe tí ó tó fiwé tiyín? Àṣàkù àjàrà Efraimu kò ha dára ju gbogbo ìkórè àjàrà Abieseri lọ bí?
A [on] powiedział: Cóż takiego uczyniłem w porównaniu z wami? Czyż nie lepszy jest ostatni zbiór winogron Efraima niż pierwszy zbiór Abiezera?
3 Ọlọ́run ti fi Orebu àti Seebu àwọn olórí àwọn ará Midiani lé yín lọ́wọ́. Kí ni ohun tí Mose ṣe tí ó tó fiwé e yín tàbí tí ó tó àṣeyọrí i yín?” Nígbà tí ó wí èyí ríru ìbínú wọn rọlẹ̀.
Bóg wydał w wasze ręce książąt Midianu – Oreba i Zeeba. Cóż mogłem takiego uczynić w porównaniu z wami? Gdy to powiedział, ich duch uspokoił się wobec niego.
4 Gideoni àti àwọn ọ̀ọ́dúnrún ọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ tẹ̀síwájú láti lépa àwọn ọ̀tá bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó ti rẹ̀ wọ́n, wọ́n dé Jordani wọ́n sì kọjá sí òdìkejì.
A gdy Gedeon przybył do Jordanu, przeprawił się przez niego wraz z trzystoma mężczyznami, którzy z nim byli, znużonymi i w pościgu.
5 Ó wí fún àwọn ọkùnrin Sukkoti pé, “Ẹ fún àwọn ọmọ-ogun mi ní oúnjẹ díẹ̀, nítorí ó ti rẹ̀ wọ́n, èmi sì ń lépa Seba àti Salmunna àwọn ọba Midiani.”
I powiedział do mieszkańców Sukkot: Dajcie, proszę, po bochenku chleba ludowi, który idzie za mną, bo jest znużony, a ja ścigam Zebacha i Salmunnę, królów Midianu.
6 Ṣùgbọ́n àwọn ìjòyè Sukkoti fèsì pé ṣé ọwọ́ rẹ ti tẹ Seba àti Salmunna náà ni? Èéṣe tí àwa yóò ṣe fún àwọn ológun rẹ ní oúnjẹ?
Lecz książęta Sukkot odpowiedzieli mu: Czy dłonie Zebacha i Salmunny są już w twoich rękach, żebyśmy mieli dać twemu wojsku chleba?
7 Gideoni dá wọn lóhùn pé, “Ó dára, nígbà tí Olúwa bá fi Seba àti Salmunna lé mi lọ́wọ́ tán èmi yóò fi ẹ̀gún ijù àti ẹ̀gún òṣùṣú ya ẹran-ara yín.”
Gedeon odpowiedział: Kiedy PAN wyda Zebacha i Salmunnę w moje ręce, wtedy wymłócę wasze ciała cierniem pustyni i ostami.
8 Láti ibẹ̀, ó lọ sí Penieli ó sì bẹ̀ wọ́n bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́, ṣùgbọ́n àwọn náà dá a lóhùn bí àwọn ará Sukkoti ti dá a lóhùn.
Potem wyruszył stamtąd do Penuel i mówił do nich podobnie, ale ludzie z Penuel odpowiedzieli mu [tak samo] jak odpowiedzieli mieszkańcy Sukkot.
9 Nígbà náà ni ó sọ fún àwọn ọkùnrin Penieli pé, “Nígbà tí mo bá ṣẹ́gun tí mo sì padà dé ní àlàáfíà, èmi yóò wó ilé ìṣọ́ yìí.”
Powiedział więc też mężczyznom z Penuel: Gdy wrócę w pokoju, zburzę tę wieżę.
10 Ní àsìkò náà Seba àti Salmunna wà ní Karkori pẹ̀lú ọmọ-ogun wọn tí ó tó ẹgbẹ̀rún mẹ́ẹ̀ẹ́dógún ọkùnrin, àwọn wọ̀nyí ni ó ṣẹ́kù nínú gbogbo ogun àwọn ènìyàn apá ìlà-oòrùn, nítorí ọ̀kẹ́ mẹ́fà ọkùnrin tí ó fi idà jà ti kú ní ojú ogun.
