< Jeremiah 13 >

1 Èyí ni ohun tí Olúwa wí fún mi: “Lọ kí o sì ra àmùrè aṣọ ọ̀gbọ̀, kí o sì dì í mọ́ ẹ̀gbẹ́ rẹ, kí o má sì ṣe jẹ́ kí omi kí ó kàn án.”
Tak powiedział PAN do mnie: Idź i kup sobie lniany pas, przepasz nim swoje biodra, ale nie kładź go do wody.
2 Bẹ́ẹ̀ ni mo ra àmùrè gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti wí, mo sì dì í mọ́ ẹ̀gbẹ́ mi.
Kupiłem więc pas według rozkazu PANA i przepasałem [nim] swoje biodra.
3 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá nígbà kejì,
Potem ponownie doszło do mnie słowo PANA mówiące:
4 “Mú àmùrè tí o rà, kí o sì fiwé ẹ̀gbẹ́ rẹ, kí o sì lọ sí Perati, kí o lọ pa á mọ́ sí pàlàpálá òkúta.”
Weź ten pas, który kupiłeś i który jest na twoich biodrach, i wstań, idź nad Eufrat i ukryj go tam w szczelinie skalnej.
5 Nígbà náà ni mo lọ pa á mọ́ ní Perati gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti wí fún mi.
Poszedłem więc i ukryłem go nad Eufratem, jak mi PAN rozkazał.
6 Lẹ́yìn ọjọ́ díẹ̀, Olúwa sọ fún mi, “Lọ sí Perati kí o lọ mú àmùrè tí mo ní kí o pamọ́ síbẹ̀.”
A po upływie wielu dni PAN powiedział do mnie: Wstań, idź nad Eufrat i weź stamtąd pas, który ci rozkazałem tam ukryć.
7 Nígbà náà ni mo lọ sí Perati mo lọ wá àmùrè mi níbi tí mo pa á mọ́ sí, ṣùgbọ́n nísinsin yìí àmùrè náà ti bàjẹ́, kò sì wúlò fún ohunkóhun mọ́.
Poszedłem wtedy nad Eufrat, wykopałem i wziąłem pas z miejsca, gdzie go ukryłem, a oto pas był zbutwiały tak, że do niczego się nie nadawał.
8 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá pé:
Potem doszło do mnie słowo PANA mówiące:
9 “Èyí ni ohun tí Olúwa sọ: ‘Bákan náà ni èmi yóò run ìgbéraga Juda àti ìgbéraga ńlá ti Jerusalẹmu.
Tak mówi PAN: Tak zniszczę pychę Judy i wielką pychę Jerozolimy.
10 Àwọn ènìyàn búburú tí ó kùnà láti gbọ́ ọ̀rọ̀ mi, tí wọ́n ń lo agídí ọkàn wọn, tí ó sì ń rìn tọ àwọn òrìṣà láti sìn wọ́n, àti láti foríbalẹ̀ fún wọn, yóò sì dàbí àmùrè yìí tí kò wúlò fún ohunkóhun.
Ten zły lud, który się wzbrania słuchać moich słów, który postępuje według uporu swego serca i idzie za innymi bogami, aby im służyć i dać im pokłon, stanie się jak ten pas, który się do niczego nie nadaje.
11 Nítorí bí a ti lẹ àmùrè mọ́ ẹ̀gbẹ́ ènìyàn, bẹ́ẹ̀ ni a lẹ agbo ilé Israẹli àti gbogbo ilé Juda mọ́ mi,’ ni Olúwa wí, ‘kí wọn kí ó lè jẹ́ ènìyàn ògo àti ìyìn fún mi, ṣùgbọ́n wọn kò fẹ́ gbọ́.’
Jak bowiem pas przylega do bioder mężczyzny, tak sprawiłem, że przylgnął do mnie cały dom Izraela i cały dom Judy, mówi PAN, aby był moim ludem, moją sławą, chwałą i ozdobą. Lecz nie posłuchali.
