< Isaiah 57 >

1 Olódodo ṣègbé kò sí ẹnìkan tí ó rò ó lọ́kàn ara rẹ̀; a mú àwọn ẹni mímọ́ lọ, kò sì ṣí ẹni tó yé pé a ti mú àwọn olódodo lọ láti yọ wọ́n kúrò nínú ibi.
Sprawiedliwy ginie, a nikt nie bierze sobie tego do serca. Ludzie pobożni odchodzą, a nikt nie zważa na to, że sprawiedliwy jest zabierany przed nadejściem zła.
2 Gbogbo àwọn tí ń rìn déédé ń wọ inú àlàáfíà; wọ́n rí ìsinmi bí wọ́n ti ń sùn nínú ikú.
Dostąpi pokoju i odpocznie na swoim łożu każdy, kto postępuje uczciwie.
3 “Ṣùgbọ́n ẹ súnmọ́ ìhìn-ín, ẹ̀yin ọmọ aláfọ̀ṣẹ, ẹ̀yin irú-ọmọ panṣágà àti àgbèrè!
Ale wy zbliżcie się tutaj, synowie czarownicy, potomstwo cudzołożnika i nierządnicy.
4 Ta ni ó fi ń ṣẹlẹ́yà? Ta ni o ń yọ ṣùtì sí tí o sì yọ ahọ́n síta? Ẹ̀yin kì í ha ṣe ọlọ̀tẹ̀ ènìyàn bí, àti ìran àwọn òpùrọ́?
Z kogo się naigrawacie? Na kogo rozdziawiacie usta i wywieszacie język? Czy nie jesteście synami nierządu, potomstwem fałszu;
5 Ẹ gbinájẹ fún ìṣekúṣe láàrín igi óákù àti lábẹ́ gbogbo igi tí ń gbilẹ̀; ẹ fi àwọn ọmọ yín rú ẹbọ nínú kòtò jíjìn àti lábẹ́ àwọn pàlàpálá òkúta.
[Wy], którzy uprawiacie nierząd z posągami pod każdym zielonym drzewem, zabijając swoje dzieci przy potokach, pod wysokimi skałami?
6 Àwọn ère tí ó wà ní àárín òkúta dídán wọ́n n nì, nínú kòtò jíjìn ni ìpín in yín; àwọ̀n ni ìpín in yín. Bẹ́ẹ̀ ni, sí wọn ni ẹ ti ta ọrẹ ohun mímu yín sílẹ̀ àti láti ta ọrẹ ìyẹ̀fun. Nítorí àwọn nǹkan wọ̀nyí, ǹjẹ́ ó yẹ kí n dáwọ́ dúró?
Wśród gładkich kamieni potoku jest twój dział. Właśnie one są twoim losem, na nie wylewasz ofiarę z płynów i ofiarowujesz ofiarę z pokarmów. Czyż w tym miałbym mieć upodobanie?
7 Ìwọ ti ṣe ibùsùn rẹ lórí òkè gíga tí ó rẹwà; níbẹ̀ ni ẹ lọ láti lọ ṣe ìrúbọ yín.
Na górze wysokiej i wyniosłej postawiłaś swoje łoże i tam wstępowałaś, aby składać ofiary.
8 Lẹ́yìn àwọn ìlẹ̀kùn yín àti òpó ìlẹ̀kùn yín níbẹ̀ ni ẹ fi àwọn àmì òrìṣà yín sí. Ní kíkọ̀ mí sílẹ̀, ẹ ṣí ibùsùn yín sílẹ̀, ẹ gun orí rẹ̀ lọ, ẹ sì ṣí i sílẹ̀ gbagada; ẹ ṣe àdéhùn pẹ̀lú àwọn tí ẹ fẹ́ràn ibùsùn wọn, ẹ̀yin sì ń wo ìhòhò wọn.
A za drzwiami i za odrzwiami postawiłaś swoją pamiątkę, gdyż odchodząc ode mnie, odkrywałaś się [innym], wstąpiłaś i rozszerzyłaś swoje łoże, czyniąc z nimi przymierze; kochałaś ich łoże w każdym miejscu, gdzie [je] widziałaś.
9 Ẹ̀yin lọ sí Moleki pẹ̀lú òróró olifi ẹ sì fi kún òórùn dídùn yín. Ẹ rán ikọ̀ yín lọ jìnnà réré; ẹ sọ̀kalẹ̀ sí ibojì pẹ̀lú! (Sheol h7585)
Chodziłaś także do króla z olejkiem i mnożyłaś swoje wonności; posłałaś daleko swoich posłańców, a poniżałaś się aż do grobu. (Sheol h7585)
10 Àwọn ọ̀nà yín gbogbo ti mú àárẹ̀ ba á yín, ṣùgbọ́n ẹ kò ní sọ pé, ‘Kò sí ìrètí mọ́?’ Ẹ rí okun kún agbára yín, nípa bẹ́ẹ̀ òòyì kò kọ́ ọ yín.
Zmęczyłaś się licznymi swymi drogami, ale nie powiedziałaś: Na próżno. Znalazłaś pomoc w swojej ręce, dlatego nie osłabłaś.