A Zebach i Salmunna byli w Karkor, a z nimi ich wojsko w liczbie około piętnastu tysięcy, wszyscy, którzy pozostali z całego wojska ludzi ze wschodu; a poległo sto dwadzieścia tysięcy mężczyzn dobywających miecz.
11 Gideoni gba ọ̀nà tí àwọn darandaran máa ń rìn ní apá ìhà ìlà-oòrùn Noba àti Jogbeha ó sì kọjú ogun sí àwọn ọmọ-ogun náà nítorí wọ́n ti túra sílẹ̀.
Wtedy Gedeon ciągnął drogą tych, którzy mieszkali w namiotach, na wschód od Nobach i Jogbeha, i uderzył na obóz, który czuł się bezpieczny.
12 Seba àti Salmunna, àwọn ọba Midiani méjèèjì sá, ṣùgbọ́n Gideoni lépa wọn ó sì mú wọn, ó run gbogbo ogun wọn.
A gdy Zebach i Salmunna uciekli, ścigał ich i pojmał obu królów Midianu, Zebecha i Salmunnę, całe zaś wojsko rozgromił.
13 Gideoni ọmọ Joaṣi gba ọ̀nà ìgòkè Heresi padà sẹ́yìn láti ojú ogun.
Potem Gedeon, syn Joasza, wrócił z bitwy, zanim wzeszło słońce;
14 Ó mú ọ̀dọ́mọkùnrin kan ará Sukkoti, ó sì béèrè àwọn ìbéèrè ní ọwọ́ rẹ̀, ọ̀dọ́mọkùnrin náà sì kọ orúkọ àwọn ìjòyè Sukkoti mẹ́tàdínlọ́gọ́rin fún un tí wọ́n jẹ́ àgbàgbà ìlú náà.
I schwytał młodzieńca spośród mieszkańców Sukkot, i wypytał go, a ten spisał mu książąt Sukkot i jego starszych, siedemdziesięciu siedmiu mężczyzn.
15 Nígbà náà ni Gideoni wá ó sọ fún àwọn ọkùnrin Sukkoti pé, “Seba àti Salmunna nìwọ̀nyí nípa àwọn tí ẹ̀yin fi mí ṣẹ̀fẹ̀ nígbà tí ẹ wí pé, ‘Ṣé ó ti ṣẹ́gun Seba àti Salmunna? Èéṣe tí àwa ó fi fún àwọn ọmọ-ogun rẹ tí ó ti rẹ̀ ní oúnjẹ?’”
Wtedy przyszedł do mężczyzn Sukkot i powiedział: Oto Zebach i Salmunna, z powodu których mi urągaliście, mówiąc: Czy dłonie Zebacha i Salmunny są już w twoich rękach, abyśmy mieli dać chleba twoim znużonym mężczyznom?
16 Ó mú àwọn àgbàgbà ìlú náà, ó sì fi kọ́ àwọn Sukkoti lọ́gbọ́n nípa jíjẹ wọ́n ní yà pẹ̀lú àwọn ẹ̀gún ijù àti ẹ̀gún ọ̀gàn.
Wziął więc starszych tego miasta oraz ciernie z pustyni i osty i wysmagał nimi mężczyzn Sukkot.
17 Ó wó ilé ìṣọ́ Penieli, ó sì pa àwọn ọkùnrin ìlú náà.
Zburzył także wieżę Penuel i zabił mężczyzn tego miasta.
18 Gideoni bi Seba àti Salmunna pé, “Irú ọkùnrin tí ẹ pa ní Tabori, báwo ni wọ́n ṣe rí?” “Àwọn ọkùnrin náà dàbí rẹ ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn dàbí ọmọ ọba,” ní ìdáhùn wọn.
Potem powiedział do Zebacha i Salmunny: Co to byli za mężczyźni, których zabiliście w Tabor? A oni odpowiedzieli: Byli tacy jak ty; każdy z nich z wyglądu jak syn króla.
