< Joel 2 >

1 Ẹ fun ìpè ní Sioni, ẹ sì fún ìpè ìdágìrì ní òkè mímọ́ mi. Jẹ́ kí àwọn ará ilẹ̀ náà wárìrì, nítorí tí ọjọ́ Olúwa ń bọ̀ wá, nítorí ó kù sí dẹ̀dẹ̀.
Zadmijcie w trąbę na Syjonie, krzyczcie na mojej świętej górze! Niech zadrżą wszyscy mieszkańcy ziemi, bo nadchodzi dzień PANA, bo już [jest] bliski;
2 Ọjọ́ òkùnkùn àti ìrọ́kẹ̀kẹ̀, ọjọ́ ìkùùkuu àti òkùnkùn biribiri. Bí ọyẹ́ òwúrọ̀ ti í la bo orí àwọn òkè ńlá: àwọn ènìyàn ńlá àti alágbára; ya dé, ti kó ti ì sí irú rẹ̀ rí, bẹ́ẹ̀ ni irú rẹ̀ kì yóò sí mọ́ lẹ́yìn rẹ̀, títí dé ọdún ìran dé ìran.
Dzień ciemności i mroku, dzień obłoku i chmury, jak zorza ranna rozciągnięta po górach. Lud wielki i potężny, któremu równego nie było od wieków i po nim nigdy nie będzie aż do lat najdalszych pokoleń.
3 Iná ń jó níwájú wọ́n; ọwọ́ iná sì ń jó lẹ́yìn wọn. Ilẹ̀ náà dàbí ọgbà Edeni níwájú wọn, àti lẹ́yìn wọn bí ahoro ijù; nítòótọ́, kò sì sí ohun tí yóò bọ́ lọ́wọ́ wọn.
Przed jego obliczem ogień pożerający, a za nim płomień palący. Ta ziemia [jest] przed nim jak ogród Eden, ale po nim będzie opustoszałe pustkowie – przed nim nie ujdzie nikt.
4 Ìrí wọn dàbí ìrí àwọn ẹṣin; wọ́n ń sáré lọ bí àwọn ẹlẹ́ṣin ogun.
Ich wygląd jest podobny do wyglądu koni i pobiegną jak jeźdźcy.
5 Bí ariwo kẹ̀kẹ́ ogun ni wọn ń fo ní orí òkè bí ariwo ọ̀wọ́-iná tí ń jó koríko gbígbẹ, bí akọni ènìyàn tí a kójọ fún ogun.
Po wierzchołkach gór będą skakać jak grzmot rydwanów, jak szum płomienia ognia, co pożera ściernisko, jak lud potężny uszykowany do bitwy.
6 Ní ojú wọn, àwọn ènìyàn yóò jẹ ìrora púpọ̀: gbogbo ojú ní yóò ṣú dudu.
Na ich widok narody się zlękną, wszystkie [ich] twarze poczernieją jak garnek.
7 Wọn yóò sáré bi àwọn alágbára; wọn yóò gùn odi bí ọkùnrin ológun; olúkúlùkù wọn yóò sì rìn lọ ní ọ̀nà rẹ̀, wọn kì yóò sì yà kúrò ni ọ̀nà wọn.
Pobiegną jak wojownicy, wedrą się na mury jak waleczni wojownicy; każdy z nich pójdzie swoją drogą, a nie zboczą ze swoich ścieżek.
8 Bẹ́ẹ̀ ni ẹnìkan kì yóò kọlu ẹnìkejì rẹ̀; olúkúlùkù wọn yóò rìn ní ọ̀nà rẹ̀, nígbà tí wọn bá sì ṣubú lù idà wọn kì yóò gbọgbẹ́.
Jeden drugiego nie ściśnie, każdy pójdzie swoją drogą. A choć i na miecz upadną, nie będą zranieni.
9 Wọn yóò sáré síwá sẹ́yìn ní ìlú; wọn yóò súré lórí odi, wọn yóò gùn orí ilé; wọn yóò gbà ojú fèrèsé wọ̀ inú ilé bí olè.
