< Isaiah 60 >

1 “Dìde, tànmọ́lẹ̀, nítorí ìmọ́lẹ̀ rẹ ti dé, ògo Olúwa sì ràdàbò ọ́.
Powstań, zajaśniej, ponieważ przyszła twoja światłość i chwała PANA wzeszła nad tobą.
2 Kíyèsi i, òkùnkùn bo ilẹ̀ ayé òkùnkùn biribiri sì wà lórí àwọn ènìyàn, ṣùgbọ́n Olúwa ràn bò ọ́ ògo rẹ̀ sì farahàn lórí i rẹ.
Oto bowiem ciemność okryje ziemię i mrok – ludy, ale nad tobą wzejdzie PAN i jego chwała pojawi się nad tobą.
3 Àwọn orílẹ̀-èdè yóò wá sí ìmọ́lẹ̀ rẹ, àti àwọn ọba sí ìmọ́lẹ̀ òwúrọ̀ rẹ.
I pójdą narody do twojej światłości, a królowie do blasku twojego wschodu.
4 “Gbé ojú rẹ sókè, kí o sì wò. Gbogbo wọn ṣa ara jọ pọ̀, wọ́n sì wá sọ́dọ̀ rẹ; àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin yóò wá láti ọ̀nà jíjìn, àwọn ọmọ rẹ obìnrin ni a ó tọ́jú ní ẹ̀gbẹ́ rẹ.
Podnieś wokoło swe oczy i spójrz: ci wszyscy, którzy się zgromadzili, przyjdą do ciebie. Twoi synowie przyjdą z daleka i twoje córki będą wychowane przy twoim boku.
5 Nígbà náà ni ìwọ yóò wò tí ojú rẹ yóò máa dán, ọkàn rẹ yó fò, yó sì kún fún ayọ̀; ọrọ̀ inú Òkun ni a ó kò wá sọ́dọ̀ rẹ, sí ọ̀dọ̀ rẹ ni ọrọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè yóò wá.
Wtedy zobaczysz i rozweselisz się, twoje serce zadrży i rozszerzy się, gdyż nawróci się do ciebie tłum morski, a siły narodów przyjdą do ciebie.
6 Ọ̀wọ́ ìbákasẹ yóò bo gbogbo ilẹ̀ rẹ, àwọn ọ̀dọ́ ìbákasẹ Midiani àti Efani. Àti gbogbo wọn láti Ṣeba yóò wá, wọn yóò mú wúrà àti tùràrí lọ́wọ́ tí wọn yóò sì máa kéde ìyìn Olúwa.
Okryje cię mnóstwo wielbłądów, dromadery z Midianu i Efy. Przyjdą wszyscy z Szeby, przyniosą złoto i kadzidło i będą głosić chwałę PANA.
7 Gbogbo agbo ẹran ìlú Kedari ni a ó kójọ sọ́dọ̀ rẹ, àwọn àgbò ti Nebaioti yóò sìn ọ́; wọn yóò jẹ́ ọrẹ ìtẹ́wọ́gbà lórí i pẹpẹ mi, bẹ́ẹ̀ ni n ó sì ṣe tẹmpili ògo mi lọ́ṣọ̀ọ́.
Wszystkie stada Kedaru zgromadzą się u ciebie, barany Nebajotu będą ci służyć: wstąpią na mój ołtarz, gdzie będą przyjęte; i tak ozdobię dom mego majestatu.
8 “Ta ni àwọn wọ̀nyí tí ń fò lọ bí i kurukuru, gẹ́gẹ́ bí àwọn àdàbà sí ìtẹ́ wọn?
I powiesz: Kim są ci, co nadciągają jak obłoki i jak gołębie do swoich okien?
9 Lóòtítọ́ àwọn erékùṣù bojú wò mí; ní ìṣíwájú ni àwọn ọkọ̀ ojú omi Tarṣiṣi; mú àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ wá láti ọ̀nà jíjìn, pẹ̀lú fàdákà àti wúrà wọn, fún ti ọlá Olúwa Ọlọ́run rẹ, Ẹni Mímọ́ Israẹli, nítorí òun ti fi ohun dídára ṣe ó lọ́ṣọ̀ọ́.
Zaprawdę wyspy oczekują mnie, a na czele okręty Tarszisz, aby przyprowadzić twoich synów z daleka, a z nimi ich srebro i złoto, do imienia PANA, twego Boga, i do Świętego Izraela, bo cię uwielbił.
10 “Àwọn àjèjì yóò tún ògiri rẹ mọ àwọn ọba wọn yóò sì sìn ọ́. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ní ìbínú ni mo lù ọ́, ní àánú èmi yóò ṣe inú rere sí ọ.
Synowie cudzoziemców odbudują twoje mury i ich królowie będą ci służyć, gdyż w moim gniewie uderzyłem cię, a w mojej łaskawości zlitowałem się nad tobą.
11 Gbogbo ẹnu-bodè rẹ ni yóò wà ní ṣíṣí sílẹ̀, a kì yóò tì wọ́n ní ọ̀sán àti ní òru, tó bẹ́ẹ̀ tí àwọn ọkùnrin yóò le è kó ọrọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè wá tí àwọn ọba wọn yóò ṣáájú ní ọ̀wọ̀ọ̀wọ́ ìṣẹ́gun.
I twoje bramy będą nieustannie otwarte, nie będą zamknięte ani w dzień, ani w nocy, aby można było przyprowadzić do ciebie siły narodów, i aby ich królowie byli przyprowadzeni.
