< Joshua 12 >

1 Ìwọ̀nyí ní àwọn ọba ilẹ̀ náà tí àwọn ará Israẹli ṣẹ́gun, tí wọ́n sì gba ilẹ̀ wọn ní ìlà-oòrùn Jordani, láti odò Arnoni dé òkè Hermoni, pẹ̀lú gbogbo ìhà ìlà-oòrùn aginjù:
Now these are the kings of the land, whom the children of Israel smote, and possessed their land on the other side of Jordan toward the rising of the sun, from the river Arnon to mount Hermon, and all the plain on the east:
2 Sihoni ọba àwọn Amori, tí ó jẹ ọba ní Heṣboni. Ó ṣe àkóso láti Aroeri tí ń bẹ ní etí odò Arnoni, láti ìlú tó wà ní àárín àfonífojì náà dé odò Jabbok, èyí tí ó jẹ́ ààlà àwọn ọmọ Ammoni. Pẹ̀lú ìdajì àwọn ará Gileadi.
Sihon king of the Amorites, who dwelt in Heshbon, and ruled from Aroer, which is upon the bank of the river Arnon, and from the middle of the river, and half Gilead, even to the river Jabbok, which is the border of the children of Ammon;
3 Ó sì ṣe àkóso ní orí ìlà-oòrùn aginjù láti Òkun Kinnereti sí ìhà Òkun ti aginjù (ti o túmọ̀ sí Òkun Iyọ̀), sí Beti-Jeṣimoti, àti láti gúúsù lọ dé ìsàlẹ̀ ẹsẹ̀ òkè Pisga.
And from the plain to the sea of Chinneroth on the east, and to the sea of the plain, even the salt sea on the east, the way to Bethjeshimoth; and from the south, under Ashdothpisgah:
4 Àti agbègbè Ogu ọba Baṣani, ọ̀kan nínú àwọn tí ó kù nínú àwọn ará Refaimu, ẹni tí ó jẹ ọba ní Aṣtarotu àti Edrei.
And the land of Og king of Bashan, who was of the remnant of the giants, that dwelt at Ashtaroth and at Edrei,
5 Ó ṣe àkóso ní orí òkè Hermoni, Saleka, Baṣani títí dé ààlà àwọn ènìyàn Geṣuri àti Maakati, àti ìdajì Gileadi dé ààlà Sihoni ọba Heṣboni.
And reigned in mount Hermon, and in Salcah, and in all Bashan, to the border of the Geshurites and the Maachathites, and half Gilead, the border of Sihon king of Heshbon.
6 Mose ìránṣẹ́ Olúwa àti àwọn ọmọ Israẹli sì borí wọn. Mose ìránṣẹ́ Olúwa sì fi ilẹ̀ wọn fún àwọn ẹ̀yà Reubeni, àwọn ẹ̀yà Gadi àti ìdajì ẹ̀yà Manase kí ó jẹ́ ohun ìní wọn.
Them did Moses the servant of the LORD and the children of Israel smite: and Moses the servant of the LORD gave it for a possession to the Reubenites, and the Gadites, and the half tribe of Manasseh.
7 Ìwọ̀nyí ní àwọn ọba ilẹ̀ náà tí Joṣua àti àwọn ọmọ Israẹli ṣẹ́gun ní ìhà ìwọ̀-oòrùn Jordani, láti Baali-Gadi ní àfonífojì Lebanoni sí òkè Halaki, èyí tí o lọ sí ọ̀nà Seiri (Joṣua sì fi ilẹ̀ wọn fún àwọn ẹ̀yà Israẹli ní ilẹ̀ ìní gẹ́gẹ́ bí ìpín ẹ̀yà wọn:
And these are the kings of the country whom Joshua and the children of Israel smote on this side of Jordan on the west, from Baalgad in the valley of Lebanon even to the mount Halak, that goeth up to Seir; which Joshua gave to the tribes of Israel for a possession according to their divisions;
8 ilẹ̀ òkè, ní ẹsẹ̀ òkè ní ìhà ìwọ̀-oòrùn òkè aginjù, ní gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ òkè, ní aginjù àti nì gúúsù ilẹ̀ àwọn ará: Hiti, Amori, Kenaani, Peresi, Hifi àti àwọn ará Jebusi).
In the mountains, and in the valleys, and in the plains, and in the springs, and in the wilderness, and in the south country; the Hittites, the Amorites, and the Canaanites, the Perizzites, the Hivites, and the Jebusites:
9 Ọba Jeriko, ọ̀kan ọba Ai (tí ó wà nítòsí Beteli), ọ̀kan
The king of Jericho, one; the king of Ai, which is beside Bethel, one;
10 ọba Jerusalẹmu, ọ̀kan ọba Hebroni, ọ̀kan
The king of Jerusalem, one; the king of Hebron, one;
11 ọba Jarmatu, ọ̀kan ọba Lakiṣi, ọ̀kan
The king of Jarmuth, one; the king of Lachish, one;
12 ọba Egloni, ọ̀kan ọba Geseri, ọ̀kan
The king of Eglon, one; the king of Gezer, one;
13 ọba Debiri, ọ̀kan ọba Gederi, ọ̀kan
The king of Debir, one; the king of Geder, one;
14 ọba Horma, ọ̀kan ọba Aradi, ọ̀kan
The king of Hormah, one; the king of Arad, one;
15 ọba Libina, ọ̀kan ọba Adullamu, ọ̀kan
The king of Libnah, one; the king of Adullam, one;
16 ọba Makkeda, ọ̀kan ọba Beteli, ọ̀kan
The king of Makkedah, one; the king of Bethel, one;
17 ọba Tapua, ọ̀kan ọba Heferi, ọ̀kan
The king of Tappuah, one; the king of Hepher, one;
18 ọba Afeki, ọ̀kan ọba Laṣaroni, ọ̀kan
The king of Aphek, one; the king of Lasharon, one;
19 ọba Madoni, ọ̀kan ọba Hasori, ọ̀kan
The king of Madon, one; the king of Hazor, one;
20 ọba Ṣimroni-Meroni, ọ̀kan ọba Akṣafu, ọ̀kan
The king of Shimronmeron, one; the king of Achshaph, one;
21 ọba Taanaki, ọ̀kan ọba Megido, ọ̀kan
The king of Taanach, one; the king of Megiddo, one;
22 ọba Kedeṣi, ọ̀kan ọba Jokneamu ni Karmeli, ọ̀kan
The king of Kedesh, one; the king of Jokneam of Carmel, one;
23 ọba Dori (ní Nafoti Dori), ọ̀kan ọba Goyimu ní Gilgali, ọ̀kan
The king of Dor in the heights of Dor, one; the king of the nations of Gilgal, one;
24 ọba Tirsa, ọ̀kan. Gbogbo àwọn ọba náà jẹ́ mọ́kànlélọ́gbọ̀n.
The king of Tirzah, one: all the kings thirty and one.

< Joshua 12 >