12 “Sọ fún wọn, ‘Èyí ni Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ Israẹli wí, gbogbo ìgò ni à ó fi ọtí wáìnì kún.’ Bí wọ́n bá sì sọ fún ọ pé, ‘Ṣé a kò mọ̀ pé gbogbo ìgò ni ó yẹ láti bu ọtí wáìnì kún?’
Dlatego powiedz im to słowo: Tak mówi PAN, Bóg Izraela: Każdy dzban zostanie napełniony winem; a gdy powiedzą: Czyż nie wiemy, że wszelki dzban zostanie napełniony winem?
13 Nítorí náà sọ fún wọn pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí: Èmi yóò fi ìmutípara kún gbogbo olùgbé ilẹ̀ yìí pẹ̀lú ọba tí ó jókòó lórí ìtẹ́ Dafidi, àwọn àlùfáà, àwọn wòlíì gbogbo àwọn tó ń gbé ní Jerusalẹmu.
Wtedy im odpowiesz: Tak mówi PAN: Oto napełnię pijaństwem wszystkich mieszkańców tej ziemi i królów, którzy siedzą na tronie Dawida, i kapłanów oraz proroków, a także wszystkich mieszkańców Jerozolimy;
14 Èmi yóò ti èkínní lu èkejì, àwọn baba àti ọmọkùnrin pọ̀ ni Olúwa wí. Èmi kì yóò dáríjì, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò ṣàánú, èmi kì yóò ṣe ìyọ́nú láti máa pa wọ́n run.’”
I roztrzaskam jednych o drugich, zarówno ojców, jak i synów, mówi PAN. Nie pożałuję i nie oszczędzę nikogo ani nie zlituję się, lecz zniszczę ich.
15 Gbọ́ kí o sì fetísílẹ̀, ẹ má ṣe gbéraga, nítorí Olúwa ti sọ̀rọ̀.
Słuchajcie i nakłońcie ucha, nie wynoście się, bo PAN przemawia.
16 Ẹ fi ògo fún Olúwa Ọlọ́run yín, kí ó tó mú òkùnkùn wá, àti kí ó tó mú ẹsẹ̀ yín tàsé lórí òkè tí ó ṣókùnkùn. Nígbà tí ẹ̀yin sì ń retí ìmọ́lẹ̀, òun yóò sọ ọ́ di òjìji yóò sì ṣe bi òkùnkùn biribiri.
Oddajcie chwałę PANU, swemu Bogu, zanim sprowadzi ciemność i zanim potkną się wasze nogi w mrocznych górach; gdy będziecie czekać na światłość, oto [Bóg] zamieni je w cień śmierci [i] przemieni w mrok.
17 Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin kò bá fetísílẹ̀, Èmi yóò sọkún ní ìkọ̀kọ̀ nítorí ìgbéraga yín. Ojú mi yóò sun ẹkún kíkorò, tí omi ẹkún, yóò sì máa sàn jáde, nítorí a kó agbo Olúwa lọ ìgbèkùn.
A jeśli tego nie usłuchacie, moja dusza będzie płakać w skrytości z powodu [waszej] pychy, a moje oko będzie nieustannie płakało i roniło łzy, bo trzoda PANA zostanie pojmana.
18 Sọ fún ọba àti ayaba pé, “Ẹ rẹ ara yín sílẹ̀, ẹ sọ̀kalẹ̀ láti orí ìtẹ́ yín, adé ògo yín bọ́ sí ilẹ̀ láti orí yín.”
Powiedz królowi i królowej: Ukorzcie się i usiądźcie [na ziemi], bo spadła z waszej głowy korona waszej chwały.