12 Nítorí pé orílẹ̀-èdè tàbí ilẹ̀ ọba tí kì yóò sìn ọ́ ni yóò parun; pátápátá ni yóò sì dahoro.
Ten naród i królestwo, które nie będą ci służyć, zginą. Takie narody właśnie zostaną do szczętu spustoszone.
13 “Ògo Lebanoni yóò wá sí ọ̀dọ̀ rẹ, igi junifa, firi àti sípírẹ́ṣì papọ̀, láti bu ọlá fún ilé ìsìn mi; àti pé èmi yóò sì ṣe ibi ẹsẹ̀ mi lógo.
Chwała Libanu przyjdzie do ciebie: razem cyprys, sosna oraz bukszpan, na ozdobę miejsca mojej świątyni. I wsławię miejsce moich nóg.
14 Àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin àwọn apọ́nilójú rẹ yóò wá foríbalẹ̀ fún ọ; gbogbo àwọn tí ó ti kẹ́gàn rẹ ni wọn yóò tẹríba níwájú rẹ wọn yóò sì pè ọ́ ní ìlú Olúwa, Sioni ti Ẹni Mímọ́ Israẹli.
Przyjdą też do ciebie w pokorze synowie tych, którzy cię trapili, i będą się kłaniać do twoich stóp wszyscy ci, którzy tobą wzgardzili. I nazwą cię Miastem PANA, Syjonem Świętego Izraela.
15 “Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a ti kórìíra rẹ, a sì kọ̀ ọ́ sílẹ̀, láìsí ẹnìkan tí ó ń gba ọ̀dọ̀ rẹ kọjá, Èmi yóò ṣe ọ́ ní ìṣògo ayérayé àti ayọ̀ àtìrandíran.
Za to, że byłaś opuszczona i znienawidzona tak, że nie było nikogo, kto by przez ciebie przechodził, uczynię cię wiecznym dostojeństwem, radością z pokolenia na pokolenie.
16 Ìwọ yóò mu wàrà gbogbo orílẹ̀-èdè a ó sì fun ọ́ ni ọmú àwọn ọba. Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ̀ pé, Èmi Olúwa, èmi ni Olùgbàlà rẹ, Olùdáǹdè rẹ, Alágbára ti Jakọbu.
Będziesz ssać mleko narodów i piersiami królów będziesz karmiona. I poznasz, że ja jestem PANEM, twoim Zbawicielem i twoim Odkupicielem, Mocarzem Jakuba.
17 Dípò idẹ, èmi ó mú wúrà wá fún ọ, dípò fàdákà èmi ó mú irin wá. Dípò igi yóò mú idẹ wá fún ọ, àti irin dípò òkúta. Èmi yóò fi àlàáfíà ṣe àwọn ìjòyè rẹ àti òdodo gẹ́gẹ́ bí alákòóso rẹ.
Zamiast miedzi naniosę złota, a zamiast żelaza naniosę srebra, zamiast drewna – miedzi, a zamiast kamieni – żelazo. Ustanowię nad tobą spokojnych zwierzchników i urzędników sprawiedliwych.
18 A kì yóò gbọ́ nípa rògbòdìyàn ní ilẹ̀ rẹ mọ́, tàbí ìdahoro àti ìparun nínú agbègbè rẹ, ṣùgbọ́n ìwọ yóò pe ògiri rẹ ní ìgbàlà àti àwọn ẹnu-bodè rẹ ní ìyìn.
Nie będzie więcej słychać o przemocy w twojej ziemi ani o spustoszeniu i zniszczeniu w twoich granicach; ale nazwiesz swoje mury Zbawieniem, a twoje bramy – Chwałą.
19 Òòrùn kì yóò sì jẹ́ ìmọ́lẹ̀ rẹ ní ọ̀sán mọ́, tàbí kí ìtànṣán òṣùpá tún ràn sí ọ mọ́, nítorí Olúwa ni yóò jẹ́ ìmọ́lẹ̀ rẹ ayérayé, àti Ọlọ́run rẹ yóò jẹ́ ògo rẹ.
Słońce nie będzie już twoją światłością za dnia ani księżyc już nie zaświeci ci swoim blaskiem; ale PAN będzie twoją wieczną światłością, a twój Bóg – twoją chwałą.
20 Òòrùn rẹ kì yóò sì wọ̀ mọ́, àti òṣùpá rẹ kì yóò sì wọ òòkùn mọ́; Olúwa ni yóò jẹ́ ìmọ́lẹ̀ ayérayé rẹ, àti àwọn ọjọ́ arò rẹ yóò sì dópin.
Nie zajdzie już więcej twoje słońce, a twój księżyc nie ukryje się, bo PAN będzie twoją wieczną światłością i skończą się dni twojej żałoby.
21 Lẹ́yìn náà ni gbogbo àwọn ènìyàn rẹ yóò di òdodo àwọn ni yóò sì jogún ilẹ̀ náà títí ayé. Àwọn ni irúgbìn tí mo ti gbìn, iṣẹ́ ọwọ́ mi, láti fi ọláńlá mi hàn.
Cały twój lud będzie sprawiedliwy. Odziedziczy ziemię na wieki, będzie latoroślą mego szczepu, dziełem moich rąk, abym był uwielbiony.
22 Èyí tí ó kéré jù nínú yín yóò di ẹgbẹ̀rún kan, èyí tí ó kéré yóò di orílẹ̀-èdè ńlá. Èmi ni Olúwa; ní àkókò rẹ̀, Èmi yóò ṣe èyí kánkán.”
Najmniejszy rozmnoży się tysiąckrotnie, a malutki – w naród potężny. Ja, PAN, dokonam tego rychło, w swoim czasie.

< Isaiah 60 >