19 Gideoni dáhùn pé, “Arákùnrin mi ni wọ́n, àwọn ọmọ ìyá mi. Mo fi Olúwa búra, bí ó bá ṣe pé ẹ dá ẹ̀mí wọn sí, èmi náà ò nípa yín.”
I powiedział: [To byli] moi bracia, synowie mojej matki. Jak żyje PAN, gdybyście zachowali ich przy życiu, nie zabiłbym was.
20 Ó yí padà sí Jeteri, ọmọ rẹ̀ tí ó dàgbà jùlọ, ó wí fún un pé, “Pa wọ́n!” Ṣùgbọ́n Jeteri kò fa idà rẹ̀ yọ láti pa wọ́n nítorí ó jẹ́ ọ̀dọ́mọdé ẹ̀rù sì bà á láti pa wọ́n.
Potem powiedział do Jetera, swego pierworodnego: Wstań i zabij ich. Lecz młodzieniec nie dobył swego miecza, ponieważ bał się, gdyż był jeszcze chłopcem.
21 Seba àti Salmunna dá Gideoni lóhùn pé, “Wá pa wá fún raàrẹ, ‘Nítorí bí ènìyàn bá ti rí bẹ́ẹ̀ ni agbára rẹ̀ yóò rí.’” Gideoni bọ́ síwájú ó sì pa wọ́n, ó sì mú ohun ọ̀ṣọ́ tí ó wà ní ọrùn àwọn ìbákasẹ wọn.
Wtedy Zebach i Salmunna powiedzieli: Ty wstań i rzuć się na nas, jaki bowiem mężczyzna, taka jego siła. Wstał więc Gedeon, zabił Zebacha i Salmunnę i zabrał klejnoty, które były na szyjach ich wielbłądów.
22 Àwọn ará Israẹli wí fún Gideoni pé, “Jọba lórí wa—ìwọ, àwọn ọmọ rẹ àti àwọn ọmọ ọmọ rẹ pẹ̀lú, nítorí tí ìwọ ti gbà wá lọ́wọ́ àwọn ará Midiani.”
I powiedzieli Izraelici do Gedeona: Panuj nad nami, ty i twój syn, i syn twego syna. Wybawiłeś nas bowiem z rąk Midianitów.
23 Ṣùgbọ́n Gideoni dá wọn lóhùn pé, “Èmi kì yóò jẹ ọba lórí yín, bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ mi kì yóò jẹ ọba lórí yín. Olúwa ni yóò jẹ ọba lórí yín.”
Lecz Gedeon odpowiedział im: Nie ja będę panował nad wami ani nie mój syn będzie panował nad wami. PAN będzie panował nad wami.
24 Gideoni sì wí pé, “Mo ní ẹ̀bẹ̀ kan tí mo fẹ́ bẹ̀ yín kí ẹnìkọ̀ọ̀kan yín fún mi ní yẹtí kọ̀ọ̀kan láti inú ohun ti ó kàn yín láti inú ìkógun.” (Àṣà àwọn ará Iṣmaeli ni láti máa fi yẹtí wúrà sétí.)
Gedeon powiedział jeszcze do nich: Będę was prosił o jedną rzecz, aby każdy z was dał mi kolczyki ze swego łupu. Mieli bowiem złote kolczyki, bo byli Izmaelitami.
25 Wọ́n dáhùn pé, “Tayọ̀tayọ̀ ni àwa yóò fi wọ́n sílẹ̀.” Wọ́n tẹ́ aṣọ kan sílẹ̀ ọkùnrin kọ̀ọ̀kan sì ń sọ yẹtí kọ̀ọ̀kan tí ó kàn wọ́n láti ibi ìkógun síbẹ̀.
I powiedzieli: Chętnie damy. Rozpostarli szatę i każdy rzucał na nią kolczyki ze swoich łupów.