11 “Ta ni ó ń pá yín láyà tí ń bà yín lẹ́rù tí ẹ fi ń ṣèké sí mi, àti tí ẹ̀yin kò fi rántí mi tàbí kí ẹ rò yí nínú ọkàn yín? Ǹjẹ́ kì í ṣe nítorí dídákẹ́ jẹ́ẹ́ mi fún ìgbà pípẹ́ tí ẹ̀yin kò fi bẹ̀rù mi?
Kogo się bałaś i lękałaś, że skłamałaś, i nie pamiętałaś o mnie ani nie wzięłaś sobie tego do serca? Czy ja nie milczałem, i to od dawna, a ty mnie się nie boisz?
12 Èmi yóò ṣí òdodo yín páyà àti iṣẹ́ yín, wọn kì yóò sì ṣe yín ní àǹfààní.
Opowiem twoją sprawiedliwość i twoje uczynki, które nic ci nie pomogą.
13 Nígbà tí ẹ bá kígbe fún ìrànlọ́wọ́ ẹ jẹ́ kí àkójọ àwọn ère yín gbà yín! Atẹ́gùn yóò gbá gbogbo wọn lọ, èémí lásán làsàn ni yóò gbá wọn lọ. Ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá fi mí ṣe ààbò rẹ̀ ni yóò jogún ilẹ̀ náà yóò sì jogún òkè mímọ́ mi.”
Gdy zawołasz, niech wybawi cię twoja zgraja; ale wszystkich ich wiatr rozniesie i pochwyci marność. Lecz ten, który mi zaufa, odziedziczy ziemię i posiądzie moją świętą górę.
14 A ó sì sọ wí pé: “Tún mọ, tún mọ, tún ọ̀nà náà ṣe! Ẹ mú àwọn ohun ìkọ̀sẹ̀ kúrò ní ọ̀nà àwọn ènìyàn mi.”
I powiedzą: Wyrównajcie, wyrównajcie, przygotujcie drogę, usuńcie przeszkody z drogi mojego ludu.
15 Nítorí èyí ni ohun tí Ẹni gíga àti ọlọ́lá jùlọ wí ẹni tí ó wà títí láé, tí orúkọ rẹ̀ jẹ́ mímọ́: “Mo ń gbé ní ibi gíga àti ibi mímọ́, ṣùgbọ́n pẹ̀lú ẹni n nì tí ó ní ìròbìnújẹ́ àti ẹ̀mí ìrẹ̀lẹ̀, láti sọ ẹ̀mí onírẹ̀lẹ̀ náà jí àti láti sọ ẹ̀mí oníròbìnújẹ́ n nì jí.
Tak bowiem mówi Wysoki i Wyniosły, który zamieszkuje wieczność, którego imię to Święty: Ja, który mieszkam na wysokościach, na miejscu świętym, mieszkam i z tym, który jest skruszony i uniżony w duchu, aby ożywić ducha pokornych i ożywić serce skruszonych.
16 Èmi kì yóò fẹ̀sùn kan ni títí láé, tàbí kí n máa bínú sá á, nítorí nígbà náà ni ọkàn ènìyàn yóò rẹ̀wẹ̀sì níwájú mi èémí ènìyàn tí mo ti dá.
Nie będę się spierał na wieki ani nie będę wiecznie się gniewał, bo zemdlałby przede mną duch i dusze, które uczyniłem.
17 Inú bí mi nítorí ẹ̀ṣẹ̀ ọ̀kánjúwà rẹ̀; mo fìyà jẹ ẹ́, mo sì fojú mi pamọ́ ní ìbínú; síbẹ̀, ó tẹ̀síwájú nínú tinú-mi-ni n ó ṣe ọ̀nà rẹ̀.
Z powodu jego niegodziwej chciwości rozgniewałem się i uderzyłem go. Ukryłem się i rozgniewałem, on jednak był uparty i poszedł drogą swego serca.
18 Èmi ti rí ọ̀nà rẹ̀ gbogbo, ṣùgbọ́n Èmi yóò wò ó sàn; Èmi yóò tọ́ ọ ṣọ́nà n ó sì mú ìtùnú tọ̀ ọ́ wá,
Widziałem jego drogi, lecz uzdrowię go. Poprowadzę go i przywrócę mu pociechę, również tym, którzy z nim płaczą.
19 ní dídá ìyìn sí ètè àwọn tí ń ṣọ̀fọ̀ ní Israẹli. Àlàáfíà, àlàáfíà fún àwọn tí ó wà lókèèrè àti nítòsí,” ni Olúwa wí, “Àti pé, Èmi yóò wo wọ́n sàn.”
Stworzę owoc warg: Pokój, pokój dalekiemu i bliskiemu, mówi PAN; i tak uzdrowię go.
20 Ṣùgbọ́n àwọn ìkà dàbí i ríru Òkun tí kò le è sinmi, tí ìgbì rẹ̀ ń rú pẹ̀tẹ̀pẹ́tẹ̀ àti ẹrọ̀fọ̀ sókè.
Lecz bezbożni będą jak wzburzone morze niemogące się uspokoić, którego wody wyrzucają muł i błoto.
21 “Kò sí àlàáfíà fún àwọn ìkà,” ni Ọlọ́run mi wí.
Nie ma pokoju dla bezbożnych, mówi mój Bóg.

< Isaiah 57 >