< Genesis 22 >

1 Nígbà tí ó ṣe, Ọlọ́run dán Abrahamu wò, ó pè é, ó sì wí pé, “Abrahamu.” Abrahamu sì dáhùn pé, “Èmi nìyí.”
After these dedes God dyd proue Abraham and sayde vnto him: Abraham. And he answered: here am I.
2 Ọlọ́run sì wí pé, “Mú ọmọ rẹ, àní Isaaki ọmọ rẹ kan ṣoṣo nì, tí ìwọ fẹ́ràn, lọ sí ilẹ̀ Moria, kí o sì fi rú ẹbọ sísun níbẹ̀ lórí ọ̀kan nínú àwọn òkè tí èmi yóò sọ fún ọ.”
And he sayde: take thy only sonne Isaac whome thou louest and get the vnto the lande of Moria and sacrifyce him there for a sacrifyce vpon one of the mountayns which I will shewe the
3 Abrahamu sì dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ó sì di kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀ ní gàárì, ó sì mú méjì nínú àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ àti Isaaki ọmọ rẹ̀, ó sì ṣẹ́ igi fún ẹbọ sísun, ó sì gbéra lọ sí ibi tí Ọlọ́run ti sọ fún un.
Than Abraham rose vp early in the mornynge and sadled his asse and toke two of his meyny wyth him and Isaac his sonne: ad clove wod for the sacrifyce and rose vp and gott him to the place which God had appoynted him.
4 Nígbà tí ó di ọjọ́ kẹta, Abrahamu gbé ojú sókè, ó sì rí ibi tí ó ń lọ ní òkèrè,
The thirde daye Abraham lyfte vp his eyes and sawe the place a farr of
5 Abrahamu sì wí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Ẹ̀yin, ẹ dúró níhìn-ín pẹ̀lú kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, èmi àti ọmọ yìí yóò lọ sí ohunkóhun láti sin Ọlọ́run, a ó sì tún padà wá bá a yín.”
and sayde vnto his yong men: byde here with the asse. I and the lad will goo yonder and worshippe and come agayne vnto you.
6 Abrahamu sì gbé igi ẹbọ sísun náà ru Isaaki, òun fúnra rẹ̀ sì mú iná àti ọ̀bẹ. Bí àwọn méjèèjì ti ń lọ,
And Abraham toke the wodd of the sacrifyce and layde it vpon Isaac his sonne and toke fyre in his hande and a knyfe. And they went both of them together.
7 Isaaki sì sọ fún Abrahamu baba rẹ̀ wí pé, “Baba mi.” Abrahamu sì dalóhùn pé, “Èmi nìyí ọmọ mi.” Isaaki sì tún wí pé, “Wò ó iná àti igi nìyí, ṣùgbọ́n níbo ni ọ̀dọ́-àgùntàn fún ẹbọ sísun náà wà?”
Than spake Isaac vnto Abraham his father and sayde: My father? And he answered here am I my sonne. And he sayde: Se here is fyre and wodd but where is the shepe for sacrifyce?
8 Abrahamu sì dáhùn pé, “Ọmọ mi, Ọlọ́run fúnra rẹ̀ ni yóò pèsè ọ̀dọ́-àgùntàn fún ẹbọ sísun náà.” Bẹ́ẹ̀ ni àwọn méjèèjì jùmọ̀ ń lọ.
And Abraham sayde: my sonne God wyll prouyde him a shepe for sacrifyce. So went they both together.
9 Nígbà tí wọn sì dé ibi tí Ọlọ́run sọ fún Abrahamu, ó mọ pẹpẹ kan, ó sì to igi lé e lórí, ó sì di Isaaki ọmọ rẹ̀, ó sì da dùbúlẹ̀ lórí pẹpẹ náà.
And when they came vnto the place which God shewed him Abraha made an aulter there and dressed the wodd ad bownde Isaac his sonne and layde him on the aulter aboue apon the wodd.
10 Abrahamu sì nawọ́ mú ọ̀bẹ, láti dúńbú ọmọ rẹ̀.
And Abraham stretched forth his hande and toke the knyfe to haue kylled his sonne.
11 Ṣùgbọ́n angẹli Olúwa ké sí i láti ọ̀run wá wí pé “Abrahamu! Abrahamu!” Abrahamu sì dáhùn pé, “Èmi nìyí.”
Than the angell of the LORde called vnto him from heauen saynge: Abraham Abraham. And he answered: here am I.
