< Genesis 21 >

1 Olúwa sì bẹ Sara wò bí ó ti wí, Olúwa sì ṣe fún Sara gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣèlérí.
A PAN nawiedził Sarę, jak powiedział, i uczynił PAN Sarze, jak zapowiedział.
2 Sara sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan fún Abrahamu ní ọjọ́ ogbó rẹ̀, ní àkókò náà gan an tí Ọlọ́run ti ṣèlérí fún un.
Sara poczęła bowiem i urodziła Abrahamowi syna w jego starości w tym czasie, który przepowiedział mu Bóg.
3 Abrahamu sì sọ orúkọ ọmọ náà tí Sara bí fun un ní Isaaki.
Abraham nadał swemu synowi, który mu się urodził, którego mu urodziła Sara, imię Izaak.
4 Nígbà tí Isaaki pé ọmọ ọjọ́ mẹ́jọ, Abrahamu sì kọ ọ́ ní ilà gẹ́gẹ́ bí Ọlọ́run ti pàṣẹ fún un.
I Abraham obrzezał swego syna Izaaka, gdy ten miał osiem dni, jak Bóg mu rozkazał.
5 Ẹni ọgọ́rùn-ún ọdún ni Abrahamu nígbà tí ó bí Isaaki.
A Abraham miał sto lat, gdy mu się urodził jego syn Izaak.
6 Sara sì wí pé, “Ọlọ́run ti pa mí lẹ́rìn-ín. Gbogbo ẹni tí ó bá sì gbọ́ pé mo bímọ yóò rẹ́rìn-ín pẹ̀lú mi.”
Wtedy Sara powiedziała: Bóg dał mi powód do śmiechu; ktokolwiek [o tym] usłyszy, będzie się śmiał ze mną.
7 Ó sì fi kún un pé, “Ta ni ó le sọ fún Abrahamu pé, Sara yóò di ọlọ́mọ? Síbẹ̀síbẹ̀, mo sì tún bí ọmọ fún Abrahamu ní ìgbà ogbó rẹ.”
I dodała: Kto by powiedział Abrahamowi, że Sara będzie karmiła piersią dzieci? Gdyż urodziłam mu syna w jego starości.
8 Nígbà tí ọmọ náà dàgbà, ó sì gbà á lẹ́nu ọmú, ní ọjọ́ tí a gba Isaaki lẹ́nu ọmú, Abrahamu ṣe àsè ńlá.
Dziecko rosło i zostało odstawione od piersi. I Abraham wyprawił wielką ucztę w dniu odstawienia Izaaka.
9 Ṣùgbọ́n Sara rí ọmọ Hagari ará Ejibiti tí ó bí fún Abrahamu tí ó fi ṣe ẹlẹ́yà,
Gdy Sara zobaczyła syna Egipcjanki Hagar, którego ta urodziła Abrahamowi, szydzącego;
10 ó sì wí fún Abrahamu pé, “Lé ẹrúbìnrin yìí àti ọmọ rẹ̀ jáde, nítorí ọmọ ẹrú yìí kò ní bá ọmọ mi Isaaki pín ogún.”
Powiedziała do Abrahama: Wyrzuć tę niewolnicę i jej syna, bo syn tej niewolnicy nie będzie dziedziczyć z moim synem Izaakiem.
11 Ọ̀rọ̀ náà sì ba Abrahamu lọ́kàn jẹ́ gidigidi nítorí ọmọ rẹ̀ náà sá à ni Iṣmaeli i ṣe.
Słowa te wydały się Abrahamowi bardzo przykre ze względu na jego syna.
12 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run wí fun Abrahamu pé, “Má ṣe ba ọkàn jẹ́ nítorí ọmọ náà àti ẹrúbìnrin rẹ. Gbọ́ ohun tí Sara wí fún ọ, nítorí nínú Isaaki ni a ó ti pe irú-ọmọ rẹ̀.
Wtedy Bóg powiedział do Abrahama: Niech ci nie będzie przykro z powodu chłopca i twojej niewolnicy. Posłuchaj wszystkiego, co Sara mówi do ciebie, bo w Izaaku będzie nazwane twoje potomstwo.
