< Isaiah 43 >

1 Ṣùgbọ́n ní ìsinsin yìí, ohun tí Olúwa wí nìyìí, ẹni tí ó dá ọ, ìwọ Jakọbu, ẹni tí ó mọ ọ́, ìwọ Israẹli: “Má bẹ̀rù, nítorí Èmi ti dá ọ nídè; Èmi ti pè ọ́ ní orúkọ; tèmi ni ìwọ ṣe.
Ale teraz tak mówi PAN, który cię stworzył, Jakubie, i który cię ukształtował, Izraelu: Nie bój się, bo cię odkupiłem i wezwałem cię po imieniu; jesteś mój.
2 Nígbà tí ìwọ bá ń la omi kọjá, Èmi yóò wà pẹ̀lú rẹ; àti nígbà tí ìwọ bá ń la odò kọjá wọn kì yóò bò ọ́ mọ́lẹ̀. Nígbà tí ìwọ bá la iná kọjá, kò ní jó ọ; ahọ́n iná kò ní jó ọ lára.
Gdy pójdziesz przez wody, będę z tobą, jeśli przez rzeki, one cię nie zaleją. Gdy pójdziesz przez ogień, nie spłoniesz i płomień cię nie spali.
3 Nítorí Èmi ni Olúwa Ọlọ́run rẹ, Ẹni Mímọ́ Israẹli Olùgbàlà rẹ; Èmi fi Ejibiti ṣe ìràpadà rẹ, Kuṣi àti Seba dípò rẹ.
Ja bowiem jestem PANEM, twoim Bogiem, Świętym Izraela, twoim Zbawicielem. Dałem Egipt na okup za ciebie, Etiopię i Sabę zamiast ciebie.
4 Nítorí pé o ṣe iyebíye àti ọ̀wọ́n níwájú mi, àti nítorí pé mo fẹ́ràn rẹ, Èmi yóò fi ènìyàn rọ́pò fún ọ, àti ènìyàn dípò ẹ̀mí rẹ.
Ponieważ jesteś w moich oczach drogi, jesteś uwielbiony, a ja cię umiłowałem – dlatego dałem ludzi za ciebie i narody za twoje życie.
5 Má bẹ̀rù nítorí èmi wà pẹ̀lú rẹ; Èmi yóò mú àwọn ọmọ rẹ láti ìlà-oòrùn wá èmi ó sì kó ọ jọ láti ìwọ̀-oòrùn.
Nie bój się, bo ja jestem z tobą; ze wschodu przyprowadzę twoje potomstwo i z zachodu cię zgromadzę.
6 Èmi yóò sọ fún àríwá pé, ‘Fi wọ́n sílẹ̀!’ Àti fún gúúsù, ‘Má ṣe dá wọn dúró.’ Mú àwọn ọmọkùnrin mi láti ọ̀nà jíjìn wá àti àwọn ọ̀dọ́mọbìnrin mi láti ìpẹ̀kun ilẹ̀ ayé—
Powiem północy: Oddaj; a południu: Nie zatrzymuj. Przyprowadź moich synów z daleka i moje córki z krańców ziemi;
7 ẹnikẹ́ni tí a ń pe orúkọ mi mọ́, tí mo dá fún ògo mi, tí mo mọ̀ àti tí mo ṣe.”
Każdego, kto nazywany jest moim imieniem i którego dla swojej chwały stworzyłem, ukształtowałem i uczyniłem.
8 Sin àwọn tí ó ní ojú ṣùgbọ́n tí wọ́n fọ́jú jáde, tí wọ́n ní etí ṣùgbọ́n tí wọn dití.
Wyprowadź lud ślepy, który już ma oczy, i głuchy, który już ma uszy.
9 Gbogbo orílẹ̀-èdè kó ra wọn jọ àwọn ènìyàn sì kó ra wọn papọ̀. Ta ni nínú wọn tó sọ àsọtẹ́lẹ̀ yìí tí ó sì kéde fún wa àwọn nǹkan ti tẹ́lẹ̀? Jẹ́ kí wọ́n mú àwọn ẹlẹ́rìí wọn wọlé wá láti fihàn pé wọ́n tọ̀nà tó bẹ́ẹ̀ tí àwọn mìíràn yóò gbọ́, tí wọn yóò sọ pé, “Òtítọ́ ni.”