12 Angẹli Olúwa sì wí pé, “Má ṣe fọwọ́ kan ọmọ náà, ìwọ kò sì gbọdọ̀ ṣe é ni ohun kan. Nísinsin yìí ni mo mọ̀ pé o bẹ̀rù Ọlọ́run, nítorí pé ìwọ kò fi ọmọ rẹ, àní, ọmọ rẹ kan ṣoṣo dù mí.”
And he sayde: laye not thy handes apon the childe nether do any thinge at all vnto him for now I knowe that thou fearest God in yt thou hast not kepte thine only sonne fro me.
13 Abrahamu sì gbójú sókè, ó sì rí àgbò kan tí ó fi ìwo há pàǹtírí, ó sì lọ mú un, ó sì fi rú ẹbọ sísun dípò ọmọ rẹ̀.
And Abraham lyfted vp his eyes and loked aboute: and beholde there was a ram caught by the hornes in a thykette. And he went and toke the ram and offred him vp for a sacrifyce in the steade of his sonne
14 Abrahamu sì pe orúkọ ibẹ̀ ni, Jehofah Jire. Bẹ́ẹ̀ ni a sì ń wí títí di òní olónìí pé, “Ní orí òkè Olúwa, ni a ó ti pèsè.”
And Abraham called the name of the place the LORde will see: wherfore it is a come saynge this daye: in the mounte will the LORde be sene.
15 Angẹli Olúwa sì tún pe Abrahamu láti ọ̀run wá lẹ́ẹ̀kejì.
And the Angell of the LORde cryed vnto Abraham from heaven the seconde tyme
16 Ó sì wí pé, Olúwa wí pé, “Mo fi ara mi búra, níwọ̀n bí ìwọ ti ṣe èyí, tí ìwọ kò fi ọmọ rẹ, àní, ọmọ rẹ kan ṣoṣo dù mí,
saynge: by my selfe haue I sworne (sayth the LORde) because thou hast done this thinge and hast not spared thy only sonne
17 nítòótọ́, ní bíbùkún èmi ó bùkún fún ọ, àti ní bíbísí èmi ó sì mú ọ bí sí i bí i ìràwọ̀ ojú ọ̀run àti bí iyanrìn etí Òkun. Irú-ọmọ rẹ yóò sì gba ẹnu ibodè àwọn ọ̀tá wọn,
that I will blesse th and multiplye thy seed as the starres of heaven and as the sonde vpo the seesyde. And thy seed shall possesse the gates of hys enymies.
18 àti nípasẹ̀ irú-ọmọ rẹ ni a ó ti bùkún fún gbogbo orílẹ̀-èdè ayé nítorí tí ìwọ gbọ́rọ̀ sí mi lẹ́nu.”
And in thy seed shall all the nations of the earth be blessed because thou hast obeyed my voyce.
19 Nígbà náà ni Abrahamu padà tọ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ lọ. Gbogbo wọn sì padà lọ sí Beerṣeba. Abrahamu sì jókòó ní Beerṣeba.
So turned Abraham agayne vnto his yonge men and they rose vp and wet to gether to Berseba. And Abraham dwelt at Berseba
20 Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí ni a wí fún Abrahamu pé, “Milka aya Nahori bí àwọn ọmọkùnrin fún un.
And it chaused after these thiges that one tolde Abraham saynge: Beholde Milcha she hath also borne childern vnto thy brother Nachor:
21 Usi àkọ́bí rẹ̀, Busi arákùnrin rẹ̀, Kemueli (baba Aramu).
Hus his eldest sonne and Bus his brother and Lemuell the father of the Sinans
22 Kesedi, Haso, Pildasi, Jidlafi, àti Betueli.”
and Cesed and Haso and Pildas and Iedlaph and Bethuel.
23 Betueli sì ni baba Rebeka. Milka sì bí àwọn ọmọ mẹ́jọ wọ̀nyí fún Nahori arákùnrin Abrahamu.
And Bethuel begat Rebecca. These. viij. dyd Milcha bere to Nachor Abrahams brother
24 Àlè rẹ̀ tí ń jẹ́ Reuma náà bí àwọn ọmọkùnrin wọ̀nyí fun un: Teba, Gahamu, Tahasi àti Maaka.
And his concubyne called Rheuma she bare also Tebah Gaham Thahas and Maacha.

< Genesis 22 >