13 Èmi yóò sọ ọmọ ẹrúbìnrin náà di orílẹ̀-èdè pẹ̀lú, nítorí ọmọ rẹ ni.”
Syna zaś [tej] niewolnicy również uczynię narodem, bo jest on twoim potomstwem.
14 Abrahamu sì dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ó sì mú oúnjẹ àti ìgò omi kan, ó sì kó wọn fún Hagari, ó kó wọn lé e léjìká, ó sì lé e jáde pẹ̀lú ọmọ náà. Ó sì lọ lọ́nà rẹ, ó sì ń ṣe alárìnkiri ní ijù Beerṣeba.
Abraham wstał więc wcześnie rano, wziął chleb i bukłak wody i dał Hagar, wkładając jej to na ramię, oraz [wziął] dziecko i odprawił ją. Ona zaś odeszła i błąkała się po pustyni Beer-Szeby.
15 Nígbà tí omi inú ìgò náà tan, ó gbé ọmọ náà sí abẹ́ igbó.
A gdy skończyła się woda w bukłaku, porzuciła dziecko pod jednym z krzewów.
16 Ó sì lọ, ó sì jókòó nítòsí ibẹ̀, níwọ̀n bí ìtafà kan, nítorí, ó rò ó nínú ara rẹ̀ pé, “Èmi kò fẹ́ wo bí ọmọ náà yóò ṣe kú.” Bí ó sì ti jókòó sí tòsí ibẹ̀, ó bẹ̀rẹ̀ sí ní sọkún.
Potem odeszła i usiadła naprzeciw niego w odległości strzału z łuku. Mówiła bowiem: Nie będę patrzyła na śmierć dziecka. Usiadła więc naprzeciw niego i zaczęła głośno płakać.
17 Ọlọ́run gbọ́ ohun ẹkún náà, Angẹli Ọlọ́run sì pe Hagari láti ọ̀run, ó sì wí fun un pé, “Hagari, kín ni ó ṣe ọ́? Má bẹ̀rù nítorí Ọlọ́run ti gbọ́ ẹkún ọmọ náà níbi tí o tẹ́ ẹ sí.
I Bóg usłyszał głos chłopca, i Anioł Boga zawołał na Hagar z nieba: Co ci jest, Hagar? Nie bój się, bo Bóg usłyszał głos chłopca [tam], gdzie jest.
18 Dìde, gbé ọmọ náà sókè, kí o sì dìímú (tù ú nínú) nítorí èmi yóò sọ ọmọ náà di orílẹ̀-èdè ńlá.”
Wstań, podnieś chłopca i weź go za rękę, bo uczynię go wielkim narodem.
19 Ọlọ́run sì ṣí ojú Hagari, ó sì rí kànga kan, ó lọ síbẹ̀, ó rọ omi kún inú ìgò náà, ó sì fún ọmọ náà mu.
Wtedy Bóg otworzył jej oczy i zobaczyła studnię z wodą. Poszła więc, napełniła bukłak wodą i dała chłopcu pić.
20 Ọlọ́run sì wà pẹ̀lú ọmọ náà bí ó ti ń dàgbà, ó ń gbé nínú ijù, ó sì di tafàtafà.
I Bóg był z chłopcem. Urósł i mieszkał na pustyni, i stał się łucznikiem.
21 Nígbà tí ó ń gbé ni aginjù ní Parani, ìyá rẹ̀ fẹ́ ìyàwó fún un láti ilẹ̀ Ejibiti wá.
A mieszkał na pustyni Paran. I jego matka wzięła dla niego żonę z ziemi Egiptu.
22 Ní àkókò yìí ni ọba Abimeleki àti Fikoli, olórí ogun rẹ̀ wí fún Abrahamu pé, “Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ̀ nínú gbogbo ohun tí ó ń ṣe.
W tym czasie Abimelek wraz z dowódcą swego wojska Pikolem powiedział do Abrahama: Bóg jest z tobą we wszystkim, co czynisz.