Niech wszystkie narody zbiorą się razem i niech się zgromadzą ludy. Kto spośród nich może ogłosić i oznajmić nam przeszłe rzeczy? Niech postawią swoich świadków, a będą usprawiedliwieni; albo niech słyszą i powiedzą: To jest prawda!
10 “Ẹ̀yin ni ẹlẹ́rìí mi,” ni Olúwa wí, “Àti ìránṣẹ́ mi tí èmi ti yàn, tó bẹ́ẹ̀ tí ẹ̀yin yóò fi mọ̀ àti tí ẹ̀yin ó fi gbà mí gbọ́ tí yóò sì yé e yín pé èmi ni ẹni náà. Ṣáájú mi kò sí ọlọ́run tí a dá, tàbí a ó wa rí òmíràn lẹ́yìn mi.
Wy jesteście moimi świadkami, mówi PAN, i moim sługą, którego wybrałem, abyście poznali mnie i wierzyli mi, i zrozumieli, że to ja jestem. Przede mną nie został stworzony żaden Bóg ani po mnie nie będzie.
11 Èmi, àní Èmi, Èmi ni Olúwa, yàtọ̀ sí èmi, kò sí olùgbàlà mìíràn.
Ja, ja jestem PANEM i oprócz mnie nie ma zbawiciela.
12 Èmi ti fihàn, mo gbàlà mo sì ti kéde Èmi, kì í sì í ṣe àwọn àjèjì òrìṣà láàrín yín. Ẹ̀yin ni ẹlẹ́rìí mi,” ni Olúwa wí, “Pé Èmi ni Ọlọ́run.
Ja ogłaszałem, wybawiałem i opowiadałem, gdy nie było wśród was żadnego obcego [boga]. Wy jesteście moimi świadkami, mówi PAN, że ja jestem Bogiem.
13 Bẹ́ẹ̀ ni, àti láti ayérayé Èmi ni ẹni náà. Kò sí ẹnikẹ́ni tí ó lè gbà kúrò lọ́wọ́ mi. Nígbà tí mo bá ṣe nǹkan, ta ni ó lè yí i padà?”
Zanim powstał dzień, ja jestem, a nie ma nikogo, kto by wyrwał [cokolwiek] z mojej ręki. Gdy coś uczynię, któż to odwróci?
14 Èyí ni ohun tí Olúwa wí, olùràpadà rẹ, Ẹni Mímọ́ ti Israẹli: “Nítorí rẹ Èmi yóò ránṣẹ́ sí Babeli láti mú wọn sọ̀kalẹ̀ wá gẹ́gẹ́ bí ìsáǹsá, gbogbo ará Babeli, nínú ọkọ̀ ojú omi nínú èyí tí wọ́n fi ń ṣe ìgbéraga.
Tak mówi PAN, wasz Odkupiciel, Święty Izraela: Ze względu na was posłałem do Babilonu i zerwałem wszystkie rygle, i [powaliłem] Chaldejczyków, którzy się chlubią w swoich okrętach.
15 Èmi ni Olúwa, Ẹni Mímọ́ rẹ, Ẹlẹ́dàá Israẹli, ọba rẹ.”
Ja jestem PANEM, waszym Świętym, Stwórcą Izraela, waszym Królem.
16 Èyí ni ohun tí Olúwa wí, Ẹni náà tí ó la ọ̀nà nínú Òkun, ipa ọ̀nà láàrín alagbalúgbú omi,
Tak mówi PAN, który toruje drogę przez morze i ścieżkę przez potężne wody;
17 ẹni tí ó wọ́ àwọn kẹ̀kẹ́ àti ẹṣin jáde, àwọn jagunjagun àti ohun ìjà papọ̀, wọ́n sì sùn síbẹ̀, láìní lè dìde mọ́, wọ́n kú pirá bí òwú-fìtílà:
Który wyprowadza rydwany i konie, wojsko i siły; upadli razem, a nie powstaną: zgaśli, dotlili się jak knot.
18 “Gbàgbé àwọn ohun àtẹ̀yìnwá; má ṣe gbé nínú ohun àtijọ́.
Nie wspominajcie przeszłych rzeczy, na starodawne nie zważajcie.
