< Genesis 33 >

1 Jakọbu sì gbójú sókè, ó sì rí Esau àti irinwó ọkùnrin tí wọ́n ń bọ̀, ó sì pín àwọn ọmọ fún Lea, Rakeli àti àwọn ìránṣẹ́bìnrin méjèèjì.
Potem Jakub podniósł oczy i zobaczył, że Ezaw nadchodzi, a z nim czterystu mężczyzn. Podzielił więc dzieci między Leę, Rachelę a dwie służące.
2 Ó sì ti àwọn ìránṣẹ́bìnrin àti àwọn ọmọ wọn síwájú, Lea àti àwọn ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọ̀wọ́ kejì tí ó tẹ̀lé wọn, Rakeli àti Josẹfu sì wà lẹ́yìn pátápátá.
I postawił na przodzie służące i ich dzieci, za nimi Leę i jej dzieci, a na końcu Rachelę z Józefem.
3 Jakọbu fúnra rẹ̀ wa lọ síwájú pátápátá, ó sì tẹríba ní ìgbà méje bí ó ti ń súnmọ́ Esau, arákùnrin rẹ̀.
Sam zaś wyszedł przed nich i pokłonił się siedem razy aż do ziemi, zanim doszedł do swego brata.
4 Ṣùgbọ́n Esau sáré pàdé Jakọbu, ó sì dì mọ́ ọn, ó rọ̀ mọ́ ọn lọ́rùn, ó sì fẹnukò ó lẹ́nu. Àwọn méjèèjì sì sọkún.
Ale Ezaw wybiegł mu naprzeciw, objął go, rzucił mu się na szyję i całował go. I płakali.
5 Nígbà tí Esau sì ṣe àkíyèsí àwọn ìyàwó àti ọmọ Jakọbu, ó béèrè lọ́wọ́ Jakọbu pé, “Ti ta ni àwọn wọ̀nyí?” Jakọbu sì fèsì wí pé, “Èyí ni àwọn ọmọ tí Ọlọ́run nínú àánú rẹ̀ ti fi fún ìránṣẹ́ rẹ.”
Potem podniósł oczy, zobaczył żony i dzieci i zapytał: [A] kim [są] ci przy tobie? I odpowiedział: [To są] dzieci, które Bóg w swej łaskawości dał twemu słudze.
6 Nígbà náà ni àwọn ìránṣẹ́bìnrin àti àwọn ọmọ wọn súnmọ́ tòsí, wọ́n sì tẹríba.
Wtedy przybliżyły się służące ze swoimi dziećmi i pokłoniły się.
7 Lẹ́yìn náà ni Lea àti àwọn ọmọ rẹ̀ pẹ̀lú dé, wọ́n sì tún tẹríba. Ní ìkẹyìn ni Josẹfu àti Rakeli dé, wọ́n sì tún tẹríba pẹ̀lú.
Przybliżyła się też Lea ze swoimi dziećmi i pokłoniły się. Potem przybliżyli się Józef i Rachela i pokłonili się.
8 Esau sì béèrè pé, “Kí ni èrò rẹ tí o fi to àwọn ọ̀wọ̀ọ̀wọ́ tí mo pàdé wọ̀nyí?” Jakọbu dáhùn pé, “Kí n ba le rí ojúrere rẹ ni olúwa mi.”
I [Ezaw] zapytał: Co znaczy cały ten obóz, z którym się spotkałem? [Jakub] odpowiedział: Abym znalazł łaskę w oczach mego pana.
9 Ṣùgbọ́n Esau wí pé, “Tèmi ti tó mi, pa èyí tí o ní mọ́ fún ara rẹ.”
Wtedy Ezaw powiedział: Ja mam dosyć, mój bracie, zatrzymaj to, co twoje.
10 Jakọbu bẹ̀ ẹ́ wí pé, “Rárá bẹ́ẹ̀ kọ́, bí ó bá ṣe pé, mo rí ojúrere rẹ, jọ̀wọ́ gba ọrẹ lọ́wọ́ mi. Bí mo ṣe rí ojú rẹ̀ yìí, ó dàbí wí pé mo rí ojú Ọlọ́run ni báyìí, tí inú rẹ̀ ti dùn sí mi.