Po mieście będą chodzić, po murze [będą] biegać, wdrapią się na domy i wejdą oknami jak złodziej.
10 Ayé yóò mì níwájú wọn; àwọn ọ̀run yóò wárìrì; oòrùn àti òṣùpá yóò ṣókùnkùn, àwọn ìràwọ̀ yóò sì fà ìmọ́lẹ̀ wọn sẹ́yìn.
Przed nimi zadrży ziemia, niebiosa się poruszą, słońce i księżyc będą zaćmione, a gwiazdy stracą swój blask.
11 Olúwa yóò sì bú ramúramù jáde níwájú ogun rẹ̀: nítorí ibùdó rẹ̀ tóbi gidigidi; nítorí alágbára ní òun, tí n mú ọ̀rọ̀ rẹ̀ ṣẹ; nítorí ọjọ́ Olúwa tóbi ó sì ní ẹ̀rù gidigidi; ara ta ni ó lè gbà á?
A PAN wyda swój głos przed swoim wojskiem, gdyż jego obóz jest ogromny, gdyż mocny [jest] ten, który wykonuje jego słowo. Wielki jest bowiem dzień PANA i bardzo straszliwy! Któż go zniesie?
12 “Ǹjẹ́ nítorí náà nísinsin yìí,” ni Olúwa wí, “Ẹ fi gbogbo ọkàn yín yípadà sí mi, àti pẹ̀lú àwẹ̀, àti pẹ̀lú ẹkún, àti pẹ̀lú ọ̀fọ̀.”
Dlatego jeszcze [i] teraz, mówi PAN, wróćcie do mnie całym swym sercem, w poście, płaczu i w lamencie.
13 Ẹ sì fa ọkàn yín ya, kì í sì í ṣe aṣọ yín, ẹ sì yípadà sí Olúwa Ọlọ́run yín, nítorí tí o pọ̀ ní oore-ọ̀fẹ́, ó sì kún fun àánú, ó lọ́ra láti bínú, ó sì ṣeun púpọ̀, ó sì ronúpìwàdà láti ṣe búburú.
Rozdzierajcie swoje serca, a nie swoje szaty, i nawróćcie się do PANA, waszego Boga, bo on jest łaskawy i miłosierny, nieskory do gniewu i hojny w miłosierdzie i żałuje nieszczęścia.
14 Ta ni ó mọ̀ bí òun yóò yípadà, kí o sì ronúpìwàdà, kí ó sì fi ìbùkún sílẹ̀ lẹ́yìn rẹ̀— àní ọrẹ-jíjẹ àti ọrẹ mímu fún Olúwa Ọlọ́run yín?
Któż wie, czy nie zawróci i nie będzie mu żal, i nie zostawi po sobie błogosławieństwa [na] ofiarę z pokarmów i z płynów dla PANA, swego Boga?
15 Ẹ fún ìpè ní Sioni, ẹ ya àwẹ̀ kan sí mímọ́, ẹ pe àjọ tí ó ni ìrònú.
Zadmijcie w trąbę na Syjonie, ogłoście święty post, zwołajcie zgromadzenie.
16 Ẹ kó àwọn ènìyàn jọ, ẹ ya ìjọ sí mímọ́; ẹ pe àwọn àgbàgbà jọ, ẹ kó àwọn ọmọdé jọ, àti àwọn tí ń mú ọmú, jẹ kí ọkọ ìyàwó kúrò nínú ìyẹ̀wù rẹ̀. Kí ìyàwó sì kúrò nínú iyàrá rẹ̀.
Zgromadźcie lud, poświęćcie zgromadzenie, zbierzcie starców, zbierzcie dzieci i [niemowlęta] ssące piersi. Niech oblubieniec wyjdzie ze swojej izby, a oblubienica ze swojej komnaty.
