< Jeremiah 8 >

1 “‘Ní ìgbà náà ni Olúwa wí pé, wọn yóò mú egungun àwọn ọba Juda àti egungun àwọn ìjòyè, egungun àwọn àlùfáà àti egungun àwọn wòlíì àti egungun àwọn olùgbé Jerusalẹmu kúrò nínú ibojì.
W tym czasie, mówi PAN, wydobędą z ich grobów kości królów Judy, kości ich książąt, kości kapłanów, kości proroków i kości mieszkańców Jerozolimy;
2 A ó yọ wọ́n síta fún oòrùn àti òṣùpá àti gbogbo àwọn ìràwọ̀ ojú ọ̀run tí wọ́n ti fẹ́ràn tí wọ́n sì ti sìn, àti àwọn tí wọ́n ti tọ̀ lẹ́yìn tí wọ́n ti wá tí wọ́n sì ti foríbalẹ̀ fún. Kì yóò ṣà wọ́n jọ tàbí sìn wọ́n, wọn yóò dàbí ìdọ̀tí tó wà lórí ilẹ̀.
I rozrzucą je przed słońcem, przed księżycem i przed całym zastępem nieba, które oni kochali, którym służyli, za którymi szli, których szukali i którym oddawali pokłon. Nie będą zebrane ani pogrzebane, [lecz] staną się nawozem na powierzchni ziemi.
3 Níbikíbi tí mo bá lé wọn lọ, gbogbo àwọn ìyókù wọn yóò fẹ́ ikú ju ìyè lọ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.’
I cała reszta ocalałych z tego przewrotnego rodu będzie wybierać [raczej] śmierć niż życie we wszystkich miejscach, gdzie zostali, kiedy ich wygnałem, mówi PAN zastępów.
4 “Wí fún wọn pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “‘Bí ènìyàn bá ṣubú lulẹ̀, wọn kì í padà dìde bí? Nígbà tí ènìyàn bá yà kúrò ní ọ̀nà rẹ, kì í yí padà bí?
Dlatego powiesz do nich: Tak mówi PAN: Czy nie powstaje ten, który upadł? Czy nie zawraca ten, który zbłądził?
5 Èéṣe nígbà náà àwọn ènìyàn wọ̀nyí fi yà kúrò lọ́nà rẹ̀? Kí ló dé tí Jerusalẹmu fi yà kúrò ní gbogbo ìgbà? Wọ́n rọ̀ mọ́ ẹ̀tàn; wọ́n kọ̀ láti yípadà.
Czemu więc odwrócił się ten lud Jerozolimy wiecznym odstępstwem? Trzymają się kłamstwa, nie chcą wrócić.
6 Mo ti fetísílẹ̀ dáradára, wọn kò sọ ohun tí ó tọ́. Kò sí ẹnìkan tó ronúpìwàdà nínú ìwà búburú rẹ̀, kí ó wí pé, “Kí ni mo ṣe?” Olúkúlùkù ń tọ ọ̀nà rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ẹṣin tó ń lọ sójú ogun.
Uważałem i słyszałem: nie mówią właściwie, nikt nie żałuje swej niegodziwości, mówiąc: Cóż uczyniłem? Każdy biegnie swoją drogą, jak koń pędzący do bitwy.
7 Kódà, ẹyẹ àkọ̀ ojú ọ̀run mọ ìgbà tirẹ̀, àdàbà, alápáǹdẹ̀dẹ̀ àti lékèélékèé mọ àkókò ìṣípò padà wọn. Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn mi kò mọ ohun tí Olúwa wọn fẹ́.
Nawet bocian na niebiosach zna swoje ustalone pory; synogarlica, żuraw i jaskółka przestrzegają czasu swego przylotu. Lecz mój lud nie zna sądu PANA.
8 “‘Báwo ni ẹ̀yin ṣe lè wí pé, “Àwa gbọ́n, nítorí a ní òfin Olúwa,” nígbà tí ó jẹ́ pé kálámù èké àwọn akọ̀wé ti àwọn sọ ọ́ di ẹ̀tàn.
Jakże [możecie] mówić: My jesteśmy mądrzy, a prawo PANA [jest] przy nas? Oto zaprawdę na próżno uczynił je; daremne jest pióro pisarzy.
9 Ojú yóò ti àwọn ọlọ́gbọ́n, a ó dà wọ́n láàmú, wọn yóò sì kó sí ìgbèkùn. Nítorí wọ́n ti kọ ọ̀rọ̀ Olúwa, irú ọgbọ́n wo ló kù tí wọ́n ní?
Mędrcy się zawstydzili. Są przestraszeni i pojmani. Oto odrzucają słowo PANA, jaką więc mają mądrość?
10 Nítorí náà, èmi yóò fi ìyàwó wọn fún àwọn ọkùnrin mìíràn àti ilẹ̀ wọn fún àwọn ẹlòmíràn. Láti èyí tó kéré jù dé èyí tó dàgbà jù, gbogbo wọn ni èrè àjẹjù ń jẹ lógún; àwọn wòlíì àti àwọn àlùfáà pẹ̀lú ń hùwà ẹ̀tàn.
Dlatego ich żony dam innym, ich pola tym, którzy ich zdobędą, bo od najmniejszego aż do największego – wszyscy są oddani chciwości, od proroka aż do kapłana – wszyscy działają podstępnie.
