< Genesis 33 >

1 Jakọbu sì gbójú sókè, ó sì rí Esau àti irinwó ọkùnrin tí wọ́n ń bọ̀, ó sì pín àwọn ọmọ fún Lea, Rakeli àti àwọn ìránṣẹ́bìnrin méjèèjì.
Iacob lyfte vp his eyes and sawe hys brother Esau come and with him. iiij. hundred men. And he deuyded the childern vnto Lea and vnto Rahel and vnto ye ij. maydens.
2 Ó sì ti àwọn ìránṣẹ́bìnrin àti àwọn ọmọ wọn síwájú, Lea àti àwọn ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọ̀wọ́ kejì tí ó tẹ̀lé wọn, Rakeli àti Josẹfu sì wà lẹ́yìn pátápátá.
And he put the maydens ad their childern formest ad Lea and hir childern after and Rahel ad Ioseph hindermost.
3 Jakọbu fúnra rẹ̀ wa lọ síwájú pátápátá, ó sì tẹríba ní ìgbà méje bí ó ti ń súnmọ́ Esau, arákùnrin rẹ̀.
And he went before them and fell on the grownde, vij. tymes vntill he came vnto his brother.
4 Ṣùgbọ́n Esau sáré pàdé Jakọbu, ó sì dì mọ́ ọn, ó rọ̀ mọ́ ọn lọ́rùn, ó sì fẹnukò ó lẹ́nu. Àwọn méjèèjì sì sọkún.
Esau ranne agaynst him and enbraced hym and fell on his necke and kyssed him and they wepte.
5 Nígbà tí Esau sì ṣe àkíyèsí àwọn ìyàwó àti ọmọ Jakọbu, ó béèrè lọ́wọ́ Jakọbu pé, “Ti ta ni àwọn wọ̀nyí?” Jakọbu sì fèsì wí pé, “Èyí ni àwọn ọmọ tí Ọlọ́run nínú àánú rẹ̀ ti fi fún ìránṣẹ́ rẹ.”
And he lifte vp his eyes and sawe the wyves and their childern and sayde: what are these which thou there hast? And he sayde: they are the childern which God hath geuen thy seruaunte.
6 Nígbà náà ni àwọn ìránṣẹ́bìnrin àti àwọn ọmọ wọn súnmọ́ tòsí, wọ́n sì tẹríba.
Than came the maydens forth ad dyd their obaysaunce.
7 Lẹ́yìn náà ni Lea àti àwọn ọmọ rẹ̀ pẹ̀lú dé, wọ́n sì tún tẹríba. Ní ìkẹyìn ni Josẹfu àti Rakeli dé, wọ́n sì tún tẹríba pẹ̀lú.
Lea also and hir childern came and dyd their obaysaunce. And last of all came Ioseph and Rahel and dyd their obaysaunce.
8 Esau sì béèrè pé, “Kí ni èrò rẹ tí o fi to àwọn ọ̀wọ̀ọ̀wọ́ tí mo pàdé wọ̀nyí?” Jakọbu dáhùn pé, “Kí n ba le rí ojúrere rẹ ni olúwa mi.”
And he sayde: what meanyst thou with all ye drooues which I mett. And he answered: to fynde grace in the syghte of my lorde.
9 Ṣùgbọ́n Esau wí pé, “Tèmi ti tó mi, pa èyí tí o ní mọ́ fún ara rẹ.”
And Esau sayde: I haue ynough my brother kepe that thou hast vnto thy silf.
10 Jakọbu bẹ̀ ẹ́ wí pé, “Rárá bẹ́ẹ̀ kọ́, bí ó bá ṣe pé, mo rí ojúrere rẹ, jọ̀wọ́ gba ọrẹ lọ́wọ́ mi. Bí mo ṣe rí ojú rẹ̀ yìí, ó dàbí wí pé mo rí ojú Ọlọ́run ni báyìí, tí inú rẹ̀ ti dùn sí mi.
