< Isaiah 24 >

1 Kíyèsi i, Olúwa yóò sọ ohun gbogbo dòfo ní ilẹ̀ ayé yóò sì pa á run òun yóò pa ojú u rẹ̀ rẹ́ yóò sì fọ́n àwọn olùgbé ibẹ̀ káàkiri—
Some day, Yahweh is going to destroy everything on the earth. He will devastate it and cause it to become a desert and scatter its people.
2 bákan náà ni yóò sì rí fún àlùfáà àti àwọn ènìyàn, fún ọ̀gá àti ọmọ ọ̀dọ̀, fún ìyá-ilé àti ọmọbìnrin, fún olùtà àti olùrà, fún ayáni àti atọrọ fún ayánilówó àti onígbèsè.
He will scatter everyone— priests and common people, servants and their masters, maids and their mistresses, buyers and sellers, lenders and borrowers, people who owe money and people who are owed money.
3 Ilé ayé ni a ó sọ di ahoro pátápátá a ó sì jẹ gbogbo rẹ̀ run. Olúwa ni ó ti sọ ọ̀rọ̀ yìí.
Nothing that is worth anything will be left on earth; everything valuable will be destroyed. [That will surely happen because] Yahweh has said it.
4 Ilẹ̀ ayé ti gbẹ ó sì sá, ayé ń ṣòjòjò, àárẹ̀ mú un, àwọn ẹni gíga ilẹ̀ ayé wà nínú ìpọ́njú
[Everything on] the earth will dry up and die [DOU]; its important people will become weak and unimportant.
5 àwọn ènìyàn ayé ti bà á jẹ́; wọ́n ti pa àwọn òfin run wọ́n ṣe lòdì sí àwọn ìlànà wọ́n sì ti ba májẹ̀mú ayérayé jẹ́.
The earth has become unacceptable to Yahweh because the people who live on it have disobeyed his laws; they have rejected the agreement that he intended to last forever.
6 Nítorí náà, ègún kan ti jẹ ayé run; àwọn ènìyàn rẹ̀ ní láti ru ẹ̀bi wọn. Nítorí náà, àwọn olùgbé ayé ti gbiná dànù, àwọn ẹ̀tàhóró ló sì kù.
Therefore, [Yahweh] will curse the earth; the people who live on it must be punished because of the sins that they have committed. They will be destroyed by fire, and [only a] few people will remain [alive].
7 Wáìnì tuntun ti gbẹ, àjàrà sì ti rọ, gbogbo àwọn aláríyá sì kérora.
The grapevines will wither, and there will be no [grapes to make] wine. All [the people] who were previously happy will then groan and mourn.
8 Àríyá ti ṣaworo ti dákẹ́ ariwo àwọn tí ń ṣàjọyọ̀ ti dáwọ́ dúró ayọ̀ dùùrù ti dákẹ́ jẹ́ẹ́.
People will no longer play cheerful songs with tambourines, people will no longer play joyfully on their harps, and people will no longer shout noisily [during their celebrations].
9 Kò ṣe é ṣe fún wọn láti máa mu wáìnì pẹ̀lú orin kíkọ mọ́ ọtí líle ti di ìkorò fún àwọn ọ̀mu.
People will no longer sing while they drink wine, and [all] their alcoholic drinks will taste bitter.
10 Ìlú tí a run ti dahoro, ẹnu-ọ̀nà àbáwọlé kọ̀ọ̀kan ni a dí pa.
[Towns and] cities will be desolate; every house will be locked to prevent thieves from entering.
11 Ní òpópónà ni wọ́n ti ń kígbe fún wáìnì gbogbo ayọ̀ ọ wọn ti di ìbànújẹ́, gbogbo àríyá ni a lé kúrò lórí ilẹ̀ ayé.
[Mobs] will gather in the streets, wanting wine; no one on the earth will be happy [DOU] any more.
12 Ìlú ni a ti fi sílẹ̀ ní ahoro, ìlẹ̀kùn rẹ̀ ni a sì tì pa bámú bámú.
Cities will be ruined and [all] their gates will be battered/broken into pieces.
13 Bẹ́ẹ̀ ni yóò sì rí ní orí ilẹ̀ ayé àti láàrín àwọn orílẹ̀-èdè pẹ̀lú, gẹ́gẹ́ bí ìgbà tí a lu igi olifi, tàbí gẹ́gẹ́ bí i pàǹtí tí ó ṣẹ́kù lẹ́yìn tí a kórè èso tán.
