< Isaiah 34 >

1 Súnmọ́ tòsí, ẹ̀yin orílẹ̀-èdè láti gbọ́, tẹ́tí sílẹ̀ ẹ̀yin ènìyàn jẹ́ kí ayé gbọ́, àti ẹ̀kún rẹ̀, ayé àti ohun gbogbo tí ó ti inú rẹ̀ jáde.
Zbliżcie się, narody, aby słuchać, i wy, ludy, słuchajcie uważnie! Niech słucha ziemia i to, co ją napełnia, świat i wszystko, co się na nim rodzi.
2 Nítorí ìbínú Olúwa ń bẹ lára gbogbo orílẹ̀-èdè, àti ìrunú rẹ̀ lórí gbogbo ogun wọn: o ti fi wọ́n fún pípa.
Bo oburzenie PANA spadło na wszystkie narody, jego zapalczywość – na wszystkie ich wojska. Wytracił je doszczętnie, wydał je na rzeź.
3 Àwọn ti a pa nínú wọn ni a ó sì jù sóde, òórùn wọn yóò ti inú òkú wọn jáde, àwọn òkè ńlá yóò sì yọ̀ nínú ẹ̀jẹ̀ wọn.
Ich zabici będą porzuceni, a z ich trupów będzie unosił się smród i ich krew z gór popłynie.
4 Gbogbo àwọn ogun ọ̀run ni yóò di yíyọ́, a ó sì ká àwọn ọ̀run jọ bí i tákàdá, gbogbo ogun wọn yóò si ṣubú lulẹ̀, bí ewé ti n bọ́ kúrò lára àjàrà, àti bí i bíbọ́ èso lára igi ọ̀pọ̀tọ́.
Cały zastęp niebios stopnieje, a niebiosa jak zwój zostaną zwinięte, całe ich zastępy opadną, jak opada liść z winorośli i jak opada niedojrzały owoc z drzewa figowego.
5 Nítorí ti a rẹ idà mi ní ọ̀run, kíyèsi í, yóò sọ̀kalẹ̀ wá sórí Edomu, sórí àwọn ènìyàn tí mo ti parun fún ìdájọ́.
Mój miecz bowiem nasyci się na niebie. Oto spadnie na Edom i na lud, który przekląłem, na sąd.
6 Idà Olúwa kún fún ẹ̀jẹ̀ a mú un sanra fún ọ̀rá, àti fún ẹ̀jẹ̀ ọ̀dọ́-àgùntàn àti ewúrẹ́, fún ọ̀rá ìwé àgbò— nítorí Olúwa ni ìrúbọ kan ní Bosra, àti ìpakúpa ńlá kan ní ilẹ̀ Edomu.
Miecz PANA jest pełny krwi, pokrył się tłuszczem i krwią baranków i kozłów, tłuszczem nerek baranich, bo ofiara PANA dokonuje się w Bosra, a wielka rzeź w ziemi Edom.
7 Àti àwọn àgbáǹréré yóò ba wọn sọ̀kalẹ̀ wá, àti àwọn ẹgbọrọ màlúù pẹ̀lú àwọn akọ màlúù, ilé wọn ni a ó fi ẹ̀jẹ̀ rin, a ó sì fi ọ̀rá sọ ekuru wọn di ọlọ́ràá.
Zstąpią z nimi jednorożce i byki z wołami, ich ziemia nasiąknie krwią, a ich proch nasyci się tłuszczem.
8 Nítorí ọjọ́ ẹ̀san Olúwa ni, àti ọdún ìsanpadà, nítorí ọ̀ràn Sioni.
To jest bowiem dzień pomsty PANA i rok odpłaty za spór z Syjonem.
9 Odò rẹ̀ ni a ó sì sọ di ọ̀dà, àti eruku rẹ̀ di imí-ọjọ́, ilẹ̀ rẹ̀ yóò sì di ọ̀dà tí ń jóná.
Potoki obrócą się w smołę, a proch w siarkę, jego ziemia stanie się smołą płonącą.
