< Genesis 15 >

1 Lẹ́yìn èyí, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Abramu wá lójú ìran pé, “Abramu má ṣe bẹ̀rù. Èmi ni ààbò rẹ, Èmi sì ni èrè ńlá rẹ.”
After these deades ye worde of God came vnto Abram in a vision saynge feare not Abram I am thy shilde and thy rewarde shalbe exceadynge greate.
2 Ṣùgbọ́n Abramu wí pé, “Olúwa Olódùmarè, kí ni ìwọ yóò fi fún mi níwọ̀n ìgbà tí èmi kò bímọ, Elieseri ará Damasku ni yóò sì jogún mi,”
And Abram answered: LORde Iehouah what wilt thou geue me: I goo childlesse and the cater of myne housse this Eleasar of Damasco hath a sonne.
3 Abramu sì tún tẹ̀síwájú pé, “Ìwọ kò fún mi ní ọmọ, nítorí náà ẹrú nínú ilé mi sì ni yóò jẹ́ àrólé mi.”
And Abram sayd: se to me hast thou geven no seed: lo a lad borne in my housse shalbe myne heyre.
4 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tún tọ̀ ọ́ wá pé, “Ọkùnrin yìí kọ́ ni yóò jẹ́ àrólé rẹ bí kò ṣe ọmọ tí ìwọ bí fúnra rẹ̀ ni yóò jẹ́ àrólé rẹ.”
And beholde the worde of the LORde spake vnto Abram sayenge: He shall not be thyne heyre but one that shall come out of thyne awne bodye shalbe thyne heyre.
5 Olúwa sì mú Abramu jáde sí ìta ó sì wí fún un pé, “Gbé ojú sókè sí ọ̀run kí o sì ka àwọn ìràwọ̀ bí ó bá ṣe pé ìwọ le è kà wọ́n.” Ó sì wí fun un pé, “Nítorí náà, báyìí ni irú-ọmọ rẹ yóò rí.”
And he brought him out at the doores ad sayde. Loke vpp vnto heaven and tell the starres yf thou be able to nobre them. And sayde vnto him Even so shall thy seed be.
6 Abramu gba Olúwa gbọ́, a sì kà á sí òdodo fún un.
And Abram beleved the LORde and it was counted to him for rightwesnes.
7 Ó sì tún wí fún un pé, “Èmi ni Olúwa tí ó mú ọ jáde láti Uri ti Kaldea láti fún ọ ní ilẹ̀ yìí láti jogún.”
And he sayde vnto hym: I am the LORde that brought the out of Vrin Chaldea to geue the this lande to possesse it.
8 Ṣùgbọ́n Abramu wí pé, “Olúwa Olódùmarè, báwo ni mo ṣe lè mọ̀ pé ilẹ̀ náà yóò jẹ́ ohun ìní mi?”
And he sayde: LORde God whereby shall I knowe that I shall possesse it?
9 Nítorí náà, Olúwa wí fún un pé, “Mú abo màlúù, ewúrẹ́ àti àgbò ọlọ́dún mẹ́ta mẹ́ta wá, àti àdàbà kan àti ọmọ ẹyẹlé kan.”
And he sayde vnto him: take an heyfer of. iij. yere olde and a she gotte of thre yeres olde and a thre yere olde ram a turtill doue and a yonge pigeon.
10 Abramu sì mú gbogbo nǹkan wọ̀nyí wá, ó sì là wọ́n sí méjì méjì, ó sì fi ẹ̀là èkínní kọjú sí èkejì, ṣùgbọ́n kò la àwọn ẹyẹ ní tiwọn.
And he toke all these and devyded them in the myddes and layde euery pece one over agenst a nother. But the foules devyded he not.
11 Àwọn ẹyẹ igún sì ń wá sórí òkú ẹran náà, Abramu sì ń lé wọn.
And the byrdes fell on the carcases but Abra droue the awaye.
12 Bí oòrùn ti ń wọ̀, Abramu sùn lọ fọnfọn, òkùnkùn biribiri tí ó kún fún ẹ̀rù sì bò ó.
And when the sonne was doune there fell a slomber apon Abram. And loo feare and greate darknesse came apon hym.
13 Nígbà náà ni Olúwa wí fún Abramu pé, “Mọ èyí dájú pé, irú-ọmọ rẹ yóò ṣe àtìpó ní ilẹ̀ àjèjì, wọn ó sì sọ wọn di ẹrú, wọn ó sì pọ́n wọn lójú fún irinwó ọdún.
And he sayde vnto Abram: knowe this of a suertie that thi seed shalbe a straunger in a lande that perteyneth not vnto the. And they shall make bondmen of them and entreate them evell iiij. hundred yeares.
14 Ṣùgbọ́n orílẹ̀-èdè náà tí wọn yóò máa sìn, ni èmi ó dá lẹ́jọ́, lẹ́yìn náà ni wọn ó sì jáde pẹ̀lú ọrọ̀ púpọ̀.
But the nation whom they shall serue wyll I iudge. And after warde shall they come out wyth greate substace.
15 Ṣùgbọ́n ìwọ yóò tọ àwọn baba rẹ lọ ni àlàáfíà, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ yóò sì di arúgbó kí a tó gbé ọ sin.
Neuerthelesse thou shalt goo vnto thi fathers in peace ad shalt be buried when thou art of a good age:
16 Ní ìran kẹrin àwọn ìran rẹ yóò padà wá sí ibi. Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ará Amori kò ì tí ì kún òsùwọ̀n.”
ad in the fourth generation they shall come hyther agayne for the wekednesse of the Amorites ys not yet full.
17 Nígbà tí oòrùn wọ̀ tí ilẹ̀ sì ṣú, ìkòkò iná tí ń ṣèéfín àti ọwọ́ iná sì ń kọjá láàrín ẹ̀là ẹran náà.
When the sonne was doune and it was waxed darke: beholde there was a smokynge furnesse and a fyre brand that went betwene the sayde peces.
18 Ní ọjọ́ náà gan an ni Olúwa dá májẹ̀mú pẹ̀lú Abramu, ó sì wí pé, “Àwọn ìran rẹ ni èmi yóò fi ilẹ̀ yìí fún, láti odò Ejibiti dé odò ńlá Eufurate:
And that same daye the LORde made a covenaunte with Abram saynge: vnto thy seed wyll I geue thys londe fro the ryver of Egypte even vnto the greate ryver euphrates:
19 ilẹ̀ àwọn ará Keni, àti ti ará Kenissiti, àti ará Kadmoni,
the kenytes the kenizites the Cadmonites
20 àti ti ará Hiti, àti ti ará Peresi, àti ti ará Refaimu.
the Hethites the Pherezites the Raphaims
21 Àti ti ará Amori, àti ti ará Kenaani, àti ti ará Girgaṣi àti ti ará Jebusi.”
the Amorytes the Canaanites the Gergesites and the Iebusites.

< Genesis 15 >