Iacob answered: oh nay but yf I haue founde grace in thy syghte receaue my preaset of my hade: for I haue sene thy face as though I had sene ye face of God: wherfore receaue me to grace
11 Jọ̀wọ́ gba àwọn ohun tí mo mú wá wọ̀nyí lọ́wọ́ mi. Nítorí Ọlọ́run ti fi oore-ọ̀fẹ́ rẹ̀ hàn sí mi, gbogbo ohun tí mo fẹ́ sì ni mo ní.” Nígbà tí Jakọbu sì rọ̀ ọ́ pé Esau gbọdọ̀ gbà wọ́n, Esau sì gbà á.
and take my blessynge that I haue brought the for God hath geuen it me frely. And I haue ynough of all thynges. And so he compelled him to take it.
12 Nígbà náà ni Esau wí pé, “Jẹ́ kí a máa lọ, n ó sìn ọ.”
And he sayde: let us take oure iourney and goo and I will goo in thy copany.
13 Ṣùgbọ́n Jakọbu wí fún un pé, “Ṣe ìwọ náà ṣe àkíyèsí pé ọ̀pọ̀ nínú àwọn ọmọ wọ̀nyí kéré, àwọn màlúù àti àgùntàn pẹ̀lú sì ní àwọn ọmọ kéékèèké. Bí a bá dà wọ́n rìn jìnnà ju bí agbára wọn ṣe mọ lọ, wọ́n lè kú.
And he sayde vnto him: my lorde knoweth that I haue tendre childern ewes and kyne with yonge vnder myne hande which yf men shulde ouerdryue but euen one daye the hole flocke wolde dye.
14 Èmi bẹ̀ ọ́, máa lọ síwájú ìránṣẹ́ rẹ, àwọn ó sì máa rọra bọ̀, títí èmi àti àwọn ọmọ yóò fi dé ọ̀dọ̀ olúwa mi ní Seiri.”
Let my lorde therfore goo before his servaunte and I will dryue fayre and softly accordynge as the catell that goth before me and the childern be able to endure: vntill I come to mi lorde vnto Seir.
15 Esau wí pé, “Jẹ́ kí n fi díẹ̀ sílẹ̀ fún ọ nínú àwọn ọkùnrin mi nígbà náà.” Jakọbu wí pé, “Èéṣe, àní kí n sá à rí ojúrere olúwa mi?”
And Esau sayde: let me yet leaue some of my folke with the. And he sayde: what neadeth it? let me fynde grace in the syghte of my lorde
16 Ní ọjọ́ náà gan an ni Esau padà lọ sí Seiri.
So Esau went his waye agayne yt same daye vnto Seir.
17 Jakọbu sì lọ sí Sukkoti, ó sì kọ́ ilé fún ara rẹ̀, ó sì ṣe ọgbà fún àwọn ẹran. Ìdí èyí ní a fi ń pe ibẹ̀ ní Sukkoti.
And Iacob toke his iourney toward Sucoth and bylt him an house and made boothes for his catell: wherof the name of the place is called Sucoth.
18 Lẹ́yìn ìgbà tí Jakọbu tí Padani-Aramu dé, àlàáfíà ni Jakọbu dé ìlú Ṣekemu ní ilẹ̀ Kenaani, ó sì pàgọ́ sí itòsí ìlú náà.
And Iacob went to Salem to ye cytie of Sichem in the lande of Canaa after that he was come from Mesopotamia and pitched before the cyte
19 Ó sì ra ilẹ̀ kan tí ó pàgọ́ sí ni ọgọ́rùn-ún owó fàdákà lọ́wọ́ àwọn ọmọ Hamori tí í ṣe baba Ṣekemu.
and bought a parcell of ground where he pitched his tent of the childern of Hemor Sichems father for an hundred lambes.
20 Níbẹ̀ ni ó gbé tẹ́ pẹpẹ kan tí ó pè ní El Elohe Israẹli.
And he made there an aulter and there called vpon the myghtie God of Israell.

< Genesis 33 >