17 Jẹ́ kí àwọn àlùfáà, àwọn ìránṣẹ́ Olúwa, sọkún láàrín ìloro àti pẹpẹ. Sí jẹ́ kí wọn wí pé, “Dá àwọn ènìyàn rẹ sí, Olúwa. Má sì ṣe fi ìní rẹ fun ẹ̀gàn, tí yóò sì di òwe ní àárín àwọn kèfèrí. Èéṣe tí wọn yóò fi wí láàrín àwọn ènìyàn pé, ‘Ọlọ́run wọn ha da?’”
Niech kapłani, słudzy PANA, płaczą między przedsionkiem a ołtarzem i [niech] mówią: Przepuść, PANIE, swemu ludowi i nie wydawaj swego dziedzictwa na pohańbienie, aby poganie nad nimi nie panowali. Czemu mieliby mówić wśród narodów: Gdzie jest ich Bóg?
18 Nígbà náà ní Olúwa yóò jowú fún ilẹ̀ rẹ̀, yóò sì káàánú fún ènìyàn rẹ̀.
Wtedy PAN będzie zazdrosny o swoją ziemię i zlituje się nad swoim ludem.
19 Nítòótọ́, Olúwa yóò dá wọn lóhùn, yóò sì wí fun àwọn ènìyàn rẹ̀ pé: “Wò ó èmi yóò rán ọkà, àti ọtí wáìnì tuntun, àti òróró sí i yín, a ó sì fi wọn tẹ́ yín lọ́rùn; Èmi kì yóò sì fi yín ṣe ẹ̀gàn mọ́ láàrín àwọn aláìkọlà.
I PAN odezwie się, i powie do swego ludu: Oto ześlę wam zboże, moszcz i oliwę i nasycicie się nimi, a już nie wydam was na pohańbienie pośród pogan.
20 “Ṣùgbọ́n èmi yóò lé ogun àríwá jìnnà réré kúrò lọ́dọ̀ yín, èmi yóò sì lé e lọ sí ilẹ̀ tí ó ṣá, tí ó sì di ahoro, pẹ̀lú ojú rẹ̀ sí Òkun ìlà-oòrùn, àti ẹ̀yìn rẹ̀ sí ìwọ̀-oòrùn Òkun. Òórùn rẹ̀ yóò sì gòkè, òórùn búburú rẹ̀ yóò sì gòkè.” Nítòótọ́ ó ti ṣe ohun ńlá.
Oddalę od was północne [wojsko] i zapędzę je do ziemi suchej i spustoszonej. Przednia jego straż [obróci się] ku morzu wschodniemu, a jego tylna straż – ku morzu zachodniemu; i rozejdzie się jego smród i zgnilizna, bo postępował wyniośle.
21 Má bẹ̀rù, ìwọ ilẹ̀; jẹ́ kí inú rẹ̀ dùn kí o sì yọ̀, nítorí Olúwa ti ṣe ohun ńlá.
Nie bój się, ziemio! Ciesz się i raduj, bo PAN uczyni wielkie rzeczy.
22 Ẹ má bẹ̀rù, ẹranko igbó, nítorí pápá oko aginjù ń rú. Nítorí igi ń so èso rẹ̀, igi ọ̀pọ̀tọ́ àti àjàrà ń so èso ọ̀rọ̀ wọn.
Nie bójcie się, polne zwierzęta, bo zarosło pastwisko na pustyni, a drzewa wydają swoje owoce, drzewo figowe i winorośl wydają swoją moc.
23 Ẹ jẹ́ kí inú yín dùn, ẹ̀yin ọmọ Sioni, ẹ sì yọ̀ nínú Olúwa Ọlọ́run yín, nítorí ó ti fi àkọ́rọ̀ òjò fún yín bí ó ti tọ́, Òun ti mú kí òjò rọ̀ sílẹ̀ fún un yín, àkọ́rọ̀ àti àrọ̀kúrò òjò ní oṣù kìn-ín-ní.
I wy, synowie Syjonu, cieszcie się i radujcie w PANU, waszym Bogu. Da wam bowiem deszcz wczesny i ześle wam deszcz jesienny i wiosenny, jak dawniej.
