< Judges 21 >

1 Àwọn ọkùnrin Israẹli ti búra ní Mispa pé, “Kò sí ẹnìkan nínú wa tí yóò fi ọmọ obìnrin rẹ̀ fún ẹ̀yà Benjamini ní ìyàwó.”
Mężczyźni Izraela przysięgli też w Mispie: Żaden z nas nie da swojej córki Beniaminowi za żonę.
2 Àwọn ènìyàn náà lọ sí Beteli: ilé Ọlọ́run, níbi tí wọ́n jókòó níwájú Ọlọ́run títí di àṣálẹ́, wọ́n gbé ohùn wọn sókè, wọ́n sì sọkún kíkorò.
Udał się więc lud do domu Bożego, gdzie trwał aż do wieczora przed Bogiem, podnosząc lament i gorzko płacząc.
3 Wọ́n sọkún wí pé, “Háà! Olúwa Ọlọ́run Israẹli, èéṣe tí nǹkan yìí fi ṣẹlẹ̀ sí Israẹli? Èéṣe tí ẹ̀yà kan yóò fi run nínú Israẹli lónìí?”
I powiedzieli: O PANIE, Boże Izraela, dlaczego to się stało w Izraelu, że ubyło dzisiaj z Izraela jedno pokolenie?
4 Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì àwọn ènìyàn náà mọ pẹpẹ kan wọ́n sì rú ẹbọ sísun àti ọrẹ àlàáfíà.
A nazajutrz lud wstał wcześnie rano i zbudował tam ołtarz, i złożył całopalenia oraz ofiary pojednawcze.
5 Àwọn ọmọ Israẹli sì béèrè wí pé, “Èwo nínú ẹ̀yà Israẹli ni ó kọ̀ láti péjọ síwájú Olúwa?” Torí pé wọ́n ti fi ìbúra ńlá búra pé, ẹnikẹ́ni tí ó bá kọ̀ láti péjọ níwájú Olúwa ní Mispa pípa ni àwọn yóò pa á.
Potem synowie Izraela powiedzieli: Kto spośród wszystkich pokoleń Izraela nie przyszedł do zgromadzenia do PANA? Złożyli bowiem uroczystą przysięgę przeciw temu, który by nie przyszedł do PANA do Mispy, mówiąc: Poniesie śmierć.
6 Àwọn ọmọ Israẹli sì banújẹ́ fún àwọn arákùnrin wọn, àwọn ẹ̀yà Benjamini. Wọ́n wí pé, “A ti ké ẹ̀yà kan kúrò lára Israẹli lónìí.”
I synom Izraela było żal Beniamina, swego brata, i mówili: Dziś zostało odcięte jedno pokolenie od Izraela.
7 Báwo ni a yóò ṣe rí aya fún àwọn tí ó ṣẹ́kù, nítorí àwa ti fi Olúwa búra láti má fi ọ̀kankan nínú àwọn ọmọbìnrin wa fún wọn ní aya.
Co uczynimy dla tych, którzy pozostali, aby mieli żony, skoro przysięgliśmy na PANA, że im nie damy naszych córek za żony?
8 Wọ́n sì béèrè wí pé, “Èwo ni nínú ẹ̀yà Israẹli ni ó kọ̀ láti bá àwọn ènìyàn péjọ níwájú Olúwa ní Mispa?” Wọ́n rí i pé kò sí ẹnikẹ́ni tí ó wa láti Jabesi Gileadi tí ó wá sí ibùdó fún àjọ náà.
Powiedzieli więc: Czy jest ktoś wśród pokoleń Izraela, kto nie przyszedł do Mispy do PANA? A oto nie przyszedł do obozu zgromadzenia nikt z Jabesz-Gilead.
9 Nítorí pé nígbà tí wọ́n ka àwọn ènìyàn, wọ́n rí i pé kò sí ẹnìkankan láti inú àwọn ará Jabesi Gileadi tí ó wà níbẹ̀.
[Gdy] bowiem przeliczono lud, nie było tam nikogo z mieszkańców Jabesz-Gilead.