23 Ǹjẹ́ nísinsin yìí, fi Ọlọ́run búra fún mi, ìwọ kì yóò tàn mí àti àwọn ọmọ mi àti àwọn ìran mi, ìwọ yóò fi inú rere hàn fún mi àti orílẹ̀-èdè tí ìwọ ti ṣe àtìpó, bí mo ti fihàn fún ọ pẹ̀lú.”
Teraz [więc] przysięgnij mi tu na Boga, że nie postąpisz zdradliwie wobec mnie ani mego syna, ani mego wnuka. [Ale] według miłosierdzia, które ci okazałem, postąpisz ze mną i z ziemią, w której jesteś przybyszem.
24 Abrahamu sì wí pé, “Èmí búra.”
Abraham odpowiedział: Przysięgam.
25 Nígbà náà ni Abrahamu fi ẹ̀dùn ọkàn rẹ̀ hàn fún Abimeleki nípa kànga tí àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ gbà lọ́wọ́ rẹ̀.
I Abraham poskarżył się Abimelekowi z powodu studni z wodą, którą mu przemocą zabrali słudzy Abimeleka.
26 Ṣùgbọ́n Abimeleki dáhùn pé, “Èmi kò mọ ẹni tí ó ṣe nǹkan yìí. Ìwọ kò sì sọ fún mi, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò gbọ́, bí kò ṣe lónìí.”
Abimelek powiedział: Nie wiem, kto to uczynił. Ani nie powiedziałeś mi o tym, ani nie słyszałem o tym aż dopiero dziś.
27 Abrahamu sì mú àgùntàn àti màlúù wá, ó sì kó wọn fún Abimeleki. Àwọn méjèèjì sì dá májẹ̀mú.
Abraham wziął więc owce i woły i dał je Abimelekowi, i obaj zawarli przymierze.
28 Abrahamu sì ya abo ọ̀dọ́-àgùntàn méje nínú agbo àgùntàn rẹ̀ sọ́tọ̀.
I Abraham wydzielił z trzody siedmioro jagniąt.
29 Abimeleki sì béèrè lọ́wọ́ Abrahamu pé, “Kín ni ìtumọ̀ yíyà tí ìwọ ya àwọn ọ̀dọ́-àgùntàn méje wọ̀nyí sọ́tọ̀ sí.”
Abimelek zapytał Abrahama: Po co te siedmioro jagniąt, które postawiłeś osobno?
30 Ó dalóhùn pé, “Gba àwọn abo ọ̀dọ́-àgùntàn méje wọ̀nyí lọ́wọ́ mi gẹ́gẹ́ bí ẹ̀rí pé èmi ni mo gbẹ́ kànga yìí.”
A [on] odpowiedział: Te siedem owiec weźmiesz z moich rąk, aby były świadectwem, że wykopałem tę studnię.
31 Nítorí náà ni a ṣe ń pe ibẹ̀ náà ni Beerṣeba nítorí níbẹ̀ ni àwọn méjèèjì gbé búra.
Dlatego nazwano to miejsce Beer-Szeba, bo tam obaj sobie przysięgli.
32 Lẹ́yìn májẹ̀mú tí wọ́n dá ní Beerṣeba yìí, ni Abimeleki àti Fikoli olórí ogun rẹ̀ padà sí ilẹ̀ àwọn ará Filistini.
Tak zawarli przymierze w Beer-Szebie. Potem Abimelek i Pikol, dowódca jego wojska, wstali i wrócili do ziemi Filistynów.
33 Abrahamu lọ́ igi tamariski kan sí Beerṣeba, níbẹ̀ ni ó sì pe orúkọ Olúwa Ọlọ́run ayérayé.
[Abraham] zaś zasadził drzewa w Beer-Szebie i wzywał tam imienia PANA, Boga wiecznego.
34 Abrahamu sì gbé ilẹ̀ àwọn ará Filistini fún ọjọ́ pípẹ́.
I Abraham gościł w ziemi Filistynów przez wiele dni.

< Genesis 21 >