24 Àwọn ilẹ̀ ìpakà yóò kún fún ọkà; àti ọpọ́n wọn nì yóò sàn jáde pẹ̀lú ọtí wáìnì tuntun àti òróró.
I spichlerze będą napełnione zbożem, a tłocznie będą opływać moszczem i oliwą.
25 “Èmi yóò sì mú ọdún wọ̀nyí ti eṣú jẹ run padà fún un yín. Èyí tí eṣú agénijẹ àti eṣú jewéjewé ọwọ́ eṣú agénijẹ àti kòkòrò ajẹnirun mìíràn ti fi jẹ àwọn ogun ńlá mi tí mo rán sí àárín yín.
W ten sposób wynagrodzę wam lata zjedzone przez szarańczę, larwę, robactwo i gąsienicę, moje wielkie wojsko, które wysyłałem na was.
26 Ẹ̀yin yóò ni ọ̀pọ̀lọpọ̀ láti jẹ, títí ẹ̀yin yóò fi yó ẹ ó sì yín orúkọ Olúwa Ọlọ́run yín, ẹni tí ó fi ìyanu bá yín lò; ojú kì yóò sì ti àwọn ènìyàn mi láéláé.
Wtedy będziecie jeść obficie i będziecie nasyceni; będziecie chwalić imię PANA, swego Boga, który uczynił wam cudowne rzeczy, a mój lud nigdy nie będzie pohańbiony.
27 Ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, èmi wà láàrín Israẹli, àti pé; Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín, àti pé kò sí ẹlòmíràn, ojú kì yóò sì ti àwọn ènìyàn mí láéláé.
I dowiecie się, że ja jestem wśród Izraela, że ja jestem PAN, wasz Bóg, i że nie ma żadnego innego; a mój lud nigdy nie będzie pohańbiony.
28 “Yóò sì ṣe níkẹyìn ọjọ́, èmi yóò tú nínú Ẹ̀mí mí sí ara ènìyàn gbogbo; àwọn ọmọ yín ọkùnrin àti àwọn ọmọ yín obìnrin yóò máa sọtẹ́lẹ̀, àwọn arúgbó yín yóò máa lá àlá, àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin yín yóò máa ríran.
I stanie się potem, że wyleję swojego Ducha na wszelkie ciało, i będą prorokować wasi synowie i wasze córki, wasi starcy będą mieć sny, a wasi młodzieńcy – widzenia.
29 Àti pẹ̀lú sí ara àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ ọkùnrin, àti sí ara àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ obìnrin, ní èmi yóò tú ẹ̀mí mí jáde ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì.
Nawet na sługi i służebnice wyleję w tych dniach swojego Ducha.
30 Èmi yóò sì fi iṣẹ́ ìyanu hàn ní ọrun àti ní ayé, ẹ̀jẹ̀ àti iná, àti ọ̀wọ́n èéfín.
I ukażę cuda na niebie i na ziemi, krew, ogień i kłęby dymu.
31 A á sọ oòrùn di òkùnkùn, àti òṣùpá di ẹ̀jẹ̀, kí ọjọ́ ńlá àti ọjọ́ ẹ̀rù Olúwa tó dé.
Słońce zamieni się w ciemność, a księżyc w krew, zanim nadejdzie dzień PANA, wielki i straszny.
32 Yóò sí ṣe, ẹnikẹ́ni tí ó ba ké pè orúkọ Olúwa ní a ó gbàlà, nítorí ní òkè Sioni àti ní Jerusalẹmu ní ìgbàlà yóò gbé wà, bí Olúwa ti wí, àti nínú àwọn ìyókù tí Olúwa yóò pè.
I stanie się, że każdy, kto wezwie imienia PANA, zostanie wybawiony, bo na górze Syjon i w Jerozolimie będzie wybawienie, jak powiedział PAN, [to jest] w resztkach, które PAN powoła.

< Joel 2 >