19 Àwọn ìlú tí ó wà ní gúúsù ni à ó tì pa, kò sì ní sí ẹnikẹ́ni láti ṣí wọn. Gbogbo Juda ni a ó kó lọ sí ilẹ̀ ìgbèkùn, gbogbo wọn ni a ó kó lọ ní ìgbèkùn pátápátá.
Miasta południa będą zamknięte i nikt ich nie otworzy. Cała Juda zostanie uprowadzona do niewoli, zostanie całkowicie uprowadzona.
20 Gbé ojú rẹ sókè, kí o sì wo àwọn tí ó ń bọ̀ láti àríwá. Níbo ni agbo ẹran tí a fi sí abẹ́ àkóso rẹ wà; àgùntàn tí ò ń mú yangàn.
Podnieście swoje oczy i patrzcie na tych, którzy przybywają z północy. Gdzie jest ta trzoda, którą ci powierzono, twoja wspaniała trzoda?
21 Kí ni ìwọ yóò wí nígbà tí Olúwa bá dúró lórí rẹ àwọn tí o mú bí ọ̀rẹ́ àtàtà. Ǹjẹ́ kò ní jẹ́ ìrora fún ọ bí aboyún tó ń rọbí?
Co powiesz, gdy on cię nawiedzi? Ty bowiem nauczyłaś ich, [aby byli] wodzami i zwierzchnikami nad tobą. Czy nie ogarną cię bóle jak rodzącą kobietę?
22 Tí o bá sì bi ara rẹ léèrè, “Kí ni ìdí rẹ̀ tí èyí fi ṣẹlẹ̀ sí mi?” Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹ̀ṣẹ̀ tí o ṣẹ̀ ni aṣọ rẹ fi fàya tí a sì ṣe é ní ìṣekúṣe.
A jeśli powiesz w swoim sercu: Dlaczego to mnie spotkało? Z powodu ogromu twojej nieprawości poły twojej [szaty] zostały odkryte i twoje pięty będą gwałtownie obnażone.
23 Ǹjẹ́ Etiopia le yí àwọ̀ rẹ̀ padà? Tàbí ẹkùn lè yí àwọ̀ rẹ̀ padà? Bí èyí kò ti lè rí bẹ́ẹ̀ náà ni ẹ̀yin tí ìwà búburú bá ti mọ́ lára kò lè ṣe rere.
Czy Etiopczyk może zmienić swoją skórę albo lampart swoje pręgi? Podobnie wy, czy możecie czynić dobrze, skoro przywykliście czynić źle?
24 “N ó fọ́n ọn yín ká bí i ìyàngbò tí ẹ̀fúùfù ilẹ̀ aṣálẹ̀ ń fẹ́.
Dlatego rozproszę ich jak plewy unoszone przez wiatr pustynny.
25 Èyí ni ìpín tìrẹ; tí mo ti fi sílẹ̀ fún ọ,” ni Olúwa wí, “Nítorí ìwọ ti gbàgbé mi o sì gbẹ́kẹ̀lé àwọn ọlọ́run àjèjì.
Taki będzie twój los [i] dział wymierzony ci przeze mnie, mówi PAN, [za to], że o mnie zapomniałaś i zaufałaś kłamstwu.
26 N ó sí aṣọ lójú rẹ, kí ẹ̀sín rẹ le hàn síta—
Tak więc odkryję poły twojej [szaty] aż do twarzy, aby była widoczna twoja sromota.
27 ìwà àgbèrè àti ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́, àìlójútì panṣágà rẹ! Mo ti rí ìwà ìríra rẹ, lórí òkè àti ní pápá. Ègbé ni fún ọ ìwọ Jerusalẹmu! Yóò ti pẹ́ tó tí o ó fi máa wà ní àìmọ́?”
Widziałem twoje cudzołóstwa i twoje rżenie, hańbę twojego nierządu i twoje obrzydliwości na pagórkach i na polach. Biada tobie, Jerozolimo! Czy się nie oczyścisz? Jak długo jeszcze?

< Jeremiah 13 >