19 Wò ó, Èmi ń ṣe ohun tuntun! Nísinsin yìí, ó ti yọ sókè; àbí o kò rí i bí? Èmi ń ṣe ọ̀nà kan nínú aṣálẹ̀ àti odò nínú ilẹ̀ ṣíṣá.
Oto ja czynię nową rzecz i zaraz się pojawi. Czy nie poznacie tego? Utoruję drogę na pustkowiu i [uczynię] rzeki na pustyni.
20 Àwọn ẹhànnà ẹranko bọ̀wọ̀ fún mi, àwọn ajáko àti àwọn òwìwí, nítorí pé mo pèsè omi nínú aṣálẹ̀ àti odò nínú ilẹ̀ sísá, láti fi ohun mímu fún àwọn ènìyàn mi, àyànfẹ́ mi,
Chwalić mnie będą zwierzęta polne, smoki i sowy, gdyż dostarczę wodę na pustkowie i [uczynię] rzeki na pustyni, aby napoić swój lud, swój lud wybrany.
21 àwọn ènìyàn tí mo dá fún ara mi kí wọn kí ó lè kéde ìyìn mi.
Ten lud, który dla siebie stworzyłem, będzie opowiadać moją chwałę.
22 “Síbẹ̀síbẹ̀ ìwọ kò tí ì ké pè mí, ìwọ Jakọbu, àárẹ̀ kò tí ì mú ọ nítorí mi ìwọ Israẹli.
A jednak ty nie wzywałeś mnie, Jakubie, lecz męczyłeś się mną, Izraelu.
23 Ìwọ kò tí ì mú àgùntàn wá fún mi fún ẹbọ sísun, tàbí kí o bọ̀wọ̀ fún mi pẹ̀lú ẹbọ rẹ. Èmi kò tí ì wàhálà rẹ pẹ̀lú ọrẹ ìyẹ̀fun tàbí kí n dààmú rẹ pẹ̀lú ìbéèrè fún tùràrí.
Nie przyniosłeś mi baranka na swoje całopalenie, nie czciłeś mnie swymi ofiarami. Nie zmuszałem cię do służenia [mi] ofiarami i nie obciążałem cię ofiarą kadzidła;
24 Ìwọ kò tí ì ra kalamusi olóòórùn dídùn fún mi, tàbí kí o da ọ̀rá ẹbọ rẹ bò mí. Ṣùgbọ́n ẹ ti wàhálà mi pẹ̀lú ẹ̀ṣẹ̀ yín ẹ sì ti dààmú mi pẹ̀lú àìṣedéédéé yín.
Nie kupiłeś mi za pieniądze wonności ani mnie nie nasyciłeś tłuszczem swoich ofiar. Ale obciążyłeś mnie swoimi grzechami i utrudziłeś mnie swoimi nieprawościami.
25 “Èmi, àní Èmi, Èmi ni ẹni tí ó wẹ àwọn àìṣedéédéé rẹ nù, nítorí èmi fún ara mi, tí n kò sì rántí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ mọ́.
Ja, właśnie ja, zmazuję twoje przestępstwa ze względu na siebie, a twoich grzechów nie wspomnę.
26 Bojú wo ẹ̀yìn rẹ fún mi, jẹ́ kí a jọ ṣe àríyànjiyàn ọ̀rọ̀ náà papọ̀; ro ẹjọ́ láti fihàn pé o kò lẹ́sẹ̀ lọ́rùn.
Przypomnij mi, rozprawmy się ze sobą, powiedz, co masz na swoje usprawiedliwienie.
27 Baba yín àkọ́kọ́ dẹ́ṣẹ̀; àwọn agbẹnusọ yín ṣọ̀tẹ̀ sí mi.
Twój pierwszy ojciec zgrzeszył, a twoi nauczyciele wykroczyli przeciwko mnie.
28 Nítorí náà, èmi ti sọ àwọn olórí ibi mímọ́ náà di àìmọ́, bẹ́ẹ̀ ni èmi ti fi Jakọbu fún ègún àti Israẹli fún ẹ̀gàn.
Dlatego zhańbiłem książąt świątyni i wydałem Jakuba klątwie, a Izraela zniewagom.

< Isaiah 43 >