< Genesis 15 >

1 Lẹ́yìn èyí, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Abramu wá lójú ìran pé, “Abramu má ṣe bẹ̀rù. Èmi ni ààbò rẹ, Èmi sì ni èrè ńlá rẹ.”
Po tych wydarzeniach słowo PANA doszło do Abrama w widzeniu: Nie bój się, Abramie. Ja jestem twoją tarczą i twoją niezmiernie obfitą nagrodą.
2 Ṣùgbọ́n Abramu wí pé, “Olúwa Olódùmarè, kí ni ìwọ yóò fi fún mi níwọ̀n ìgbà tí èmi kò bímọ, Elieseri ará Damasku ni yóò sì jogún mi,”
I Abram powiedział: Panie BOŻE, co mi dasz, skoro ja jestem bezdzietny, a szafarzem mego domu [jest] ten Damasceńczyk Eliezer?
3 Abramu sì tún tẹ̀síwájú pé, “Ìwọ kò fún mi ní ọmọ, nítorí náà ẹrú nínú ilé mi sì ni yóò jẹ́ àrólé mi.”
Abram dodał: Oto nie dałeś mi potomka, a sługa [urodzony] w moim domu będzie moim dziedzicem.
4 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tún tọ̀ ọ́ wá pé, “Ọkùnrin yìí kọ́ ni yóò jẹ́ àrólé rẹ bí kò ṣe ọmọ tí ìwọ bí fúnra rẹ̀ ni yóò jẹ́ àrólé rẹ.”
A oto [dotarło] do niego słowo PANA: Nie on będzie twoim dziedzicem, lecz ten, który wyjdzie z twego wnętrza, będzie twoim dziedzicem.
5 Olúwa sì mú Abramu jáde sí ìta ó sì wí fún un pé, “Gbé ojú sókè sí ọ̀run kí o sì ka àwọn ìràwọ̀ bí ó bá ṣe pé ìwọ le è kà wọ́n.” Ó sì wí fun un pé, “Nítorí náà, báyìí ni irú-ọmọ rẹ yóò rí.”
Potem wyprowadził go na dwór i powiedział: Spójrz teraz na niebo i policz gwiazdy, jeśli będziesz mógł je policzyć; i powiedział mu: Takie będzie twoje potomstwo.
6 Abramu gba Olúwa gbọ́, a sì kà á sí òdodo fún un.
I uwierzył PANU, i poczytano mu [to] za sprawiedliwość.
7 Ó sì tún wí fún un pé, “Èmi ni Olúwa tí ó mú ọ jáde láti Uri ti Kaldea láti fún ọ ní ilẹ̀ yìí láti jogún.”
Potem powiedział do niego: Ja jestem PANEM, który cię wyprowadził z Ur chaldejskiego, aby ci dać tę ziemię w posiadanie.
8 Ṣùgbọ́n Abramu wí pé, “Olúwa Olódùmarè, báwo ni mo ṣe lè mọ̀ pé ilẹ̀ náà yóò jẹ́ ohun ìní mi?”
[Abram] zapytał: Panie BOŻE, po czym poznam, że ją odziedziczę?
9 Nítorí náà, Olúwa wí fún un pé, “Mú abo màlúù, ewúrẹ́ àti àgbò ọlọ́dún mẹ́ta mẹ́ta wá, àti àdàbà kan àti ọmọ ẹyẹlé kan.”
I odpowiedział mu: Weź dla mnie trzyletnią jałówkę, trzyletnią kozę i trzyletniego barana, a także synogarlicę i pisklę gołębia.
10 Abramu sì mú gbogbo nǹkan wọ̀nyí wá, ó sì là wọ́n sí méjì méjì, ó sì fi ẹ̀là èkínní kọjú sí èkejì, ṣùgbọ́n kò la àwọn ẹyẹ ní tiwọn.
Wziął więc to wszystko i rozciął na połowy; a jedną część położył naprzeciwko drugiej, ale ptaków nie rozcinał.
11 Àwọn ẹyẹ igún sì ń wá sórí òkú ẹran náà, Abramu sì ń lé wọn.
Kiedy zleciało się ptactwo do tej padliny, Abram je odganiał.
12 Bí oòrùn ti ń wọ̀, Abramu sùn lọ fọnfọn, òkùnkùn biribiri tí ó kún fún ẹ̀rù sì bò ó.
[Gdy] słońce zachodziło, głęboki sen ogarnął Abrama i oto groza wielkiej ciemności zapadła na niego.
13 Nígbà náà ni Olúwa wí fún Abramu pé, “Mọ èyí dájú pé, irú-ọmọ rẹ yóò ṣe àtìpó ní ilẹ̀ àjèjì, wọn ó sì sọ wọn di ẹrú, wọn ó sì pọ́n wọn lójú fún irinwó ọdún.
I [PAN] powiedział do Abrama: Wiedz o tym dobrze, że twoje potomstwo będzie przybyszem w cudzej ziemi i wezmą je w niewolę, i będzie uciskane [przez] czterysta lat.
14 Ṣùgbọ́n orílẹ̀-èdè náà tí wọn yóò máa sìn, ni èmi ó dá lẹ́jọ́, lẹ́yìn náà ni wọn ó sì jáde pẹ̀lú ọrọ̀ púpọ̀.
A ja osądzę ten naród, któremu będą służyć; a potem wyjdą [stamtąd] z wielkim dobytkiem.
15 Ṣùgbọ́n ìwọ yóò tọ àwọn baba rẹ lọ ni àlàáfíà, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ yóò sì di arúgbó kí a tó gbé ọ sin.
Ale ty odejdziesz w pokoju do twoich ojców i będziesz pochowany w dobrej starości.
16 Ní ìran kẹrin àwọn ìran rẹ yóò padà wá sí ibi. Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ará Amori kò ì tí ì kún òsùwọ̀n.”
A w czwartym pokoleniu wrócą tutaj, bo jeszcze nie dopełniła się nieprawość Amorytów.
17 Nígbà tí oòrùn wọ̀ tí ilẹ̀ sì ṣú, ìkòkò iná tí ń ṣèéfín àti ọwọ́ iná sì ń kọjá láàrín ẹ̀là ẹran náà.
Gdy słońce zaszło i nastała ciemność, oto [ukazał się] dymiący piec i ognista pochodnia, która przechodziła między tymi połowami [zwierząt].
18 Ní ọjọ́ náà gan an ni Olúwa dá májẹ̀mú pẹ̀lú Abramu, ó sì wí pé, “Àwọn ìran rẹ ni èmi yóò fi ilẹ̀ yìí fún, láti odò Ejibiti dé odò ńlá Eufurate:
W tym właśnie dniu PAN zawarł przymierze z Abramem, mówiąc: Twemu potomstwu dam tę ziemię, od rzeki Egiptu aż do wielkiej rzeki, rzeki Eufrat;
19 ilẹ̀ àwọn ará Keni, àti ti ará Kenissiti, àti ará Kadmoni,
Kenitów, Kenizytów i Kadmonitów;
20 àti ti ará Hiti, àti ti ará Peresi, àti ti ará Refaimu.
Chetytów, Peryzzytów i Refaitów;
21 Àti ti ará Amori, àti ti ará Kenaani, àti ti ará Girgaṣi àti ti ará Jebusi.”
Amorytów, Kananejczyków, Girgaszytów i Jebusytów.

< Genesis 15 >