10 A kì yóò pa á ní òru tàbí ní ọ̀sán; èéfín rẹ̀ yóò gòkè láéláé: yóò dahoro láti ìran dé ìran, kò sí ẹnìkan tí yóò là á kọjá láé àti láéláé.
Nie zagaśnie ani w nocy, ani w dzień, jej dym będzie się unosił na wieki. Z pokolenia na pokolenie będzie pustkowiem; na wieki wieków nikt przez nią nie przejdzie.
11 Òwìwí aginjù, àti àkàlà ni yóò ni ín, àti òwìwí àti ẹyẹ ìwò ni yóò máa gbé inú rẹ̀. Ọlọ́run yóò sì na sórí Edomu okùn ìwọ̀n ìparun àti òkúta òfo.
Ale pelikan i bąk ją posiądą, a sowa i kruk w niej zamieszkają. Rozciągnie on nad nią sznur spustoszenia i próżne wagi.
12 Ní ti àwọn ìjòyè rẹ̀ ẹnìkan kì yóò sí níbẹ̀ tiwọn ó pè wá sí ìjọba, gbogbo àwọn olórí i rẹ̀ yóò sì di asán.
Wezwą jej szlachtę na królestwo, ale nie będzie tam żadnego, a wszyscy jej książęta obrócą się wniwecz.
13 Ẹ̀gún yóò sì hù jáde nínú àwọn ààfin rẹ̀ wọ̀nyí, ẹ̀gún ọ̀gán nínú ìlú olódi rẹ̀. Yóò jẹ́ ibùgbé àwọn akátá àti àgbàlá fún àwọn òwìwí.
W ich pałacach wyrosną ciernie, w ich zamkach – pokrzywy i osty. Będzie siedliskiem smoków i dziedzińcem dla strusiów.
14 Àwọn ẹranko ijù àti àwọn ìkookò ni yóò pàdé, àti ewúrẹ́ igbó kan yóò máa kọ sí èkejì rẹ̀, iwin yóò máa gbé ibẹ̀ pẹ̀lú, yóò sì rí ibi ìsinmi fún ara rẹ̀.
Tam będą się spotykać dzikie zwierzęta pustyni ze strasznymi bestiami wysp, a kozice będą się nawoływać; tam leżeć będzie płomykówka i znajdzie dla siebie odpoczynek.
15 Òwìwí yóò tẹ́ ìtẹ́ rẹ̀ síbẹ̀, yóò yé, yóò sì pa, yóò sì kójọ lábẹ́ òjìji rẹ̀: àwọn gúnnugún yóò péjọ síbẹ̀ pẹ̀lú, olúkúlùkù pẹ̀lú ẹnìkejì rẹ̀.
Tam sowa się zagnieździ, zniesie jajka, wyleży [młode] i zbierze je w swoim cieniu. Tam też zlecą się sępy, jeden z drugim.
16 Ẹ wo ìwé Olúwa, kí ẹ sì kà. Ọ̀kan nínú ìwọ̀nyí kì yóò yẹ̀, kò sí ọ̀kan tí yóò fẹ́ èkejì rẹ̀ kù: nítorí Olúwa ti pàṣẹ ẹnu rẹ̀ ló sì fi kó wọn jọ Ẹ̀mí rẹ̀ ló sì fi tò wọ́n jọ.
Szukajcie w księdze PANA i czytajcie. Ani jedno z nich nie przepadnie, żadne z nich nie będzie bez drugiego, bo usta PANA to rozkazały, a jego Duch je zgromadził.
17 Ó ti di ìbò fún wọn, ọwọ́ rẹ̀ sì ti pín in fún wọn nípa títa okùn, wọn ó jogún rẹ̀ láéláé, láti ìran dé ìran ni wọn ó máa gbé inú rẹ̀.
On też rzucił dla nich los i jego ręka wydzieliła im [to] sznurem mierniczym. Posiadać ją będą na wieki, będą w niej mieszkać z pokolenia na pokolenie.

< Isaiah 34 >