It will be like that all over the earth: [there will only be a few people still alive], like what happens when [workers] beat all the olives off a tree [and there are only a few left], [or] when they harvest the grapes and there are only a few left [on the vines].
14 Wọ́n gbé ohùn wọn sókè, wọ́n sì hó fún ayọ̀; láti ìwọ̀-oòrùn ni wọn yóò ti polongo ọláńlá Olúwa.
But [those who are left alive] will sing joyfully; people [in nations] to the west [of Israel] will declare that Yahweh is very great;
15 Nítorí náà ní ìlà-oòrùn ẹ fi ògo fún Olúwa; gbé orúkọ Olúwa ga, àní Ọlọ́run Israẹli, ní àwọn erékùṣù ti inú Òkun.
people in nations to the east [of Israel will also] praise Yahweh [MTY]; in countries across the sea, people will praise Yahweh, the God whom we Israelis [worship].
16 Láti òpin ayé wá ni a ti gbọ́ orin; “Ògo ni fún olódodo n nì.” Ṣùgbọ́n mo wí pé, “Mo ṣègbé, mo ṣègbé! “Ègbé ni fún mi! Alárékérekè dalẹ̀! Pẹ̀lú ìhàlẹ̀ ni àgàbàgebè fi dalẹ̀!”
We will hear [people] in the most distant places on the earth singing praise to [Yahweh], the [truly] righteous one. But [now], I am [SYN] very sad. Weep for me, [because] I have become thin and weak. Terrible things are happening! Treacherous [people still] betray/deceive others everywhere [DOU].
17 Ìpayà, isà òkú, àti ìdẹ̀kùn ń dúró dè ọ́, ìwọ ènìyàn ilẹ̀ ayé.
You people all over the earth, you will be terrified, and you will fall into deep pits and traps/snares.
18 Ẹnikẹ́ni tí ó bá sá nítorí ariwo ìpayà yóò ṣubú sínú ihò, ẹnikẹ́ni tí ó bá sì yọ́ jáde nínú ihò ni ìdẹ̀kùn yóò gbámú. Ibodè ọ̀run ti wà ní ṣíṣí sílẹ̀, ìpìlẹ̀ ayé mì tìtì.
Those who [try to] flee because they are terrified will fall into [deep] pits, and those who climb out of the pits will be caught by traps/snares. The sky will split open and torrents [SIM] [of rain will fall]; the foundations of the earth will shake.
19 Ilẹ̀ ayé ti fọ́ ilẹ̀ ayé ti fọ́ dànù, a ti mi ilẹ̀ ayé rìrìrìrì.
The earth will split apart and be shattered; it will shake violently.
20 Ilẹ̀ ayé yí gbiri bí ọ̀mùtí, ó bì síwá sẹ́yìn bí ahéré nínú afẹ́fẹ́; ẹ̀bi ìṣọ̀tẹ̀ rẹ̀ ń pa á lẹ́rù tó bẹ́ẹ̀ tí ó fi ṣubú láìní lè dìde mọ́.
[It will be as though] the earth will stagger like [SIM] a drunk; it will shake like [SIM] a hut [shakes in a windstorm]. It will collapse and not [be able to] rise again, [because] the guilt of the people who rebel [against Yahweh] is very great.
21 Ní ọjọ́ náà ni Olúwa yóò jẹ ẹ́ ní yà gbogbo agbára tí ó wà lókè lọ́run àti àwọn ọba tí ó wà lórí ilẹ̀ ayé.
At that time, Yahweh will punish the [wicked] powerful beings in the skies and the wicked kings on the earth.
22 A ó sì kó wọn jọ pọ̀, gẹ́gẹ́ bí ará túbú jọ sínú ihò, a ó tì wọ́n mọ́ inú túbú, a ó sì bẹ̀ wọ́n wò lẹ́yìn ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọjọ́.
They will [all] be gathered together and thrown into a dungeon/pit. They will be shut/locked in that dungeon/pit, and later they will be punished.
23 A ó rẹ òṣùpá sílẹ̀, ojú yóò sì ti oòrùn; nítorí Olúwa àwọn ọmọ-ogun yóò jẹ ọba ní orí òkè Sioni àti ní Jerusalẹmu, àti níwájú àwọn àgbàgbà rẹ ní ògo.
At that time the light of the moon and the sun will be lessened; [it will be as though] they are ashamed [in the presence of] Yahweh, because he, the Commander of the armies of angels, will rule gloriously (on Zion Hill/in Jerusalem), in the presence of the leaders [of his people].

< Isaiah 24 >