I Jakub powiedział: Nie, proszę, jeśli znalazłem teraz łaskę w twoich oczach, przyjmij dar z mojej ręki, bo gdy zobaczyłem twoje oblicze, to jakbym widział oblicze Boga, i ty łaskawie mnie przyjąłeś.
11 Jọ̀wọ́ gba àwọn ohun tí mo mú wá wọ̀nyí lọ́wọ́ mi. Nítorí Ọlọ́run ti fi oore-ọ̀fẹ́ rẹ̀ hàn sí mi, gbogbo ohun tí mo fẹ́ sì ni mo ní.” Nígbà tí Jakọbu sì rọ̀ ọ́ pé Esau gbọdọ̀ gbà wọ́n, Esau sì gbà á.
Przyjmij, proszę, mój dar, który ci przyniosłem, bo Bóg hojnie mi błogosławił, a mam dość wszystkiego. I tak nalegał na niego, że to przyjął.
12 Nígbà náà ni Esau wí pé, “Jẹ́ kí a máa lọ, n ó sìn ọ.”
[Ezaw] powiedział: Ruszajmy w drogę i chodźmy, a ja pójdę przed tobą.
13 Ṣùgbọ́n Jakọbu wí fún un pé, “Ṣe ìwọ náà ṣe àkíyèsí pé ọ̀pọ̀ nínú àwọn ọmọ wọ̀nyí kéré, àwọn màlúù àti àgùntàn pẹ̀lú sì ní àwọn ọmọ kéékèèké. Bí a bá dà wọ́n rìn jìnnà ju bí agbára wọn ṣe mọ lọ, wọ́n lè kú.
I [Jakub] mu odpowiedział: Mój pan wie, że mam ze sobą dzieci wątłe, a owce i krowy karmią młode. Jeśli popędzi się je przez cały dzień, zginie całe stado.
14 Èmi bẹ̀ ọ́, máa lọ síwájú ìránṣẹ́ rẹ, àwọn ó sì máa rọra bọ̀, títí èmi àti àwọn ọmọ yóò fi dé ọ̀dọ̀ olúwa mi ní Seiri.”
Niech mój pan, proszę, idzie przed swoim sługą, a ja będę szedł powoli, jak nadąży stado, które jest przede mną, i jak nadążą dzieci, aż przyjdę do mego pana do Seiru.
15 Esau wí pé, “Jẹ́ kí n fi díẹ̀ sílẹ̀ fún ọ nínú àwọn ọkùnrin mi nígbà náà.” Jakọbu wí pé, “Èéṣe, àní kí n sá à rí ojúrere olúwa mi?”
Wtedy Ezaw powiedział: Zostawię więc przy tobie [część] ludzi, którzy są ze mną. A on odpowiedział: A na cóż to? Obym znalazł łaskę w oczach mego pana.
16 Ní ọjọ́ náà gan an ni Esau padà lọ sí Seiri.
I tego dnia Ezaw wrócił swą drogą do Seiru.
17 Jakọbu sì lọ sí Sukkoti, ó sì kọ́ ilé fún ara rẹ̀, ó sì ṣe ọgbà fún àwọn ẹran. Ìdí èyí ní a fi ń pe ibẹ̀ ní Sukkoti.
A Jakub wyruszył do Sukkot i zbudował sobie dom, i zrobił szałasy dla swoich stad. Dlatego nazwał to miejsce Sukkot.
18 Lẹ́yìn ìgbà tí Jakọbu tí Padani-Aramu dé, àlàáfíà ni Jakọbu dé ìlú Ṣekemu ní ilẹ̀ Kenaani, ó sì pàgọ́ sí itòsí ìlú náà.
I Jakub przyszedł szczęśliwie do miasta Sychem, które było w ziemi Kanaan, gdy wrócił z Paddan-Aram, i rozbił obóz przed miastem.
19 Ó sì ra ilẹ̀ kan tí ó pàgọ́ sí ni ọgọ́rùn-ún owó fàdákà lọ́wọ́ àwọn ọmọ Hamori tí í ṣe baba Ṣekemu.
I za sto monet kupił od synów Hemora, ojca Sychema, część pola, na którym rozbił swój namiot.
20 Níbẹ̀ ni ó gbé tẹ́ pẹpẹ kan tí ó pè ní El Elohe Israẹli.
Tam też postawił ołtarz i nazwał go: Mocny Bóg Izraela.

< Genesis 33 >