26 Ìwọ̀n òrùka wúrà tí ó béèrè fún tó ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀sán ìwọ̀n ṣékélì, láìka àwọn ohun ọ̀ṣọ́ àti ohun sísorọ̀ tí ó wà lára ìlẹ̀kẹ̀ ọrùn àti aṣọ elése àlùkò tí àwọn ọba Midiani ń wọ̀ tàbí àwọn ẹ̀wọ̀n tí ó wà ní ọrùn àwọn ìbákasẹ wọn.
I waga [tych] złotych kolczyków, o które poprosił, wyniosła tysiąc siedemset syklów złota, nie licząc klejnotów i wisiorków, i szkarłatnych szat, które nosili królowie Midianu, i nie licząc łańcuchów, które były na szyjach ich wielbłądów.
27 Gideoni fi àwọn wúrà náà ṣe efodu èyí tí ó gbé kalẹ̀ ní Ofira ìlú rẹ̀. Àwọn ọmọ Israẹli sì sọ ara wọn di àgbèrè nípa sínsin-ín ní ibẹ̀. Ó sì di ìdẹ̀kùn fún Gideoni àti ìdílé rẹ̀.
A Gedeon zrobił z tego efod i umieścił go w swoim mieście, w Ofra. Tam cały Izrael, chodząc za nim, uprawiał nierząd, a stało się to sidłem dla Gedeona i jego domu.
28 Báyìí ni a ṣe tẹrí àwọn ará Midiani ba níwájú àwọn ọmọ Israẹli bẹ́ẹ̀ ni wọn kò tún gbé orí mọ́. Ní ọjọ́ Gideoni, Israẹli wà ní àlàáfíà fún ogójì ọdún.
Tak Midianici zostali poniżeni przed synami Izraela i nie podnieśli już swoich głów. A ziemia żyła w pokoju przez czterdzieści lat za dni Gedeona.
29 Jerubbaali ọmọ Joaṣi padà lọ láti máa gbé ní ìlú rẹ̀.
Wrócił więc Jerubbaal, syn Joasza, i mieszkał w swoim domu.
30 Àádọ́rin ọmọ ni Gideoni bí, nítorí ó ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ìyàwó.
A Gedeon miał siedemdziesięciu synów, którzy wyszli z jego bioder. Miał bowiem wiele żon.
31 Àlè rẹ̀, tó ń gbé ní Ṣekemu, pàápàá bí ọmọkùnrin kan fún un tí ó pe orúkọ rẹ̀ ní Abimeleki.
Również jego nałożnica, która była w Sychem, urodziła mu syna i nadała mu imię Abimelek.
32 Gideoni ọmọ Joaṣi kú ní ògbólógbòó ọjọ́ rẹ̀, ó sì pọ̀ ní ọjọ́ orí, wọ́n sì sin ín sí ibojì baba rẹ̀ ní Ofira ti àwọn ará Abieseri.
Potem Gedeon, syn Joasza, umarł w szczęśliwej starości i został pogrzebany w grobie swego ojca Joasza, w Ofra Abiezerytów.
33 Láìpẹ́ jọjọ lẹ́yìn ikú Gideoni ni àwọn ará Israẹli ṣe àgbèrè tọ Baali lẹ́yìn, wọ́n fi Baali-Beriti ṣe òrìṣà wọn.
A gdy Gedeon umarł, synowie Izraela odwrócili się i uprawiali nierząd, idąc za Baalami, i ustanowili sobie Baal-Berita swoim bogiem.
34 Wọn kò sì rántí Olúwa Ọlọ́run wọn, ẹni tí ó gbà wọ́n kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wọn gbogbo tí ó wà ní gbogbo àyíká wọn.
I synowie Izraela nie pamiętali o PANU, swym Bogu, który ich wyrwał z rąk wszystkich okolicznych wrogów;
35 Wọ́n kùnà láti fi inú rere hàn sí ìdílé Jerubbaali (èyí ni Gideoni) fún gbogbo oore tí ó ṣe fún wọn.
I nie okazali miłosierdzia domowi Jerubbaala, Gedeona, za wszystkie dobrodziejstwa, jakie wyświadczył on Izraelowi.

< Judges 8 >