10 Àwọn ìjọ ènìyàn náà sì rán ẹgbàá mẹ́fà àwọn jagunjagun ọkùnrin, lọ sí Jabesi Gileadi wọ́n fún wọn ní àṣẹ pé, ẹ lọ fi idà kọlu gbogbo àwọn tí ó wà níbẹ̀, pẹ̀lú àwọn obìnrin àti àwọn ọmọ wẹ́wẹ́.
Wtedy zgromadzenie wysłało tam dwanaście tysięcy walecznych mężczyzn, nakazując im: Idźcie i zabijcie mieszkańców Jabesz-Gilead ostrzem miecza wraz z kobietami i dziećmi.
11 Wọ́n ní, “Èyí ni ẹ̀yin yóò ṣe, ẹ pa gbogbo ọkùnrin àti gbogbo obìnrin tí kì í ṣe wúńdíá.”
A tak macie postąpić: Każdego mężczyznę i każdą kobietę, która obcowała z mężczyzną, zabijecie.
12 Wọ́n rí àwọn irinwó ọ̀dọ́bìnrin tí kò mọ ọkùnrin rí nínú àwọn olùgbé Jabesi Gileadi, wọ́n sì mú wọn lọ sí ibùdó ní Ṣilo àwọn ará Kenaani.
I znaleźli wśród mieszkańców Jabesz-Gilead czterysta młodych dziewic, które nie obcowały z mężczyzną, i przyprowadzili je do obozu w Szilo, które [było] w ziemi Kanaan.
13 Gbogbo ìjọ àwọn ènìyàn sì ránṣẹ́ àlàáfíà sí àwọn Benjamini ní ihò àpáta Rimoni.
Potem całe zgromadzenie posłało do synów Beniamina, którzy [byli] na skale Rimmon, aby oznajmiać im pokój.
14 Àwọn ẹ̀yà Benjamini náà sì padà ní àkókò náà, wọ́n sì fún wọn ní àwọn obìnrin Jabesi Gileadi. Ṣùgbọ́n wọn kò kárí gbogbo wọn.
Wrócił więc Beniamin w tym czasie i dano im żony, które zachowali przy życiu spośród kobiet z Jabesz-Gilead, lecz nie starczyło [ich] dla nich.
15 Àwọn ènìyàn náà sì káàánú nítorí ẹ̀yà Benjamini, nítorí Olúwa fi àlàfo kan sílẹ̀ nínú àwọn ẹ̀yà Israẹli.
A ludowi było żal Beniamina, ponieważ PAN uczynił wyłom wśród pokoleń Izraela.
16 Àwọn olórí ìjọ àwọn ènìyàn náà wí pé, “Kí ni àwa yóò ṣe láti rí aya fún àwọn ọkùnrin tí ó kù nígbà tí a ti pa gbogbo àwọn obìnrin Benjamini run?”
Wtedy starsi zgromadzenia powiedzieli: A co uczynimy dla pozostałych, [aby mieli] żony, skoro zostały zgładzone kobiety z Beniamina?
17 Wọ́n sì wí pé, “Àwọn tí ó ṣẹ́kù tí wọ́n là nínú àwọn ẹ̀yà Benjamini ní láti ní ogún àti àrólé, kí ẹ̀yà kan nínú Israẹli má ṣe di píparun kúrò ní orí ilẹ̀.
Ponadto powiedzieli: [Musi być] dziedzictwo dla pozostałych z Beniamina, aby nie zaginęło pokolenie z Izraela.
18 Àwa kò le fi àwọn ọmọbìnrin wa fún wọn ní aya, nítorí tí àwa ọmọ Israẹli ti ṣe ìbúra yìí pé, ‘Ègún ni fún ẹnikẹ́ni tí ó fi aya fún ẹnikẹ́ni nínú ẹ̀yà Benjamini.’”
My jednak nie możemy im dać żon z naszych córek, gdyż synowie Izraela przysięgli: Przeklęty ten, kto da żonę Beniaminowi.
