< Genesis 15 >

1 Lẹ́yìn èyí, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Abramu wá lójú ìran pé, “Abramu má ṣe bẹ̀rù. Èmi ni ààbò rẹ, Èmi sì ni èrè ńlá rẹ.”
After all this had happened, God spoke to Abram in a vision, telling him, “Don't be afraid, Abram! I am your protector, and your truly great reward!”
2 Ṣùgbọ́n Abramu wí pé, “Olúwa Olódùmarè, kí ni ìwọ yóò fi fún mi níwọ̀n ìgbà tí èmi kò bímọ, Elieseri ará Damasku ni yóò sì jogún mi,”
But Abram replied, “Lord God, what good is whatever you give me? I don't have any children, and the heir to all that I have is Eliezer of Damascus.”
3 Abramu sì tún tẹ̀síwájú pé, “Ìwọ kò fún mi ní ọmọ, nítorí náà ẹrú nínú ilé mi sì ni yóò jẹ́ àrólé mi.”
Abram went on to complain, “Look! You haven't given me any children, so a servant from my household has to be my heir!”
4 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tún tọ̀ ọ́ wá pé, “Ọkùnrin yìí kọ́ ni yóò jẹ́ àrólé rẹ bí kò ṣe ọmọ tí ìwọ bí fúnra rẹ̀ ni yóò jẹ́ àrólé rẹ.”
But then the Lord told him, “This man won't be your heir. Your heir will be your very own son.”
5 Olúwa sì mú Abramu jáde sí ìta ó sì wí fún un pé, “Gbé ojú sókè sí ọ̀run kí o sì ka àwọn ìràwọ̀ bí ó bá ṣe pé ìwọ le è kà wọ́n.” Ó sì wí fun un pé, “Nítorí náà, báyìí ni irú-ọmọ rẹ yóò rí.”
The Lord took Abram outside and said to him, “Look up at the sky. See if you can count the stars! That's how many descendants you will have!”
6 Abramu gba Olúwa gbọ́, a sì kà á sí òdodo fún un.
Abram trusted what the Lord said, and so the Lord counted Abram as being in a right relationship with him.
7 Ó sì tún wí fún un pé, “Èmi ni Olúwa tí ó mú ọ jáde láti Uri ti Kaldea láti fún ọ ní ilẹ̀ yìí láti jogún.”
The Lord also told him, “I am the Lord, who led you from Ur of the Chaldeans to give you this land for you to own.”
8 Ṣùgbọ́n Abramu wí pé, “Olúwa Olódùmarè, báwo ni mo ṣe lè mọ̀ pé ilẹ̀ náà yóò jẹ́ ohun ìní mi?”
“But Lord God, how can I be certain that I will own it?” Abram asked.
9 Nítorí náà, Olúwa wí fún un pé, “Mú abo màlúù, ewúrẹ́ àti àgbò ọlọ́dún mẹ́ta mẹ́ta wá, àti àdàbà kan àti ọmọ ẹyẹlé kan.”
The Lord told him, “Bring me a cow, a goat, and a ram, all of them three years old, together with a dove and a young pigeon.”
10 Abramu sì mú gbogbo nǹkan wọ̀nyí wá, ó sì là wọ́n sí méjì méjì, ó sì fi ẹ̀là èkínní kọjú sí èkejì, ṣùgbọ́n kò la àwọn ẹyẹ ní tiwọn.
So Abram took and killed the three animals. Then he cut them in half, and placed each half opposite the other. However, he didn't cut the birds in half.
11 Àwọn ẹyẹ igún sì ń wá sórí òkú ẹran náà, Abramu sì ń lé wọn.
When vultures flew down on the carcasses, Abram frightened them off.
12 Bí oòrùn ti ń wọ̀, Abramu sùn lọ fọnfọn, òkùnkùn biribiri tí ó kún fún ẹ̀rù sì bò ó.
As the sun went down, a deep sleep came over Abram, and at the same time a dense and terrifying darkness fell on him.
13 Nígbà náà ni Olúwa wí fún Abramu pé, “Mọ èyí dájú pé, irú-ọmọ rẹ yóò ṣe àtìpó ní ilẹ̀ àjèjì, wọn ó sì sọ wọn di ẹrú, wọn ó sì pọ́n wọn lójú fún irinwó ọdún.
The Lord explained to Abram, “You can be absolutely sure that your descendants will be strangers in a foreign land, where they will be slaves and mistreated for 400 years.
14 Ṣùgbọ́n orílẹ̀-èdè náà tí wọn yóò máa sìn, ni èmi ó dá lẹ́jọ́, lẹ́yìn náà ni wọn ó sì jáde pẹ̀lú ọrọ̀ púpọ̀.
However, I will punish the nation that makes them slaves, and later on they will leave, taking many valuable possessions with them.
15 Ṣùgbọ́n ìwọ yóò tọ àwọn baba rẹ lọ ni àlàáfíà, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ yóò sì di arúgbó kí a tó gbé ọ sin.
But as for you, you will die in peace and be buried, having lived a good long life.
16 Ní ìran kẹrin àwọn ìran rẹ yóò padà wá sí ibi. Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ará Amori kò ì tí ì kún òsùwọ̀n.”
Four generations later your descendants will come back here to live, because right now the sins of the Amorites have not reached their full extent.”
17 Nígbà tí oòrùn wọ̀ tí ilẹ̀ sì ṣú, ìkòkò iná tí ń ṣèéfín àti ọwọ́ iná sì ń kọjá láàrín ẹ̀là ẹran náà.
After the sun set and it grew dark, suddenly a smoking furnace and a flaming torch appeared and passed between the halves of the animal carcasses.
18 Ní ọjọ́ náà gan an ni Olúwa dá májẹ̀mú pẹ̀lú Abramu, ó sì wí pé, “Àwọn ìran rẹ ni èmi yóò fi ilẹ̀ yìí fún, láti odò Ejibiti dé odò ńlá Eufurate:
This is how the Lord made an agreement with Abram that day and promised him, “I'm giving this land to your descendants. It extends from the Wadi of Egypt to the great Euphrates River,
19 ilẹ̀ àwọn ará Keni, àti ti ará Kenissiti, àti ará Kadmoni,
and includes the territory of the Kenites, Kenizzites, Kadmonites,
20 àti ti ará Hiti, àti ti ará Peresi, àti ti ará Refaimu.
Hittites, Perizzites, Rephaites,
21 Àti ti ará Amori, àti ti ará Kenaani, àti ti ará Girgaṣi àti ti ará Jebusi.”
Amorites, Canaanites, Girgashites, and Jebusites.”

< Genesis 15 >