11 Wọ́n tọ́jú ọgbẹ́ àwọn ènìyàn mi gẹ́gẹ́ bí èyí tí kò jinlẹ̀. “Àlàáfíà, àlàáfíà,” ni wọ́n ń wí, nígbà tí kò sí àlàáfíà.
I leczą rany córki mego ludu [tylko] powierzchownie, mówiąc: Pokój, pokój! Ale nie ma pokoju.
12 Ǹjẹ́ wọ́n tijú fún ìṣe ìríra wọn? Bẹ́ẹ̀ kọ́, wọn kò ní ìtìjú rárá; wọn kò tilẹ̀ mọ bí wọ́n ti ṣe ń tì jú. Nítorí náà wọn yóò ṣubú pẹ̀lú àwọn tó ti ṣubú, a ó sì wó wọ́n lulẹ̀ nígbà tí a bá bẹ̀ wọ́n wò, ni Olúwa wí.
Czy zawstydzili się, że popełnili obrzydliwość? Bynajmniej, wcale się nie zawstydzili ani nie potrafili rumienić. Dlatego upadną wśród tych, co mają upaść. W czasie gdy ich nawiedzę, upadną, mówi PAN.
13 “‘Èmi yóò mú ìkórè wọn kúrò, ni Olúwa wí. Kì yóò sí èso lórí igi àjàrà. Kì yóò sí ọ̀pọ̀tọ́ lórí igi, ewé wọn yóò sì rẹ̀ sílẹ̀. Ohun tí mo ti fi fún wọn ni à ó gbà kúrò.’”
Doszczętnie ich wykorzenię, mówi PAN. Nie będzie winogron na winorośli ani żadnych fig na drzewie figowym, nawet liść opadnie, a to, co im dałem, zostanie im zabrane.
14 “Èéṣe tí àwa fi jókòó ní ibí yìí? A kó ara wa jọ! Jẹ́ kí a sálọ sí ìlú olódi kí a sì ṣègbé síbẹ̀. Nítorí tí Olúwa Ọlọ́run wa ti pinnu pé a ó ṣègbé. Yóò sì fún wa ní omi onímájèlé mu, nítorí àwa ti ṣẹ̀ sí i.
Czemu [tu] siedzimy? Zbierzcie się, wejdźmy do miast warownych i tam będziemy milczeć. PAN bowiem, nasz Bóg, każe nam milczeć i daje nam do picia wodę żółci, gdyż zgrzeszyliśmy przeciwko PANU.
15 Àwa ń retí àlàáfíà kò sí ìre kan, tí ó wá ní ìgbà ìmúláradá bí kò ṣe ìpayà nìkan.
Oczekiwaliśmy pokoju, ale nic dobrego [nie przyszło]; czasu uzdrowienia – a oto strach.
16 Ìró ìfọn imú ẹṣin àwọn ọlọ̀tẹ̀ là ń gbọ́ láti Dani, yíyan àwọn akọ ẹṣin mú gbogbo ilẹ̀ wárìrì. Wọ́n wá láti pa ilẹ̀ náà run, gbogbo ohun tó wà níbẹ̀, ìlú náà àti gbogbo olùgbé ibẹ̀.
Od Dan słychać parskanie jego koni, na odgłos rżenia jego mocarzy zadrżała cała ziemia. Nadciągają, aby pożreć ziemię i wszystko, co jest na niej, miasto i jego mieszkańców.
17 “Wò ó, èmi yóò rán àwọn ejò olóró sí àárín yín, paramọ́lẹ̀ tí ẹ kò lè pa oró wọn, yóò sì bù yín jẹ,” ni Olúwa wí.
Oto bowiem poślę na was najbardziej jadowite węże, których nie można zaklinać, i będą was kąsać, mówi PAN.
18 Olùtùnú mi, nígbà tí ìbànújẹ́ ọkàn mi, rẹ̀wẹ̀sì nínú mi.
Moje serce, które miało mnie posilać w smutku, mdleje we mnie.
19 Fetí sí ẹkún àwọn ènìyàn mi láti ilẹ̀ jíjìnnà wá: “Olúwa kò ha sí ní Sioni bí? Ọba rẹ̀ kò sí níbẹ̀ mọ́ ni?” “Èéṣe tí wọ́n fi mú mi bínú pẹ̀lú ère wọn, pẹ̀lú àwọn òrìṣà àjèjì tí wọn kò níláárí?”
Oto głos krzyku córki mego ludu z dalekiej ziemi: Czy nie ma PANA na Syjonie? Czy nie ma na nim jego króla? Czemu pobudzili mnie do gniewu swoimi bożkami i obcymi próżnościami? – [odpowiada PAN].
20 “Ìkórè ti rékọjá, ìgbà ẹ̀ẹ̀rùn ti parí, síbẹ̀ a kò gbà wá là.”
Przeminęło żniwo, skończyło się lato, a my nie jesteśmy wybawieni.
21 Níwọ́n ìgbà tí a pa àwọn ènìyàn mi run, èmi náà run pẹ̀lú, èmi ṣọ̀fọ̀, ìrora sì mú mi káká.
Z powodu rany córki mojego ludu jestem ranny, pogrążony w żałobie, ogarnęło mnie przerażenie.
22 Kò ha sí ìkunra ní Gileadi bí? Kò ha sí àwọn oníṣègùn níbẹ̀? Kí ló ha dé tí kò fi sí ìwòsàn fún ọgbẹ́ àwọn ènìyàn mi?
Czy nie ma balsamu w Gileadzie? Czy nie ma tam lekarza? Czemu więc nie jest uleczona córka mojego ludu?

< Jeremiah 8 >