19 Wọ́n sì wí pé, “Kíyèsi i ayẹyẹ ọlọ́dọọdún fún Olúwa wà ní Ṣilo ní ìhà àríwá Beteli àti ìhà ìlà-oòrùn òpópó náà tí ó gba Beteli kọjá sí Ṣekemu, àti sí ìhà gúúsù Lebona.”
Potem powiedzieli: Oto co roku [odbywa się] uroczyste święto PANA w Szilo, które [leży] na północ od Betel, na wschód od drogi wiodącej od Betel do Sychem, a na południe od Lebony.
20 Wọ́n sì fi àṣẹ fún àwọn ará Benjamini pé, “Ẹ lọ kí ẹ sì fi ara pamọ́ nínú àwọn ọgbà àjàrà
Nakazali więc synom Beniamina: Idźcie i przygotujcie zasadzkę w winnicach;
21 kí ẹ sì wà ní ìmúrasílẹ̀. Nígbà tí àwọn ọmọbìnrin Ṣilo bá jáde láti lọ darapọ̀ fún ijó, kí ẹ yára jáde láti inú àwọn ọgbà àjàrà wọ̀n-ọn-nì kí ẹnìkọ̀ọ̀kan yín gbé aya kan nínú àwọn ọmọbìnrin Ṣilo kí ẹ padà sí ilẹ̀ Benjamini.
I wypatrujcie, gdy córki Szilo wyjdą gromadnie do tańca, wtedy wyjdźcie z winnic i niech każdy z was porwie sobie żonę spośród córek Szilo, a potem idźcie do ziemi Beniamina.
22 Nígbà tí àwọn baba wọn tàbí àwọn arákùnrin wọn bá fi ẹjọ́ sùn wá, àwa yóò wí fún wọn pé, ‘Ẹ ṣe wá ní oore nípa ríràn wọ́n lọ́wọ́, nítorí àwa kò rí aya fún wọn ní àkókò ogun, ẹ̀yin kò sì ní jẹ̀bi, nítorí pé ẹ̀yin kọ́ ni ó fi àwọn ọmọbìnrin yín fún wọn bí aya.’”
A gdy przyjdą ich ojcowie albo bracia, by skarżyć się przed nami, powiemy im: Zmiłujcie się nad nimi ze względu na nas, ponieważ nie wzięliśmy dla każdego z nich żony na wojnie, a wy też im ich nie daliście, gdyż bylibyście wtedy winni.
23 Èyí sì ni ohun tí àwọn ẹ̀yà Benjamini ṣe. Nígbà tí àwọn ọmọbìnrin náà ń jó lọ́wọ́, ọkùnrin kọ̀ọ̀kan mú ọmọbìnrin kọ̀ọ̀kan, wọ́n sì gbé e lọ láti di aya rẹ̀. Wọ́n sì padà sí ilẹ̀ ìní wọn, wọ́n sì tún àwọn ìlú náà kọ́, wọ́n sì tẹ̀dó sínú wọn.
Wtedy synowie Beniamina uczynili tak i wzięli sobie żony spośród tańczących, które porwali, odpowiednio do swojej liczby. Potem odeszli i wrócili do swego dziedzictwa, odbudowali miasta i zamieszkali w nich.
24 Ní àkókò náà, àwọn ọmọ Israẹli kúrò ní ibẹ̀, wọ́n lọ sí ilé àti ẹ̀yà rẹ̀ olúkúlùkù sí ilẹ̀ ìní rẹ̀.
W tym czasie synowie Izraela rozeszli się stamtąd, każdy do swego pokolenia i do swego domu, a każdy poszedł stamtąd do swego dziedzictwa.
25 Ní àwọn ọjọ́ wọ̀nyí, kò sí ọba ní ilẹ̀ Israẹli; olúkúlùkù sì ń ṣe bí ó ti tọ́ ní ojú ara rẹ̀.
W tych dniach nie było króla w Izraelu. Każdy czynił to, co było słuszne w jego oczach.

< Judges 21 >